< Néhémie 5 >

1 Alors s'éleva un grand cri du peuple et de ses femmes contre leurs frères les Juifs.
Nísinsin yìí àwọn ènìyàn àti àwọn ìyàwó wọn kígbe ńlá sókè sí àwọn Júù arákùnrin wọn.
2 Car il y en avait qui disaient: « Nous, nos fils et nos filles, nous sommes nombreux. Allons chercher du blé, afin de manger et de vivre. »
Àwọn kan ń wí pé, “Àwa àti àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa pọ̀; kí àwa kí ó le è jẹ, kí a sì wà láààyè, a gbọdọ̀ rí oúnjẹ.”
3 Il y en avait aussi qui disaient: « Nous hypothéquons nos champs, nos vignes et nos maisons. Allons chercher du blé, à cause de la famine. »
Àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ti fi oko wa ọgbà àjàrà wa àti ilé wa dógò kí àwa kí ó lè rí oúnjẹ ní àkókò ìyàn.”
4 Il y en avait aussi qui disaient: « Nous avons emprunté de l'argent pour le tribut du roi en utilisant nos champs et nos vignes comme garantie.
Síbẹ̀ àwọn mìíràn wí pé, “Àwa ní láti yá owó láti san ìṣákọ́lẹ̀ fún ọba lórí àwọn oko wa àti àwọn ọgbà àjàrà wa.
5 Mais maintenant, notre chair est comme la chair de nos frères, nos enfants comme leurs enfants. Et voici que nous amenons nos fils et nos filles en esclavage pour les asservir, et certaines de nos filles ont été amenées en esclavage. Il n'est pas non plus en notre pouvoir d'y remédier, car d'autres hommes possèdent nos champs et nos vignes. »
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a jẹ́ ẹran-ara kan àti ẹ̀jẹ̀ kan gẹ́gẹ́ bí àwọn ará ìlú wa tí àwọn ọmọkùnrin wa sì dára bí í tiwọn, síbẹ̀ àwa ní láti fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wa sí oko ẹrú. Díẹ̀ nínú àwọn ọmọbìnrin wa ti wà lóko ẹrú náà, ṣùgbọ́n àwa kò ní agbára, nítorí àwọn oko àti ọgbà àjàrà wa ti di ti ẹlòmíràn.”
6 J'ai été très irrité quand j'ai entendu leur cri et ces paroles.
Èmi bínú gidigidi nígbà tí mo gbọ́ igbe wọn àti àwọn ẹ̀sùn wọ̀nyí.
7 Alors je me consultai, je contestai avec les nobles et les chefs, et je leur dis: « Vous exigez l'usure, chacun de son frère. » Je tins une grande assemblée contre eux.
Mo rò wọ́n wò ní ọkàn mi mo sì fi ẹ̀sùn kan ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè. Mo sọ fún wọn pé, ẹ̀yin ń gba owó èlé lọ́wọ́ àwọn ará ìlú u yín! Nítorí náà mo pe àpéjọ ńlá láti bá wọn wí.
8 Je leur dis: « Nous avons racheté, selon notre capacité, nos frères les Juifs qui avaient été vendus aux nations; et vous, voulez-vous même vendre vos frères, et qu'ils soient vendus à nous? » Alors ils se turent, et ne trouvèrent pas un mot à dire.
Mo sì wí fún wọn pé, “Níbi tí àwa ní agbára mọ, àwa ti ra àwọn Júù arákùnrin wa tí a ti tà fún àwọn tí kì í ṣe Júù padà. Nísinsin yìí ẹ̀yìn ń ta àwọn arákùnrin yín, tí àwa sì tún ní láti rà wọ́n padà!” Wọ́n dákẹ́, nítorí wọn kò rí ohunkóhun sọ.
9 Je dis aussi: « Ce que vous faites n'est pas bien. Ne devriez-vous pas marcher dans la crainte de notre Dieu, à cause de l'opprobre des nations, nos ennemies?
Nítorí náà, mo tẹ̀síwájú pé, “Ohun tí ẹ̀ ń ṣe kò dára. Kò ha yẹ kí ẹ máa rìn nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run bí, láti yẹra fún ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn tí í ṣe ọ̀tá wa?
10 Moi aussi, mes frères et mes serviteurs, je leur prête de l'argent et du blé. De grâce, cessons cette usure.
Èmi àti àwọn arákùnrin mi àti àwọn ènìyàn mi, pẹ̀lú ń yá àwọn ènìyàn lówó àti oúnjẹ. Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí a dáwọ́ owó èlé gbígbà yìí dúró!
11 Rendez-leur, je vous prie, dès aujourd'hui, leurs champs, leurs vignes, leurs oliviers et leurs maisons, ainsi que le centième de l'argent, du blé, du vin nouveau et de l'huile que vous leur faites payer. »
Ẹ fún wọn ní oko wọn, ọgbà àjàrà wọn, ọgbà olifi wọn àti ilé e wọn pẹ̀lú owó èlé tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn ìdá ọgọ́rùn-ún owó, oúnjẹ, wáìnì tuntun àti òróró tí ẹ ti gbà lọ́wọ́ wọn padà kíákíá.”
