< Esdras 9 >

1 Lorsque ces choses se passèrent, les princes s'approchèrent de moi et dirent: « Le peuple d'Israël, les prêtres et les lévites ne se sont pas séparés des peuples du pays, en suivant leurs abominations, celles des Cananéens, des Héthiens, des Phéréziens, des Jébusiens, des Ammonites, des Moabites, des Égyptiens et des Amoréens.
Lẹ́yìn ìgbà tí a ti ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí tán, àwọn olórí tọ̀ mí wá, wọ́n sì wí pé, “Àwọn ènìyàn Israẹli, tí ó fi mọ́ àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, kò tì í ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò láàrín àwọn ènìyàn agbègbè tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra bí i ti àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti, àwọn ará Peresi, àwọn ará Jebusi, àwọn ará Ammoni, àwọn ará Moabu, àwọn ará Ejibiti àti ti àwọn ará Amori.
2 Car ils ont pris de leurs filles pour eux et pour leurs fils, de sorte que leur progéniture sainte s'est mêlée aux peuples des pays. Oui, la main des princes et des gouvernants a été la principale responsable de cette infamie. »
Wọ́n ti fẹ́ lára àwọn ọmọbìnrin wọn fún ara wọn àti fún àwọn ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí aya, wọ́n ti da irú-ọmọ ìran mímọ́ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn ti ó wà ní àyíká wọn. Àwọn olórí àti àwọn ìjòyè ta àwọn ènìyàn tókù yọ nínú híhu ìwà àìṣòótọ́.”
3 Lorsque j'entendis cela, je déchirai mon vêtement et ma robe, j'arrachai les cheveux de ma tête et de ma barbe, et je m'assis confus.
Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo tu irun orí àti irùngbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìjayà.
4 Alors tous ceux qui tremblaient devant les paroles du Dieu d'Israël s'assemblèrent auprès de moi, à cause de la faute des exilés; et je restai assis, confus, jusqu'à l'offrande du soir.
Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó wárìrì sí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Israẹli kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìṣòótọ́ àwọn ìgbèkùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìjayà títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́.
5 A l'offrande du soir, je me suis relevé de mon humiliation, avec mon vêtement et ma robe déchirés; je suis tombé à genoux, et j'ai étendu les mains vers Yahvé, mon Dieu;
Ní ìgbà tí ó di àkókò ìrúbọ àṣálẹ́, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
6 et j'ai dit: « Mon Dieu, j'ai honte et je rougis de lever ma face vers toi, mon Dieu, car nos iniquités se sont multipliées au-dessus de notre tête, et notre culpabilité s'est élevée jusqu'aux cieux.
Mo sì gbàdúrà: “Ojú tì mí gidigidi, tí n kò fi lè gbé ojú mi sókè sí ọ̀dọ̀ rẹ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá di púpọ̀ ní orí wa, ẹ̀bi wa sì ga kan àwọn ọ̀run.
7 Depuis les jours de nos pères, nous avons été extrêmement coupables jusqu'à ce jour; et à cause de nos iniquités, nous, nos rois et nos prêtres, nous avons été livrés entre les mains des rois des pays, à l'épée, à la captivité, au pillage et à la confusion de visage, comme cela se passe aujourd'hui.
Láti ọjọ́ àwọn baba wá ni ẹ̀bi wa ti pọ̀ jọjọ títí di ìsinsin yìí. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wa, àwa àti àwọn ọba wa àti àwọn àlùfáà wa ni a ti sọ di ẹni idà, ẹni ìgbèkùn, ìkógun àti ẹni ẹ̀sín lọ́wọ́ àwọn àjèjì ọba, bí ó ti rí lónìí.
8 Or, pour un peu de temps, l'Éternel, notre Dieu, a fait grâce de nous laisser un reste pour nous échapper, et de nous donner un pieu dans son sanctuaire, afin que notre Dieu éclaire nos yeux, et qu'il nous ranime un peu dans notre servitude.
“Ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí, fún ìgbà díẹ̀, ni a ti fi oore-ọ̀fẹ́ fún wa láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa wá láti sálà, àti láti fi èèkàn fún wa ni ibi mímọ́ rẹ̀, nítorí kí Ọlọ́run kí ó lè mú ojú wa mọ́lẹ̀, kí ó sì tún wa gbé dìde díẹ̀ kúrò nínú ìgbèkùn wa.
