< Nombres 16 >

1 Or Koré, fils de Jitsehar, fils de Kehath, fils de Lévi, avec Dathan et Abiram, fils d'Éliab, et On, fils de Péleth, fils de Ruben, prirent quelques hommes.
Kora ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi àwọn ọmọ Reubeni: Datani àti Abiramu, àwọn ọmọ Eliabu, àti Oni ọmọ Peleti mú ènìyàn mọ́ra.
2 Ils se levèrent devant Moïse, avec une partie des enfants d'Israël, deux cent cinquante chefs de l'assemblée, appelés à l'assemblée, hommes de renom.
Wọ́n sì dìde sí Mose, pẹ̀lú àádọ́ta lé nígba ọkùnrin nínú àwọn ọmọ Israẹli, ìjòyè nínú ìjọ, àwọn olórúkọ nínú àjọ, àwọn ọkùnrin olókìkí.
3 Ils s'assemblèrent contre Moïse et Aaron, et leur dirent: « Vous prenez trop sur vous, car toute l'assemblée est sainte, chacun d'eux, et Yahvé est au milieu d'eux! Pourquoi vous élevez-vous au-dessus de l'assemblée de Yahvé? »
Wọ́n kó ara wọn jọ láti tako Mose àti Aaroni, wọ́n sọ fún wọn pé, “Ẹ ti kọjá ààyè yín, ó tó gẹ́ẹ́! Mímọ́ ni gbogbo ènìyàn, kò sí ẹni tí kò mọ́ láàrín wọn, Olúwa sì wà pẹ̀lú wọn, nítorí kí wá ni ẹ̀yin ṣe gbé ara yín ga ju ìjọ ènìyàn Olúwa lọ?”
4 Lorsque Moïse l'entendit, il tomba sur sa face.
Nígbà tí Mose gbọ́ èyí, ó dojúbolẹ̀,
5 Il dit à Koré et à toute sa troupe: « Demain matin, l'Éternel fera connaître qui est à lui et qui est saint, et il le fera approcher de lui. Il fera approcher de lui celui qu'il choisira.
Ó sì sọ fún Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ pé, “Ní ọ̀la ni Olúwa yóò fi ẹni tí í ṣe tirẹ̀ àti ẹni tó mọ́ hàn, yóò sì mú kí ẹni náà súnmọ́ òun. Ẹni tí ó bá yàn ni yóò mú kí ó súnmọ́ òun.
6 Fais ceci: que Koré et toute sa troupe prennent des encensoirs,
Kí Kora àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ̀ ṣe èyí, ẹ mú àwo tùràrí.
7 y mettent du feu et y déposent de l'encens devant Yahvé demain. L'homme que choisira Yahvé sera saint. Vous êtes allés trop loin, fils de Lévi! »
Kí ẹ sì fi iná àti tùràrí sínú rẹ̀ lọ́la níwájú Olúwa, yóò sì ṣe, ọkùnrin tí Olúwa bá yàn òun ni. Ẹ̀yin ọmọ Lefi, ẹ ti kọjá ààyè yín!”
8 Moïse dit à Koré: « Écoutez, fils de Lévi!
Mose sì tún sọ fún Kora pé, “Ẹ gbọ́ báyìí o, ẹ̀yin ọmọ Lefi!
9 Est-ce peu de chose pour vous que le Dieu d'Israël vous ait séparés de l'assemblée d'Israël, pour vous faire approcher de lui, afin que vous fassiez le service de la tente de l'Éternel et que vous vous teniez devant l'assemblée pour la servir?
Kò ha tọ́ fún yín pé Ọlọ́run Israẹli ti yà yín sọ́tọ̀ lára ìjọ Israẹli yòókù, tó sì mú yín súnmọ́ ara rẹ̀ láti ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ Olúwa àti láti dúró ṣiṣẹ́ ìsìn níwájú àwọn ènìyàn?
