< Zacharie 1 >

1 Au huitième mois de la deuxième année de Darius, la parole de l'Éternel fut adressée au prophète Zacharie, fils de Bérékia, fils d'Iddo, en ces termes:
Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
2 L'Éternel a été très mécontent de vos pères.
“Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3 C'est pourquoi tu leur diras: L'Éternel des armées dit: « Revenez à moi, dit l'Éternel des armées, et je reviendrai à vous », dit l'Éternel des armées.
Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Ne soyez pas comme vos pères, à qui les anciens prophètes ont annoncé, en disant: L'Éternel des armées dit: « Revenez maintenant de vos mauvaises voies et de vos mauvaises actions »; mais ils n'ont pas écouté et ne m'ont pas écouté, dit l'Éternel.
Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
5 Vos pères, où sont-ils? Et les prophètes, vivent-ils éternellement?
Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
6 Mais mes paroles et mes décrets, que j'ai prescrits à mes serviteurs les prophètes, n'ont-ils pas atteint vos pères? Ils se repentirent et dirent: « Ce que Yahvé des armées avait décidé de nous faire, selon nos voies et nos pratiques, il l'a fait avec nous ».
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
7 Le vingt-quatrième jour du onzième mois, qui est le mois de Shebat, la deuxième année de Darius, la parole de Yahvé fut adressée au prophète Zacharie, fils de Béréchia, fils d'Iddo, en ces termes:
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
8 « J'ai eu une vision pendant la nuit: voici un homme monté sur un cheval roux, qui se tenait parmi les myrtes qui étaient dans un ravin; et derrière lui, il y avait des chevaux roux, bruns et blancs.
Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
9 Je demandai alors: « Mon seigneur, qu'est-ce que c'est? » L'ange qui m'a parlé m'a dit: « Je vais te montrer ce que c'est. »
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
10 L'homme qui se tenait parmi les myrtes répondit: « Ce sont ceux que Yahvé a envoyés pour aller et venir sur la terre. »
Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
11 Ils firent leur rapport à l'ange de Yahvé qui se tenait parmi les myrtes, et dirent: « Nous avons parcouru la terre de long en large, et voici que toute la terre est en repos et en paix. »
Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
12 L'ange de Yahvé répondit: « Yahvé des armées, jusqu'à quand n'auras-tu pas pitié de Jérusalem et des villes de Juda, contre lesquelles tu t'es indigné pendant soixante-dix ans? »
Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
13 Yahvé répondit à l'ange qui me parlait par des paroles aimables et réconfortantes.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
14 L'ange qui m'a parlé m'a dit: « Proclame, en disant: « L'Éternel des armées dit: « Je suis jaloux de Jérusalem et de Sion, d'une grande jalousie.
Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
15 Je suis très irrité contre les nations qui sont à l'aise; car je n'étais qu'un peu mécontent, mais elles ont ajouté à la calamité. »
Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
16 C'est pourquoi Yahvé dit: « Je suis revenu à Jérusalem avec miséricorde. Ma maison y sera bâtie, dit Yahvé des armées, et une ligne sera tendue sur Jérusalem. »"
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
17 « Proclamez encore, en disant: « Yahvé des armées dit: « Mes villes regorgeront de nouveau de prospérité, et Yahvé consolera de nouveau Sion, et choisira de nouveau Jérusalem »".
“Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
18 Je levai les yeux et je vis, et voici, il y avait quatre cornes.
Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
19 Je demandai à l'ange qui parlait avec moi: « Qu'est-ce que c'est? » Il me répondit: « Ce sont les cornes qui ont dispersé Juda, Israël et Jérusalem. »
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
20 Yahvé me montra quatre artisans.
Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21 Et j'ai demandé: « Que viennent-ils faire? » Il dit: « Ce sont les cornes qui ont dispersé Juda, de sorte que personne n'a levé la tête; mais celles-ci sont venues pour les terrifier, pour abattre les cornes des nations qui ont levé leur corne contre le pays de Juda pour le disperser. »
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”

< Zacharie 1 >