< Proverbes 6 >

1 Mon fils, si tu es devenu la garantie de ton prochain, si vous avez frappé vos mains en gage pour un étranger,
Ọmọ mi, bí ìwọ bá ṣe onídùúró fún aládùúgbò rẹ, bí ìwọ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún àjèjì ènìyàn,
2 vous êtes piégés par les mots de votre bouche; tu es pris au piège par les paroles de ta bouche.
bí a bá ti fi ọ̀rọ̀ tí ó sọ dẹkùn mú ọ, tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ ti kó ọ sí pàkúté.
3 Fais-le maintenant, mon fils, et délivre-toi, puisque tu es tombé dans la main de ton voisin. Allez, humiliez-vous. Appuyez votre plaidoyer auprès de votre voisin.
Nígbà náà, ṣe èyí, ìwọ ọmọ mi, láti gba ara rẹ níwọ̀n bí o ti kó ṣọ́wọ́ aládùúgbò rẹ: lọ kí o sì rẹ ara rẹ sílẹ̀; bẹ aládùúgbò rẹ dáradára.
4 Ne laisse pas tes yeux s'endormir, ni le sommeil à vos paupières.
Má ṣe jẹ́ kí oorun kí ó kùn ọ́, tàbí kí o tilẹ̀ tòògbé rárá.
5 Libère-toi, comme une gazelle de la main du chasseur, comme un oiseau échappant au piège de l'oiseleur.
Gba ara rẹ sílẹ̀, bí abo èsúró kúrò lọ́wọ́ ọdẹ, bí ẹyẹ kúrò nínú okùn àwọn pẹyẹpẹyẹ.
6 Va vers la fourmi, paresseux. Considérez ses manières, et soyez sage;
Tọ èèrà lọ, ìwọ ọ̀lẹ; kíyèsi ìṣe rẹ̀, kí o sì gbọ́n!
7 qui n'ont ni chef, ni surveillant, ni dirigeant,
Kò ní olùdarí, kò sí alábojútó tàbí ọba,
8 lui fournit du pain en été, et recueille sa nourriture dans la moisson.
síbẹ̀, a kó ìpèsè rẹ̀ jọ ní àsìkò òjò yóò sì kó oúnjẹ rẹ̀ jọ ní àsìkò ìkórè.
9 Combien de temps vas-tu dormir, paresseux? Quand sortiras-tu de ton sommeil?
Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò dùbúlẹ̀, ìwọ ọ̀lẹ? Nígbà wo ni ìwọ yóò jí kúrò lójú oorun rẹ?
10 Un peu de sommeil, un peu d'assoupissement, un petit pliage des mains pour dormir...
Oorun díẹ̀, òògbé díẹ̀, ìkáwọ́gbera láti sinmi díẹ̀.
11 ainsi votre pauvreté viendra comme un voleur, et votre rareté en tant qu'homme armé.
Òsì yóò sì wá sórí rẹ bí ìgárá ọlọ́ṣà àti àìní bí adigunjalè.
12 Un homme sans valeur, un homme d'iniquité, est celui qui marche avec une bouche perverse,
Ènìyànkénìyàn àti ènìyàn búburú, tí ń ru ẹnu àrékérekè káàkiri,
13 qui cligne des yeux, qui fait des signes avec ses pieds, qui fait des gestes avec ses doigts,
tí ó ń ṣẹ́jú pàkòpàkò, ó ń fi ẹsẹ̀ rẹ̀ sọ̀rọ̀ ó sì ń fi ìka ọwọ́ rẹ̀ júwe,
14 dans le cœur duquel il y a de la perversité, qui invente continuellement le mal, qui sème toujours la discorde.
tí ó ń pète búburú pẹ̀lú ẹ̀tàn nínú ọkàn rẹ̀ ìgbà gbogbo ni ó máa ń dá ìjà sílẹ̀.
15 C'est pourquoi sa calamité viendra soudainement. Il sera brisé soudainement, et ce sans remède.
Nítorí náà ìdààmú yóò dé bá a ní ìṣẹ́jú akàn; yóò parun lójijì láìsí àtúnṣe.
16 Il y a six choses que Yahvé déteste; oui, sept qui sont une abomination pour lui:
Àwọn ohun mẹ́fà wà tí Olúwa kórìíra, ohun méje ní ó jẹ́ ìríra sí i,
17 des yeux arrogants, une langue mensongère, des mains qui ont versé du sang innocent,
Ojú ìgbéraga, ahọ́n tó ń parọ́ ọwọ́ tí ń ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀,
18 un cœur qui conçoit de mauvais plans, des pieds qui sont prompts à courir au mal,
ọkàn tí ń pète ohun búburú, ẹsẹ̀ tí ó yára láti sáré sínú ìwà ìkà,
19 un faux témoin qui profère des mensonges, et celui qui sème la discorde entre les frères.
ajẹ́rìí èké tí ń tú irọ́ jáde lẹ́nu àti ènìyàn tí ń dá ìjà sílẹ̀ láàrín àwọn ọmọ ìyá kan.
