< 2 Chroniques 15 >
1 L’Esprit de Dieu vint sur Azarias, fils d’Oded,
Ẹ̀mí Ọlọ́run wá sórí Asariah ọmọ Odedi.
2 qui alla au-devant d’Asa et lui dit: « Ecoutez-moi, Asa, et tout Juda et tout Benjamin. Yahweh est avec vous quand vous êtes avec lui; si vous le cherchez, il se laissera trouver par vous; mais si vous l’abandonnez, il vous abandonnera.
Ó jáde lọ bá Asa, ó sì wí fún un pé, “Tẹ́tí si mi Asa, àti gbogbo Juda àti Benjamini. Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nígbà tí ìwọ bá wà pẹ̀lú rẹ̀. Ti ìwọ bá wá a, ìwọ yóò rí i ní ẹ̀bá ọ̀dọ̀ rẹ ṣùgbọ́n tí ìwọ bá kọ̀ ọ́ sílẹ̀, òun yóò kọ̀ ọ́ sílẹ̀.
3 Pendant longtemps Israël a été sans vrai Dieu, sans prêtre qui enseignât, sans loi;
Fún ọjọ́ pípẹ́ ni Israẹli ti wà láì sin Ọlọ́run òtítọ́, àti láìní àlùfáà ti ń kọ́ ni, àti láìní òfin.
4 mais, dans sa détresse, il s’est retourné vers Yahweh, son Dieu; ils l’ont cherché, et s’est laissé trouver par eux.
Ṣùgbọ́n nínú ìpọ́njú wọn, wọ́n yí padà si Olúwa Ọlọ́run Israẹli, wọ́n sì wa kiri. Wọ́n sì ri i ní ẹ̀gbẹ́ wọn.
5 Dans ces temps-là, pas de sécurité pour ceux qui allaient et venaient, car de grandes confusions pesaient sur tous les habitants des pays.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ó léwu kí ènìyàn máa rìn ìrìnàjò kiri, nítorí tí gbogbo àwọn olùgbé ilẹ̀ náà wà nínú làálàá ńlá.
6 On se heurtait, peuple contre peuple, ville contre ville, parce que Dieu les agitait par toutes sortes de tribulations.
Orílẹ̀-èdè kan ń run èkejì àti ìlú kan sí òmíràn nítorí Ọlọ́run ń yọ wọ́n lẹ́nu pẹ̀lú oríṣìíríṣìí ìpọ́njú.
7 Vous donc, montrez-vous forts, et que vos mains ne faiblissent pas, car il y aura récompense pour vos œuvres. »
Ṣùgbọ́n fun ìwọ, jẹ́ alágbára, kí ó má sì ṣe ṣàárẹ̀. Nítorí tí a ó fi èrè sí iṣẹ́ ẹ̀ rẹ.”
8 En entendant ces paroles, la prophétie d’Oded, le prophète, Asa prit courage; il fit disparaître les abominations de tout le pays de Juda et de Benjamin et des villes qu’il avait prises dans la montagne d’Ephraïm, et restaura l’autel de Yahweh qui était devant le portique de Yahweh.
Nígbà tí Asa gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí àti àsọtẹ́lẹ̀ Asariah ọmọ Odedi wòlíì, ó mú àyà rẹ̀ le. Ó sì mú gbogbo ohun ìríra kúrò ní gbogbo ilẹ̀ Juda àti Benjamini àti kúrò nínú àwọn ìlú tí ó ti fi agbára mú ní orí òkè Efraimu. Ó tún pẹpẹ Olúwa ṣe tí ó wà ní iwájú portiko ti ilé Olúwa.
9 Il rassembla tout Juda et Benjamin, et ceux d’Ephraïm, de Manassé et de Siméon qui étaient venus séjourner parmi eux; car un grand nombre de gens d’Israël avaient passé de son côté, en voyant que Yahweh, son Dieu, était avec lui.
Nígbà náà, ó pe gbogbo Juda àti Benjamini jọ àti àwọn ènìyàn láti Efraimu, Manase àti Simeoni tí ó ti ṣe àtìpó ní àárín wọn. Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti Israẹli nígbà tí wọ́n rí i wí pé Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
10 Ils s’assemblèrent à Jérusalem le troisième mois de la quinzième année du règne d’Asa.
Wọ́n péjọ sí Jerusalẹmu ní oṣù kẹta ọdún kẹ́ẹ̀dógún ti ìjọba Asa.
11 Ce jour-là, ils immolèrent à Yahweh, sur le butin qu’ils avaient amené, sept cents bœufs et sept mille brebis.
Ní àkókò yìí, wọ́n rú ẹbọ sí Olúwa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin akọ màlúù àti ẹ̀ẹ́dẹ́gbàárin àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ láti ibi ìkógun tí wọ́n ti kó padà.
12 Ils prirent l’engagement solennel de chercher Yahweh, le Dieu de leurs pères, de tout leur cœur et de toute leur âme,
Wọ́n sì tún dá májẹ̀mú láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wọn tinútinú wọn àti tọkàntọkàn wọn.
13 et quiconque ne rechercherait pas Yahweh, le Dieu d’Israël, serait mis à mort, le petit comme le grand, l’homme comme la femme.
Pé ẹnikẹ́ni tí kò bá wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli, pípa ni á ó pa á láti ẹni kékeré dé orí ẹni ńlá àti ọkùnrin àti obìnrin.
14 Ils firent un serment à Yahweh à haute voix, avec des cris d’allégresse, au son des trompettes et des cors;
Wọ́n sì búra ní ohùn rara fún Olúwa àti pẹ̀lú ìhó ńlá àti pẹ̀lú ìpè àti pẹ̀lú fèrè.
15 tout Juda fut dans la joie de ce serment, car ils avaient juré de tout leur cœur; car c’est de leur pleine volonté qu’ils avaient cherché Yahweh, et il s’était laissé trouver par eux; et Yahweh leur donna la paix tout à l’entour.
Gbogbo Juda yọ̀ nípa ìbúra náà nítorí wọ́n ti búra tinútinú wọn wọ́n sì fi gbogbo ìfẹ́ inú wọn wá a, wọ́n sì rí i, Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi yí káàkiri.
16 Le roi Asa ôta même à Maacha, sa mère, la dignité de reine-mère, parce qu’elle avait fait une idole abominable pour Astarté. Asa abattit son idole abominable et, l’ayant réduite en poudre, il la brûla au torrent de Cédron.
Ọba Asa sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
17 Mais les hauts lieux ne disparurent pas d’Israël, quoique le cœur d’Asa fut parfait pendant toute sa vie.
Ṣùgbọ́n a kò mú àwọn ibi gíga náà kúrò ní Israẹli; síbẹ̀síbẹ̀ ọkàn Asa wà ní pípé ní ọjọ́ rẹ̀ gbogbo.
18 Il déposa dans la maison de Dieu les choses consacrées par son père et les choses consacrées par lui-même, de l’argent, de l’or et des vases.
Ó sì mú àwọn ohun mímọ́ náà ti baba rẹ̀ àti àwọn ohun mímọ́ ti òun tìkára rẹ̀ tirẹ̀ wá sínú ilé Ọlọ́run, wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò náà.
19 Il n’y eut pas de guerre jusqu’à la trente-cinquième année du règne d’Asa.
Kò sí ogun mọ́ títí fún ọdún márùndínlógójì ti ìjọba Asa.