< Jérémie 15 >

1 Et Yahvé me dit: « Moïse et Samuel ont beau se tenir devant moi, mon esprit ne s'est pas tourné vers ce peuple. Chasse-les de ma vue, et qu'ils sortent!
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún mi pé: “Kódà kí Mose àti Samuẹli dúró níwájú mi, ọkàn mi kì yóò lọ sọ́dọ̀ àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Mú wọn kúrò níwájú mi! Jẹ́ kí wọn ó lọ!
2 Lorsqu'ils te demanderont: « Où sortirons-nous? », tu leur répondras: « Yahvé dit »: « Ceux qui sont pour la mort, à la mort; ceux qui sont pour l'épée, pour l'épée; ceux qui sont pour la famine, à la famine; et ceux qui sont pour la captivité, à la captivité. »
Tí wọ́n bá sì bi ọ́ pé, ‘Níbo ni kí a lọ?’ Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: “‘Àwọn tí a kọ ikú mọ́, sí ikú; àwọn tí a kọ idà mọ́, sí idà; àwọn tí a kọ ìyàn mọ́, sí ìyàn; àwọn tí a kọ ìgbèkùn mọ́ sí ìgbèkùn.’
3 « J'établirai sur eux quatre espèces, » dit Yahvé: « l'épée pour tuer, les chiens pour déchirer, les oiseaux du ciel et les animaux de la terre, pour dévorer et détruire.
“Èmi yóò rán oríṣìí ìjìyà mẹ́rin láti kọlù wọ́n,” ni Olúwa wí, “Idà láti pa, àwọn ajá láti wọ́ wọn lọ, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹranko orí ilẹ̀ láti jẹ àti láti parun.
4 Je les ferai aller et venir parmi tous les royaumes de la terre, à cause de Manassé, fils d'Ézéchias, roi de Juda, pour ce qu'il a fait à Jérusalem.
N ó sọ wọ́n di ẹni ìkórìíra níwájú gbogbo ìjọba ayé torí ohun tí Manase ọmọ Hesekiah ọba Juda ṣe ní Jerusalẹmu.
5 Car qui aura pitié de toi, Jérusalem? Qui va vous pleurer? Qui viendra demander votre bien-être?
“Ta ni yóò ṣàánú rẹ, ìwọ Jerusalẹmu? Ta ni yóò dárò rẹ? Ta ni yóò dúró béèrè àlàáfíà rẹ?
6 Vous m'avez rejeté, dit Yahvé. « Vous avez fait marche arrière. C'est pourquoi j'ai étendu ma main contre vous. et vous a détruit. Je suis fatigué de montrer de la compassion.
O ti kọ̀ mí sílẹ̀,” ni Olúwa wí, “Ìwọ sì wà nínú ìpadàsẹ́yìn. Nítorí náà, Èmi yóò dáwọ́lé ọ, èmi ó sì pa ọ́ run, Èmi kò sì ní fi ojú àánú wò ọ́ mọ́.
7 Je les ai vannés avec un éventail aux portes du pays. Je les ai privés d'enfants. J'ai détruit mon peuple. Ils ne sont pas revenus sur leurs pas.
Èmi kò tún lè fi ìfẹ́ hàn si ọ, Èmi yóò fi àtẹ fẹ́ wọn sí ẹnu-ọ̀nà ìlú náà. Èmi yóò mú ìṣọ̀fọ̀ àti ìparun bá àwọn ènìyàn mi nítorí pé wọn kò tí ì yípadà kúrò lọ́nà wọn.
8 Leurs veuves sont plus nombreuses que le sable des mers. J'ai fait venir sur eux, contre la mère des jeunes gens, un destructeur à midi. J'ai fait en sorte que l'angoisse et la terreur s'abattent soudainement sur elle.
Èmi yóò jẹ́ kí àwọn opó wọn pọ̀ ju yanrìn Òkun lọ. Ní ọjọ́-kanrí ni èmi ó mú apanirun kọlu àwọn ìyá ọmọkùnrin wọn. Lójijì ni èmi yóò mú ìfòyà àti ìbẹ̀rù bá wọn.
9 Celle qui a porté sept enfants se languit. Elle a abandonné l'esprit. Son soleil s'est couché alors qu'il faisait encore jour. Elle a été déçue et déconcertée. Je livrerai leur résidu à l'épée devant leurs ennemis, dit Yahvé.
Ìyá ọlọ́mọ méje yóò dákú, yóò sì mí ìmí ìgbẹ̀yìn. Òòrùn rẹ yóò wọ̀ lọ́sàn án gangan, yóò di ẹni ẹ̀tẹ́ òun àbùkù. Èmi yóò fi àwọn tí ó bá yè síwájú àwọn ọ̀tá wọn tí idà wà lọ́wọ́ wọn,” ni Olúwa wí.
10 Malheur à moi, ma mère, de ce que tu m'as enfanté, un homme de dispute, et un homme de discorde pour toute la terre! Je n'ai pas prêté, et les hommes ne m'ont pas prêté non plus; mais chacun d'entre eux me maudit.
