< 1 Chroniques 27 >

1 Les enfants d’Israël selon leur nombre, chefs de familles, chefs de milliers et de centaines, officiers au service du roi pour tout ce qui concernait les divisions, celles qui arrivaient et celles qui partaient, mois par mois, pendant tous les mois de l’année, — chaque division étant de vingt-quatre mille hommes, — étaient:
Wọ̀nyí ni ìwé àkójọ orúkọ àwọn ọmọ Israẹli, àwọn olórí àwọn ìdílé, àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn ìjòyè wọn. Tí ó n sin ọba nínú gbogbo ohun tí ó kan ìpín àwọn ọmọ-ogun tí ó wà lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn ní oṣooṣù ní gbogbo ọdún. Ìpín kọ̀ọ̀kan jẹ́ ẹgbàá méjìlá ọkùnrin.
2 A la tête de la première division, pour le premier mois, était Jesboam, fils de Zabdiel, et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes.
Ní ti alákòóso lórí ìpín kìn-ín-ní fún oṣù kìn-ín-ní jẹ́ Jaṣobeamu ọmọ Sabdieli àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní abẹ́ ìpín tirẹ̀.
3 Il était d’entre les fils de Pharès, et il commandait tous les chefs des troupes du premier mois. —
Ó jẹ́ ìran ọmọ Peresi àti olóyè fún gbogbo àwọn ìjòyè ológun fún oṣù kìn-ín-ní.
4 A la tête de la division du deuxième mois était Dudia, l’Ahohite; Macelloth, le prince, était un chef de sa division; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Alákòóso fún ìpín àwọn ọmọ-ogun fún oṣù kejì jẹ́ Dodai ará Ahohi; Mikloti jẹ́ olórí ìpín tirẹ̀. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
5 Le chef de la troisième division, pour le troisième mois, était Banaïas, fils du prêtre Joïada, chef; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes.
Olórí àwọn ọmọ-ogun ẹlẹ́ẹ̀kẹta fún oṣù kẹta jẹ́ Benaiah ọmọ Jehoiada àlùfáà. Ó jẹ́ olóyè, àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
6 Ce Banaïas était le héros des Trente, à la tête des Trente; Amizabad, son fils, était un chef de sa division. —
Èyí ni Benaiah náà tí ó jẹ́ ọkùnrin ńlá láàrín àwọn ọgbọ̀n àti lórí àwọn ọgbọ̀n. Ọmọ rẹ̀ Amisabadi jẹ́ alákòóso lórí ìpín tirẹ̀.
7 Le quatrième, pour le quatrième mois, était Asaël, frère de Joab, et, après lui, Zabadias, son fils; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin fún oṣù kẹrin, jẹ́ Asaheli arákùnrin Joabu: ọmọ rẹ̀ Sebadiah jẹ́ arọ́pò rẹ̀. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
8 Le cinquième, pour le cinquième mois, était le chef Samaoth, l’Izrahite; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Ẹ̀karùnún fún oṣù karùn-ún, jẹ́ olórí Ṣamhuti ará Israhi. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
9 Le sixième, pour le sixième mois, était Hira, fils d’Accès, de Thécua; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Ẹ̀kẹfà fún oṣù kẹfà jẹ́ Ira ọmọ Ikẹsi, ará Tekoi. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
10 Le septième, pour le septième mois, était Hellès, le Phallonite, des fils d’Ephraïm; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Èkeje fún oṣù keje jẹ́ Helesi ará Peloni, ará Efraimu. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni o wà ní ìpín rẹ̀.
11 Le huitième, pour le huitième mois, était Sobochaï, le Husathite, de la famille des Zarahites; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Ẹ̀kẹjọ fún oṣù kẹjọ jẹ́ Sibekai ará Huṣati, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
12 Le neuvième, pour le neuvième mois, était Abiézer, d’Anathoth, des fils de Benjamin; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Ẹ̀kẹsànán fún oṣù kẹsànán jẹ́. Abieseri ará Anatoti, ará Benjamini ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
13 Le dixième, pour le dixième mois, était Maraï, de Nétopha, de la famille des Zaharites; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Ẹ̀kẹwàá fún oṣù kẹwàá jẹ́ Maharai ará Netofa, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
14 Le onzième, pour le onzième mois, était Banaïas, de Pharathon des fils d’Ephraïm; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Ìkọkànlá fún oṣù kọkànlá jẹ́ Benaiah ará Piratoni ará Efraimu ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
15 Le douzième, pour le douzième mois, était Holdaï, de Nétopha, de la famille d’Othoniel; et il y avait dans sa division vingt-quatre mille hommes. —
Èkejìlá fún oṣù kejìlá jẹ́ Heldai ará Netofa láti ìdílé Otnieli. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
16 Et il y avait à la tête des tribus d’Israël: des Rubénites: Eliézer, fils de Zéchri; des Siméonites: Saphatias, fils de Maacha;
Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà tí Israẹli: lórí àwọn ará Reubeni: Elieseri ọmọ Sikri; lórí àwọn ọmọ Simeoni: Ṣefatia ọmọ Maaka;
17 des Lévites: Hasabias, fils de Camuel; de la famille d’Aaron: Sadoc;
lórí Lefi: Haṣabiah ọmọ Kemueli; lórí Aaroni: Sadoku;
18 de Juda: Eliu, frère de David; d’Issachar, Amri, fils de Michaël;
lórí Juda: Elihu arákùnrin Dafidi; lórí Isakari: Omri ọmọ Mikaeli;
19 de Zabulon: Jesmaïas, fils d’Abdias; de Nephtali: Jérimoth, fils d’Ozriel;
lórí Sebuluni: Iṣmaiah ọmọ Obadiah; lórí Naftali: Jerimoti ọmọ Asrieli;
20 des fils d’Ephraïm: Osée, fils d’Ozaziu; de la demi-tribu de Manassé: Joël, fils de Phadaïas;
lórí àwọn ará Efraimu: Hosea ọmọ Asasiah; lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase: Joẹli ọmọ Pedaiah;
21 de la demi-tribu de Manassé, en Galaad: Jaddo, fils de Zacharias; de Benjamin: Jasiel, fils d’Abner;
lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ní Gileadi: Iddo ọmọ Sekariah; lórí Benjamini: Jaasieli ọmọ Abneri;
22 de Dan: Ezrihel, fils de Jéroham. Ce sont les princes des tribus d’Israël.
