< Isaïe 38 >
1 En ces jours-là, Ézéchias était malade et près de mourir. Le prophète Ésaïe, fils d'Amoz, vint le trouver et lui dit: « Yahvé dit: « Mets en ordre ta maison, car tu vas mourir et tu ne vivras pas. »
Ní ọjọ́ náà ni Hesekiah ṣe àìsàn dé ojú ikú. Wòlíì Isaiah ọmọ Amosi sì lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ohun tí Olúwa wí nìyìí: Palẹ̀ ilé è rẹ mọ́, bí ó ti yẹ nítorí pé ìwọ yóò kú; ìwọ kì yóò dìde àìsàn yìí.”
2 Alors Ézéchias tourna son visage vers la muraille et pria Yahvé,
Hesekiah yí ojú u rẹ̀ sí ara ògiri, ó sì gba àdúrà sí Olúwa,
3 et dit: « Souviens-toi maintenant, Yahvé, je t'en supplie, que j'ai marché devant toi dans la vérité et avec un cœur parfait, et que j'ai fait ce qui est bon à tes yeux. » Et Ézéchias pleura amèrement.
“Rántí, Ìwọ Olúwa, bí mo ti rìn pẹ̀lú òtítọ́ níwájú rẹ, àti bí mo ti fi ọkàn dídúró ṣinṣin ṣe ohun tí ó dára ní ojú ù rẹ.” Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah sì sọkún kíkorò.
4 Et la parole de Yahvé fut adressée à Ésaïe, en ces termes:
Lẹ́yìn náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Isaiah wá pé,
5 « Va, et dis à Ézéchias: « Yahvé, le Dieu de David, ton père, dit: « J'ai entendu ta prière. J'ai vu tes larmes. Voici, je vais ajouter quinze ans à ta vie.
“Lọ kí o sì sọ fún Hesekiah pé, ‘Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Ọlọ́run Dafidi baba rẹ sọ pé, Èmi ti gbọ́ àdúrà rẹ mo sì ti rí omijé rẹ, Èmi yóò fi ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dógún kún ọjọ́ ayé rẹ.
6 Je te délivrerai, toi et cette ville, de la main du roi d'Assyrie, et je défendrai cette ville.
Èmi yóò sì gba ìwọ àti ìlú yìí sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ọba Asiria. Èmi yóò sì dáàbò bo ìlú yìí.
7 Ce sera pour vous un signe de la part de l'Éternel: l'Éternel fera ce qu'il a dit.
“‘Èyí yìí ni àmì tí Olúwa fún ọ láti fihàn wí pé Olúwa yóò mú ìpinnu rẹ̀ ṣẹ.
8 Voici, je vais faire en sorte que l'ombre du cadran solaire, qui s'est couchée sur le cadran solaire d'Achaz avec le soleil, revienne en arrière de dix pas.''". Le soleil revint donc de dix pas sur le cadran solaire sur lequel il s'était couché.
Èmi yóò mú òjìji oòrùn kí ó padà sẹ́yìn ní ìṣísẹ̀ mẹ́wàá nínú èyí tí ó fi sọ̀kalẹ̀ ní ibi àtẹ̀gùn ti Ahasi.’” Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn padà sẹ́yìn ní ìṣísẹ̀ mẹ́wàá sí ibi tí ó ti dé tẹ́lẹ̀.
9 Écriture d'Ézéchias, roi de Juda, lorsqu'il fut malade et qu'il fut guéri de sa maladie:
Ìwé tí Hesekiah ọba Juda kọ lẹ́yìn àìsàn rẹ̀ nígbà tí ó ti gbádùn tán.
10 J'ai dit: « Au milieu de ma vie, j'entre dans les portes du séjour des morts. Je suis privé du résidu de mes années. » (Sheol )
Èmi wí pé, “Ní àárín gbùngbùn ọjọ́ ayé mi èmi ó ha kọjá lọ ní ibodè ikú kí a sì dùn mí ní àwọn ọdún mi tí ó ṣẹ́kù?” (Sheol )
11 J'ai dit: « Je ne verrai pas Yah, Yah sur la terre des vivants. Je ne verrai plus l'homme avec les habitants du monde.
Èmi wí pé, “Èmi kì yóò lè tún rí Olúwa mọ́, àní Olúwa, ní ilẹ̀ àwọn alààyè; èmi kì yóò lè síjú wo ọmọ ènìyàn mọ́, tàbí kí n wà pẹ̀lú àwọn tí ó sì ń gbe orílẹ̀ ayé báyìí.
12 Ma demeure est enlevée, et est emporté loin de moi comme la tente d'un berger. J'ai enroulé ma vie comme un tisserand. Il me coupera du métier à tisser. Du jour à la nuit, vous allez m'achever.