9 Car nous sommes des esclaves; mais notre Dieu ne nous a pas abandonnés dans notre servitude, et il nous a témoigné de la bonté aux yeux des rois de Perse, pour nous faire revivre, pour relever la maison de notre Dieu, pour en réparer les ruines, et pour nous donner une muraille en Juda et à Jérusalem.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwa jẹ́ ẹrú, Ọlọ́run wa kò fi wa sílẹ̀ nínú ìgbèkùn wa. Ó ti fi àánú hàn fún wa ni iwájú àwọn ọba Persia: Ó ti fún wa ní ìgbé ayé tuntun láti tún odi ilé Ọlọ́run wa mọ, kí a sì tún àwókù rẹ̀ ṣe, ó sì fi odi ààbò fún wa ní Juda àti ní Jerusalẹmu.
10 « Maintenant, notre Dieu, que dirons-nous après cela? Car nous avons abandonné tes commandements,
“Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, kí ni àwa yóò wí lẹ́yìn èyí? Nítorí tí àwa kọ àṣẹ rẹ sílẹ̀
11 que tu as prescrits par tes serviteurs les prophètes, en disant: Le pays dont vous allez prendre possession est un pays souillé par la souillure des peuples de ce pays, par leurs abominations, qui l'ont rempli d'un bout à l'autre de leurs souillures.
èyí tí ìwọ ti pa fún wa láti ẹnu àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, nígbà ti ìwọ wí pé, ‘Ilẹ̀ náà ti ẹ̀yin ń wọ̀ lọ láti gbà n nì jẹ́ ilẹ̀ aláìmọ́ tó kún fún ẹ̀gbin àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, nípa ṣíṣe ohun ìríra àti híhu ìwà èérí ti kún ún láti ìkángun kan dé èkejì.
12 Maintenant, ne donnez pas vos filles à leurs fils. Ne prenez pas leurs filles pour vos fils, et ne recherchez pas leur paix ou leur prospérité pour toujours, afin d'être forts et de manger les biens du pays, et de le laisser en héritage à vos enfants pour toujours.''
Nítorí náà, ẹ má ṣe fi àwọn ọmọbìnrin yín fún àwọn ọmọkùnrin wọn ní ìyàwó tàbí kí ẹ fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn fún àwọn ọmọkùnrin yín ní ìyàwó. Ẹ má ṣe dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn nígbàkígbà kí ẹ̀yin kí ó sì le lágbára, kí ẹ sì le máa jẹ ire ilẹ̀ náà, kí ẹ sì le fi í sílẹ̀ fún àwọn ọmọ yín gẹ́gẹ́ bí ogún ayérayé.’
13 « Après tout ce qui nous est arrivé à cause de nos mauvaises actions et de notre grande culpabilité, puisque toi, notre Dieu, tu nous as punis moins que ne le méritaient nos iniquités, et que tu nous as donné un tel reste,
“Ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa jẹ́ àyọríṣí iṣẹ́ búburú wa àti ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ńlá wa, síbẹ̀, Ọlọ́run wa, ìjìyà ti ìwọ fún wa kéré si ìjìyà tí ó yẹ fún ẹ̀ṣẹ̀ ti a dá, ìwọ sì fún wa ní àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù bí èyí.
14 violerons-nous encore tes commandements, et nous associerons-nous aux peuples qui commettent ces abominations? Ne seras-tu pas irrité contre nous jusqu'à ce que tu nous aies consumés, de sorte qu'il n'y ait plus de reste, ni d'échappatoire?
Ǹjẹ́ ó yẹ kí àwa tún yẹ̀ kúrò nínú àṣẹ rẹ, kí a sì máa ṣe ìgbéyàwó papọ̀ pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí wọn ti ṣe onírúurú ohun ìríra báyìí? Ṣe ìwọ kò ní bínú sí wa láti pa wá run tí kì yóò sẹ́ ku ẹnikẹ́ni tí yóò là?
15 Yahvé, le Dieu d'Israël, tu es juste, car il nous reste un reste qui s'est échappé, comme c'est le cas aujourd'hui. Voici, nous sommes devant toi dans notre culpabilité, car personne ne peut se tenir devant toi à cause de cela. »
Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ìwọ jẹ́ olódodo! Àwa ìgbèkùn tí ó ṣẹ́kù bí ó ti rí lónìí. Àwa dúró níwájú rẹ nínú ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ wa, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé nítorí èyí ẹnikẹ́ni nínú wa kò lè dúró níwájú rẹ”.

< Esdras 9 >