< 2 Rois 22 >
1 Josias avait huit ans lorsqu'il devint roi, et il régna trente et un ans à Jérusalem. Le nom de sa mère était Jedida, fille d'Adaja, de Bozkath.
Josiah jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́jọ nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlélọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Jedida ọmọbìnrin Adaiah; ó wá láti Boskati.
2 Il fit ce qui est droit aux yeux de l'Éternel, il marcha dans toute la voie de David, son père, et ne se détourna ni à droite ni à gauche.
Ó sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Dafidi baba a rẹ̀, kò sì yípadà sí apá ọ̀tún tàbí sí apá òsì.
3 La dix-huitième année du roi Josias, le roi envoya Shaphan, fils d'Azalia, fils de Meshullam, le scribe, à la maison de l'Éternel, en disant:
Ní ọdún kejìdínlógún tí ó fi jẹ ọba. Ọba Josiah rán akọ̀wé, Ṣafani ọmọ Asalia, ọmọ Meṣullamu, sí ilé Olúwa. Ó wí pé,
4 « Monte vers Hilkija, le grand prêtre, pour qu'il compte l'argent qu'on apporte à la maison de l'Éternel et que les gardiens du seuil ont recueilli du peuple.
“Gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ Hilkiah olórí àlùfáà, kí o sì jẹ́ kí ó ṣírò iye owó tí a mú wá sí ilé Olúwa, tí àwọn olùṣọ́nà ti gbà lọ́wọ́ àwọn ènìyàn.
5 Qu'ils le remettent entre les mains des ouvriers qui ont la garde de la maison de l'Éternel, et qu'ils le donnent aux ouvriers de la maison de l'Éternel, pour réparer les dégâts de la maison,
Ẹ sì jẹ́ kí wọn ó fi lé àwọn ọkùnrin tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé Olúwa. Kí ẹ sì jẹ́ kí àwọn ọkùnrin san án fún àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń tún ilé Olúwa ṣe.
6 aux charpentiers, aux constructeurs et aux maçons, et pour acheter du bois et des pierres de taille pour réparer la maison.
Àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àwọn ọ̀mọ̀lé àti àwọn akọ́lé. Bákan náà ni wọ́n ra igi àti òkúta ọlọ́ṣọ̀ọ́ láti fi tún tẹmpili ṣe.
7 Mais on ne leur demandera pas de compte pour l'argent remis entre leurs mains, car ils agissent fidèlement. »
Ṣùgbọ́n wọn kò ní láti ṣe ìṣirò fún owó náà tí a fi fún wọn, nítorí wọ́n ṣe òtítọ́.”
8 Hilkija, le grand prêtre, dit à Shaphan, le scribe: « J'ai trouvé le livre de la loi dans la maison de Yahvé. » Hilkija remit le livre à Shaphan, qui le lut.
Hilkiah olórí àlùfáà sọ fún Ṣafani akọ̀wé pé, “Èmi rí ìwé òfin nílé Olúwa.” Ó fi fún Ṣafani, ẹni tí ó kà á.
9 Shaphan, le scribe, revint vers le roi et lui rapporta la parole, en disant: « Tes serviteurs ont vidé l'argent qui se trouvait dans la maison et l'ont remis entre les mains des ouvriers chargés de la surveillance de la maison de l'Éternel. »
Nígbà náà, Ṣafani akọ̀wé lọ sí ọ̀dọ̀ ọba. Ó sì sọ fún un pé, “Àwọn ìjòyè rẹ ti san owó náà tí ó wà nínú ilé Olúwa. Èmi sì ti fi lé ọwọ́ àwọn tí ó ń ṣe iṣẹ́ náà àti àwọn alábojútó nílé Olúwa.”
10 Shaphan, le scribe, informa le roi en disant: « Le prêtre Hilkija m'a remis un livre. » Puis Shaphan le lut devant le roi.
Nígbà náà Ṣafani akọ̀wé sọ fún ọba pé, “Hilkiah àlùfáà ti fún un ní ìwé kan.” Ṣafani kà lára rẹ̀ níwájú ọba.
11 Lorsque le roi eut entendu les paroles du livre de la loi, il déchira ses vêtements.
Nígbà tí ọba gbọ́ ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé òfin, ó sì fa aṣọ rẹ̀ ya.
12 Le roi donna cet ordre au sacrificateur Hilkija, à Ahikam, fils de Schaphan, à Acbor, fils de Michée, à Schaphan, le scribe, et à Asaja, serviteur du roi:
Ó pa àṣẹ yìí fún Ahikamu àlùfáà, Hilkiah ọmọ Ṣafani, Akbori ọmọ Mikaiah, àti Ṣafani akọ̀wé àti Asaiah ìránṣẹ́ ọba.