20 Mon fils, garde le commandement de ton père, et n'abandonnez pas l'enseignement de votre mère.
Ọmọ mi, pa àṣẹ baba rẹ mọ́ má sì ṣe kọ ẹ̀kọ́ ìyá rẹ sílẹ̀.
21 Lie-les continuellement sur ton cœur. Attachez-les autour de votre cou.
Jẹ́ kí wọn wà nínú ọkàn rẹ láéláé so wọ́n mọ́ ọrùn rẹ.
22 Quand tu marcheras, il te conduira. Quand vous dormirez, il veillera sur vous. Quand vous vous réveillerez, il parlera avec vous.
Nígbà tí ìwọ bá ń rìn, wọn yóò ṣe amọ̀nà rẹ; nígbà tí ìwọ bá sùn, wọn yóò máa ṣe olùṣọ́ rẹ; nígbà tí o bá jí, wọn yóò bá ọ sọ̀rọ̀.
23 Car le commandement est une lampe, et la loi est légère. Les reproches d'instruction sont le chemin de la vie,
Nítorí àwọn àṣẹ yìí jẹ́ fìtílà, ẹ̀kọ́ yìí jẹ́ ìmọ́lẹ̀, àti ìtọ́nisọ́nà ti ìbáwí ni ọ̀nà sí ìyè.
24 pour vous préserver de la femme immorale, de la flatterie de la langue de l'épouse volage.
Yóò pa ọ́ mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin búburú, kúrò lọ́wọ́ ẹnu dídùn obìnrin àjèjì.
25 Ne convoite pas sa beauté dans ton cœur, ni la laisser vous captiver avec ses paupières.
Má ṣe ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ si nínú ọkàn rẹ nítorí ẹwà rẹ tàbí kí o jẹ́ kí ó fi ojú rẹ̀ fà ọ́ mọ́ra.
26 Car une prostituée vous réduit à un morceau de pain. La femme adultère chasse votre précieuse vie.
Nítorí pé nípasẹ̀ àgbèrè obìnrin ni ènìyàn fi ń di oníṣù-àkàrà kan, ṣùgbọ́n àyà ènìyàn a máa wá ìyè rẹ̀ dáradára.
27 Un homme peut-il ramasser du feu sur ses genoux, et que ses vêtements ne soient pas brûlés?
Ǹjẹ́ ọkùnrin ha le è gbé iná lé orí itan kí aṣọ rẹ̀ má sì jóná?
28 Ou peut-on marcher sur des charbons ardents, et ses pieds ne seront pas brûlés?
Ǹjẹ́ ènìyàn le è máa rìn lórí iná? Kí ẹsẹ̀ rẹ̀ sì má jóná?
29 Il en est de même pour celui qui va vers la femme de son prochain. Quiconque la touche ne restera pas impuni.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sùn pẹ̀lú aya aláya; kò sí ẹni tí ó fọwọ́ kàn án tí yóò lọ láìjìyà.
30 Les hommes ne méprisent pas un voleur. s'il vole pour se satisfaire quand il a faim,
Àwọn ènìyàn kì í kẹ́gàn olè tí ó bá jalè nítorí àti jẹun nígbà tí ebi bá ń pa á.
31 mais s'il est retrouvé, il restituera sept fois. Il donnera toutes les richesses de sa maison.
Síbẹ̀ bí ọwọ́ bá tẹ̀ ẹ́, ó gbọdọ̀ san ìlọ́po méje bí ó tilẹ̀ kó gbogbo ohun tó ní nílé tà.
32 Celui qui commet un adultère avec une femme est dépourvu d'intelligence. Celui qui le fait détruit sa propre âme.
Ṣùgbọ́n ẹni tí ń ṣe àgbèrè kò nírònú; ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe bẹ́ẹ̀ ó ń pa ara rẹ̀ run ni.
33 Il recevra des blessures et le déshonneur. Son opprobre ne sera pas effacé.
Ìfarapa àti ìtìjú ni tirẹ̀, ẹ̀gàn rẹ̀ kì yóò sì kúrò láéláé.
34 Car la jalousie excite la fureur du mari. Il n'épargnera pas au jour de la vengeance.
Nítorí owú yóò ru ìbínú ọkọ sókè, kì yóò sì ṣàánú nígbà tí ó bá ń gbẹ̀san.
35 Il ne tiendra compte d'aucune rançon, il ne sera pas non plus satisfait, même si vous lui faites de nombreux cadeaux.
Kò nígbà nǹkan kan bí ohun ìtánràn; yóò kọ àbẹ̀tẹ́lẹ̀, bí ó ti wù kí ó pọ̀ tó.

< Proverbes 6 >