< Jérémie 2 >
1 La parole de Yahvé me fut adressée, en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé:
2 « Va, et proclame aux oreilles de Jérusalem: « Yahvé dit », « Je me souviens pour vous de la gentillesse de votre jeunesse, votre amour en tant que mariée, comment tu m'as poursuivi dans le désert, dans une terre qui n'a pas été ensemencée.
“Lọ kí o sì kéde sí etí Jerusalẹmu pé: “Báyìí ni Olúwa wí, “‘Èmi rántí ìṣeun ìgbà èwe rẹ, ìfẹ́ ìgbéyàwó rẹ àti nígbà tí ìwọ tẹ̀lé mi nínú ijù, nínú ìyàngbẹ ilẹ̀.
3 Israël était la sainteté pour Yahvé, les prémices de son accroissement. Tous ceux qui le dévorent seront tenus pour coupables. Le malheur viendra sur eux, dit Yahvé. »
Israẹli jẹ́ mímọ́ sí Olúwa, àkọ́kọ́ èso ìkórè rẹ̀, gbogbo ẹnikẹ́ni tí ó jẹ run ni a ó dá lẹ́bi, ibi yóò sì wá sí orí wọn,’” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí.
4 Écoutez la parole de Yahvé, maison de Jacob, et toutes les familles de la maison d'Israël!
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ìdílé Jakọbu àti gbogbo ẹ̀yin ará ilé Israẹli.
5 Yahvé dit, « Quelle iniquité vos pères ont-ils trouvée en moi, qu'ils se sont éloignés de moi, et ont marché après une vanité sans valeur, et sont devenus sans valeur?
Báyìí ni Olúwa wí: “Irú àìṣedéédéé wo ni baba yín rí lọ́wọ́ mi, tí wọ́n fi jìnnà sí mi? Wọ́n tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán, àwọn fúnra wọn sì di asán.
6 Ils n'ont pas dit: « Où est l'Éternel qui nous a fait monter du pays d'Égypte? qui nous a conduit dans le désert, à travers un pays de déserts et de fosses, à travers un pays de sécheresse et d'ombre de la mort, à travers une terre que personne n'a traversée, et où aucun homme ne vivait?
Wọn kò béèrè, ‘Níbo ni Olúwa wà, tí ó mú wa jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, tí ó mú wa la aginjù já, tí ó mú wa la àárín pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti ihò, ìyàngbẹ ilẹ̀ àti òkùnkùn biribiri, ilẹ̀ ibi tí ẹnikẹ́ni kò là kọjá, tí ẹnikẹ́ni kò sì tẹ̀dó sí?’
7 Je vous ai fait entrer dans un pays abondant. pour manger ses fruits et ses bienfaits; mais quand vous êtes entrés, vous avez souillé mon pays, et ont fait de mon héritage une abomination.
Èmi mú yín wá sí ilẹ̀ ọlọ́ràá láti máa jẹ èso ibẹ̀ àti ọrọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin wọ inú rẹ̀, ẹ sì bà á jẹ́, ẹ sì sọ ogún mi di ohun ìríra.
8 Les prêtres ne disaient pas: « Où est Yahvé? et ceux qui s'occupent de la loi ne me connaissaient pas. Les dirigeants ont aussi transgressé mes règles, et les prophètes ont prophétisé par Baal et suivi des choses qui ne profitent pas.
Àwọn àlùfáà kò béèrè wí pé, ‘Níbo ni Olúwa wà?’ Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú òfin kò si mọ̀ mí, àwọn olùṣọ́ sì ṣẹ̀ sí mi. Àwọn wòlíì sì ń sọtẹ́lẹ̀ nípa òrìṣà Baali, wọ́n sì ń tẹ̀lé àwọn òrìṣà asán.
9 « C'est pourquoi je contesterai encore avec vous, dit Yahvé, « et je me disputerai avec les enfants de vos enfants ».
“Nítorí náà, mo fi ẹ̀sùn kàn yín lẹ́ẹ̀kan sí i,” ni Olúwa wí. “Èmi ó sì fi ẹ̀sùn kan àwọn ọmọ ọwọ́ rẹ.
10 Car passez dans les îles de Kittim, et regardez. Envoie à Kedar, et réfléchis bien, et voir s'il y a eu une telle chose.
