< Ézéchiel 10 >

1 Alors je regardai, et voici, dans l'espace qui était au-dessus de la tête des chérubins, il y avait au-dessus d'eux comme une pierre de saphir, comme l'apparence d'un trône.
Mo sì wò ó, mo rí ohun kan tó dàbí òkúta safire nínú òfúrufú tó wà lókè orí kérúbù, ìrísí ohun yìí sì dàbí ìtẹ́.
2 Il parla à l'homme vêtu de lin, et dit: « Va entre les roues tournantes, jusque sous le chérubin, remplis tes deux mains de charbons ardents d'entre les chérubins, et répands-les sur la ville. » Il est entré pendant que je regardais.
Olúwa sì sọ fún ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun pé, “Lọ sí àárín àwọn kẹ̀kẹ́ tó wà lábẹ́ kérúbù. Bu ẹyin iná tó kúnwọ́ rẹ láàrín kérúbù, kí o sì fọ́n sórí ìlú náà.” Ó sì lọ lójú mi.
3 Or les chérubins se tenaient à droite de la maison quand l'homme entra, et la nuée remplissait le parvis intérieur.
Àwọn kérúbù dúró sí apá gúúsù tẹmpili nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ìkùùkuu sì bo inú àgbàlá.
4 La gloire de Yahvé monta du chérubin et se tint au-dessus du seuil de la maison; la maison fut remplie de la nuée, et le parvis fut rempli de l'éclat de la gloire de Yahvé.
Ògo Olúwa sì kúrò lórí àwọn kérúbù, ó bọ́ sí ibi ìloro tẹmpili. Ìkùùkuu sì bo inú tẹmpili, àgbàlá sì kún fún ìmọ́lẹ̀ àti ògo Olúwa.
5 Le bruit des ailes des chérubins se faisait entendre jusqu'au parvis extérieur, comme la voix du Dieu tout-puissant quand il parle.
A sì gbọ́ ariwo ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí títí dé àgbàlá tó wà ní ìta gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí Ọlọ́run Olódùmarè bá ń sọ̀rọ̀.
6 Lorsqu'il donna cet ordre à l'homme vêtu de lin: « Prends du feu entre les roues tournantes, entre les chérubins », il entra et se tint près d'une roue.
Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún ọkùnrin aláṣọ funfun yìí pé, “Mú iná láàrín àwọn kẹ̀kẹ́, láàrín àwọn kérúbù,” ó sì lọ dúró ṣẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ náà.
7 Le chérubin étendit sa main d'entre les chérubins vers le feu qui était entre les chérubins; il en prit une partie, et la mit dans les mains de l'homme vêtu de lin, qui la prit et sortit.
Ọ̀kan nínú àwọn kérúbù sì nawọ́ sí ibi iná tó wà láàrín kérúbù yòókù. Ó mú lára rẹ, ó fi sínú ọwọ́ ọkùnrin aláṣọ funfun, òun náà gbà á, ó sì jáde lọ.
8 La forme d'une main d'homme apparaissait ici dans les chérubins sous leurs ailes.
(Ohun tó dàbí ọwọ́ ènìyàn wà lábẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí.)
9 Je regardai, et voici, il y avait quatre roues à côté des chérubins, une roue à côté d'un chérubin, et une autre roue à côté d'un autre chérubin. L'aspect des roues était semblable à une pierre de béryl.
Nígbà tí mo sì wò, kíyèsí i, àwọn kẹ̀kẹ́ mẹ́rin wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kérúbù yìí, kẹ̀kẹ́ kọ̀ọ̀kan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kérúbù kọ̀ọ̀kan; ìrí àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ń tàn yanran bí àwọ̀ òkúta berili.
10 Elles avaient toutes les quatre la même apparence, comme une roue dans une roue.
Ní ti ìrísí wọn, gbogbo wọn jọra wọn; ọ̀kọ̀ọ̀kan rí bí ìgbà tí kẹ̀kẹ́ kan wà nínú kẹ̀kẹ́ mìíràn.
11 Quand elles allaient, elles allaient dans leurs quatre directions. Ils ne se tournaient pas en marchant, mais ils suivaient la tête jusqu'à l'endroit où elle se trouvait. Ils ne se tournaient pas en marchant.
