< Jérémie 48 >
1 De Moab. Yahvé des Armées, le Dieu d'Israël, dit: « Malheur à Nebo! Car elle est dévastée. Kiriathaim est déçu. Il est pris. Misgab est mis à mal et en panne.
Nípa Moabu. Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Ègbé ni fún Nebo nítorí a ó parun. A dójútì Kiriataimu, a sì mú un, ojú yóò ti alágbára, a ó sì fọ́nká.
2 Les louanges de Moab n'existent plus. A Heshbon, ils ont conçu le mal contre elle: « Venez! Coupons-lui la possibilité d'être une nation. Vous aussi, les fous, vous serez réduits au silence. L'épée vous poursuivra.
Moabu kò ní ní ìyìn mọ́, ní Heṣboni ni wọn ó pète ìparun rẹ̀, ‘Wá, kí a pa orílẹ̀-èdè náà run.’ Àti ẹ̀yin òmùgọ̀ ọkùnrin pàápàá ni a ó pa lẹ́nu mọ́, a ó fi idà lé e yín.
3 Le son d'un cri venant de Horonaim, désolation et grande destruction!
Gbọ́ igbe ní Horonaimu, igbe ìrora àti ìparun ńlá.
4 Moab est détruit. Ses petits ont fait entendre un cri.
Moabu yóò di wíwó palẹ̀; àwọn ọmọdé rẹ̀ yóò kígbe síta.
5 Car ils monteront par la montée de Luhith en pleurant continuellement. Car à la descente des Horonaïm, ils ont entendu la détresse du cri de destruction.
Wọ́n gòkè lọ sí Luhiti, wọ́n ń sọkún kíkorò bí wọ́n ti ń lọ; ní ojú ọ̀nà sí Horonaimu igbe ìrora ìparun ni à ń gbọ́ lọ.
6 Fuyez! Sauvez vos vies! Soyez comme le buisson de genévrier dans le désert.
Sá! Àsálà fún ẹ̀mí yín; kí ẹ sì dàbí aláìní ní aginjù.
7 Car, parce que tu t'es confié dans tes œuvres et dans tes trésors, vous serez également pris. Chemosh partira en captivité, ses prêtres et ses princes ensemble.
Níwọ́n ìgbà tí o gbẹ́kẹ̀lé agbára àti ọrọ̀ rẹ, a ó kó ìwọ náà ní ìgbèkùn, Kemoṣi náà yóò lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn pẹ̀lú àlùfáà àti àwọn aláṣẹ rẹ̀.
8 Le destructeur s'abattra sur toutes les villes, et aucune ville n'y échappera; la vallée aussi périra, et la plaine sera détruite, comme Yahvé l'a dit.
Gbogbo ìlú rẹ ni apanirun yóò dojúkọ, ìlú kan kò sì ní le là. Àfonífojì yóò di ahoro àti ilẹ̀ títẹ́ ni a ó run, nítorí tí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
9 Donnez des ailes à Moab, pour qu'elle puisse voler et s'enfuir: et ses villes deviendront une désolation, sans personne pour les habiter.
Fi iyọ̀ sí Moabu, nítorí yóò ṣègbé, àwọn ìlú rẹ yóò sì di ahoro láìsí ẹni tí yóò gbé inú rẹ̀.
10 « Maudit soit celui qui accomplit l'œuvre de Yahvé avec négligence; et maudit soit celui qui retient son épée du sang.
“Ìfibú ni fún ẹni tí ó fi ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ Olúwa, ìfibú ni fún ẹni tí ó pa idà mọ́ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀.
11 « Moab a été à l'aise dès sa jeunesse, et il s'est installé sur sa lie, et n'a pas été vidée d'un navire à l'autre, et il n'est pas allé en captivité; son goût reste donc en lui, et son odeur n'est pas modifiée.
“Moabu ti wà ní ìsinmi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá bí i ọtí wáìnì lórí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀, tí a kò dà láti ìgò kan sí èkejì kò tí ì lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn rí. Ó dùn lẹ́nu bí ó ti yẹ, òórùn rẹ̀ kò yí padà.