Rékọjá lọ sí erékùṣù àwọn ara Kittimu, kí ẹ sì wò ó, ránṣẹ́ lọ sí ìlú Kedari, kí ẹ sì kíyèsi gidigidi; kí ẹ wò bí irú nǹkan báyìí bá ń bẹ níbẹ̀?
11 Une nation a changé ses dieux, qui ne sont pas vraiment des dieux? Mais mon peuple a changé sa gloire pour ce qui ne profite pas.
Orílẹ̀-èdè kan ha á pa ọlọ́run rẹ̀ dà? (Síbẹ̀, wọ́n kì í ṣe iṣẹ́ ọlọ́run.) Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi ti pààrọ̀ Ọlọ́run ògo wọn fún àwọn ère tí kò níyì.
12 « Cieux, soyez étonnés de ce qui suit et avoir horriblement peur. Soyez très désolés », dit Yahvé.
Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì kí ẹ sì wárìrì pẹ̀lú ìbẹ̀rù ńlá,” ni Olúwa wí.
13 « Car mon peuple a commis deux maux: ils m'ont abandonné, moi, la source d'eau vive, et se sont taillés des citernes: des citernes cassées qui ne peuvent pas contenir d'eau.
“Àwọn ènìyàn mi ti dẹ́ṣẹ̀ méjì, wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, Èmi orísun omi ìyè, wọ́n sì ti ṣe àmù, àmù fífọ́ tí kò lè gba omi dúró.
14 Israël est-il un esclave? Est-il né dans l'esclavage? Pourquoi est-il devenu un captif?
Israẹli ha á jẹ́ ọmọ ọ̀dọ̀ ẹrú nípa ìbí? Kí ló ha a dé tí ó fi di ìkógun?
15 Les jeunes lions ont rugi contre lui et ont élevé leur voix. Ils ont fait de ses terres des déchets. Ses villes sont brûlées, sans habitant.
Àwọn kìnnìún ké ramúramù; wọ́n sì ń bú mọ́ wọn. Wọ́n ti fi ilẹ̀ rẹ̀ ṣòfò; ìlú rẹ̀ ti di jíjóná, ó sì ti di ìkọ̀sílẹ̀.
16 Les enfants de Memphis et de Tachpanès ont brisé la couronne de ta tête.
Bákan náà, àwọn ọkùnrin Memfisi àti Tafanesi wọ́n ti fa adé orí rẹ yọ.
17 « N'est-ce pas vous qui l'avez provoqué? en ce que tu as abandonné Yahvé ton Dieu, quand il te conduisait par le chemin?
Ẹ̀yin kò ha a ti fa èyí sórí ara yín nípa kíkọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀ nígbà tí ó tọ́ ọ lójú ọ̀nà?
18 Maintenant, que gagnez-vous à aller en Égypte, pour boire les eaux du Shihor? Ou bien, pourquoi voulez-vous aller jusqu'en Assyrie, pour boire les eaux du fleuve?
Kí ló dé tí o ṣe wá lọ Ejibiti láti lọ mu omi ní Ṣihori? Kí ló dé tí o sì fi lọ sí Asiria láti lọ mú omi ni odò Eufurate náà?
19 « Ta propre méchanceté te corrigera, et votre retour en arrière vous réprimandera. Sachez donc et voyez que c'est une chose mauvaise et amère, que tu as abandonné Yahvé ton Dieu, et que ma crainte ne soit pas en vous, dit le Seigneur, Yahvé des Armées.
Iṣẹ́ búburú yín yóò fìyà jẹ yín ìpadàsẹ́yìn rẹ yóò sì bá ọ wí mọ̀ kí o sì rí i wí pé ibi àti ohun búburú yóò sì jẹ́ tìrẹ nígbà tí o ti kọ Olúwa Ọlọ́run sílẹ̀, ẹ kò sì ní ìbẹ̀rù fún mi,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
20 « Car il y a longtemps que j'ai brisé ton joug, et briser vos liens. Tu as dit: « Je ne servirai pas ». car sur chaque haute colline et sous chaque arbre vert, tu t'es incliné, jouant la prostituée.
