< Nombres 6 >

1 Yahvé parla à Moïse, et dit:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Parle aux enfants d'Israël, et dis-leur: Quand un homme ou une femme fera un vœu spécial, le vœu de naziréat, pour se séparer de Yahvé,
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ pàtàkì, ẹ̀jẹ́ ìyara-ẹni-sọ́tọ̀ sí Olúwa nípa àìgé irun orí (Nasiri),
3 il se séparera du vin et des boissons fortes. Il ne boira pas de vinaigre de vin ni de vinaigre de boisson fermentée, il ne boira pas de jus de raisin et ne mangera pas de raisins frais ou secs.
irú ẹni bẹ́ẹ̀ gbọdọ̀ yàgò fún wáìnì tàbí ọtí líle, ọtí wáìnì kíkan àti àwọn ohun mímu mìíràn tó bá kan. Kò gbọdọ̀ mu èso àjàrà tàbí kí ó jẹ èso àjàrà tútù tàbí gbígbẹ.
4 Pendant toute la durée de sa séparation, il ne mangera rien de ce qui provient de la vigne, depuis les pépins jusqu'aux peaux.
Níwọ́n ìgbà tí ó sì jẹ́ Nasiri, ní kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí a fi èso àjàrà ṣe, ìbá à ṣe kóró tàbí èèpo rẹ̀.
5 "'Pendant toute la durée de son vœu de séparation, aucun rasoir ne viendra sur sa tête, jusqu'à l'accomplissement des jours où il se séparera de Yahvé. Il sera saint. Il laissera croître les mèches des cheveux de sa tête.
“‘Ní gbogbo ìgbà ẹ̀jẹ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, kí abẹ kankan má ṣe kàn án ní orí. Ó gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ títí tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa yóò fi pé; ó gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí rẹ̀ gùn.
6 "'Tous les jours où il se séparera de Yahvé, il ne s'approchera pas d'un cadavre.
“‘Ní gbogbo àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Olúwa kò gbọdọ̀ súnmọ́ òkú ènìyàn.
7 Il ne se rendra pas impur pour son père, pour sa mère, pour son frère ou pour sa sœur, lorsqu'ils mourront, car sa séparation d'avec Dieu est sur sa tête.
Ìbá à ṣe òkú baba, àti ìyá rẹ̀, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin tàbí àbúrò rẹ̀, kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nítorí wọn, nítorí pé àmì ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ sí Ọlọ́run wà ní orí rẹ̀.
8 Tous les jours de sa séparation, il est saint pour Yahvé.
Ní gbogbo àsìkò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ yìí, ó jẹ́ mímọ́ sí Olúwa.
9 "'Si un homme meurt subitement à côté de lui et qu'il souille la tête de sa séparation, il se rasera la tête le jour de sa purification. Le septième jour, il la rasera.
“‘Bí ẹnìkan bá kú ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní òjijì, tí ó sì ba irun rẹ̀ tó yà sọ́tọ̀ jẹ́; ó gbọdọ̀ gé irun rẹ̀ ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe ọjọ́ keje.
10 Le huitième jour, il apportera au prêtre, à l'entrée de la tente de la Rencontre, deux tourterelles ou deux jeunes pigeons.
Ní ọjọ́ kẹjọ, yóò mú àdàbà méjì àti ọmọ ẹyẹlé méjì wá sọ́dọ̀ àlùfáà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
11 Le prêtre offrira l'une en sacrifice pour le péché et l'autre en holocauste; il fera l'expiation pour lui, parce qu'il a péché à cause d'un mort, et il sanctifiera sa tête ce même jour.
Àlùfáà yóò fi ọ̀kan rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun láti fi ṣe ètùtù fún un nítorí pé ó ti ṣẹ̀ nípa wíwà níbi tí òkú ènìyàn wà. Yóò sì ya orí rẹ̀ sí mímọ́ ní ọjọ́ náà gan an.
12 Il séparera pour Yahvé les jours de sa séparation, et il apportera un agneau mâle d'un an en sacrifice de culpabilité; mais les jours précédents seront annulés, car sa séparation a été souillée.
Ó gbọdọ̀ ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ sí Olúwa fún àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀, ó sì gbọdọ̀ mú akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀bi. Kò sì ní í ka àwọn ọjọ́ ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀ nítorí pé ó tí ba ara rẹ̀ jẹ́ ní àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀.
13 « Voici la loi du naziréen: lorsque les jours de sa séparation seront accomplis, il sera amené à l'entrée de la tente d'assignation,
“‘Èyí ni òfin fún Nasiri nígbà tí àkókò ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ bá pé. Wọn ó mu wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.