12 C'est pourquoi voici, les jours viennent, dit Yahvé, « que j'enverrai vers lui ceux qui versent, et ils vont le verser; et ils videront ses vaisseaux, et briser leurs récipients en morceaux.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí n ó rán àwọn tí ó n da ọtí láti inú àwọn ìgò tí wọ́n ó sì dà á síta; wọn ó sọ àwọn ìgò rẹ̀ di òfo, wọn ó sì fọ́ àwọn ife rẹ̀.
13 Moab aura honte de Kemosch, comme la maison d'Israël a eu honte de Béthel, sa confiance.
Nígbà náà Moabu yóò sì tú u nítorí Kemoṣi, bí ojú ti í ti ilé Israẹli nígbà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Beteli.
14 « Comment pouvez-vous dire: « Nous sommes des hommes puissants »? et des hommes vaillants pour la guerre »?
“Báwo ni o ṣe lè sọ pé, ‘Ajagun ni wá, alágbára ní ogun jíjà’?
15 Moab est dévasté, et ils sont montés dans ses villes, et ses jeunes hommes choisis sont allés à l'abattoir, » dit le Roi, dont le nom est Yahvé des Armées.
A ó pa Moabu run, a ó sì gba àwọn ìlú rẹ̀; a ó sì dúńbú àwọn arẹwà ọkùnrin rẹ̀,” ni ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 « La calamité de Moab est proche, et son malheur se précipite.
“Ìṣubú Moabu súnmọ́; ìpọ́njú yóò dé kánkán.
17 Vous tous qui êtes autour de lui, plaignez-vous de lui; et vous tous qui connaissez son nom, dites, « Comment le personnel fort est brisé, la belle tige!
Ẹ dárò fún, gbogbo ẹ̀yin tí ó yí i ká gbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó. Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹ títóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’
18 « Fille qui habite à Dibon, descends de ta gloire, et s'asseoir dans la soif; car le destructeur de Moab est monté contre toi. Il a détruit vos forteresses.
“Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ, kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ, ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Diboni, nítorí tí ẹni tí ó pa Moabu run yóò dojúkọ ọ́ yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.
19 Habitant d'Arœr, tenez-vous sur le chemin et veillez. Demandez à celui qui fuit, et à celle qui s'échappe; dire: « Qu'est-ce qui a été fait?
Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran, ìwọ tí ń gbé ní Aroeri. Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà ‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’
20 Moab est déçu; car il est en panne. Gémissez et pleurez! Dites par l'Arnon que Moab est dévasté.
Ojú ti Moabu nítorí tí a wó o lulẹ̀. Ẹ hu, kí ẹ sì kígbe! Ẹ kéde rẹ̀ ní Arnoni pé, a pa Moabu run.
21 Le jugement est venu sur le pays de la plaine - sur Holon, sur Jahzah, sur Mephaath,
Ìdájọ́ ti dé sí àwọn òkè pẹrẹsẹ, sórí Holoni, Jahisa àti Mefaati,
22 sur Dibon, sur Nebo, sur Beth Diblathaim,
sórí Diboni, Nebo àti Beti-Diblataimu,
23 sur Kiriathaim, sur Beth Gamul, sur Beth Meon,
sórí Kiriataimu, Beti-Gamu àti Beti-Meoni,
24 sur Kerioth, sur Bozrah, et sur toutes les villes du pays de Moab, de loin ou de près.
sórí Kerioti àti Bosra, sórí gbogbo ìlú Moabu, nítòsí àti ní ọ̀nà jíjìn.
25 La corne de Moab est coupée, et son bras est cassé », dit Yahvé.
A gé ìwo Moabu kúrò, apá rẹ̀ dá,” ni Olúwa wí.
26 « Fais-le boire, car il s'est élevé contre Yahvé. Moab se vautrera dans son vomi, et lui aussi sera tourné en dérision.
“Ẹ jẹ́ kí a mú u mutí nítorí ó kó ìdọ̀tí bá Olúwa, jẹ́ kí Moabu lúwẹ̀ẹ́ nínú èébì rẹ̀, kí ó di ẹni ẹ̀gàn.
27 Car Israël n'était-il pas pour vous une dérision? Il a été trouvé parmi des voleurs? Car aussi souvent que vous parlez de lui, vous secouez la tête.
Ǹjẹ́ Israẹli kò di ẹni ẹ̀gàn rẹ? Ǹjẹ́ a kó o pẹ̀lú àwọn olè tó bẹ́ẹ̀ tí o ń gbọn orí rẹ̀ pẹ̀lú yẹ̀yẹ́ nígbàkígbà bí a bá sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀?