10 Et qu'il vous ait fait approcher, et tous vos frères, les fils de Lévi, avec vous? Cherchez-vous aussi le sacerdoce?
Ó ti mú àwọn ènìyàn yín tó jẹ́ ọmọ Lefi súnmọ́ ara rẹ̀, ṣùgbọ́n báyìí ẹ tún ń wá ọnà láti ṣiṣẹ́ àlùfáà.
11 C'est pourquoi vous vous êtes rassemblés, toi et toute ta troupe, contre Yahvé! Qu'est-ce qu'Aaron pour que vous vous plaigniez de lui? »
Olúwa ni ìwọ àti gbogbo ẹlẹgbẹ́ rẹ takò. Ta a ni Aaroni jẹ́ tí ẹ̀yin ó fi kùn sí i?”
12 Moïse envoya appeler Dathan et Abiram, les fils d'Eliab, et ils dirent: « Nous ne monterons pas!
Mose sì ránṣẹ́ sí Datani àti Abiramu àwọn ọmọ Eliabu. Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kò ní í wá!
13 Est-ce peu de chose que tu nous aies fait monter d'un pays où coulent le lait et le miel, pour nous tuer dans le désert, et que tu te fasses aussi prince sur nous?
Kò ha tó gẹ́ẹ́ pé o ti mú wa jáde láti ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin láti pa wá sínú aginjù yìí? O tún wá fẹ́ sọ ara rẹ di olúwa lé wa lórí bí?
14 Tu ne nous as pas fait entrer dans un pays où coulent le lait et le miel, et tu ne nous as pas donné en héritage des champs et des vignes. Veux-tu crever les yeux de ces hommes? Nous ne monterons pas. »
Síbẹ̀síbẹ̀ ìwọ kò sì tí ì mú wa dé ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, bẹ́ẹ̀ ni o kò sì pín ilẹ̀ ìní àti ọgbà àjàrà. Ìwọ ha fẹ́ sọ wá di ẹrú bí? Rárá o, àwa kì yóò gòkè wá!”
15 Moïse se mit dans une grande colère et dit à Yahvé: « Ne respecte pas leur offrande. Je ne leur ai pas pris un seul âne, et je n'ai fait de mal à aucun d'entre eux. »
Nígbà náà ni Mose bínú gidigidi, ó sì sọ fún Olúwa pé, “Má ṣe gba ọrẹ wọn, èmi kò gba kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ lọ́wọ́ wọn, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì pa ẹnikẹ́ni nínú wọn lára!”
16 Moïse dit à Koré: « Toi et toute ta troupe, vous irez demain devant l'Éternel, toi, eux et Aaron.
Mose sọ fún Kora pé, “Ìwọ àti ọmọ lẹ́yìn rẹ gbọdọ̀ fi ara hàn níwájú Olúwa lọ́la—gbogbo yín, ìwọ, àwọn ọmọ lẹ́yìn rẹ àti Aaroni.
17 Chacun prendra son encensoir et y mettra du parfum, et chacun apportera devant l'Éternel son encensoir, deux cent cinquante encensoirs; toi aussi, et Aaron, chacun avec son encensoir. »
Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín mú àwo tùràrí, kí ó sì fi tùràrí sínú rẹ̀, kí gbogbo rẹ̀ jẹ́ àádọ́ta lé nígba àwo tùràrí kí ẹ sì ko wá síwájú Olúwa. Ìwọ àti Aaroni yóò mú àwo tùràrí wá pẹ̀lú.”
18 Ils prirent chacun leur encensoir, y mirent du feu, y déposèrent du parfum, et se tinrent à l'entrée de la Tente de la Rencontre avec Moïse et Aaron.
Nígbà náà ni oníkálùkù wọn mú àwo tùràrí, wọ́n fi iná àti tùràrí sí i nínú, wọ́n sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, àwọn pẹ̀lú Mose àti Aaroni.