14 et il présentera son offrande à l'Éternel: un agneau mâle d'un an sans défaut pour l'holocauste, une brebis d'un an sans défaut pour le sacrifice pour le péché, un bélier sans défaut pour le sacrifice d'actions de grâces,
Níbẹ̀ ni yóò ti mú ọrẹ wá fún Olúwa, akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan tí kò ní àbùkù fún ẹbọ sísun àti ẹgbọrọ-àgùntàn ọlọ́dún kan, tí kò ní àbùkù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò kan tí kò ní àbùkù fún ọrẹ àlàáfíà,
15 une corbeille de pains sans levain, des gâteaux de fleur de farine pétrie à l'huile, et des galettes sans levain ointes d'huile, avec leur offrande et leur libation.
pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu, apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí a kò fi ìwúkàrà ṣe, àkàrà tí a fi ìyẹ̀fun dáradára pò mọ́ òróró àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí a fi òróró sọjọ̀ lé lórí.
16 Le prêtre les présentera devant l'Éternel, et il offrira son sacrifice pour le péché et son holocauste.
“‘Àlùfáà yóò gbé gbogbo rẹ̀ wá síwájú Olúwa, yóò sì rú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ẹbọ sísun.
17 Il offrira le bélier en sacrifice d'actions de grâces à l'Éternel, avec la corbeille de pains sans levain. Le prêtre offrira également son offrande de repas et sa libation.
Àlùfáà yóò fi àgbò náà rú ẹbọ àlàáfíà sí Olúwa, pẹ̀lú apẹ̀rẹ̀ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà; yóò rú ẹbọ ohun jíjẹ àti ọrẹ ohun mímu.
18 Le naziréen rasera sa tête de séparation à l'entrée de la Tente d'assignation, prendra les cheveux de sa tête de séparation et les mettra sur le feu qui est sous le sacrifice d'actions de grâces.
“‘Nígbà náà ni Nasiri náà yóò fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Yóò fi irun náà sínú iná tó wà lábẹ́ ẹbọ àlàáfíà.
19 Le prêtre prendra l'épaule bouillie du bélier, un gâteau sans levain de la corbeille et une galette sans levain, et il les posera sur les mains du naziréen, après qu'il aura rasé sa tête de séparation;
“‘Lẹ́yìn tí Nasiri bá ti fá irun ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ tan, àlùfáà yóò mú apá àgbò bíbọ̀, àkàrà aláìwú kan àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ tí kò ní ìwúkàrà láti inú apẹ̀rẹ̀ yóò sì kó gbogbo rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 et le prêtre les agitera en sacrifice d'agitation devant Yahvé. Elles sont saintes pour le prêtre, avec la poitrine qu'on agite et la cuisse qu'on offre. Après cela, le naziréen pourra boire du vin.
Àlùfáà yóò fi gbogbo rẹ̀ níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, wọ́n jẹ́ mímọ́, wọ́n sì jẹ́ ti àlùfáà pẹ̀lú igẹ̀ tí a fì àti itan tí wọ́n mú wá. Lẹ́yìn èyí, Nasiri náà lè mu wáìnì.
21 "'Voici la loi du naziréen qui fait un vœu et de son offrande à Yahvé pour sa séparation, en plus de ce qu'il peut se permettre. Selon le vœu qu'il prononce, il doit agir de la même manière, selon la loi de sa séparation. »"
“‘Èyí ni òfin Nasiri tó jẹ́ ẹ̀jẹ́, ọrẹ rẹ̀ sí Olúwa, yóò wà ní ìbámu pẹ̀lú ìyàsọ́tọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Nasiri, ní àfikún sí àwọn ohun mìíràn tó lágbára láti mú wá. Ó gbọdọ̀ mú ẹ̀jẹ́ tó jẹ́ ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin Nasiri.’”
22 Yahvé parla à Moïse et dit:
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 « Parle à Aaron et à ses fils, et dis: « Voici comment vous bénirez les enfants d'Israël. Vous leur direz,
“Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, ‘Báyìí ni kí ẹ ṣe máa súre fún àwọn ọmọ Israẹli. Ẹ sọ fún wọn pé,
24 Yahvé te bénit et te garde.
“‘“Kí Olúwa bùkún un yín, kí ó sì pa yín mọ́.
25 Yahvé fait briller sa face sur vous, et être gracieux envers vous.
Kí Olúwa kí o mú ojú rẹ̀ kí ó mọ́lẹ̀ sí i yín lára. Kí ó sì ṣàánú fún un yín.
26 Yahvé lève sa face vers vous, et te donner la paix.
Kí Olúwa bojú wò yín, kí ó sì fún un yín ní àlàáfíà.”’
27 « Ils mettront mon nom sur les enfants d'Israël, et je les bénirai. »
“Báyìí ni wọn ó ṣe fi orúkọ mi sára àwọn ọmọ Israẹli, Èmi ó sì bùkún wọn.”

< Nombres 6 >