Háà! Ó ṣe tí ìyá mi bí mi, ọkùnrin tí gbogbo ilẹ̀ dojúkọ tí wọ́n sì bá jà! Èmi kò wínni, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò yá lọ́wọ́ ẹnikẹ́ni, síbẹ̀, gbogbo ènìyàn ló ń fi mí ré.
11 Yahvé dit, « Très certainement, je vous renforcerai pour de bon. Je ferai certainement en sorte que l'ennemi t'adresse des suppliques au moment du malheur. et au temps de l'affliction.
Olúwa sọ pé, “Dájúdájú èmi ò dá ọ sí fún ìdí kan pàtó; dájúdájú mo mú kí àwọn ọ̀tá rẹ tẹríba níwájú rẹ nígbà ibi àti ìpọ́njú.
12 Peut-on briser le fer, même le fer du nord, et le bronze?
“Ǹjẹ́ ẹnìkan lè fi ọwọ́ ṣẹ́ irin irin láti àríwá tàbí idẹ?
13 Je donnerai tes biens et tes trésors pour un pillage sans prix, et cela pour tous vos péchés, même dans toutes vos frontières.
“Gbogbo ọlá àti ìṣúra rẹ ni èmi ó fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìkógun láìgba nǹkan kan nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jákèjádò orílẹ̀-èdè rẹ.
14 Je les ferai passer avec vos ennemis dans un pays que vous ne connaissez pas; car un feu est allumé dans ma colère, qui brûleront sur vous. »
Èmi yóò fi ọ́ ṣẹrú fún àwọn ọ̀tá rẹ ní ìlú tí ìwọ kò mọ̀ nítorí ìbínú mi yóò rán iná tí yóò jó ọ.”
15 Yahvé, tu sais. Souviens-toi de moi, rends-moi visite, et venge-moi de mes persécuteurs. Tu es patient, alors ne m'enlève pas. Sachez que pour vous, j'ai souffert l'opprobre.
Ó yé ọ, ìwọ Olúwa; rántí mi kí o sì ṣe ìtọ́jú mi. Gbẹ̀san mi lára àwọn tó dìtẹ̀ mi. Ìwọ ti jìyà fún ìgbà pípẹ́, má ṣe mú mi lọ; nínú bí mo ṣe jìyà nítorí tìrẹ.
16 Vos mots ont été trouvés, et je les ai mangés. Vos paroles ont été pour moi une joie et l'allégresse de mon cœur, car je suis appelé par ton nom, Yahvé, Dieu des armées.
Nígbà tí ọ̀rọ̀ rẹ dé, mo jẹ wọ́n, àwọn ni ìdùnnú àti ayọ̀ ọkàn mi, nítorí pé orúkọ rẹ ni a fi ń pè mí, Ìwọ Olúwa Ọlọ́run Alágbára.
17 Je ne me suis pas assis dans l'assemblée de ceux qui s'amusent et se réjouissent. Je me suis assis seul à cause de ta main, car tu m'as rempli d'indignation.
Èmi kò fìgbà kan jókòó láàrín àwọn ẹlẹ́gàn, n ko bá wọn yọ ayọ̀ pọ̀; mo dá jókòó torí pé ọwọ́ rẹ wà lára mi, ìwọ sì ti fi ìbínú rẹ kún inú mi.
18 Pourquoi ma douleur est-elle perpétuelle, et ma blessure incurable, qui refuse d'être guéri? Serez-vous vraiment pour moi comme un ruisseau trompeur, comme les eaux qui échouent?
Èéṣe tí ìrora mi kò lópin, tí ọgbẹ́ mi kò sì ṣe é wòsàn? Ní òtítọ́ ìwọ yóò dàbí kànga ẹ̀tàn sí mi, gẹ́gẹ́ bí ìsun tó kọ̀ tí kò sun?
19 C'est pourquoi Yahvé dit, « Si tu reviens, alors je te ramènerai à nouveau, pour que tu puisses te tenir devant moi; et si vous enlevez le précieux du vilain, tu seras comme ma bouche. Ils reviendront vers vous, mais vous n'y retournerez pas.
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, “Tí o bá ronúpìwàdà, Èmi ó dá ọ padà wá kí o lè máa sìn mí; tí ó bá sọ ọ̀rọ̀ tó dára, ìwọ yóò di agbẹnusọ mi. Jẹ́ kí àwọn ènìyàn yìí kọjú sí ọ; ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ kọjú sí wọn.
20 Je ferai de toi pour ce peuple une muraille de bronze fortifiée. Ils se battront contre vous, mais ils ne prévaudront pas contre vous; car je suis avec vous pour vous sauver et pour vous délivrer, dit Yahvé.
Èmi fi ọ́ ṣe odi idẹ tí ó lágbára, sí àwọn ènìyàn wọ̀nyí; wọn ó bá ọ jà ṣùgbọ́n wọn kò ní lè borí rẹ, nítorí pé, mo wà pẹ̀lú rẹ láti gbà ọ́ là, kí n sì dáàbò bò ọ́,” ni Olúwa wí.
21 « Je vous délivrerai de la main des méchants, et je vous rachèterai de la main du terrible. »
“Èmi yóò gbà ọ́ sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ìkà ènìyàn, Èmi yóò sì rà ọ́ padà kúrò lọ́wọ́ àwọn ẹni búburú.”

< Jérémie 15 >