19 Koré rassembla toute la congrégation en face d'eux à l'entrée de la Tente de la Rencontre. La gloire de Yahvé apparut à toute l'assemblée.
Nígbà tí Kora kó gbogbo àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ jọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé, ògo Olúwa sì farahan gbogbo ìjọ ènìyàn.
20 Yahvé parla à Moïse et à Aaron, et dit:
Olúwa sì sọ fún Mose àti Aaroni pé,
21 « Retirez-vous du milieu de cette assemblée, afin que je les consume en un instant. »
“Ẹ ya ara yín sọ́tọ̀ kúrò láàrín ìjọ wọ̀nyí, kí ń ba à le pa wọ́n run lẹ́ẹ̀kan náà.”
22 Ils tombèrent sur leur face, et dirent: « Dieu, le Dieu des esprits de toute chair, si un seul homme pèche, seras-tu irrité contre toute l'assemblée? »
Ṣùgbọ́n Mose àti Aaroni dojúbolẹ̀ wọ́n sì kígbe sókè pé, “Ọlọ́run, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, Ìwọ ó wa bínú sí gbogbo ìjọ ènìyàn nígbà tó jẹ́ pé ẹnìkan ló ṣẹ̀?”
23 Yahvé parla à Moïse et dit:
Olúwa tún sọ fún Mose pé,
24 « Parle à l'assemblée, et dis: « Ne restez pas autour de la tente de Koré, de Dathan et d'Abiram.
“Sọ fún ìjọ ènìyàn pé, ‘Kí wọ́n jìnnà sí àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu.’”
25 Moïse se leva et alla vers Dathan et Abiram, et les anciens d'Israël le suivirent.
Mose sì dìde lọ bá Datani àti Abiramu àwọn àgbàgbà Israẹli sì tẹ̀lé.
26 Il parla à l'assemblée en disant: « Sortez, je vous prie, des tentes de ces méchants hommes, et ne touchez à rien de ce qui leur appartient, de peur que vous ne soyez consumés par tous leurs péchés! ».
Ó sì kìlọ̀ fún ìjọ ènìyàn pé, “Ẹ kúrò ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú yìí! Ẹ má ṣe fọwọ́ kan ohun kan tí í ṣe tiwọn kí ẹ má ba à parun nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
27 Et ils s'éloignèrent de la tente de Koré, de Dathan et d'Abiram, de tous côtés. Dathan et Abiram sortirent, et se tinrent à l'entrée de leurs tentes, avec leurs femmes, leurs fils et leurs petits enfants.
Àwọn ènìyàn sì sún kúrò ní àgọ́ Kora, Datani àti Abiramu. Datani àti Abiramu jáde, àwọn ìyàwó wọn àti àwọn ọmọ wọn sì dúró sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ wọn.
28 Moïse dit: « Vous saurez ainsi que c'est Yahvé qui m'a envoyé faire toutes ces choses, car elles ne viennent pas de ma propre volonté.
Nígbà náà ni Mose wí pé, “Báyìí ni ẹ ó ṣe mọ̀ pé Olúwa ló rán mi láti ṣe gbogbo iṣẹ́ wọ̀nyí àti pé kì í ṣe ìfẹ́ inú mi ni àwọn ohun tí mò ń ṣe.
29 Si ces hommes meurent de la mort commune à tous les hommes, ou s'ils éprouvent ce que tous les hommes éprouvent, alors Yahvé ne m'a pas envoyé.
Bí àwọn ènìyàn yìí bá kú bí gbogbo ènìyàn ti ń kú, bí ìrírí wọn kò bá sì yàtọ̀ sí ti àwọn ènìyàn yòókù, a jẹ́ pé kì í ṣe Olúwa ló rán mi.