Gẹ́gẹ́ bí àgọ́ olùṣọ́-àgùntàn, ilé mi ni a ti wó lulẹ̀ tí a sì gbà kúrò lọ́wọ́ mi. Gẹ́gẹ́ bí ahunṣọ mo ti ká ayé mi nílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni òun sì ti ké mi kúrò lára àṣà; ọ̀sán àti òru ni ìwọ ṣe òpin mi.
13 J'ai attendu patiemment jusqu'au matin. Il brise tous mes os comme un lion. Du jour à la nuit, vous allez m'achever.
Èmi fi sùúrù dúró títí di àfẹ̀mọ́júmọ́, ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí kìnnìún ó ti fọ́ gbogbo egungun mi; ọ̀sán àti òru ni ìwọ fi ṣe òpin mi.
14 Je bavardais comme une hirondelle ou une grue. J'ai gémi comme une colombe. Mes yeux faiblissent en regardant vers le haut. Seigneur, je suis opprimé. Sois ma sécurité. »
Èmi dún gẹ́gẹ́ bí àkọ̀ tàbí alápáǹdẹ̀dẹ̀, èmi káàánú gẹ́gẹ́ bí aṣọ̀fọ̀ àdàbà. Ojú mi rẹ̀wẹ̀sì gẹ́gẹ́ bí mo ti ń wo àwọn ọ̀run. Ìdààmú bá mi, Ìwọ Olúwa, wá fún ìrànlọ́wọ́ mi!”
15 Que vais-je dire? Il m'a à la fois parlé, et l'a fait lui-même. Je marcherai prudemment toutes mes années à cause de l'angoisse de mon âme.
Ṣùgbọ́n kí ni èmi lè sọ? Òun ti bá mi sọ̀rọ̀ àti pé òun tìkára rẹ̀ ló ti ṣe èyí. Èmi yóò máa rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ mi nítorí ìpọ́njú ẹ̀mí mi yìí.
16 Seigneur, les hommes vivent par ces choses; et mon esprit trouve la vie dans chacun d'eux. Tu me rétablis et me fais vivre.
Olúwa, nípa nǹkan báwọ̀nyí ni àwọn ènìyàn ń gbé; àti pé ẹ̀mí mi rí iyè nínú wọn pẹ̀lú. Ìwọ dá ìlera mi padà kí o sì jẹ́ kí n wà láààyè.
17 Voici, pour la paix, j'ai eu de grandes angoisses, mais tu as, par amour pour mon âme, délivré celle-ci de la fosse de la corruption; car tu as rejeté tous mes péchés derrière ton dos.
Nítòótọ́ fún àlàáfíà ara mi ni, ní ti pé mo ní ìkorò ńlá. Nínú ìfẹ́ rẹ ìwọ pa mí mọ́, kúrò nínú ọ̀gbun ìparun; ìwọ sì ti fi gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ẹ̀yìn rẹ.
18 Car le séjour des morts ne peut te louer. La mort ne peut pas te célébrer. Ceux qui descendent dans la fosse ne peuvent espérer votre vérité. (Sheol )
Nítorí pé isà òkú kò le è yìn ọ́, ipò òkú kò le è kọ orin ìyìn rẹ; àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ sínú ọ̀gbun kò lè ní ìrètí fún òtítọ́ rẹ. (Sheol )
19 Le vivant, le vivant, il te louera, comme je le fais aujourd'hui. Le père fera connaître ta vérité aux enfants.
Alààyè, àwọn alààyè wọ́n ń yìn ọ́, gẹ́gẹ́ bí èmi ti ń ṣe lónìí; àwọn baba sọ fún àwọn ọmọ wọn nípa òtítọ́ rẹ.
20 L'Éternel me sauvera. C'est pourquoi nous chanterons mes chansons avec des instruments à cordes tous les jours de notre vie dans la maison de Yahvé.
Olúwa yóò gbà mí là bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò sì kọrin pẹ̀lú ohun èlò olókùn ní gbogbo ọjọ́ ayé wa nínú tẹmpili ti Olúwa.
21 Or Ésaïe avait dit: « Qu'on prenne un gâteau de figues, qu'on le pose en cataplasme sur l'ulcère, et il guérira. »
Isaiah ti sọ pé, “Pèsè ìṣù ọ̀pọ̀tọ́ (ohun gbígbóná tí a dì mọ́ ojú egbò) kí o sì fi sí ojú oówo náà, òun yóò sì gbádùn.”
22 Ézéchias aussi avait dit: « Quel est le signe que je monterai à la maison de l'Éternel? »
Hesekiah sì béèrè pé, “Kí ni yóò jẹ́ àmì pé èmi yóò gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa?”