< Ézéchiel 32 >

1 La douzième année, au douzième mois, le premier jour du mois, la parole de Yahvé me fut adressée, en ces termes:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 « Fils d'homme, élève une complainte sur Pharaon, roi d'Égypte, et dis-lui, « Tu as été comparé à un jeune lion des nations; mais vous êtes comme un monstre dans les mers. Tu t'es échappé avec tes rivières, et tu as agité les eaux avec tes pieds, et ont souillé leurs rivières. »
“Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Farao ọba Ejibiti kí o sì wí fún un: “‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà; ìwọ dàbí ohun ẹ̀mí búburú inú àwọn omi okun to ń lọ káàkiri inú àwọn odò rẹ, ìwọ fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ omi láti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.
3 Le Seigneur Yahvé dit: « J'étendrai mon filet sur toi avec une compagnie de peuples nombreux. Ils vous feront monter dans mon filet.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyàn èmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́ wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.
4 Je vous laisserai sur la terre. Je vous jetterai en plein champ, et fera en sorte que tous les oiseaux du ciel se posent sur toi. Je rassasierai de toi les animaux de toute la terre.
Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀ èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba. Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ní orí rẹ. Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fi ìwọra gbé ara wọn lórí rẹ.
5 Je déposerai ta chair sur les montagnes, et remplissez les vallées de votre hauteur.
Èmi yóò tan ẹran-ara rẹ ká sórí àwọn òkè gíga ìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kún àwọn àárín àwọn òkè gíga.
6 J'arroserai aussi de votre sang le pays dans lequel vous vous baignez, même dans les montagnes. Les cours d'eau seront pleins de vous.
Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń sàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náà gbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga, àwọn àlàfo jíjìn ní wọn yóò kún fún ẹran-ara rẹ.
7 Quand je t'éteindrai, je couvrirai les cieux. et rend ses étoiles sombres. Je couvrirai le soleil d'un nuage, et la lune ne donnera pas sa lumière.
Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn; èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
8 Je ferai s'obscurcir sur toi tous les luminaires du ciel, et mettre les ténèbres sur ton pays, dit le Seigneur Yahvé.
Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀run ni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ; èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ̀ rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 « Je vais aussi troubler le cœur de nombreux peuples, quand je vous détruirai parmi les nations, dans les pays que vous n'avez pas connus.
Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rú nígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wá ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò í tí ì mọ̀.
10 Oui, je ferai en sorte que beaucoup de peuples s'étonnent de toi, et leurs rois auront une peur bleue de toi, quand je brandirai mon épée devant eux. Ils trembleront à chaque instant, chaque homme pour sa propre vie, au jour de ta chute. »
Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rùbà ọ́, àwọn ọba wọn yóò sì wárìrì fún ìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ, nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọn. Ní ọjọ́ ìṣubú rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrì ní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.
11 Car le Seigneur Yahvé dit: « L'épée du roi de Babylone viendra sur toi.
“‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Idà ọba Babeli yóò wá sí orí rẹ,
12 Je ferai tomber ta multitude par les épées des puissants. Ce sont tous les impitoyables des nations. Ils réduiront à néant l'orgueil de l'Égypte, et toute sa multitude sera détruite.
Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ó tí ipa idà àwọn alágbára ènìyàn ṣubú àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú jùlọ. Wọn yóò tú ìgbéraga Ejibiti ká, gbogbo ìjọ rẹ ní a yóò dá ojú wọn bolẹ̀.
13 Je détruirai aussi tous ses animaux à côté des grandes eaux. Le pied de l'homme ne les troublera plus, et les sabots des animaux ne les dérangeront pas.
Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóò parun ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀ ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni ẹrọ̀fọ̀.
14 Alors je rendrai leurs eaux limpides, et faire couler leurs rivières comme de l'huile, » dit le Seigneur Yahvé.
Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòrò kí àwọn odò rẹ̀ kí o sàn bí epo, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 « Quand je rendrai le pays d'Égypte désert et dévasté, une terre dépourvue de ce dont elle était pleine, quand je frapperai tous ceux qui y habitent, alors ils sauront que je suis Yahvé.
Nígbà tí mo bá sọ Ejibiti di ahoro, tí mo sì kó gbogbo ohun tí ó wà ní orí ilẹ̀ náà kúrò. Nígbà tí mo bá gé àwọn olùgbé ibẹ̀ lulẹ̀, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
16 "''C'est la complainte avec laquelle ils se lamenteront. C'est avec elle que les filles des nations se lamenteront. Elles se lamenteront avec elle sur l'Égypte et sur toute sa multitude, dit le Seigneur Yahvé.''"
“Èyí yìí ni ẹkún tí a yóò sun fún un. Àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè yóò sun ún; nítorí Ejibiti àti gbogbo ìjọ rẹ, wọn yóò sun ún, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
17 La douzième année, le quinzième jour du mois, la parole de l'Éternel me fut adressée, en ces mots:
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mí wá:
18 Fils d'homme, pleure sur la multitude de l'Égypte, et précipite-la, elle et les filles des nations célèbres, dans les profondeurs de la terre, avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún lórí Ejibiti kí o sì ránṣẹ́ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ àti òun àti àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè alágbára, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ìsàlẹ̀, kòtò.
19 Devant qui passes-tu en beauté? Descends, et sois couchée avec les incirconcis.
Sọ fún wọn, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ní ojúrere jù àwọn tí o kù lọ? Lọ sí ìsàlẹ̀ kí a sì tẹ́ ọ sí àárín àwọn aláìkọlà náà.’