30 Mais si Yahvé fait du nouveau, si la terre ouvre sa bouche et les engloutit avec tout ce qui leur appartient, et qu'ils descendent vivants dans le séjour des morts, alors vous comprendrez que ces hommes ont méprisé Yahvé. » (Sheol h7585)
Ṣùgbọ́n bí Olúwa bá ṣe ohun tuntun, tí ilẹ̀ sì la ẹnu, tó gbé wọn mì, àwọn pẹ̀lú gbogbo ohun tí wọ́n ní, tí wọ́n sì wọ inú ibojì wọn lọ láààyè, nígbà náà ni ẹ̀yin ó mọ̀ pé àwọn ènìyàn yìí ti kẹ́gàn Olúwa.” (Sheol h7585)
31 Comme il achevait de prononcer toutes ces paroles, le sol qui était sous eux se fendit.
Bí ó sì ṣe parí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ilẹ̀ pín sí méjì nísàlẹ̀ wọn,
32 La terre ouvrit sa bouche et les engloutit avec leurs familles, tous les hommes de Koré et tous leurs biens.
ilẹ̀ sì lanu ó sì gbé wọn mì pẹ̀lú gbogbo ará ilé wọn àti àwọn ènìyàn Kora àti gbogbo ohun tí wọ́n ní.
33 Ils descendirent vivants dans le séjour des morts, avec tout ce qui leur appartenait. La terre se referma sur eux, et ils périrent du milieu de l'assemblée. (Sheol h7585)
Gbogbo wọn sì sọ̀kalẹ̀ sínú ibojì wọn láààyè pẹ̀lú ohun gbogbo tí wọ́n ní, ilẹ̀ sì padé mọ́ wọn, wọ́n sì ṣègbé kúrò láàrín ìjọ ènìyàn. (Sheol h7585)
34 Tout Israël qui les entourait s'enfuit à leur cri, car ils disaient: « De peur que la terre ne nous engloutisse ».
Gbogbo ènìyàn Israẹli tí ó yí wọn ká sì sálọ tí àwọn yòókù gbọ́ igbe wọn, wọ́n wí pé, “Ilẹ̀ yóò gbé àwa náà mì pẹ̀lú.”
35 Le feu sortit de Yahvé et dévora les deux cent cinquante hommes qui offraient le parfum.
Iná sì jáde láti ọ̀dọ̀ Olúwa ó sì run àádọ́ta lé nígba ọkùnrin tí wọ́n mú tùràrí wá.
36 Yahvé parla à Moïse, et dit:
Olúwa sọ fún Mose pé,
37 Parle à Éléazar, fils du sacrificateur Aaron, pour qu'il retire les brasiers de l'ardeur, et qu'il disperse le feu loin du camp, car ils sont saints,
“Sọ fún Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà, pé kí ó mú àwọn àwo tùràrí jáde kúrò nínú iná nítorí pé wọ́n jẹ́ mímọ́, kí ó sì tan iná náà káàkiri sí ibi tó jìnnà.
38 même les brasiers de ceux qui ont péché contre leur propre vie. Qu'on en fasse des plaques pour couvrir l'autel, car ils les ont offerts devant Yahvé. C'est pourquoi ils sont saints. Ils seront un signe pour les enfants d'Israël. »
Èyí ni àwo tùràrí àwọn tí ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Kí ẹ gún àwo tùràrí yìí, kí ẹ sì fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ, wọ́n jẹ́ mímọ́ nítorí pé wọ́n ti mú wọn wá síwájú Olúwa. Kí wọ́n jẹ́ àmì fún àwọn ọmọ Israẹli.”
39 Le sacrificateur Éléazar prit les brasiers d'airain que les brûlés avaient offerts, et il les battit pour couvrir l'autel,
Eleasari tí í ṣe àlùfáà sì kó gbogbo àwo tùràrí tí àwọn tí ó jóná mú wa, ó gún wọn pọ̀, ó fi ṣe ìbòrí fún pẹpẹ,
40 afin que ce soit un souvenir pour les enfants d'Israël, et qu'aucun étranger qui ne soit pas de la race d'Aaron ne s'approche pour offrir des parfums devant l'Éternel, afin qu'il ne soit pas comme Koré et comme sa troupe, comme l'Éternel le lui a dit par Moïse.
