< Genèse 42 >
1 Jacob vit qu'il y avait du blé en Égypte, et il dit à ses fils: « Pourquoi vous regardez-vous les uns les autres? »
Nígbà tí Jakọbu mọ̀ pé ọkà wà ní Ejibiti, ó wí fún àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin pé, “Èéṣe tí ẹ ń wo ara yín lásán?”
2 Il répondit: « Voici, j'ai appris qu'il y a du blé en Égypte. Descendez-y et achetez-en pour nous, afin que nous vivions et que nous ne mourions pas. »
“Mo tí gbọ́ pé ọkà wà ní ilẹ̀ Ejibiti. Ẹ sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibẹ̀ kí ẹ sì rà wá fún wa, kí a má ba à kú.”
3 Les dix frères de Joseph descendirent pour acheter du blé en Égypte.
Nígbà náà ni mẹ́wàá nínú àwọn arákùnrin Josẹfu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Ejibiti láti ra ọkà.
4 Mais Jacob n'envoya pas Benjamin, le frère de Joseph, avec ses frères, car il dit: « De peur qu'il ne lui arrive du mal. »
Ṣùgbọ́n Jakọbu kò rán Benjamini àbúrò Josẹfu lọ pẹ̀lú wọn nítorí ẹ̀rù ń bà á kí aburú má ba à ṣẹlẹ̀ sí i.
5 Les fils d'Israël vinrent acheter parmi ceux qui étaient venus, car la famine sévissait au pays de Canaan.
Nítorí náà, àwọn ọmọ Israẹli wà lára àwọn tó lọ Ejibiti lọ ra oúnjẹ nítorí ìyàn náà mú ni ilẹ̀ Kenaani pẹ̀lú.
6 Joseph était le gouverneur du pays. C'est lui qui vendit à tous les habitants du pays. Les frères de Joseph vinrent, et ils se prosternèrent devant lui, le visage contre terre.
Nísinsin yìí, Josẹfu ni alábojútó fún gbogbo ilẹ̀ Ejibiti, òun sì ni ó ń bojútó ọkà títà fún gbogbo ènìyàn ìlú náà. Nítorí náà nígbà tí àwọn arákùnrin Josẹfu dé, wọ́n tẹríba, wọ́n sì foríbalẹ̀ fún Josẹfu.
7 Joseph vit ses frères et les reconnut, mais il se comporta comme un étranger avec eux et leur parla durement. Il leur dit: « D'où venez-vous? » Ils ont dit: « Du pays de Canaan, pour acheter de la nourriture. »
Lọ́gán tí Josẹfu ti rí àwọn arákùnrin rẹ̀ ni ó ti dá wọn mọ̀, ṣùgbọ́n ó ṣe bí i wí pé kò mọ̀ wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ líle sí wọn. Ó béèrè pé, “Níbo ni ẹ ti wá?” Wọ́n sì dáhùn pé, “Láti ilẹ̀ Kenaani ni a ti wá ra oúnjẹ.”
8 Joseph reconnut ses frères, mais ils ne le reconnurent pas.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, Josẹfu mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, síbẹ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kò mọ̀ ọ́n.
9 Joseph se souvint des rêves qu'il avait eus à leur sujet, et il leur dit: « Vous êtes des espions! Vous êtes venus voir la nudité du pays. »
Nígbà náà ni ó rántí àlá rẹ̀ tí ó lá sí wọn, ó sì wí fún wọn pé, “Amí ni yín, ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
10 Ils lui dirent: « Non, mon seigneur, mais tes serviteurs sont venus pour acheter de la nourriture.
Wọ́n dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́ olúwa wa, àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá láti ra oúnjẹ ni.
11 Nous sommes tous fils d'un seul homme, nous sommes des hommes honnêtes. Tes serviteurs ne sont pas des espions. »
Ọmọ baba ni wá, olóòtítọ́ ènìyàn sì ni wá pẹ̀lú, àwa kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.”
