< Esdras 7 >
1 Après ces choses, sous le règne d'Artaxerxès, roi de Perse, Esdras, fils de Seraja, fils d'Azaria, fils de Hilkija,
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
2 fils de Schallum, fils de Tsadok, fils d'Ahitub,
ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
3 fils d'Amaria, fils d'Azaria, fils de Meraïoth,
ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
4 fils de Zérachia, fils d'Uzzi, fils de Bukki,
ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
5 fils d'Abischua, fils de Phinées, fils d'Éléazar, fils d'Aaron, le grand prêtre,
ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
6 cet Esdras monta de Babylone. Il était un scribe habile dans la loi de Moïse, que Yahvé, le Dieu d'Israël, avait donnée; et le roi lui accorda tout ce qu'il demandait, selon la main de Yahvé, son Dieu, sur lui.
Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
7 Quelques-uns des enfants d'Israël, dont une partie des prêtres, des lévites, des chantres, des portiers et des serviteurs du temple, montèrent à Jérusalem la septième année du roi Artaxerxès.
Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
8 Il arriva à Jérusalem au cinquième mois, c'est-à-dire la septième année du roi.
Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
9 En effet, le premier jour du premier mois, il commença à monter de Babylone, et le premier jour du cinquième mois, il arriva à Jérusalem, selon la bonne main de son Dieu sur lui.
Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
10 Car Esdras avait mis son cœur à rechercher la loi de Yahvé et à la mettre en pratique, et à enseigner les lois et les ordonnances en Israël.
Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
11 Et voici la copie de la lettre que le roi Artaxerxès donna au sacrificateur Esdras, le scribe, le rédacteur des paroles des commandements de l'Éternel et de ses statuts pour Israël:
Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
12 Artaxerxès, roi des rois, A Esdras le prêtre, le scribe de la loi du Dieu parfait du ciel. Or,
Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
13 je décrète que tous ceux du peuple d'Israël, de ses prêtres et des lévites qui se trouvent dans mon royaume et qui ont l'intention de se rendre à Jérusalem de leur plein gré, iront avec vous.
Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
14 Car tu es envoyé par le roi et ses sept conseillers pour enquêter sur Juda et Jérusalem, selon la loi de ton Dieu qui est entre tes mains,
Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
15 et pour porter l'argent et l'or que le roi et ses conseillers ont offert librement au Dieu d'Israël, dont la demeure est à Jérusalem,
Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
16 et tout l'argent et l'or que tu trouveras dans toute la province de Babylone, avec les offrandes volontaires du peuple et des prêtres pour la maison de leur Dieu qui est à Jérusalem.
pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
17 Tu achèteras avec cet argent des taureaux, des béliers et des agneaux, avec leurs offrandes et leurs libations, et tu les offriras sur l'autel de la maison de ton Dieu qui est à Jérusalem.
Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
18 Tout ce que vous et vos frères jugerez bon de faire avec le reste de l'argent et de l'or, faites-le selon la volonté de votre Dieu.
Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
19 Les objets qui vous seront donnés pour le service de la maison de votre Dieu, livrez-les devant le Dieu de Jérusalem.
Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
20 Tout ce qui sera nécessaire pour la maison de ton Dieu et que tu auras l'occasion de donner, donne-le de la maison du trésor du roi.
Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
21 Moi, le roi Artaxerxès, j'ordonne à tous les trésoriers qui sont de l'autre côté du fleuve que tout ce que le prêtre Esdras, le scribe de la loi du Dieu des cieux, vous demandera, vous le ferez avec toute la diligence voulue,
Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
22 jusqu'à cent talents d'argent, cent cors de froment, cent baths de vin, cent baths d'huile, et du sel, sans qu'il soit nécessaire d'en indiquer la quantité.
tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
23 Tout ce qui est ordonné par le Dieu des cieux, que cela soit fait exactement pour la maison du Dieu des cieux; car pourquoi y aurait-il de la colère contre le royaume du roi et de ses fils?
Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
24 Nous vous informons également qu'il ne sera pas permis d'imposer un tribut, une coutume ou un péage aux prêtres, aux lévites, aux chantres, aux gardiens des portes, aux employés du temple ou aux ouvriers de cette maison de Dieu.
Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
25 Toi, Esdras, selon la sagesse de ton Dieu qui est dans ta main, nomme des magistrats et des juges qui puissent juger tout le peuple qui est au-delà du fleuve, qui tous connaissent les lois de ton Dieu, et instruire celui qui ne les connaît pas.
Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
26 Si quelqu'un ne se conforme pas à la loi de ton Dieu et à la loi du roi, que le jugement soit exécuté sur lui avec toute la diligence voulue, que ce soit la mort, le bannissement, la confiscation des biens ou la prison.
Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
27 Béni soit Yahvé, le Dieu de nos pères, qui a mis une telle chose dans le cœur du roi, pour embellir la maison de Yahvé qui est à Jérusalem;
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
28 et qui m'a accordé sa bienveillance devant le roi et ses conseillers, et devant tous les princes puissants du roi. J'ai été fortifié selon la main de Yahvé mon Dieu sur moi, et j'ai rassemblé des chefs d'Israël pour monter avec moi.
Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.