Nígbà tí wọ́n ń lọ, wọ́n tẹ̀lé ọ̀kan nínú ọ̀nà mẹ́rin tí àwọn kérúbù dojúkọ; àwọn kẹ̀kẹ́ náà kò yípadà bí àwọn kérúbù ti ń lọ. Àwọn kérúbù ń lọ sí ibi tí orí dojúkọ láì yà.
12 Tout leur corps, y compris leur dos, leurs mains, leurs ailes et les roues, était rempli d'yeux tout autour, même les roues qu'ils avaient tous les quatre.
Gbogbo ara wọn àti ẹ̀yìn, ọwọ́ wọn àti ìyẹ́ wọn, àti àwọn kẹ̀kẹ́ kún fún ojú yíkákiri kẹ̀kẹ́, tí àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ní.
13 Quant aux roues, elles étaient appelées, à ce que j'ai entendu, « les roues tournantes ».
Mo gbọ́ tí wọ́n pe àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ni “kẹ̀kẹ́ àjà.”
14 Chacune d'elles avait quatre faces. La première face était celle d'un chérubin. La deuxième face était la face d'un homme. La troisième face était la face d'un lion. La quatrième était la face d'un aigle.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn kérúbù yìí ni ojú mẹ́rin: ojú èkínní jẹ́ ojú kérúbù, ojú kejì jẹ́ ti ènìyàn, ojú kẹta jẹ́ ti kìnnìún nígbà tí ojú kẹrin jẹ́ ti ẹyẹ idì.
15 Les chérubins se sont levés. C'est l'être vivant que j'ai vu près du fleuve Kebar.
A gbé àwọn kérúbù sókè. Èyí ni àwọn ẹ̀dá alààyè tí mo rí létí odò Kebari.
16 Quand les chérubins allaient, les roues allaient à côté d'eux; et quand les chérubins levaient leurs ailes pour s'élever de la terre, les roues ne tournaient pas non plus d'à côté d'eux.
Bí àwọn kérúbù yìí bá ń lọ àwọn kẹ̀kẹ́ ẹgbẹ́ wọn náà yóò lọ; bẹ́ẹ̀ ni bí àwọn kérúbù bá tú ìyẹ́ wọn ká láti dìde nílẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ yìí kò ní kúrò lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn.
17 Quand ils se tenaient debout, ils se tenaient debout. Quand ils s'élevaient, ceux-ci s'élevaient avec eux, car l'esprit de l'être vivant était en eux.
Bí àwọn kérúbù bá dúró díẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dúró jẹ́ẹ́; bí àwọn kérúbù bá dìde àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dìde, nítorí pé ẹ̀mí àwọn ẹ̀dá alààyè yìí wà nínú wọn.
18 La gloire de Yahvé sortit du seuil de la maison et se tint au-dessus des chérubins.
Ògo Olúwa kúrò níbi ìloro tẹmpili, ó sì dúró sórí àwọn kérúbù.
19 Les chérubins levèrent leurs ailes et s'élevèrent de terre à mes yeux quand ils sortirent, avec les roues à côté d'eux. Ils se tinrent à l'entrée de la porte orientale de la maison de Yahvé, et la gloire du Dieu d'Israël était au-dessus d'eux, en haut.
Àwọn kérúbù gbé ìyẹ́ wọn sókè, wọ́n sì fò kúrò nílẹ̀ lójú mi, wọ́n sì lọ pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ wọn lẹ́ẹ̀kan náà. Wọ́n dúró níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn ilé Olúwa, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lórí wọn.
20 Voici l'être vivant que j'ai vu sous le Dieu d'Israël, près du fleuve Kebar; et j'ai su que c'étaient des chérubins.
Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀dá alààyè tí mo rí lábẹ́ Ọlọ́run Israẹli létí odò Kebari, mo sì mọ̀ pé kérúbù ni wọ́n.
21 Chacun avait quatre faces, et chacun avait quatre ailes. La forme des mains d'un homme était sous leurs ailes.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ojú mẹ́rin àti ìyẹ́ mẹ́rin, lábẹ́ ìyẹ́ wọn ni ohun tó jọ ọwọ́ ènìyàn wà.
22 Quant à la ressemblance de leurs visages, ce sont les visages que j'ai vus près du fleuve du Kebar, leur aspect et eux-mêmes. Ils allaient tous droit devant eux.
Àfiwé ojú àti ìrísí wọn rí bákan náà pẹ̀lú àwọn tí mo rí létí odò Kebari. Olúkúlùkù wọn sì ń lọ sí ọ̀kánkán tààrà.

< Ézéchiel 10 >