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ṣe sọ láti ẹnu Mose. Èyí yóò jẹ́ ohun ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, àlejò yàtọ̀ sí irú-ọmọ Aaroni kò gbọdọ̀ jó tùràrí níwájú Olúwa, ẹni tí ó bá ṣe bẹ́ẹ̀, yóò dàbí Kora àti àwọn ẹgbẹ́ rẹ̀.
41 Mais le lendemain, toute l'assemblée des enfants d'Israël se plaignit de Moïse et d'Aaron, en disant: « Vous avez tué le peuple de l'Éternel. »
Ní ọjọ́ kejì gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kùn sí Mose àti Aaroni pé, “Ẹ ti pa àwọn ènìyàn Olúwa.”
42 Lorsque l'assemblée s'assembla contre Moïse et contre Aaron, elle regarda vers la tente de la Rencontre. Et voici, la nuée la couvrait, et la gloire de Yahvé apparaissait.
Ṣùgbọ́n nígbà tí gbogbo ìjọ ènìyàn péjọ lòdì sí Mose àti Aaroni, níwájú àgọ́ ìpàdé, lójijì ni ìkùùkuu bolẹ̀, ògo Olúwa sì fi ara hàn.
43 Moïse et Aaron arrivèrent devant la tente de la Rencontre.
Nígbà náà ni Mose àti Aaroni lọ síwájú àgọ́ ìpàdé,
44 Yahvé parla à Moïse et lui dit:
Olúwa sì sọ fún Mose pé,
45 « Retirez-vous du milieu de cette assemblée, afin que je la consume en un instant. » Ils tombèrent sur leur visage.
“Yàgò kúrò láàrín ìjọ ènìyàn yìí, kí ń ba le run wọ́n ní ìṣẹ́jú kan.” Wọ́n sì dojúbolẹ̀.
46 Moïse dit à Aaron: « Prends ton encensoir, mets-y le feu de l'autel, pose-y de l'encens, porte-le rapidement à l'assemblée, et fais l'expiation pour eux, car la colère est sortie de Yahvé. La plaie a commencé. »
Mose sì sọ fún Aaroni pé, “Mú àwo tùràrí, kí o fi iná sí i lórí pẹpẹ, fi tùràrí sínú rẹ̀, kí o sì tètè mu lọ sí àárín ìjọ ènìyàn láti ṣe ètùtù fún wọn nítorí pé ìbínú Olúwa ti jáde, àjàkálẹ̀-ààrùn sì ti bẹ̀rẹ̀.”
47 Aaron fit ce que Moïse avait dit, et courut au milieu de l'assemblée. La peste avait déjà commencé parmi le peuple. Il mit l'encens et fit l'expiation pour le peuple.
Aaroni ṣe bí Mose ti wí, ó sáré lọ sí àárín àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti bẹ̀rẹ̀ láàrín wọn, ṣùgbọ́n Aaroni fín tùràrí, ó sì ṣe ètùtù fún wọn.
48 Il se plaça entre les morts et les vivants, et la peste fut arrêtée.
Ó dúró láàrín àwọn alààyè àti òkú, àjàkálẹ̀-ààrùn náà sì dúró.
49 Ceux qui moururent de la peste furent quatorze mille sept cents, sans compter ceux qui moururent à cause de l'affaire de Koré.
Ṣùgbọ́n àjàkálẹ̀-ààrùn ti pa ẹgbàá méje ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ènìyàn ní àfikún sí àwọn tí ó kú níbi ìṣẹ̀lẹ̀ Kora.
50 Aaron retourna vers Moïse à l'entrée de la tente de la Rencontre, et la peste fut arrêtée.
Aaroni padà tọ Mose lọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé nítorí pé àjàkálẹ̀-ààrùn náà ti dúró.

< Nombres 16 >