lórí Dani: Asareeli ọmọ Jerohamu. Wọ̀nyí ni àwọn ìjòyè lórí ẹ̀yà Israẹli.
23 David ne fit pas le dénombrement de ceux qui étaient âgés de vingt ans et au-dessous, car Yahweh avait dit qu’il multiplierait Israël comme les étoiles du ciel.
Dafidi kò kọ iye àwọn ọkùnrin náà ní ogún ọdún sẹ́yìn tàbí dín nítorí Olúwa ti ṣe ìlérí láti ṣe Israẹli gẹ́gẹ́ bí iye ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
24 Joab, fils de Sarvia, avait commencé le dénombrement, mais il ne l’acheva pas, la colère de Yahweh étant venue à cause de cela sur Israël, et le résultat n’en fut pas porté sur les rôles des chroniques du roi David.
Joabu ọmọ Seruiah bẹ̀rẹ̀ sí ní kà wọ́n, ṣùgbọ́n kò parí kíkà wọ́n nítorí, ìbínú dé sórí àwọn Israẹli nípasẹ̀ kíka iye àti iye náà, a kò kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé ti ọba Dafidi.
25 Asmoth, fils d’Adiel, était préposé sur les trésors du roi; Jonathan, fils d’Ozias, sur les trésors dans les champs, dans les villes, dans les villages et dans les tours;
Asmafeti ọmọ Adieli wà ní ìdí ilé ìṣúra ti ọba. Jonatani ọmọ Ussiah wà ní ìdí ilé ìṣúra ní iwájú agbègbè nínú àwọn ìlú, àwọn ìletò àti àwọn ilé ìṣọ́.
26 Ezri, fils de Chélub, sur les ouvriers des champs qui cultivaient la terre;
Esri ọmọ Kelubu wà ní ìdí àwọn òṣìṣẹ́ lórí pápá, tí wọ́n ń ko ilẹ̀ náà.
27 Séméï, de Rama, sur les vignes; Zabdias, de Sapham, sur les provisions de vin dans les vignes;
Ṣimei ará Ramoti wà ní ìdí àwọn ọgbà àjàrà. Sabdi ará Sifmi wà ní ìdí mímú jáde ti èso àjàrà fún ọpọ́n ńlá tí a ń fi ọ̀tún èso àjàrà sí.
28 Balanan, de Géder, sur les oliviers et les sycomores dans la Séphéla; Joas, sur les provisions d’huile;
Baali-Hanani ará Gederi wà ní ìdí olifi àti àwọn igi sikamore ní apá ìhà ìwọ̀-oòrùn àwọn ní ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀. Joaṣi wà ní ìdí fífún ni ní òróró olifi.
29 Séthraï, de Saron, sur les bœufs qui paissaient en Saron; Saphat, fils d’Adli, sur les bœufs dans les vallées;
Ṣitrai ará Ṣaroni wà ní ìdí fífi ọwọ́ ẹran jẹ oko ní Ṣaroni. Ṣafati ọmọ Adlai wà ní ìdí àwọn ọ̀wọ́ ẹran ní àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀.
30 Ubil, l’Ismaélite, sur les chameaux; Jadias, de Méronath, sur les ânesses;
Obili ará Iṣmaeli wà ní ìdí àwọn ìbákasẹ. Jehdeiah ará Meronoti wà ní ìdí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
31 Jaziz, l’Agarénien, sur les brebis. Tous ceux-là étaient intendants des biens du roi David.
Jasisi ará Hagari wà ní ìdí àwọn agbo ẹran. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn oníṣẹ́ tí wọ́n wà ní ìdí ẹrù ọba Dafidi.
32 Jonathan, oncle de David, était conseiller; c’était un homme de sens et de savoir. Jahiel, fils de Hachamoni, était avec les fils du roi.
Jonatani, arákùnrin Dafidi jẹ́ olùdámọ̀ràn, ọkùnrin onímọ̀ àti akọ̀wé. Jehieli ọmọ Hakmoni bojútó àwọn ọmọ ọba.
33 Achitophel était conseiller du roi, et Chusaï, l’Archéen, était ami du roi;
Ahitofeli jẹ́ olùdámọ̀ràn ọba. Huṣai ará Arki jẹ́ ọ̀rẹ́ ọba.
34 après Achitophel, Joïada, fils de Banaïas, et Abiathar. Joab était chef de l’armée du roi.
(Jehoiada ọmọ Benaiah àti nípasẹ̀ Abiatari jẹ ọba rọ́pò Ahitofeli.) Joabu jẹ́ olórí ọmọ-ogun ọba.

< 1 Chroniques 27 >