< Psaumes 140 >

1 Pour le chef musicien. Un psaume de David. Délivre-moi, Yahvé, des hommes méchants. Préservez-moi des hommes violents:
Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì, yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,
2 ceux qui conçoivent la malice dans leur cœur. Ils se rassemblent continuellement pour la guerre.
ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn; nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.
3 Ils ont aiguisé leur langue comme un serpent. Le poison de la vipère est sous leurs lèvres. (Selah)
Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò, oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.
4 Yahvé, garde-moi de la main des méchants. Préservez-moi des hommes violents qui ont décidé de me faire trébucher.
Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú; yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.
5 Les orgueilleux ont caché un piège pour moi, ils ont étendu les cordes d'un filet sur le chemin. Ils m'ont tendu des pièges. (Selah)
Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn: wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà; wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.
6 J'ai dit à Yahvé: « Tu es mon Dieu. » Écoute le cri de mes requêtes, Yahvé.
Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi; Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
7 Yahvé, le Seigneur, la force de mon salut, tu as couvert ma tête au jour du combat.
Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi, ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.
8 Yahvé, n'accorde pas les désirs des méchants. Ne laisse pas leurs mauvais plans réussir, ou ils deviendront fiers. (Selah)
Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un; má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́; kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. (Sela)
9 Quant à la tête de ceux qui m'entourent, que la malice de leurs propres lèvres les couvre.
Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni, jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.
10 Que des charbons ardents tombent sur eux. Qu'on les jette au feu, dans des fosses de boue, d'où ils ne sortent jamais.
A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára, Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná, sínú ọ̀gbun omi jíjìn, kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.
11 Un orateur méchant ne sera pas établi sur la terre. Le mal chassera l'homme violent pour le renverser.
Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé; ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.
12 Je sais que l'Éternel défendra la cause du malheureux, et la justice pour les nécessiteux.
Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró, yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.
13 Les justes rendront grâce à ton nom. Les hommes droits habiteront en ta présence.
Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ; àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.

< Psaumes 140 >