13 « Allez consulter Yahvé pour moi, pour le peuple et pour tout Juda, au sujet des paroles de ce livre qui a été trouvé; Car la colère de Yahvé s'est enflammée contre nous, parce que nos pères n'ont pas écouté les paroles de ce livre et n'ont pas agi selon tout ce qui est écrit à notre sujet. »
“Lọ, ẹ béèrè lọ́wọ́ Olúwa fún mi àti fún àwọn ènìyàn àti fún gbogbo Juda nípa ohun tí a kọ sínú ìwé yìí tí a ti rí. Títóbi ni ìbínú Olúwa tí ó ń jó sí wa nítorí àwọn baba wa kò tẹ̀lé ọ̀rọ̀ inú ìwé yìí; wọn kò ṣe ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ níbẹ̀ nípa wa.”
14 Et Hilkija, le prêtre, Ahikam, Acbor, Shaphan et Asaiah allèrent chez Hulda, la prophétesse, femme de Shallum, fils de Tikva, fils de Harhas, gardien de l'armoire (elle habitait maintenant à Jérusalem, dans le deuxième quartier), et ils lui parlèrent.
Hilkiah àlùfáà, Ahikamu àti Akbori Ṣafani pẹ̀lú Asaiah, lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì obìnrin Hulda láti lọ bá a sọ̀rọ̀, ẹni tí ó jẹ́ aya Ṣallumu ọmọ Tikfa ọmọ Harhasi alábojútó ibi ìpa aṣọ mọ́ sí. Ó ń gbé ní Jerusalẹmu ní ìdàkejì.
15 Elle leur dit: « L'Éternel, le Dieu d'Israël, dit: 'Dis à l'homme qui t'envoie vers moi:
Ó wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, Sọ fún ọkùnrin tí ó rán an yín sí mi,
16 L'Éternel dit: 'Voici, je vais faire venir le malheur sur ce lieu et sur ses habitants, toutes les paroles du livre que le roi de Juda a lu.
‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò mú ibi wá sí ibí àti àwọn ènìyàn rẹ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí a kọ sínú ìwé tí ọba Juda ti kà.
17 Parce qu'ils m'ont abandonné et qu'ils ont offert de l'encens à d'autres dieux, afin de m'irriter par tout l'ouvrage de leurs mains, ma colère s'enflammera contre ce lieu, et elle ne s'éteindra pas. »
Nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì tún sun tùràrí fún ọlọ́run mìíràn. Wọ́n sì mú mi bínú nípa gbogbo àwọn òrìṣà tí wọ́n ti fi ọwọ́ wọn dá. Ìbínú mi yóò ru sí ibí yìí, kì yóò sì rọlẹ̀.’
18 Mais dis au roi de Juda, qui t'a envoyé consulter Yahvé: « Yahvé, le Dieu d'Israël, dit: 'Au sujet des paroles que tu as entendues,
Sọ fún ọba Juda tí ó rán yín láti béèrè lọ́wọ́ Olúwa, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí nípa ọ̀rọ̀ wọ̀n-ọn-nì tí ìwọ ti gbọ́.
19 parce que ton cœur s'est attendri et que tu t'es humilié devant Yahvé en entendant ce que j'ai dit de ce lieu et de ses habitants, pour qu'ils deviennent une désolation et une malédiction, et que tu as déchiré tes vêtements et pleuré devant moi, moi aussi je t'ai entendu, dit Yahvé.
Nítorí tí ọkàn rẹ rọ̀, tí ìwọ sì ti rẹ ara rẹ sílẹ̀ níwájú Olúwa, nígbà tí ìwọ gbọ́ èyí tí mo sọ sí ibí yìí àti sí àwọn ènìyàn rẹ pé wọn yóò di ahoro àti ẹni ègún tí ìwọ sì fa aṣọ ọ̀ rẹ ya pẹ̀lú níwájú mi. Èmi ti gbọ́ tìrẹ, ni Olúwa wí.
20 C'est pourquoi voici que je vous rassemblerai auprès de vos pères, et vous serez rassemblés en paix dans votre tombeau. Vos yeux ne verront pas tout le mal que je ferai venir sur ce lieu.'"" Ils rapportèrent donc ce message au roi.
Nítorí náà èmi yóò kó ọ jọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baba à rẹ, a ó sì sin ọ́ ní àlàáfíà. Ojú rẹ kì yóò rí gbogbo àwọn ibi tí èmi yóò mú wá bá ibí yìí.’” Bẹ́ẹ̀ wọ́n mú èsì rẹ̀ padà tọ ọba wá.