12 Ils dirent alors: « Nous les rétablirons, et nous ne leur demanderons rien. Nous le ferons, comme tu le dis. » Puis j'appelai les sacrificateurs, et je leur fis jurer qu'ils accompliraient cette promesse.
Wọ́n wí pé, “Àwa yóò dá a padà. Àwa kì yóò sì béèrè ohunkóhun lọ́wọ́ wọn mọ́. Àwa yóò ṣe bí o ti wí.” Nígbà náà mo pe àwọn àlùfáà, mo sì mú kí àwọn ọlọ́lá àti àwọn ìjòyè búra láti jẹ́ kí wọ́n ṣe ohun tí wọ́n ti ṣe ìlérí.
13 Je secouai aussi mes genoux, et je dis: « Que Dieu secoue tout homme de sa maison et de son travail, qui n'accomplit pas cette promesse, qu'il soit secoué et vidé comme cela. » Toute l'assemblée dit: « Amen » et loua Yahvé. Le peuple s'est conformé à cette promesse.
Mo sì gbọn ìṣẹ́tí aṣọ mi, mo wí pé, “Báyìí ni kí Ọlọ́run gbọn olúkúlùkù ènìyàn tí kò bá pa ìlérí yìí mọ́ jáde kúrò ní ilẹ̀ ìní i rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni kí a gbọn irú ẹni bẹ́ẹ̀ jáde kí ó sì ṣófo!” Gbogbo ìjọ ènìyàn sì wí pé, “Àmín,” wọ́n sì fi ìyìn fún Olúwa. Àwọn ènìyàn náà sì ṣe bí wọ́n ti ṣe ìlérí.
14 De plus, depuis que j'ai été désigné pour être leur gouverneur dans le pays de Juda, depuis la vingtième année jusqu'à la trente-deuxième année du roi Artaxerxès, c'est-à-dire douze ans, moi et mes frères n'avons pas mangé le pain du gouverneur.
Síwájú sí í, láti ogún ọdún ọba Artasasta, nígbà tí a ti yàn mí láti jẹ́ baálẹ̀ wọn ní ilẹ̀ Juda, títí di ọdún kejìlélọ́gbọ̀n ìjọba rẹ̀—ọdún méjìlá, èmi àti àwọn arákùnrin mi kò jẹ oúnjẹ baálẹ̀.
15 Mais les anciens gouverneurs qui m'ont précédé étaient soutenus par le peuple, et ils prenaient de lui du pain et du vin, plus quarante sicles d'argent; oui, même leurs serviteurs régnaient sur le peuple, mais moi, je n'ai pas agi ainsi, à cause de la crainte de Dieu.
Ṣùgbọ́n àwọn baálẹ̀ ìṣáájú—tí ó ti wà ṣáájú mi—gbe àjàgà wúwo lé àwọn ènìyàn lórí yàtọ̀ fún oúnjẹ àti wáìnì wọ́n sì tún gba ogójì ṣékélì fàdákà lọ́wọ́ wọn. Kódà àwọn ìránṣẹ́ wọn tún jẹ gàba lórí wọn. Ṣùgbọ́n èmi kò ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
16 Oui, j'ai aussi poursuivi les travaux de cette muraille. Nous n'avons pas acheté de terres. Tous mes serviteurs étaient réunis là pour l'ouvrage.
Dípò bẹ́ẹ̀, mo fi ara mi jì fún iṣẹ́ lórí odi yìí. Gbogbo àwọn ènìyàn mi péjọ síbẹ̀ fún iṣẹ́ náà; a kò sì gba ilẹ̀ kankan.
17 De plus, il y avait à ma table, parmi les Juifs et les chefs, cent cinquante hommes, sans compter ceux qui étaient venus chez nous d'entre les nations qui nous entouraient.
Síwájú sí í, àádọ́jọ àwọn Júù àti àwọn ìjòyè jẹun lórí tábìlì mi, àti pẹ̀lú àwọn tí wọ́n wá bá wa láti àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká.
18 Or, ce qui a été préparé pour un jour, c'est un bœuf et six brebis de choix. On me préparait aussi des volailles, et une fois tous les dix jours une réserve de vin de toutes sortes. Mais pour tout cela, je n'ai pas exigé la solde du gouverneur, car la servitude était lourde pour ce peuple.
Ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan ni a máa ń pèsè màlúù kan, ààyò àgùntàn mẹ́fà àti adìyẹ fún mi àti lẹ́ẹ̀kan ní ọjọ́ mẹ́wàá ni wọ́n máa ń pèsè onírúurú wáìnì tí ó pọ̀ fún mi. Fún gbogbo èyí, èmi kò béèrè oúnjẹ baálẹ̀, nítorí ohun ti a ń béèrè lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí pọ̀ jọjọ.
19 Souviens-toi de moi, mon Dieu, pour tout le bien que j'ai fait à ce peuple.
Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere, nítorí fún gbogbo ohun tí mo ti ṣe fún àwọn ènìyàn yìí.

< Néhémie 5 >