< 2 Rois 5 >

1 Or Naaman, chef de l'armée du roi de Syrie, était un homme important auprès de son maître, et honorable, car par lui Yahvé avait donné la victoire à la Syrie; il était aussi un homme fort et vaillant, mais il était lépreux.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 Les Syriens étaient sortis par bandes, et ils avaient emmené captive du pays d'Israël une petite fille, qui était au service de la femme de Naaman.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 Elle dit à sa maîtresse: « Je voudrais que mon seigneur soit avec le prophète qui est à Samarie! Il le guérirait alors de sa lèpre. »
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Quelqu'un est entré et a dit à son seigneur: « La fille qui vient du pays d'Israël a dit cela. »
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 Le roi de Syrie dit: « Va maintenant, et j'enverrai une lettre au roi d'Israël. » Il partit, et prit avec lui dix talents d'argent, six mille pièces d'or et dix vêtements de rechange.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 Il apporta la lettre au roi d'Israël, en disant: « Lorsque cette lettre te sera parvenue, voici que je t'envoie Naaman, mon serviteur, pour que tu le guérisses de sa lèpre. »
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 Après avoir lu la lettre, le roi d'Israël déchira ses vêtements et dit: « Suis-je Dieu, pour tuer et faire vivre, que cet homme m'envoie pour guérir un homme de sa lèpre? Mais je vous prie de considérer et de voir comment il cherche une querelle contre moi. »
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 Lorsque Élisée, homme de Dieu, apprit que le roi d'Israël avait déchiré ses vêtements, il envoya dire au roi: « Pourquoi as-tu déchiré tes vêtements? Qu'il vienne maintenant vers moi, et il saura qu'il y a un prophète en Israël. »
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 Naaman arriva avec ses chevaux et ses chars, et il se tint à l'entrée de la maison d'Elisée.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 Élisée lui envoya un messager, en disant: « Va te laver dans le Jourdain sept fois, et ta chair reviendra à toi, et tu seras pur. »
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 Mais Naaman, irrité, s'en alla et dit: « Voici, je me disais: Il sortira vers moi, il se tiendra debout, il invoquera le nom de l'Éternel, son Dieu, il agitera la main sur le lieu et guérira le lépreux ».
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 L'Abana et le Pharpar, les fleuves de Damas, ne sont-ils pas meilleurs que toutes les eaux d'Israël? Ne pourrais-je pas m'y laver et être propre? » Alors il se retourna et s'en alla, furieux.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 Ses serviteurs s'approchèrent et lui parlèrent, et dirent: « Mon père, si le prophète t'avait demandé de faire quelque grande chose, ne l'aurais-tu pas fait? A combien plus forte raison, quand il te dira: « Lave-toi et sois pur »? »
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Alors il descendit et se plongea sept fois dans le Jourdain, selon la parole de l'homme de Dieu; et sa chair redevint comme la chair d'un petit enfant, et il fut pur.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 Il retourna auprès de l'homme de Dieu, lui et toute sa troupe, et vint se présenter devant lui; et il dit: « Voici, je sais qu'il n'y a de Dieu dans toute la terre qu'en Israël. Maintenant donc, je te prie de prendre un cadeau de ton serviteur. »
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 Mais il répondit: « L'Éternel est vivant, devant qui je me tiens, je n'en recevrai aucun. » Il le pressa de la prendre, mais il refusa.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 Naaman dit: « Sinon, que l'on donne à ton serviteur deux mulets chargés de terre, car ton serviteur n'offrira désormais ni holocauste ni sacrifice à d'autres dieux, mais à Yahvé.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 Que Yahvé pardonne à ton serviteur cette chose: lorsque mon maître entre dans la maison de Rimmon pour s'y prosterner, qu'il s'appuie sur ma main et que je me prosterne dans la maison de Rimmon. Quand je me prosternerai dans la maison de Rimmon, que Yahvé pardonne à ton serviteur en cette circonstance. »
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 Il lui dit: « Va en paix. » Il s'éloigna donc un peu de lui.
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 Mais Guéhazi, serviteur d'Élisée, homme de Dieu, dit: « Voici, mon maître a épargné ce Naaman le Syrien, en ne recevant pas de ses mains ce qu'il apportait. L'Éternel est vivant, je courrai après lui, et je prendrai quelque chose de lui. »
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 Guéhazi suivit donc Naaman. Naaman, voyant qu'il courait après lui, descendit du char pour aller à sa rencontre, et dit: « Tout va-t-il bien? »
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 Il répondit: « Tout va bien. Mon maître m'a envoyé dire: 'Voici qu'à l'instant même, deux jeunes gens d'entre les fils des prophètes sont venus me voir de la montagne d'Ephraïm. Donne-leur un talent d'argent et deux vêtements de rechange. »
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 Naaman dit: « Qu'il te plaise de prendre deux talents. » Il le pressa et lia deux talents d'argent dans deux sacs, avec deux vêtements de rechange, et les confia à deux de ses serviteurs, qui les portèrent devant lui.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 Lorsqu'il arriva sur la colline, il les prit de leur main et les rangea dans la maison. Puis il laissa partir les hommes, qui s'en allèrent.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Il entra, et se présenta devant son maître. Élisée lui dit: « D'où viens-tu, Guéhazi? » Il a dit: « Votre serviteur n'est allé nulle part. »
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 Il lui dit: « Mon cœur n'a-t-il pas été avec toi lorsque l'homme s'est retourné de son char pour venir à ta rencontre? Est-ce le moment de recevoir de l'argent, de recevoir des vêtements, des oliviers et des vignes, des moutons et du bétail, des serviteurs et des servantes?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 C'est pourquoila lèpre de Naaman s'attachera à toi et à ta descendance pour toujours. » Il est sorti de sa présence lépreux, blanc comme neige.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.

< 2 Rois 5 >