20 Ils tomberont parmi ceux qui sont tués par l'épée. Elle est livrée au glaive. Emporte-la avec toute sa multitude.
Wọn yóò ṣubú láàrín àwọn tí a fi idà pa. A fa idà yọ; jẹ́ kí a wọ́ Ejibiti kúrò pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀.
21 Le fort parmi les puissants lui parlera du milieu du séjour des morts, avec ceux qui le secourent. Ils sont descendus. Les incirconcis reposent, tués par l'épée. (Sheol h7585)
Láti inú isà òkú alágbára tí í ṣe aṣáájú yóò sọ nípa Ejibiti àti àwọn àlejò rẹ̀, ‘Wọn ti wá sí ìsàlẹ̀, wọn sì sùn pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.’ (Sheol h7585)
22 « Asshur est là avec toute sa troupe. Ses tombeaux sont tout autour d'elle. Ils sont tous morts, tombés par l'épée,
“Asiria wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo jagunjagun rẹ̀; àwọn isà òkú àwọn tí a ti pa sì yí i ká, gbogbo àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú.
23 leurs tombes sont placées dans les profondeurs de la fosse, et sa troupe est autour de sa tombe, tous morts, tombés par l'épée, qui semaient la terreur dans le pays des vivants.
Isà òkú wọn wà ní ibi tí ó jinlẹ̀ gan an nínú kòtò. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè ní a pa, tí ó ti ipa idà ṣubú.
24 « Voici Élam et toute sa multitude autour de son tombeau; tous ont été tués, sont tombés par l'épée, sont descendus incirconcis dans les profondeurs de la terre, ont semé la terreur dans le pays des vivants, et ont porté leur honte avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Elamu wà níbẹ̀, o yí isà òkú rẹ̀ ká pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀. Gbogbo wọn ni a pa, àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè lọ sí ìsàlẹ̀ láìkọlà sí abẹ́ ilẹ̀. Wọ́n gba ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
25 Ils ont fait d'Élam un lit parmi les morts, avec toute sa multitude. Ses sépulcres sont autour d'elle, tous incirconcis, tués par l'épée; car leur terreur a été causée dans le pays des vivants, et ils ont porté leur honte avec ceux qui descendent dans la fosse. Il est mis au nombre de ceux qui sont tués.
A ṣe ibùsùn fún un láàrín àwọn tí a pa, pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀ tí ó yí isà òkú ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, tí a fi idà pa. Nítorí pé a tan ẹ̀rù wọn ká ilẹ̀ alààyè, wọn ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò; a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a pa.
26 « Voilà Meshech, Tubal, et toute leur multitude. Leurs tombes les entourent, tous les incirconcis, tués par l'épée, car ils ont semé la terreur dans le pays des vivants.
“Meṣeki àti Tubali wà níbẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ogun wọn yí isà òkú wọn ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, wọ́n fi idà pa wọ́n nítorí ẹ̀rù tiwọn tàn ká ilẹ̀ alààyè.
27 Ils ne coucheront pas avec les puissants tombés parmi les incirconcis, qui sont descendus au séjour des morts avec leurs armes de guerre et qui ont mis leurs épées sous leurs têtes. Leurs iniquités sont sur leurs os, car ils étaient la terreur des puissants au pays des vivants. (Sheol h7585)
Wọn kì yóò sì dùbúlẹ̀ ti àwọn tí ó ṣubú nínú àwọn aláìkọlà, tí wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun wọn, wọ́n tí fi idà wọn rọ orí wọn. Ṣùgbọ́n àìṣedéédéé wọn yóò wà ní orí egungun wọn—bí wọ́n tilẹ̀ jẹ́ ẹ̀rù àwọn alágbára ní ilẹ̀ alààyè. (Sheol h7585)
28 « Mais tu seras brisé parmi les incirconcis, et tu coucheras avec ceux qui sont tués par l'épée.
“Ìwọ náà, Farao, ní yóò ṣẹ, ti yóò dùbúlẹ̀ láàrín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.
29 « Voici Édom, ses rois et tous ses princes, qui, dans leur puissance, sont couchés avec ceux qui sont tués par l'épée. Ils seront couchés avec les incirconcis, et avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Edomu wà níbẹ̀, àwọn ọba rẹ̀ àti gbogbo ọmọbìnrin ọba; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára, a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. Wọn dùbúlẹ̀ pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn ti o lọ sínú kòtò.
30 « Voilà les princes du nord, tous, et tous les Sidoniens, qui sont descendus avec les morts. Ils sont honteux de la terreur qu'ils ont causée par leur puissance. Ils gisent incirconcis avec ceux qui sont tués par l'épée, et ils portent leur honte avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Gbogbo àwọn ọmọ-aládé ilẹ̀ àríwá àti gbogbo àwọn ará Sidoni wà níbẹ̀; wọn lọ sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí a pa ní ìtìjú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ṣe okùnfà ẹ̀rù pẹ̀lú agbára wọn. Wọn sùn ní àìkọlà pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa, wọn sì ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
31 « Pharaon les verra et sera consolé de toute sa multitude, Pharaon et toute son armée, tués par l'épée », dit le Seigneur Yahvé.
“Farao, òun àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ yóò rí wọn, a yóò sì tù ú nínú nítorí gbogbo ogun rẹ̀ tí a fi idà pa, ní Olúwa Olódùmarè wí.
32 « Car j'ai mis sa terreur dans le pays des vivants. Il sera couché parmi les incirconcis, avec ceux qui sont tués par l'épée, Pharaon et toute sa multitude », dit le Seigneur Yahvé.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè, Farao àti gbogbo ogun rẹ̀ ni a yóò tẹ́ sí àárín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ézéchiel 32 >