28 Vous, habitants de Moab, quittez les villes, et habitez le rocher. Soyez comme la colombe qui fait son nid au-dessus de la bouche de l'abîme.
Kúrò ní àwọn ìlú rẹ, kí o sì máa gbé láàrín àwọn òkúta, ẹ̀yin tí ó ti ń gbé inú ìlú Moabu. Ẹ dàbí i àdàbà tí ó kọ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí ẹnu ihò.
29 « Nous avons entendu parler de l'orgueil de Moab. Il est très fier de sa hauteur, de son orgueil, son arrogance, et l'arrogance de son cœur.
“A ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu: àti ìwà mo gbọ́n tan rẹ̀ àti ìgbéraga ọkàn rẹ̀.
30 Je connais sa colère, dit Yahvé, et je sais qu'elle n'est rien; ses fanfaronnades n'ont rien donné.
Mo mọ àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n òfo ni,” ni Olúwa wí, “ìfọ́nnu rẹ̀ kò lè ṣe nǹkan kan.
31 C'est pourquoi je me lamenterai sur Moab. Oui, je vais crier pour tout Moab. Ils pleureront les hommes de Kir Heres.
Nítorí náà, mo pohùnréré ẹkún lórí Moabu fún àwọn ará Moabu ni mo kígbe lóhùn rara, mo kẹ́dùn fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti.
32 Avec plus que les pleurs de Jazer Je pleurerai pour toi, vigne de Sibma. Vos branches sont passées au-dessus de la mer. Ils ont atteint jusqu'à la mer de Jazer. Le destructeur s'est abattu sur vos fruits d'été. et sur votre millésime.
Mo sọkún fún ọ bí Jaseri ṣe sọkún ìwọ àjàrà Sibma. Ẹ̀ka rẹ tẹ̀ títí dé Òkun, wọn dé Òkun Jaseri. Ajẹnirun ti kọlu èso rẹ, ìkórè èso àjàrà rẹ.
33 L'allégresse et la joie sont enlevées du champ fructueux. et du pays de Moab. J'ai fait cesser le vin dans les pressoirs. Personne ne marchera en criant. Les cris ne seront pas des cris.
Ayọ̀ àti ìdùnnú ti kúrò nínú ọgbà àjàrà àti oko Moabu. Mo dá ọwọ́ ṣíṣàn ọtí wáìnì dúró lọ́dọ̀ olùfúntí; kò sí ẹni tí ó ń tẹ̀ wọ́n pẹ̀lú igbe ayọ̀. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé igbe wà, wọn kì í ṣe igbe ti ayọ̀.
34 Depuis le cri de Heshbon jusqu'à Elealeh, jusqu'à Jahaz, ils ont fait entendre leur voix, depuis Zoar jusqu'à Horonaïm, jusqu'à Eglath Shelishiyah; car les eaux de Nimrim deviendront aussi désolées.
“Ohùn igbe wọn gòkè láti Heṣboni dé Eleale àti Jahasi, láti Soari títí dé Horonaimu àti Eglati-Ṣeliṣi, nítorí àwọn omi Nimrimu pẹ̀lú yóò gbẹ.
35 Je ferai cesser les activités de Moab, dit l'Éternel, « celui qui offre dans le haut lieu, et celui qui brûle de l'encens à ses dieux.
Ní ti Moabu ni èmi yóò ti fi òpin sí ẹni tí ó rú ẹbọ ní ibí gíga àti ẹni tí ń sun tùràrí fún òrìṣà rẹ̀,” ni Olúwa wí.
36 C'est pourquoi mon cœur résonne pour Moab comme des flûtes, et mon cœur sonne comme des flûtes pour les hommes de Kir Heres. C'est pourquoi l'abondance qu'il a obtenue a péri.
“Nítorí náà ọkàn mi ró fún Moabu bí fèrè, ọkàn mi ró bí fèrè fún àwọn ọkùnrin Kiri-Hareseti. Nítorí ìṣúra tí ó kójọ ṣègbé.
37 Car toutes les têtes sont chauves, et chaque barbe coupée. Il y a des boutures sur toutes les mains, et le sac sur la taille.