“Nígbà àtijọ́, o ti fọ́ àjàgà rẹ sọnù, ìwọ sì já ìdè rẹ; ìwọ wí pé, ‘Èmi kì yóò sìn ọ́!’ Lóòtítọ́, lórí gbogbo òkè gíga ni àti lábẹ́ igi tí ó tànkálẹ̀ ni ìwọ dùbúlẹ̀ sí gẹ́gẹ́ bí panṣágà.
21 Pourtant, je t'avais planté une vigne noble, une semence pure et fidèle. Comment donc êtes-vous devenus pour moi les branches dégénérées d'une vigne étrangère?
Èmi ti gbìn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àjàrà ọ̀tọ̀, gẹ́gẹ́ bí ìṣúra ọlọ́lá. Báwo wá ni ìwọ ṣe yípadà sí mi di àjàrà búburú àti aláìmọ́?
22 Car si tu te laves avec de la lessive, et utiliser beaucoup de savon, mais ton iniquité est marquée devant moi », dit le Seigneur Yahvé.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé o wẹ ara rẹ pẹ̀lú sódà tí o sì lo ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọṣẹ síbẹ̀síbẹ̀ èérí ni ẹ̀ṣẹ̀ rẹ níwájú,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
23 « Comment pouvez-vous dire: « Je ne suis pas souillé »? Je ne me suis pas attaqué aux Baals? Voyez votre chemin dans la vallée. Sachez ce que vous avez fait. Tu es un dromadaire rapide qui parcourt ses chemins,
“Báwo ni ìwọ ṣe wí pé, ‘Èmi kò ṣe aláìmọ́, Èmi kò sá à tẹ̀lé àwọn Baali’? Wo bí o ṣe hùwà ní àfonífojì; wo ohun tí o ṣe. Ìwọ jẹ́ abo ìbákasẹ tí ń sá síyìn-ín sọ́hùn-ún.
24 un âne sauvage habitué au désert, qui renifle le vent dans sa soif. Quand elle est en chaleur, qui peut la repousser? Tous ceux qui la cherchent ne se lasseront pas. Dans son mois, ils la trouveront.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ igbó tí ń gbé aginjù tí ń fa ẹ̀fúùfù ìfẹ́ sí i mu rẹ, ta ni ó le è mú dúró ní àkókò rẹ̀? Kí gbogbo àwọn akọ ẹran tí o wá a kiri kì ó má ṣe dá ara wọn lágara, nítorí wọn yóò rí ní àkókò oṣù rẹ̀.
25 « Empêchez vos pieds d'être nus, et votre gorge de la soif. Mais tu as dit: « C'est en vain ». Non, car j'ai aimé des étrangers, et je les suivrai.
Dá ẹsẹ̀ dúró láìwọ bàtà, àti ọ̀fun rẹ nínú òǹgbẹ. Ṣùgbọ́n ìwọ wí pé, ‘Asán ni! Èmi fẹ́ràn àwọn ọlọ́run àjèjì, àwọn ni èmi yóò tọ̀ lẹ́yìn.’
26 Comme le voleur a honte quand on le trouve, et la maison d'Israël a honte... eux, leurs rois, leurs princes, leurs prêtres et leurs prophètes,
“Gẹ́gẹ́ bí a ṣe ń dójútì olè nígbà tí a bá mú u, bẹ́ẹ̀ náà ni ojú yóò ti ilé Israẹli— àwọn ọba àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn àlùfáà àti wòlíì wọn pẹ̀lú.
27 qui disent au bois: « Tu es mon père ». et une pierre: « Tu m'as donné naissance ». car ils m'ont tourné le dos, et non leur visage, mais au moment de leur détresse, ils diront: « Lève-toi et sauve-nous! ».
Wọ́n sọ fún igi pé, ‘Ìwọ ni baba mi,’ àti sí òkúta wí pé, ‘Ìwọ ni ó bí mi,’ wọ́n ti kọ ẹ̀yìn wọn sí mi, wọn kò kọ ojú sí mi síbẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú ìṣòro, wọn yóò wí pé, ‘Wá kí o sì gbà wá!’
28 « Mais où sont vos dieux que vous vous êtes faits? Laissez-les se lever, s'ils peuvent vous sauver au moment où vous êtes dans le pétrin, car tu as autant de dieux que tu as de villes, ô Juda.
