< Juges 4 >
1 Les enfants d'Israël firent encore ce qui est mal aux yeux de l'Éternel, après la mort d'Éhud.
Lẹ́yìn ikú Ehudu, àwọn ènìyàn Israẹli sì tún ṣẹ̀, wọ́n ṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa.
2 Yahvé les vendit entre les mains de Jabin, roi de Canaan, qui régnait à Hatsor, et dont le chef de l'armée était Sisera, qui habitait à Harosheth, chez les païens.
Nítorí náà Olúwa jẹ́ kí Jabini, ọba àwọn Kenaani, ẹni tí ó jẹ ọba ní Hasori, ṣẹ́gun wọn. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Sisera ẹni tí ń gbé Haroseti-Hagoyimu.
3 Les enfants d'Israël crièrent à Yahvé, car il avait neuf cents chars de fer, et il opprima puissamment les enfants d'Israël pendant vingt ans.
Nítorí tí ó ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún kẹ̀kẹ́ ogun irin, ó sì ń pọ́n Israẹli lójú gidigidi fún ogún ọdún, Israẹli ké pe Olúwa fún ìrànlọ́wọ́.
4 En ce temps-là, Débora, prophétesse, femme de Lappidoth, jugeait Israël.
Debora, wòlíì obìnrin, aya Lapidoti ni olórí àti aṣíwájú àwọn ará Israẹli ní àsìkò náà.
5 Elle habitait sous le palmier de Débora, entre Rama et Béthel, dans la montagne d'Ephraïm, et les enfants d'Israël montaient vers elle pour être jugés.
Òun a máa jókòó ṣe ìdájọ́ ní abẹ́ igi ọ̀pẹ tí a sọ orúkọ rẹ̀ ní ọ̀pẹ Debora láàrín Rama àti Beteli ní ilẹ̀ òkè Efraimu, àwọn ará Israẹli a sì máa wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ láti yanjú èdè-àìyedè tí wọ́n bá ní sí ara wọn, tàbí láti gbọ́ ohùn Olúwa láti ẹnu rẹ̀.
6 Elle envoya appeler Barak, fils d'Abinoam, de Kedesh Nephtali, et lui dit: « L'Éternel, le Dieu d'Israël, n'a-t-il pas donné cet ordre: Va ouvrir le chemin du mont Thabor, et prends avec toi dix mille hommes des fils de Nephtali et des fils de Zabulon?
Ní ọjọ́ kan, ó ránṣẹ́ pe Baraki ọmọ Abinoamu, ẹni tí ń gbé ní Kedeṣi ní ilẹ̀ Naftali, ó sì wí fún un pé, “Olúwa, Ọlọ́run Israẹli pa á ní àṣẹ fún un pé, ‘Kí ó kó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn akọni ọkùnrin jọ láti ẹ̀yà Naftali àti ẹ̀yà Sebuluni bí ẹgbẹ́ ogun, kí o sì síwájú wọn lọ sí òkè Tabori.
7 J'attirerai vers toi, vers le fleuve Kishon, Sisera, chef de l'armée de Jabin, avec ses chars et sa multitude, et je le livrerai entre tes mains. »
Èmi yóò sì fa Sisera olórí ogun Jabini, pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ogun rẹ àti àwọn ogun rẹ, sí odò Kiṣoni èmi yóò sì fi lé ọ lọ́wọ́ ìwọ yóò sì ṣẹ́gun wọn níbẹ̀.’”
8 Barak lui dit: « Si tu veux aller avec moi, j'irai; mais si tu ne veux pas aller avec moi, je n'irai pas. »
Baraki sì dá a lóhùn pé, “Èmi yóò lọ tí ìwọ ó bá bá mi lọ, ṣùgbọ́n tí ìwọ kì yóò bá bá mi lọ, èmi kì yóò lọ.”