Gbogbo orí ni yóò pá, gbogbo irùngbọ̀n ni a ó gé kúrò, gbogbo ọwọ́ ni a sá lọ́gbẹ́, àti aṣọ ọ̀fọ̀ ní gbogbo ẹ̀gbẹ́.
38 Sur tous les toits de Moab, et dans ses rues, on se lamente partout; car j'ai brisé Moab comme un vase qui ne plaît à personne, dit Yahvé.
Ẹkún ńlá ní yóò wà lórí gbogbo òrùlé Moabu, àti ní ìta rẹ̀, nítorí èmi ti fọ́ Moabu bí a ti ń fọ́ ohun èlò tí kò wu ni,” ni Olúwa wí.
39 « Comme elle est brisée! Comme ils gémissent! Comme Moab a tourné le dos avec honte! Ainsi Moab deviendra-t-il une dérision et une terreur pour tous ceux qui l'entourent. »
“Èéṣe tí ẹ fi fọ́ túútúú, tí ẹ sì fi ń pohùnréré ẹkún! Báwo ni Moabu ṣe yí ẹ̀yìn padà ní ìtìjú! Moabu ti di ẹni ìtìjú àti ẹ̀gàn àti ìdààmú sí gbogbo àwọn tí ó yìí ká.”
40 Car Yahvé dit: « Voici, il volera comme un aigle, et il déploiera ses ailes contre Moab.
Báyìí ni Olúwa wí: “Wò ó ẹyẹ idì náà ń fò bọ̀ nílẹ̀ ó sì na ìyẹ́ rẹ̀ lórí Moabu.
41 Kerioth est pris, et les forteresses sont saisies. Le cœur des puissants hommes de Moab en ce jour-là sera comme le cœur d'une femme dans ses douleurs.
Kerioti ni a ó kó lẹ́rú àti ilé agbára ni ó gbà. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn akọni Moabu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ó ń rọbí.
42 Moab sera détruit et ne constituera plus un peuple, parce qu'il s'est élevé contre Yahvé.
A ó pa Moabu run gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè nítorí pé ó gbéraga sí Olúwa.
43 La terreur, la fosse et le piège sont sur toi, habitant de Moab », dit Yahvé.
Ẹ̀rù àti ọ̀fìn àti okùn dídè ń dúró dè yín, ẹ̀yin ènìyàn Moabu,” ní Olúwa wí.
44 « Celui qui fuit la terreur tombera dans la fosse; et celui qui sortira de la fosse sera pris au piège, car je vais faire tomber sur lui, même sur Moab, l'année de leur visite », dit Yahvé.
“Ẹnikẹ́ni tí ó bá sá fún ẹ̀rù yóò ṣubú sínú ọ̀fìn ẹnikẹ́ni tí o bá jáde síta nínú ọ̀fìn ní à ó mú nínú okùn dídè nítorí tí èmi yóò mú wá sórí Moabu àní ọdún ìjìyà rẹ,” ní Olúwa wí.
45 « Ceux qui ont fui se tiennent sans force sous l'ombre de Heshbon; car un feu est sorti de Heshbon, et une flamme du milieu de Sihon, et a dévoré le coin de Moab, et la couronne de la tête des tumultueux.
“Ní abẹ́ òjìji Heṣboni àwọn tí ó sá dúró láìní agbára, nítorí iná ti jáde wá láti Heṣboni, àti ọwọ́ iná láti àárín Sihoni, yóò sì jó iwájú orí Moabu run, àti agbárí àwọn ọmọ aláriwo.
46 Malheur à toi, ô Moab! Le peuple de Chemosh est défait; car tes fils sont emmenés en captivité, et tes filles en captivité.
Ègbé ní fún ọ Moabu! Àwọn ènìyàn orílẹ̀-èdè Kemoṣi ṣègbé a kó àwọn ọmọkùnrin rẹ lọ sí ilẹ̀ àjèjì àti àwọn ọmọbìnrin rẹ lọ sí ìgbèkùn.
47 « Mais, dans la suite des temps, je ramènerai les captifs de Moab, » dit Yahvé. Ainsi va le jugement de Moab.
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Moabu padà ní ọjọ́ ìkẹyìn,” ni Olúwa wí. Eléyìí ní ìdájọ́ ìkẹyìn lórí Moabu.