< Job 18 >
1 Et Bildad, le Shuhite, prit la parole,
Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn, ó sì wí pé,
2 « Combien de temps allez-vous chercher les mots? Réfléchissez, et après nous parlerons.
“Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀ tì; ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ.
3 Pourquoi sommes-nous comptés comme des animaux, qui sont devenus impurs à vos yeux?
Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bí ẹranko, tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?
4 Toi qui te déchires dans ta colère, la terre sera-t-elle abandonnée pour vous? Ou bien la pierre sera-t-elle retirée de son emplacement?
Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínú ìbínú rẹ̀; kí a ha kọ ayé sílẹ̀ nítorí rẹ̀ bi? Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?
5 « Oui, la lumière des méchants sera éteinte. L'étincelle de son feu ne brillera pas.
“Nítòótọ́ ìmọ́lẹ̀ ènìyàn búburú ni a ó pa kúrò, ọ̀wọ́-iná rẹ̀ kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀.
6 La lumière sera sombre dans sa tente. Sa lampe au-dessus de lui sera éteinte.
Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn nínú àgọ́ rẹ̀, fìtílà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni a ó sì pa pẹ̀lú.
7 Les pas de sa force seront abrégés. Son propre conseil le fera tomber.
Ìrìn ẹsẹ̀ agbára rẹ̀ yóò di fífọ; ète òun tìkára rẹ̀ ni yóò bí i ṣubú.
8 Car il est jeté dans un filet par ses propres pieds, et il s'égare dans ses mailles.
Nípa ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀ ó ti bọ́ sínú àwọ̀n, ó sì rìn lórí okùn dídẹ.
9 Un piège le saisit par le talon. Un piège va l'attraper.
Tàkúté ni yóò mú un ní gìgísẹ̀, àwọn àwọ̀n tí a dẹ yóò sì ṣẹ́gun rẹ̀.
10 Un nœud coulant est caché pour lui dans le sol, un piège pour lui sur le chemin.
A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀, a sì wà ọ̀fìn fún un lójú ọ̀nà.
11 Des terreurs l'effraieront de toutes parts, et le poursuivra sur ses talons.
Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo, yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.
12 Sa force sera affamée. Calamity sera prêt à ses côtés.
Àìlera rẹ̀ yóò di púpọ̀ fún ebi, ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.
13 Les membres de son corps seront dévorés. Le premier-né de la mort dévorera ses membres.
Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀; ikú àkọ́bí ni yóò jẹ agbára rẹ̀ run.
14 Il sera déraciné de la sécurité de sa tente. Il sera amené au roi des terreurs.
A ó fà á tu kúrò nínú àgọ́ tí ó gbẹ́kẹ̀lé, a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.
15 Dans sa tente habitera ce qui n'est pas à lui. Le soufre sera répandu sur sa demeure.
Yóò sì máa jókòó nínú àgọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe tirẹ̀; sulfuru ti o jóná ni a ó fún káàkiri ibùgbé rẹ̀.
16 Ses racines seront desséchées par-dessous. Sa branche sera coupée en haut.
Gbòǹgbò rẹ̀ yóò gbẹ níṣàlẹ̀, a ó sì ké ẹ̀ka rẹ̀ kúrò lókè.
17 Son souvenir disparaîtra de la terre. Il n'aura pas de nom dans la rue.
Ìrántí rẹ̀ yóò parun kúrò ni ayé, kì yóò sí orúkọ rẹ̀ ní ìgboro ìlú.
18 Il sera chassé de la lumière dans les ténèbres, et chassé du monde.
A ó sì lé e láti inú ìmọ́lẹ̀ sí inú òkùnkùn, a ó sì lé e kúrò ní ayé.
19 Il n'aura ni fils ni petit-fils parmi son peuple, et aucun ne reste là où il a vécu.
Kì yóò ní ọmọ tàbí ọmọ ọmọ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò kù nínú agbo ilé rẹ̀.
20 Ceux qui viendront après seront étonnés de son jour, comme ceux qui les ont précédés ont été effrayés.
Ẹnu yóò ya àwọn ìran ti ìwọ̀-oòrùn sí ìgbà ọjọ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù ìwárìrì ti í bá àwọn ìran ti ìlà-oòrùn.
21 Telles sont les demeures des injustes. C'est la place de celui qui ne connaît pas Dieu. »
Nítòótọ́ irú bẹ́ẹ̀ ni ibùgbé àwọn ènìyàn búburú, èyí sì ni ipò ẹni tí kò mọ̀ Ọlọ́run.”