9 Elle répondit: « Je veux bien aller avec toi. Cependant, le voyage que tu feras ne sera pas pour ton honneur, car Yahvé vendra Sisera entre les mains d'une femme. » Déborah se leva et partit avec Barak à Kedesh.
Debora dá a lóhùn pé, “ó dára, èmi yóò bá ọ lọ. Ṣùgbọ́n ọlá ìṣẹ́gun tí o ń lọ yìí kò ní jẹ́ tìrẹ, nítorí Olúwa yóò fi Sisera lé obìnrin lọ́wọ́,” báyìí Debora bá Baraki lọ sí Kedeṣi.
10 Barak convoqua Zabulon et Nephtali à Kédesh. Dix mille hommes le suivirent, et Débora monta avec lui.
Nígbà tí Baraki pe ẹ̀yà Sebuluni àti ẹ̀yà Naftali sí Kedeṣi ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá akíkanjú ọkùnrin ogun tẹ̀lé e, Debora pẹ̀lú bá wọn lọ.
11 Or Héber, le Kénien, s'était séparé des Kéniens, des fils de Hobab, beau-frère de Moïse, et avait dressé sa tente jusqu'au chêne de Zaanannim, qui est près de Kédesh.
Ǹjẹ́ Heberi ọmọ Keni, ti ya ara rẹ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Keni, àní àwọn ọmọ Hobabu, àna Mose, ó sì pa àgọ́ rẹ̀ títí dé ibi igi óákù Saananimu, tí ó wà ni agbègbè Kedeṣi.
12 Ils dirent à Sisera que Barak, fils d'Abinoam, était monté sur le mont Thabor.
Nígbà tí a sọ fún Sisera pé Baraki ọmọ Abinoamu ti kó ogun jọ sí òkè Tabori,
13 Sisera rassembla tous ses chars, neuf cents chars de fer, et tout le peuple qui était avec lui, depuis Harosheth des Gentils jusqu'au fleuve Kishon.
Sisera kó gbogbo kẹ̀kẹ́ ogun irin rẹ̀ tí ṣe ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rún àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, láti Haroseti tí àwọn orílẹ̀-èdè wá sí odò Kiṣoni.
14 Déborah dit à Barak: « Va, car c'est le jour où l'Éternel a livré Sisera entre tes mains. L'Éternel n'est-il pas sorti avant toi? » Barak descendit donc du mont Thabor, et dix mille hommes après lui.
Debora sì wí fún Baraki pé, “Lọ! Lónìí ni Olúwa fi Sisera lé ọ lọ́wọ́, Olúwa ti lọ síwájú rẹ.” Baraki sì síwájú, àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì tẹ̀lé e lẹ́yìn, wọ́n sì kọjá sí òkè Tabori.
15 Yahvé confondit Sisera, tous ses chars et toute son armée, au fil de l'épée, devant Barak. Sisera abandonna son char et s'enfuit à pied.
Olúwa sì mú ìdàrúdàpọ̀ wá sí àárín ogun Sisera, Olúwa sì fi ojú idà ṣẹ́gun Sisera àti àwọn oníkẹ̀kẹ́ ogun àti ọmọ-ogun orí ilẹ̀ ní iwájú Baraki. Sisera sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ ó sì fi ẹsẹ̀ sálọ.
16 Mais Barak poursuivit les chars et l'armée jusqu'à Harosheth des Gentils, et toute l'armée de Sisera tomba au fil de l'épée. Il ne resta pas un seul homme.
Baraki àti àwọn ogun rẹ̀ sì lé àwọn ọ̀tá náà, àwọn ọmọ-ogun orílẹ̀ àti àwọn kẹ̀kẹ́ ogun wọn títí dé Haroseti ti àwọn orílẹ̀-èdè, gbogbo ogun Sisera sì ti ojú idà ṣubú, kò sí ọ̀kan tí ó lè sálà tàbí tí ó wà láààyè.
17 Mais Sisera s'enfuit sur ses pieds jusqu'à la tente de Jaël, femme de Héber le Kénien, car il y avait paix entre Jabin, roi de Hatsor, et la maison de Héber le Kénien.
