< Psaumes 69 >

1 Pour le chef musicien. Sur l'air de « Lilies ». Par David. Sauve-moi, Dieu, car les eaux sont arrivées jusqu'à mon cou!
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Je m'enfonce dans un bourbier profond, où il n'y a pas de point d'appui. Je suis entré dans des eaux profondes, où les flots me submergent.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Je suis fatigué de mes pleurs. Ma gorge est sèche. Mes yeux ne cherchent pas mon Dieu.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 Ceux qui me haïssent sans raison sont plus nombreux que les cheveux de ma tête. Ceux qui veulent me couper, étant mes ennemis à tort, sont puissants. Je dois restaurer ce que je n'ai pas enlevé.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Dieu, tu connais ma folie. Mes péchés ne te sont pas cachés.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Que ceux qui t'attendent ne soient pas déshonorés par moi, Seigneur Yahvé des Armées. Ne permets pas que ceux qui te cherchent soient déshonorés par moi, Dieu d'Israël.
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Parce qu'à cause de toi, j'ai porté l'opprobre. La honte a recouvert mon visage.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 Je suis devenu un étranger pour mes frères, un étranger pour les enfants de ma mère.
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Car le zèle de ta maison me consume. Les reproches de ceux qui te font des reproches sont tombés sur moi.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Quand je pleurais et que je je jeûnais, qui était à mon reproche.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Quand j'ai fait du sac mon vêtement, Je suis devenu un mot d'ordre pour eux.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 Ceux qui sont assis à la porte parlent de moi. Je suis la chanson des ivrognes.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Mais moi, je t'adresse ma prière, Yahvé, au moment opportun. Dieu, dans l'abondance de ta bonté, réponds-moi dans la vérité de ton salut.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Délivre-moi du bourbier, ne me laisse pas m'enfoncer. Laisse-moi être délivré de ceux qui me haïssent, et sortir des eaux profondes.
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Ne laisse pas les eaux de l'inondation me submerger, ni laisser les profondeurs m'engloutir. Ne laisse pas la fosse fermer sa bouche sur moi.
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Réponds-moi, Yahvé, car ta bonté est bonne. Selon la multitude de vos tendres miséricordes, tournez-vous vers moi.
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 Ne cache pas ton visage à ton serviteur, car je suis en détresse. Réponds-moi vite!
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Approche-toi de mon âme et rachète-la. Rançonnez-moi à cause de mes ennemis.
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Tu connais mon opprobre, ma honte et mon déshonneur. Mes adversaires sont tous devant vous.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 L'opprobre m'a brisé le cœur, et je suis accablé. J'ai cherché quelqu'un pour avoir pitié, mais il n'y en avait pas; pour des doudous, mais je n'en ai trouvé aucun.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Ils m'ont aussi donné du poison pour ma nourriture. Dans ma soif, ils m'ont donné du vinaigre à boire.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Que leur table devant eux devienne un piège. Qu'il devienne un châtiment et un piège.
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Que leurs yeux soient obscurcis, afin qu'ils ne voient pas. Que leur dos soit continuellement courbé.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Répands sur eux ton indignation. Laisse l'ardeur de ta colère les envahir.
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Que leur demeure soit désolée. Que personne n'habite dans leurs tentes.
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Car ils persécutent celui que vous avez blessé. Ils racontent la douleur de ceux que vous avez blessés.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Accusez-les de crime sur crime. Ne les laissez pas entrer dans votre droiture.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Qu'ils soient effacés du livre de vie, et ne pas être écrit avec les justes.
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Mais je suis dans la douleur et la détresse. Que ton salut, Dieu, me protège.
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 Je louerai le nom de Dieu par un chant, et le magnifieront dans l'action de grâce.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 Il plaira à Yahvé mieux qu'un bœuf, ou un taureau qui a des cornes et des sabots.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 Les humbles l'ont vu, et ils se sont réjouis. Vous qui cherchez Dieu, laissez vivre votre cœur.
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 Car Yahvé écoute le pauvre, et ne méprise pas son peuple captif.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Que le ciel et la terre le louent; les mers, et tout ce qui s'y déplace!
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Car Dieu sauvera Sion, et il bâtira les villes de Juda. Ils s'y installeront et en seront les propriétaires.
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 Les enfants de ses serviteurs en hériteront aussi. Ceux qui aiment son nom l'habiteront.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Psaumes 69 >