12 Il leur dit: « Non, mais vous êtes venus pour voir la nudité du pays! »
Ó wí fún wọn pé, “Rárá! Ẹ wá láti wo àṣírí ilẹ̀ wa ni.”
13 Ils dirent: « Nous, tes serviteurs, sommes douze frères, fils d'un seul homme au pays de Canaan; et voici que le plus jeune est aujourd'hui avec notre père, et l'autre n'est plus. »
Ṣùgbọ́n wọ́n tún dáhùn pé, “Arákùnrin méjìlá ni àwa ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ baba kan náà, tí ó ń gbé ní ilẹ̀ Kenaani. Èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wa ń bẹ lọ́dọ̀ baba wa, ọ̀kan sì ti kú.”
14 Joseph leur dit: « C'est comme je vous l'ai dit, en disant: « Vous êtes des espions ».
Josẹfu wí fún wọn pé, “Bí mo ti wí fún un yín náà ni, Ayọ́lẹ̀wò ni yín!
15 Par ceci, vous serez mis à l'épreuve. Par la vie de Pharaon, vous ne sortirez pas d'ici, à moins que votre plus jeune frère ne vienne ici.
Èyí sì ni a ó fi dán an yín wò, èmi búra pé, níwọ̀n ìgbà tí Farao bá wà láààyè, ẹ kì yóò kúrò níbí, àyàfi bí arákùnrin yín kan tókù bá wá sí ibí.
16 Envoie l'un d'entre vous, qu'il aille chercher ton frère, et tu seras lié, afin que tes paroles soient mises à l'épreuve et qu'on sache s'il y a de la vérité en toi, ou si, par la vie de Pharaon, tu es un espion. »
Ẹ rán ọ̀kan nínú yín lọ láti mú arákùnrin yín wá, àwa yóò fi ẹ̀yin tókù pamọ́ sínú túbú, kí àwa ba à lè mọ bóyá òtítọ́ ni ẹ̀yin ń wí. Ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ pé irọ́ ni ẹ̀yin ń pa, ní òtítọ́ bí Farao ti ń bẹ láààyè ayọ́lẹ̀wò ni yín!”
17 Il les mit tous ensemble en détention pendant trois jours.
Ó sì fi gbogbo wọn sínú túbú fún ọjọ́ mẹ́ta.
18 Le troisième jour, Joseph leur dit: « Faites cela, et vivez, car je crains Dieu.
Ní ọjọ́ kẹta, Josẹfu wí fún wọn pé, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe kí ẹ̀yin ba à le yè nítorí mo bẹ̀rù Ọlọ́run.
19 Si vous êtes des hommes honnêtes, laissez donc l'un de vos frères être lié dans votre prison; mais vous, partez, portez du blé pour la famine de vos maisons.
Tí ó bá jẹ́ pé olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ jẹ́ kí ọ̀kan nínú yín dúró ni túbú ní ìhín, nígbà tí àwọn yòókù yín yóò gbé ọkà lọ fún àwọn ará ilé e yín tí ebi ń pa.
20 Amenez-moi votre plus jeune frère; ainsi vos paroles seront vérifiées, et vous ne mourrez pas. » Ils firent ainsi.
Ṣùgbọ́n ẹ gbọdọ̀ mú arákùnrin tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn yín wá, kí n ba à le mọ òtítọ́ ohun ti ẹ ń wí, kí ẹ má ba à kú.” Wọn sì gbà láti ṣe èyí.
21 Ils se dirent les uns aux autres: « Nous sommes certainement coupables à l'égard de notre frère, en ce que nous avons vu la détresse de son âme, lorsqu'il nous suppliait, et que nous n'avons pas voulu l'écouter. C'est pourquoi cette détresse est venue sur nous. »
Wọ́n ń sọ ọ́ láàrín ara wọn wí pé, “Àwa jẹ̀bi nítòótọ́ nípa ti arákùnrin wa. A rí ìbànújẹ́ ọkàn rẹ̀ nígbà tí ó ń bẹ̀ wá nítorí ẹ̀mí rẹ̀, ṣùgbọ́n a kò gbẹ́bẹ̀, nítorí náà ni ìdààmú yìí fi dé bá wa.”
22 Ruben leur répondit: « Ne vous ai-je pas dit: « Ne péchez pas contre l'enfant », et n'avez-vous pas voulu écouter? C'est pourquoi aussi, voici, son sang est requis. »
Reubeni dá wọn ní ohùn pé, “Èmi kò wí fún yín pé kí ẹ má se ṣẹ̀ sí ọmọdékùnrin náà? Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọ́! Ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ń béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ wa.”
23 Ils ne savaient pas que Joseph les comprenait, car il y avait un interprète entre eux.
Wọn kò sì mọ̀ pé, Josẹfu ń gbọ́ wọn ní àgbọ́yé nítorí ògbufọ̀ ni ó ń lò tẹ́lẹ̀.
24 Il se détourna d`eux, et pleura. Puis il revint vers eux, leur parla, prit Siméon du milieu d'eux et le lia sous leurs yeux.
Ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún. Ó sì tún yí padà sí wọn, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ̀rọ̀. Ó mú Simeoni kúrò láàrín wọn, ó sì dè é ní ojú wọn.
25 Puis Joseph donna l'ordre de remplir leurs sacs de blé, de remettre l'argent de chacun dans son sac, et de leur donner de la nourriture pour le chemin. C'est ainsi qu'il leur fut fait.
Josẹfu pàṣẹ pé kí wọn bu ọkà kún inú àpò wọn, kí wọn sì mú owó ẹnìkọ̀ọ̀kan padà sínú àpò rẹ̀, kí wọn sì fún wọn ní ohun tí wọn yóò lò nírín-àjò wọn padà sílé. Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe èyí fún wọn,
26 Ils chargèrent leurs ânes de leur grain, et partirent de là.
wọn gbé ẹrù wọn lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, wọn sì padà lọ sí ilé.
27 Comme l'un d'eux ouvrait son sac pour donner à manger à son âne dans le lieu d'hébergement, il vit son argent. Voici, il était dans l'ouverture de son sac.
Níbi tí wọ́n ti dúró láti sùn lóru ọjọ́ náà, ọ̀kan nínú wọn tú àpò rẹ̀ láti mú oúnjẹ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, ó sì rí owó rẹ̀ ní ẹnu àpò rẹ̀.
28 Il dit à ses frères: « Mon argent a été retrouvé! Voici qu'il est dans mon sac. » Leur cœur les abandonna, et ils se tournèrent en tremblant les uns vers les autres, en disant: « Qu'est-ce que Dieu nous a fait? »
Ó sì wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “a ti dá owó mi padà, òun nìyí ní ẹnu àpò mi.” Ẹ̀rù bà wọ́n, wọ́n sì ń gbọ̀n, wọ́n sì wí pé, “Èwo nìyí tí Ọlọ́run ṣe sí wa yìí.”
29 Ils se rendirent auprès de Jacob, leur père, au pays de Canaan, et lui racontèrent tout ce qui leur était arrivé, en disant:
Nígbà tí wọ́n padà dé ọ̀dọ̀ Jakọbu baba wọn ní ilẹ̀ Kenaani, wọ́n ròyìn gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún un wí pé,
30 « Cet homme, le seigneur du pays, nous a parlé durement et nous a pris pour des espions du pays.
“Ọkùnrin náà tí í ṣe alábojútó ilẹ̀ náà, sọ̀rọ̀ líle sí wa, ó sì fi ẹ̀sùn kàn wá pé a wá yọ́ ilẹ̀ náà wò ni.
31 Nous lui avons répondu: « Nous sommes d'honnêtes hommes. Nous ne sommes point des espions.
Ṣùgbọ́n, a wí fún un pé, ‘Rárá o, olóòtítọ́ ènìyàn ni wá, a kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò.
32 Nous sommes douze frères, fils de notre père; l'un d'eux n'est plus, et le plus jeune est aujourd'hui avec notre père au pays de Canaan.
Arákùnrin méjìlá ni wá, ọmọ baba kan náà, ọ̀kan ti kú, èyí tí ó jẹ́ àbíkẹ́yìn wà lọ́dọ̀ baba wa ni ilẹ̀ Kenaani.’
33 L'homme, le seigneur du pays, nous dit: « Voici comment je saurai que vous êtes des hommes honnêtes: laissez-moi l'un de vos frères, prenez du blé pour la famine de vos maisons, et partez.
“Nígbà náà ni ọkùnrin tí ó jẹ́ alábojútó ilẹ̀ náà wí fún wa pé, ‘Báyìí ni n ó ṣe mọ̀ bóyá olóòtítọ́ ènìyàn ni yín, ẹ fi ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ níbí, pẹ̀lú mi, ẹ sì mú oúnjẹ lọ fún àwọn ará ilé yín tí ebi ń pa kú lọ, lọ́wọ́ ìyàn.
34 Amenez-moi votre plus jeune frère. Je saurai alors que vous n'êtes pas des espions, mais que vous êtes des hommes honnêtes. Je vous livrerai donc votre frère, et vous ferez du commerce dans le pays.'"
Ṣùgbọ́n ẹ mú arákùnrin yín tí ó kéré jùlọ wá fún mi kí n le mọ̀ pé dájúdájú ẹ kì í ṣe ayọ́lẹ̀wò bí kò ṣe ènìyàn tòótọ́. Nígbà náà ni n ó mú arákùnrin yín padà fún un yín, lẹ́yìn náà ẹ le máa wá ṣe òwò bí ó ti wù yín ní ilẹ̀ yìí.’”
35 Comme ils vidaient leurs sacs, voici que chacun avait dans son sac son paquet d'argent. Lorsqu'ils virent leurs liasses d'argent, eux et leur père eurent peur.
Bí wọ́n sì ti ń tú àpò ẹrù wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan bá owó tí ó san fún ọjà náà lẹ́nu àpò rẹ̀! Ẹ̀rù sì bà wọ́n gidigidi, àwọn àti baba wọn.
36 Jacob, leur père, leur dit: « Vous m'avez privé de mes enfants! Joseph n'est plus, Siméon n'est plus, et vous voulez m'enlever Benjamin. Toutes ces choses sont contre moi. »
Jakọbu baba wọn wí fún wọn pé, “Ẹ ti mú mi pàdánù àwọn ọmọ mi. N kò rí Josẹfu mọ́, bẹ́ẹ̀ ni n kò sì rí Simeoni náà mọ. Ẹ sì tún fẹ́ mú Benjamini lọ. Èmi ni gbogbo ohun búburú yìí wá ń ṣẹlẹ̀ sí!”
37 Ruben parla à son père et dit: « Tue mes deux fils, si je ne te le ramène pas. Confie-le à mes soins, et je te le ramènerai. »
Nígbà náà ni Reubeni wí fún baba rẹ̀ pé, “Pa àwọn ọmọ mi méjèèjì bí n kò bá mú Benjamini padà wá fún ọ, èmi ni kí o fà á lé lọ́wọ́, n ó sì mu un padà wá.”
38 Il dit: « Mon fils ne descendra pas avec toi, car son frère est mort et il ne reste que lui. S'il lui arrive malheur sur le chemin que vous empruntez, vous ferez descendre mes cheveux blancs avec tristesse au séjour des morts. » (Sheol )
Ṣùgbọ́n Jakọbu wí pé, “Ọmọ mi kì yóò bá a yín lọ, ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ti kú, òun nìkan sì ni ó kù nínú àwọn ọmọ ìyá rẹ̀. Bí ohunkóhun bá ṣẹlẹ̀ sí i, ìbànújẹ́ ni yóò sì pa mi kú ni ọjọ́ ogbó mi yìí.” (Sheol )