Ṣùgbọ́n Sisera ti fi ẹsẹ̀ sálọ sí àgọ́ Jaeli aya Heberi ẹ̀yà Keni: nítorí ìbá dá ọ̀rẹ́ àlàáfíà wà láàrín Jabini ọba Hasori àti ìdílé Heberi ti ẹ̀yà Keni.
18 Jaël sortit à la rencontre de Sisera et lui dit: « Rentre, mon seigneur, rentre chez moi; n'aie pas peur. » Il entra chez elle dans la tente, et elle le couvrit d'un tapis.
Jaeli sì jáde síta láti pàdé Sisera, ó sì wí fún un pé, “Wọlé sínú àgọ́ mi, Olúwa mi, wọlé wá má ṣe bẹ̀rù nítorí pé ààbò ń bẹ fún ọ.” Ó sì yà sínú àgọ́ rẹ̀, ó sì fi aṣọ bò ó.
19 Il lui dit: « Donne-moi un peu d'eau à boire, car j'ai soif. » Elle a ouvert un récipient de lait, lui a donné à boire et l'a couvert.
Sisera wí pé, “Òrùngbẹ ń gbẹ́ mí, jọ̀wọ́ fún mi ní omi mu.” Ó sì ṣí awọ wàrà kan, ó sì fún un mu ó sì tún daṣọ bò ó padà.
20 Il lui dit: « Tiens-toi à l'entrée de la tente, et si quelqu'un vient te demander: « Y a-t-il un homme ici? », tu diras: « Non ». »
Sisera sọ fún Jaeli pé, “Kí ó dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, àti pé bí ẹnikẹ́ni bá béèrè bóyá òun wà níbẹ̀ kí ó sọ pé, ‘Kò sí ẹnìkankan ní ibẹ̀.’”
21 Alors Jaël, femme de Héber, prit un piquet de tente, prit un marteau dans sa main, s'approcha doucement de lui, et frappa le piquet dans ses tempes, et il perça jusqu'au sol, car il était plongé dans un profond sommeil; il s'évanouit et mourut.
Ṣùgbọ́n Jaeli ìyàwó Heberi mú ìṣó àgọ́ tí ó mú àti òòlù ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì yọ́ wọ inú ibi tí ó sùn, nígbà tí ó ti sùn fọnfọn, nígbà náà ni ó kan ìṣó náà mọ́ òkè ìpéǹpéjú rẹ̀, ó sì wọlé ṣinṣin, ó sì kú.
22 Voici, comme Barak poursuivait Sisera, Jaël sortit à sa rencontre et lui dit: « Viens, je vais te montrer l'homme que tu cherches. » Il vint à elle; et voici, Sisera était étendu mort, et le piquet de la tente était dans ses tempes.
Nígbà tí Baraki dé bí ó ti ń lépa Sisera, Jaeli láti pàdé rẹ̀, wá, èmi yóò fi ẹni tí ìwọ ń wá hàn ọ́, báyìí ni ó tẹ̀lé e wọ inú àgọ́ lọ, kíyèsi Sisera dùbúlẹ̀ síbẹ̀ pẹ̀lú ìṣó àgọ́ ní agbárí rẹ̀ tí a ti kàn mọ́lẹ̀ ṣinṣin tí ó sì ti kú.
23 Ce jour-là, Dieu assujettit Jabin, roi de Canaan, devant les enfants d'Israël.
Ní ọjọ́ náà ni Ọlọ́run ṣẹ́gun Jabini ọba àwọn ará Kenaani ní iwájú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
24 La main des enfants d'Israël l'emporta de plus en plus sur Jabin, roi de Canaan, jusqu'à ce qu'ils eussent détruit Jabin, roi de Canaan.
Ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli sì le, ó sì ń lágbára síwájú àti síwájú sí i lára Jabini ọba Kenaani, títí wọ́n fi run òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀.