< Exode 32 >

1 Lorsque le peuple vit que Moïse tardait à descendre de la montagne, il s'assembla auprès d'Aaron et lui dit: « Viens, fais-nous des dieux qui marchent devant nous; car ce Moïse, l'homme qui nous a fait monter du pays d'Égypte, nous ne savons pas ce qu'il est devenu. »
Nígbà tí àwọn ènìyàn rí i pé Mose pẹ́ kí ó tó sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè wá, wọn péjọ yí Aaroni ká, wọ́n sì wí pé, “Wá, dá òrìṣà tí yóò máa ṣáájú wa fún wa. Bí ó ṣe ti Mose tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá, àwa kò mọ́ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí i.”
2 Aaron leur dit: « Otez les anneaux d'or qui sont aux oreilles de vos femmes, de vos fils et de vos filles, et apportez-les-moi. »
Aaroni dá wọn lóhùn pé, “Ẹ bọ́ òrùka wúrà tí ó wà ní etí àwọn ìyàwó yín, tí àwọn ọmọkùnrin yín, àti tí àwọn ọmọbìnrin yín, kí ẹ sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi.”
3 Tout le peuple enleva les anneaux d'or qui étaient à ses oreilles, et les apporta à Aaron.
Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn ènìyàn bọ́ òrùka etí wọn, wọn sì kó wọn wá fún Aaroni.
4 Il reçut ce qu'on lui tendait, le façonna avec un outil de gravure et en fit un veau moulé. Puis ils dirent: « Voici tes dieux, Israël, qui t'ont fait monter du pays d'Égypte. »
Ó sì gbà wọ́n ní ọwọ́ wọn, ó sì fi ṣe ohun ọnà fínfín, ó sì dà á ní àwòrán ẹgbọrọ màlúù. Nígbà náà ni wọn wí pé, “Israẹli, wọ̀nyí ni òrìṣà, ti ó mú un yín jáde wá láti Ejibiti.”
5 Aaron vit cela, et il bâtit un autel devant elle. Aaron fit une proclamation, et dit: « Demain sera une fête pour Yahvé. »
Nígbà ti Aaroni rí èyí, ó kọ́ pẹpẹ kan níwájú ẹgbọrọ màlúù náà, ó sì kéde pé, “Lọ́la ni àjọyọ̀ sí Olúwa.”
6 Le lendemain, ils se levèrent de bonne heure, offrirent des holocaustes et apportèrent des sacrifices de paix; le peuple s'assit pour manger et boire, et se leva pour jouer.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn dìde ní kùtùkùtù ọjọ́ kejì, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n sì mú ẹbọ àlàáfíà wá. Lẹ́yìn náà wọ́n jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde láti ṣeré.
7 Yahvé parla à Moïse: « Va, descends, car ton peuple, que tu as fait monter du pays d'Égypte, s'est corrompu!
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Sọ̀kalẹ̀ lọ, nítorí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú gòkè wá láti Ejibiti, wọ́n ti dẹ́ṣẹ̀.
8 Ils se sont détournés rapidement de la voie que je leur avais prescrite. Ils se sont fait un veau façonné, ils se sont prosternés devant lui, ils lui ont offert des sacrifices, et ils ont dit: « Ce sont tes dieux, Israël, qui t'ont fait monter du pays d'Égypte ».
Wọ́n ti yí kánkán kúrò nípa ọ̀nà tí mo ti mo pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì ti dá ère ẹgbọrọ màlúù fún ara wọn. Wọ́n ti foríbalẹ̀ fún un, wọ́n sì ti rú ẹbọ sí i, wọ́n sì ti sọ pé, ‘Israẹli wọ̀nyí ní òrìṣà tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.’”
9 Yahvé dit à Moïse: « J'ai vu ce peuple, et voici, c'est un peuple à la nuque raide.
Olúwa wí fún Mose pé, “Èmi ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, wọ́n sì jẹ́ ọlọ́rùn líle ènìyàn.
10 Maintenant, laisse-moi tranquille, afin que ma colère s'enflamme contre eux et que je les consume; et je ferai de toi une grande nation. »
Ǹjẹ́ nísinsin yìí fi mí sílẹ̀, nítorí kí ìbínú mi lè gbóná sí wọn, kí Èmi sì lè pa wọ́n run. Nígbà náà ni Èmi yóò sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá.”
11 Moïse supplia Yahvé son Dieu et dit: « Yahvé, pourquoi ta colère s'enflamme-t-elle contre ton peuple, que tu as fait sortir du pays d'Égypte avec une grande puissance et une main puissante?
Ṣùgbọ́n Mose kígbe fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìbínú rẹ yóò ṣe gbóná sí àwọn ènìyàn rẹ, tí ìwọ mú jáde láti Ejibiti wá pẹ̀lú agbára ńlá àti ọwọ́ agbára?
12 Pourquoi les Égyptiens diraient-ils: « Il les a fait sortir pour le malheur, pour les tuer dans les montagnes et les faire disparaître de la surface de la terre? Détourne-toi de ton ardente colère, et détourne-toi de ce mal contre ton peuple.
Èéṣe tí àwọn ará Ejibiti yóò ṣe wí pé, ‘Nítorí ibi ni ó ṣe mọ̀ ọ́n mọ̀ mú wọn jáde, láti pa wọ́n ní orí òkè àti láti gbá wọn kúrò lórí ayé’? Yípadà kúrò nínú ìbínú rẹ tí ó múná, yí ọkàn padà, kí o má sì ṣe mú ìparun wá sórí àwọn ènìyàn rẹ.
13 Souviens-toi d'Abraham, d'Isaac et d'Israël, tes serviteurs, à qui tu as juré par toi-même, et tu leur as dit: « Je multiplierai ta descendance comme les étoiles du ciel, et je donnerai à ta descendance tout ce pays dont j'ai parlé, et ils en hériteront pour toujours ».
Rántí àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ Abrahamu, Isaaki àti Israẹli, ẹni tí ìwọ búra fún fúnra rẹ̀, ‘Tí o wí fún wọn pé, Èmi yóò mú irú-ọmọ rẹ pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, Èmi yóò sì fún irú-ọmọ rẹ ní gbogbo ilẹ̀ tí mo ti pinnu fún wọn, yóò sì jẹ́ ogún ìní wọn láéláé.’”
14 Et Yahvé se détourna du mal qu'il avait dit qu'il ferait à son peuple.
Nígbà náà ni Olúwa dáwọ́ ìbínú rẹ̀ dúró, kò sì mú ìparun náà tí ó sọ wá sórí àwọn ènìyàn rẹ̀ mọ́.
15 Moïse se retourna et descendit de la montagne, ayant à la main les deux tables de l'alliance, tables qui étaient écrites sur leurs deux faces. Elles étaient écrites sur une face et sur l'autre.
Mose sì yípadà, ó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà pẹ̀lú òkúta wàláà ẹ̀rí méjì ní ọwọ́ rẹ̀. Wọ́n kọ ìwé síhà méjèèjì, iwájú àti ẹ̀yin.
16 Les tables étaient l'œuvre de Dieu, et l'écriture était l'écriture de Dieu, gravée sur les tables.
Iṣẹ́ Ọlọ́run sì ni wàláà náà; ìkọ̀wé náà jẹ́ ìkọ̀wé Ọlọ́run, a fín in sára àwọn òkúta wàláà náà.
17 Lorsque Josué entendit le bruit du peuple qui criait, il dit à Moïse: « Il y a un bruit de guerre dans le camp. »
Nígbà tí Joṣua gbọ́ ariwo àwọn ènìyàn tí wọ́n ń kígbe, ó sọ fún Mose pé, “Ariwo ogun wà nínú àgọ́.”
18 Il dit: « Ce n'est pas la voix de ceux qui crient victoire. Ce n'est pas la voix de ceux qui crient pour être vaincus, mais le bruit de ceux qui chantent que j'entends. »
Mose dáhùn pé, “Kì í ṣe ariwo fún ìṣẹ́gun, kì í ṣe ariwo fún aṣẹ́gun; ohùn àwọn tí ń kọrin ni mo gbọ́.”
19 Dès qu'il s'approcha du camp, il vit le veau et les danses. La colère de Moïse s'enflamma, il jeta les tables de ses mains et les brisa sous la montagne.
Nígbà tí Mose dé àgọ́, ó sì rí ẹgbọrọ màlúù náà àti ijó, ìbínú rẹ gbóná, ó sì sọ wàláà ọwọ́ rẹ̀ sílẹ̀, ó sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ ní ìsàlẹ̀ òkè náà.
20 Il prit le veau qu'ils avaient fait, le brûla au feu, le réduisit en poudre, le répandit sur l'eau et le fit boire aux enfants d'Israël.
Ó sì gbé ẹgbọrọ màlúù tí wọ́n ṣe, ó sì fi iná jó wọn; ó sì lọ̀ wọ́n kúnná, ó dà á sínú omi, ó sì mú àwọn ọmọ Israẹli mu ún.
21 Moïse dit à Aaron: « Qu'est-ce que ce peuple t'a fait, pour que tu lui aies fait subir un grand péché? ».
Mose sọ fún Aaroni pé, “Kí ni àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣe sí ọ, tí ìwọ ṣe mú wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá yìí?”
22 Aaron dit: « Ne laisse pas s'enflammer la colère de mon seigneur. Tu connais le peuple, il est déterminé à faire le mal.
Aaroni dáhùn wí pé, “Má ṣe bínú olúwa mi. Ìwọ mọ bí àwọn ènìyàn yìí ṣe burú tó.
23 Car ils m'ont dit: Fais-nous des dieux qui marchent devant nous. Quant à ce Moïse, l'homme qui nous a fait monter du pays d'Égypte, nous ne savons pas ce qu'il est devenu ».
Wọ́n sọ fún mi pé, ‘Ṣe òrìṣà fún wa, tí yóò máa ṣáájú wa. Bí ó ṣe ti Mose ẹni tí ó mú wa jáde láti Ejibiti wá àwa kò mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí i.’
24 Je leur ai dit: « Que celui qui a de l'or le prenne ». Ils me le donnèrent; je le jetai dans le feu et il en sortit ce veau. »
Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún wọn pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó ní òrùka wúrà, kí ó bọ́ ọ wá.’ Nígbà náà ni wọ́n fún mi ní wúrà, mo sì jù ú sínú iná, a sì fi ṣe ẹgbọrọ màlúù yìí!”
25 Lorsque Moïse vit que le peuple était hors de contrôle, (car Aaron l'avait laissé perdre le contrôle, provoquant la risée de ses ennemis),
Mose rí pé àwọn ènìyàn náà kò ṣe ṣàkóso àti pé Aaroni ti sọ wọ́n di aláìlákóṣo láàrín àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wọn.
26 Moïse se tint à la porte du camp et dit: « Que celui qui est du côté de l'Éternel vienne à moi. » Tous les fils de Lévi se rassemblèrent auprès de lui.
Bẹ́ẹ̀ ni Mose dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó sì wí pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá wà fún Olúwa, kí ó wá sí ọ̀dọ̀ mi.” Gbogbo àwọn ará Lefi sì péjọ yí i ká.
27 Il leur dit: « Yahvé, le Dieu d'Israël, a dit: « Que chacun mette son épée sur sa cuisse, qu'il aille de porte en porte dans tout le camp, et que chacun tue son frère, son compagnon et son prochain ».
Nígbà náà ni ó sọ fún wọn pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, wí pé, ‘Kí olúkúlùkù ọkùnrin kí ó kọ idà rẹ̀ sí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Ẹ lọ padà, kí ẹ jà láti àgọ́ kan dé òmíràn, olúkúlùkù kí ó pa arákùnrin rẹ̀ ọ̀rẹ́ rẹ̀ àti aládùúgbò rẹ.’”
28 Les fils de Lévi firent selon la parole de Moïse. Environ trois mille hommes tombèrent du peuple ce jour-là.
Àwọn ará Lefi ṣe gẹ́gẹ́ bí Mose ṣe pàṣẹ, àti ní ọjọ́ náà àwọn tí ó kú tó ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ènìyàn.
29 Moïse dit: « Consacrez-vous aujourd'hui à Yahvé, car chacun a été contre son fils et contre son frère, afin qu'il vous accorde aujourd'hui une bénédiction. »
Nígbà náà ni Mose wí pé, “Ẹ ti ya ara yín sọ́tọ̀ fún Olúwa lónìí, nítorí ìwọ ti dìde sí àwọn ọmọ rẹ àti arákùnrin rẹ, ó sì ti bùkún fún ọ lónìí.”
30 Le lendemain, Moïse dit au peuple: « Vous avez commis un grand péché. Je vais maintenant monter vers Yahvé. Je ferai peut-être l'expiation de votre péché. »
Ní ọjọ́ kejì Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ̀yin ti dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí èmi yóò gòkè lọ bá Olúwa; bóyá èmi lè ṣe ètùtù fún ẹ̀ṣẹ̀ yín.”
31 Moïse retourna auprès de Yahvé et dit: « Oh, ce peuple a commis un grand péché et s'est fait des dieux d'or.
Bẹ́ẹ̀ ni Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Yé, kí ni ẹ̀ṣẹ̀ ńlá tí àwọn ènìyàn ti dá yìí! Wọ́n ti ṣe òrìṣà wúrà fún ara wọn.
32 Mais maintenant, si tu veux, pardonne leur péché - et sinon, efface-moi de ton livre que tu as écrit. »
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, jọ̀wọ́ dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n ṣùgbọ́n tí kò bá sì ṣe bẹ́ẹ̀, pa orúkọ mi rẹ́ kúrò nínú ìwé tí ìwọ ti kọ.”
33 Yahvé dit à Moïse: « Celui qui a péché contre moi, je l'efface de mon livre.
Olúwa dá Mose lóhùn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá dẹ́ṣẹ̀ sí mi, Èmi yóò pa á rẹ́ kúrò nínú ìwé mi.
34 Va maintenant, conduis le peuple au lieu dont je t'ai parlé. Voici, mon ange ira devant toi. Néanmoins, au jour où je punirai, je les punirai pour leur péché. »
Ǹjẹ́ nísinsin yìí lọ, máa darí àwọn ènìyàn yìí lọ sí ibi ti mo sọ, angẹli mi yóò sì máa lọ ṣáájú yín. Ìgbà ń bọ̀ fún mi tì Èmi yóò ṣe ìbẹ̀wò, Èmi yóò fi yà jẹ wọ́n fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
35 Yahvé frappa le peuple, à cause de ce qu'il avait fait avec le veau qu'Aaron avait fabriqué.
Olúwa sì yọ àwọn ènìyàn náà lẹ́nu, pẹ̀lú ààrùn nítorí ohun tí wọ́n ṣe ní ti ẹgbọrọ màlúù tí Aaroni ṣe.

< Exode 32 >