< Ézéchiel 30 >

1 La parole de Yahvé me fut adressée de nouveau, en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá: wí pé:
2 « Fils d'homme, prophétise, et dis: « Le Seigneur Yahvé dit »: « Gémissez: « Hélas pour le jour!
“Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí o sì wí pé: ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Hu, kí o sì wí pé, “Ó ṣe fún ọjọ́ náà!”
3 Car le jour est proche, même le jour de Yahvé est proche. Ce sera une journée de nuages, un temps des nations.
Nítorí ọjọ́ náà súnmọ́ tòsí àní ọjọ́ Olúwa súnmọ́ tòsí, ọjọ́ tí ọjọ́ ìkùùkuu ṣú dúdú, àsìkò ìparun fún àwọn kèfèrí.
4 Une épée viendra sur l'Égypte, et l'angoisse sera en Ethiopie, quand les morts tombent en Égypte. Ils lui enlèvent sa multitude, et ses fondations sont brisées.
Idà yóò wá sórí Ejibiti ìrora ńlá yóò sì wá sórí Kuṣi. Nígbà tí àwọn tí a pa yóò ṣubú ní Ejibiti wọn yóò kò ọrọ̀ rẹ̀ lọ ìpìlẹ̀ rẹ̀ yóò sì wó lulẹ̀.
5 "« L'Éthiopie, Put, Lud, tous les peuples mélangés, Cub, et les enfants du pays qui leur est allié, tomberont avec eux par l'épée. »"
Kuṣi àti Puti, Libia, Ludi àti gbogbo Arabia, Kubu àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà tí ó mulẹ̀ yóò ṣubú nípa idà pẹ̀lú Ejibiti.
6 "'Yahvé dit: « Ceux qui soutiennent l'Égypte tomberont aussi. L'orgueil de sa puissance va tomber. Ils y tomberont par l'épée de la tour de Seveneh, » dit le Seigneur Yahvé.
“‘Èyí yìí ní Olúwa wí: “‘Àwọn àlejò Ejibiti yóò ṣubú agbára ìgbéraga rẹ yóò kùnà láti Migdoli títí dé Siene, wọn yóò ti ipa idà ṣubú nínú rẹ; ní Olúwa Olódùmarè wí.
7 « Ils seront désolés au milieu des pays désolés. Ses villes seront parmi les villes dévastées.
Wọn yóò sì wà lára àwọn ilẹ̀ tí ó di ahoro, ìlú rẹ yóò sì wà ní ara àwọn ìlú tí ó di ahoro.
8 Ils sauront que je suis Yahvé. quand j'aurai mis le feu à l'Égypte, et tous ses assistants sont détruits.
Lẹ́yìn náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá gbé iná kalẹ̀ ní Ejibiti tí gbogbo àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀ bá parun.
9 "''En ce jour-là, des messagers partiront de devant moi dans des navires pour faire peur aux Éthiopiens insouciants. Il y aura de l'angoisse sur eux, comme au jour de l'Égypte; car voici qu'elle arrive. »
“‘Ní ọjọ́ náà oníṣẹ́ yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde nínú ọkọ̀ ojú omi láti dẹ́rùbà Kuṣi tí ó wà nínú àlàáfíà. Ìrora yóò wá sórí wọn gẹ́gẹ́ bí ti ọjọ́ ìparun Ejibiti. Kíyèsi i, ó dé.
10 "'Le Seigneur Yahvé dit: « Je ferai aussi cesser la multitude de l'Égypte, par la main de Nebuchadnezzar, roi de Babylone.
“‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò mú òpin bá ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn Ejibiti láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli.
11 Lui et son peuple avec lui, le terrible des nations, seront amenés à détruire le pays. Ils tireront leurs épées contre l'Égypte, et remplir le pays de morts.
Òun àti àwọn ológun rẹ̀ ẹ̀rù àwọn orílẹ̀-èdè ní a o mú wá láti pa ilẹ̀ náà run. Wọn yóò fa idà wọn yọ sí Ejibiti ilẹ̀ náà yóò sì kún fún àwọn tí a pa.
12 Je mettrai les fleuves à sec, et vendra le pays aux mains de méchants hommes. Je rendrai la terre désolée, et tout ce qui s'y trouve, par la main d'étrangers. Moi, Yahvé, je l'ai dit. »
Èmi yóò mú kí àwọn odò Naili gbẹ, Èmi yóò sì ta ilẹ̀ náà fún àwọn ènìyàn búburú: láti ọwọ́ àwọn àjèjì ènìyàn, Èmi yóò jẹ́ kí ilẹ̀ náà àti gbogbo ohun tí ó wá nínú rẹ ṣòfò. Èmi Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
13 "'Le Seigneur Yahvé dit: « Je détruirai aussi les idoles, et je ferai cesser les images de Memphis. Il n'y aura plus de prince du pays d'Égypte. Je mettrai la peur dans le pays d'Égypte.
“‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èmi yóò pa àwọn òrìṣà run, Èmi yóò sì mú kí òpin dé bá ère gbígbẹ́ ni Memfisi. Kò ní sí ọmọ-aládé mọ́ ní Ejibiti, Èmi yóò mú kí ìbẹ̀rù gba gbogbo ilẹ̀ náà.
14 Je ferai de Pathros une désolation, et mettra le feu à Zoan, et exécutera les jugements sur No.
Èmi yóò sì mú kí Paturosi di ahoro, èmi yóò fi iná sí Ṣoani, èmi yóò sì fi ìyà jẹ Tebesi.
15 Je déverserai ma colère sur le péché, la forteresse de l'Égypte. Je couperai la multitude de No.
Èmi yóò tú ìbínú mi jáde sórí Pelusiumu ìlú odi Ejibiti èmi yóò sì ké àkójọpọ̀ Tebesi kúrò.
16 Je mettrai le feu à l'Égypte Le péché sera dans une grande angoisse. Il n'y aura pas de rupture. Memphis aura des adversaires dans la journée.
Èmi yóò ti iná bọ Ejibiti Pelusiumu yóò japoró ní ìrora. Ìjì líle yóò jà ní Tebesi Memfisi yóò wà ìpọ́njú ní ìgbà gbogbo.
17 Les jeunes gens d'Aven et de Pibeseth tomberont par l'épée. Ils iront en captivité.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin ní Heliopolisi àti Bubasiti yóò ti ipa idà ṣubú wọn yóò sì kó àwọn ìlú wọn ní ìgbèkùn.
18 A Tehaphnehes aussi, le jour se retire, quand j'y briserai les jougs de l'Égypte. L'orgueil de sa puissance cessera en elle. Quant à elle, un nuage la couvrira, et ses filles iront en captivité.
Ojú ọjọ́ yóò ṣókùnkùn ní Tafanesi nígbà tí mo bá já àjàgà Ejibiti kúrò; níbẹ̀ agbára iyì rẹ̀ yóò dópin wọn yóò fi ìkùùkuu bò ó àwọn abúlé rẹ ní wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
19 Ainsi, j'exécuterai des jugements sur l'Égypte. Alors ils sauront que je suis Yahvé. »"
Nítorí náà, Èmi yóò mú ki ìjìyà wá sórí Ejibiti, wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
20 La onzième année, au premier mois, le septième jour du mois, la parole de l'Éternel me fut adressée, en ces termes:
Ní ọjọ́ keje oṣù kìn-ín-ní ọdún kọkànlá ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá,
21 « Fils d'homme, j'ai brisé le bras de Pharaon, roi d'Égypte. Voici, on ne l'a pas pansé, on n'a pas appliqué de médicaments, on n'a pas mis de bande pour le lier, afin qu'il devienne fort pour tenir l'épée.
“Ọmọ ènìyàn, Èmi ti ṣẹ́ apá Farao ọba Ejibiti. A kò ì tí ì di apá náà papọ̀ láti mu kí ó san, a kò sì ti di i si àárín igi pẹlẹbẹ kí o lè ni agbára tó láti di idà mú.
22 C'est pourquoi le Seigneur Yahvé dit: « Voici, j'en veux à Pharaon, roi d'Égypte, et je lui briserai les bras, le bras fort et ce qui a été brisé. Je ferai tomber l'épée de sa main.
Nítorí náà, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Èmi lòdì sí Farao ọba Ejibiti. Èmi yóò sẹ́ apá rẹ̀ méjèèjì, èyí tí ó dára àti èyí tí a ti ṣẹ́ pẹ̀lú, yóò sì mú kí idà bọ́ sọnù ní ọwọ́ rẹ̀.
23 Je disperserai les Égyptiens parmi les nations, je les disperserai dans tous les pays.
Èmi yóò sì fọ́n àwọn ènìyàn Ejibiti ká sí àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká gbogbo ilẹ̀.
24 Je renforcerai les bras du roi de Babylone, et je mettrai mon épée dans sa main; mais je briserai les bras de Pharaon, et il gémira devant le roi de Babylone avec le gémissement d'un homme blessé à mort.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli ní agbára, èmi yóò sì fi idà mi sí ọwọ́ rẹ, ṣùgbọ́n èmi yóò ṣẹ́ apá Farao, yóò sì kérora níwájú rẹ̀ bí ọkùnrin tí a sá ní àṣápa.
25 Je soutiendrai les bras du roi de Babylone, mais les bras de Pharaon tomberont. Alors on saura que je suis Yahvé, quand je mettrai mon épée dans la main du roi de Babylone, et qu'il l'étendra sur le pays d'Égypte.
Èmi yóò mú kí apá ọba Babeli lé, ṣùgbọ́n apá Farao yóò sì rọ. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú idà mi sí ọwọ́ ọba Babeli yóò sì fi idà náà kọlu Ejibiti.
26 Je disperserai les Égyptiens parmi les nations et je les disperserai dans tous les pays. Alors ils sauront que je suis Yahvé.'"
Èmi yóò fọ́n àwọn ara Ejibiti ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí àárín orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì tú wọn ká sí gbogbo ilẹ̀. Nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”

< Ézéchiel 30 >