< Michée 1 >
1 Parole de Yahvé qui fut adressée à Michée, de Morasheth, aux jours de Jotham, d'Achaz et d'Ézéchias, rois de Juda, et qu'il vit concernant Samarie et Jérusalem.
Ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Mika ará Moreṣeti wá ní àkókò ìjọba Jotamu, Ahasi, àti Hesekiah, àwọn ọba Juda nìwọ̀nyí, ìran tí ó rí nípa Samaria àti Jerusalẹmu.
2 Écoutez, vous, peuples, vous tous! Écoute, ô terre, et tout ce qu'elle contient. Que le Seigneur Yahvé soit témoin contre vous, le Seigneur de son temple sacré.
Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn, fetísílẹ̀, ìwọ ayé àti gbogbo ohun tó wà níbẹ̀, kí Olúwa Olódùmarè lè ṣe ẹlẹ́rìí sí yín, Olúwa láti inú tẹmpili mímọ́ rẹ̀ wá.
3 Car voici, Yahvé sort de son lieu, et descendra et foulera les hauts lieux de la terre.
Wò ó! Olúwa ń bọ̀ wá láti ibùgbé rẹ̀; yóò sọ̀kalẹ̀, yóò sì tẹ ibi gíga ayé mọ́lẹ̀.
4 Les montagnes fondent sous lui, et les vallées se fendent comme la cire devant le feu, comme des eaux qui se déversent dans un endroit escarpé.
Àwọn òkè ńlá yóò sí yọ́ lábẹ́ rẹ̀, àwọn àfonífojì yóò sì pínyà, bí idà níwájú iná, bí omi tí ó ń sàn lọ ni ibi gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́.
5 « Tout cela à cause de la désobéissance de Jacob, et pour les péchés de la maison d'Israël. Quelle est la désobéissance de Jacob? Ce n'est pas la Samarie? Et quels sont les hauts lieux de Juda? N'est-ce pas Jérusalem?
Nítorí ìré-òfin-kọjá Jakọbu ni gbogbo èyí, àti nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli. Kí ni ìré-òfin-kọjá Jakọbu? Ǹjẹ́ Samaria ha kọ? Kí ni àwọn ibi gíga Juda? Ǹjẹ́ Jerusalẹmu ha kọ?
6 C'est pourquoi je rendrai Samarie semblable à un tas de décombres des champs, comme des endroits pour planter des vignes; et je déverserai ses pierres dans la vallée, et je découvrirai ses fondations.
“Nítorí náà, èmi yóò ṣe Samaria bí òkìtì lórí pápá, bí ibi ti à ń lò fún gbígbin ọgbà àjàrà. Èmi yóò gbá àwọn òkúta rẹ̀ dànù sínú àfonífojì. Èmi yóò sí tú ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ palẹ̀.
7 Toutes ses idoles seront mises en pièces, tous ses dons au temple seront brûlés par le feu, et je détruirai toutes ses images; car elle les a recueillis sur le salaire d'une prostituée, et au salaire d'une prostituée, ils retourneront. »
Gbogbo àwọn ère fínfín rẹ̀ ni a ó fọ́ sí wẹ́wẹ́ gbogbo àwọn ẹ̀bùn tẹmpili rẹ̀ ni a ó fi iná sun, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn òrìṣà rẹ̀ run. Nítorí tí ó ti kó àwọn ẹ̀bùn rẹ̀ jọ láti inú owó èrè panṣágà, gẹ́gẹ́ bí owó èrè panṣágà, wọn yóò sì tún padà sí owó iṣẹ́ panṣágà.”
8 C'est pourquoi je me plains et je gémis. J'irai dépouillé et nu. Je hurlerai comme les chacals et se lamenter comme les autruches.
Nítorí èyí, èmi yóò sì sọkún, èmi yóò sì pohùnréré ẹkún: èmi yóò máa lọ ní ẹsẹ̀ lásán àti ní ìhòhò. Èmi yóò ké bí akátá, èmi yóò sì máa dárò bí àwọn ọmọ ògòǹgò.
9 Car ses blessures sont incurables; car elle est arrivée jusqu'à Juda. Elle atteint la porte de mon peuple, même à Jérusalem.
Nítorí tí ọgbẹ́ rẹ̀ jẹ́ aláìlèwòtán; ó sì ti wá sí Juda. Ó sì ti dé ẹnu-bodè àwọn ènìyàn mi, àní sí Jerusalẹmu.
10 Ne le dis pas à Gath. Ne pleurez pas du tout. A Beth Ophrah, je me suis roulé dans la poussière.
Ẹ má ṣe sọ ní Gati ẹ má ṣe sọkún rárá. Ní ilẹ̀ Beti-Ofra mo yí ara mi nínú eruku.
11 Passe, habitant de Shaphir, dans la nudité et la honte. L'habitant de Zaanan ne sortira pas. Les lamentations de Beth Ezel t'enlèveront sa protection.
Ẹ kọjá lọ ni ìhòhò àti ni ìtìjú, ìwọ tí ó ń gbé ni Ṣafiri. Àwọn tí ó ń gbé ni Saanani kì yóò sì jáde wá. Beti-Eseli wà nínú ọ̀fọ̀; a ó sì gba ààbò rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ yin.
12 Car l'habitant de Maroth attend impatiemment le bien, car le mal est descendu de Yahvé jusqu'à la porte de Jérusalem.
Nítorí àwọn tí ó ń gbé ni Marati ń retí ìre, ṣùgbọ́n ibi sọ̀kalẹ̀ ti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
13 Attelez le char au coursier rapide, habitant de Lakis. Elle a été le début du péché pour la fille de Sion; car les transgressions d'Israël se sont retrouvées en toi.
Ìwọ olùgbé Lakiṣi, dì kẹ̀kẹ́ mọ́ ẹranko tí ó yára. Òun sì ni ìbẹ̀rẹ̀ ẹ̀ṣẹ̀ sí àwọn ọmọbìnrin Sioni, nítorí a rí àìṣedéédéé Israẹli nínú rẹ̀.
14 Vous ferez donc un cadeau d'adieu à Moresheth Gath. Les maisons d'Aczib seront un objet de tromperie pour les rois d'Israël.
Nítorí náà ni ìwọ ó ṣe fi ìwé ìkọ̀sílẹ̀ fún Moreṣeti Gati. Àwọn ilé Aksibu yóò jẹ́ ẹlẹ́tàn sí àwọn ọba Israẹli.
15 Je vous amènerai encore un vainqueur, habitants de Mareshah. La gloire d'Israël viendra à Adullam.
Èmi yóò sì mú àrólé kan wá sórí rẹ ìwọ olùgbé Meraṣa. Ẹni tí ó jẹ́ ògo Israẹli yóò sì wá sí Adullamu.
16 Rasez-vous la tête, et coupez vos cheveux pour les enfants de vos délices. Agrandissez votre calvitie comme le vautour, car ils sont partis en captivité loin de toi!
Fá irun orí rẹ nínú ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ aláìlágbára, sọ ra rẹ̀ di apárí bí ẹyẹ igún, nítorí wọn yóò kúrò lọ́dọ̀ rẹ lọ sí ìgbèkùn.