Níbo wá ni àwọn ọlọ́run tí ẹ ṣe fúnra yín ha a wà? Jẹ́ kí wọ́n wá kí wọ́n sì gbà yín nígbà tí ẹ bá wà nínú ìṣòro! Nítorí pé ẹ̀yin ní àwọn ọlọ́run púpọ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ṣe ni àwọn ìlú, ìwọ Juda.
29 « Pourquoi voulez-vous me disputer? Vous avez tous péché contre moi, dit Yahvé.
“Kí ló dé tí o ṣe wá ń fi ẹ̀sùn kàn mí? Gbogbo yín ni ó ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi,” ni Olúwa wí.
30 « C'est en vain que j'ai frappé tes enfants. Ils n'ont reçu aucune correction. Votre propre épée a dévoré vos prophètes, comme un lion destructeur.
“Nínú asán mo fìyà jẹ àwọn ènìyàn yín, wọn kò sì gba ìbáwí. Idà yín ti pa àwọn wòlíì yín run, gẹ́gẹ́ bí kìnnìún tí ń bú ramúramù.
31 Génération, considère la parole de Yahvé. Ai-je été un désert pour Israël? Ou une terre de ténèbres épaisses? Pourquoi mon peuple dit-il: « Nous nous sommes détachés »? Nous ne viendrons plus chez toi »?
“Ẹ̀yin ìran yìí, ẹ kíyèsi ọ̀rọ̀ Olúwa: “Mo ha ti di aginjù sí Israẹli tàbí mo jẹ ilẹ̀ olókùnkùn biribiri? Èéṣe tí àwọn ènìyàn mi ṣe wí pé, ‘A ní àǹfààní láti máa rìn kiri; àwa kì yóò tọ̀ ọ́ wá mọ́?’
32 « Une vierge peut-elle oublier ses ornements, ou une mariée sa tenue? Mais mon peuple m'a oublié pendant des jours sans nombre.
Wúńdíá ha le gbàgbé ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, tàbí ìyàwó ohun ọ̀ṣọ́ ìgbéyàwó rẹ̀? Síbẹ̀, àwọn ènìyàn mi ti gbàgbé mi ní ọjọ́ àìníye.
33 Comme tu prépares bien ton chemin pour chercher l'amour! C'est pourquoi tu as même enseigné tes voies aux méchantes femmes.
Ìwọ ti jẹ́ ọlọ́gbọ́n tó nípa ọ̀rọ̀ ìfẹ́! Àwọn obìnrin búburú yóò kẹ́kọ̀ọ́ nípa ọ̀nà rẹ.
34 Le sang des âmes des pauvres innocents se trouve aussi dans tes jupes. Vous ne les avez pas trouvés en train d'entrer par effraction, mais c'est à cause de toutes ces choses.
Lórí aṣọ rẹ ni wọ́n bá ẹ̀jẹ̀ àwọn tálákà aláìṣẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ kò ká wọn mọ́ níbi tí wọ́n ti ń rùn wọlé. Síbẹ̀ nínú gbogbo èyí
35 Tu as pourtant dit: « Je suis innocent. Sa colère s'est détournée de moi. « Voici, je vais vous juger, parce que tu dis: « Je n'ai pas péché ».
ìwọ sọ wí pé, ‘Èmi jẹ́ aláìṣẹ̀; kò sì bínú sí mi.’ Èmi yóò mú ìdájọ́ mi wá sórí rẹ nítorí pé ìwọ wí pé, ‘Èmi kò dẹ́ṣẹ̀.’
36 Pourquoi faites-vous tant d'efforts pour changer vos habitudes? Tu auras aussi honte de l'Égypte, comme vous avez eu honte de l'Assyrie.
Èéṣe tí ìwọ fi ń lọ káàkiri láti yí ọ̀nà rẹ padà? Ejibiti yóò dójútì ọ́ gẹ́gẹ́ bí i ti Asiria.
37 Vous quitterez aussi ce lieu avec les mains sur la tête; car Yahvé a rejeté ceux en qui vous vous êtes confiés, et vous ne prospérerez pas avec eux.
Ìwọ yóò sì fi ibẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú kíkáwọ́ rẹ lé orí rẹ, nítorí pé Olúwa ti kọ̀ àwọn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé sílẹ̀, kì yóò sí ìrànlọ́wọ́ kankan fún ọ láti ọ̀dọ̀ wọn.