< 2 Rois 18 >

1 La troisième année d'Osée, fils d'Éla, roi d'Israël, Ézéchias, fils d'Achaz, roi de Juda, commença à régner.
Ní ọdún kẹta Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli, Hesekiah ọmọ Ahasi ọba Juda bẹ̀rẹ̀ ìjọba.
2 Il avait vingt-cinq ans lorsqu'il devint roi, et il régna vingt-neuf ans à Jérusalem. Le nom de sa mère était Abi, fille de Zacharie.
Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Abijah ọmọbìnrin Sekariah.
3 Il fit ce qui est droit aux yeux de l'Éternel, selon tout ce qu'avait fait David, son père.
Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dafidi ti ṣe.
4 Il fit disparaître les hauts lieux, brisa les colonnes et abattit l'ashère. Il brisa aussi le serpent d'airain que Moïse avait fait, parce qu'en ce temps-là les enfants d'Israël lui offraient de l'encens, et il l'appela Nehushtan.
Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ àwọn ère òkúta, ó sì gé àwọn ère Aṣerah lulẹ̀, ó sì fọ́ ejò idẹ tí Mose ti ṣe náà túútúú, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Nehuṣitani.)
5 Il se confia en Yahvé, le Dieu d'Israël, de sorte qu'après lui il n'y eut personne comme lui parmi tous les rois de Juda et parmi ceux qui l'ont précédé.
Hesekiah sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Kò sì ṣí ẹnìkan tí ó dàbí tirẹ̀ lára gbogbo àwọn ọba Juda, bóyá kí ó tó jẹ tàbí lẹ́yìn rẹ̀.
6 Car il s'est joint à l'Éternel. Il ne s'est pas écarté de sa suite, mais il a gardé ses commandements, que l'Éternel avait prescrits à Moïse.
Ó súnmọ́ Olúwa, kò sì dẹ́kun láti tì í lẹ́yìn: ó sì pa òfin Olúwa mọ́ tí ó ti fi fún Mose.
7 L'Éternel était avec lui. Partout où il allait, il prospérait. Il se révolta contre le roi d'Assyrie et ne le servit pas.
Olúwa sì wà pẹ̀lú rẹ̀; ó sì ń ṣe rere nínú gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé. Ó ṣe ọ̀tẹ̀ sí ọba Asiria kò sì sìn ín.
8 Il frappa les Philistins jusqu'à Gaza et son territoire, depuis la tour des gardes jusqu'à la ville fortifiée.
Láti ilé ìṣọ́ títí dé ìlú olódi, ó sì pa àwọn ará Filistini run, àti títí dé Gasa àti agbègbè rẹ̀.
9 La quatrième année du roi Ézéchias, qui était la septième année d'Osée, fils d'Éla, roi d'Israël, Shalmaneser, roi d'Assyrie, monta contre Samarie et l'assiégea.
Ní ọdún kẹrin ọba Hesekiah, nígbà tí ó jẹ́ ọdún keje Hosea ọmọ Ela ọba Israẹli. Ṣalamaneseri ọba Asiria yàn lára Samaria ó sì tẹ̀dó tì í.
10 Au bout de trois ans, ils la prirent. La sixième année d'Ézéchias, qui était la neuvième année d'Osée, roi d'Israël, Samarie fut prise.
Lẹ́yìn ọdún mẹ́ta Asiria gbé e. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kó Samaria ní ọdún kẹfà Hesekiah tí ó sì jẹ́ ọdún kẹsànán Hosea ọba Israẹli.
11 Le roi d'Assyrie emmena Israël en Assyrie et le mit à Hala, sur le Habor, le fleuve de Gozan, et dans les villes des Mèdes,
Ọba Asiria lé Israẹli kúrò ní Asiria, wọ́n sì ṣe àtìpó wọn ní Hala, ní Gosani létí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
12 parce qu'ils n'avaient pas écouté la voix de Yahvé, leur Dieu, mais qu'ils avaient transgressé son alliance, tout ce que Moïse, serviteur de Yahvé, avait ordonné, et qu'ils n'avaient pas voulu l'écouter ni le mettre en pratique.
Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wọn kò pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Ṣùgbọ́n wọ́n ti dà májẹ̀mú rẹ̀ gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ. Wọn kò fi etí wọn sílẹ̀ sí òfin wọn kò sì gbé wọn jáde.
13 Or, la quatorzième année du roi Ézéchias, Sennacherib, roi d'Assyrie, monta contre toutes les villes fortes de Juda et les prit.
Ní ọdún kẹrìnlá tí Hesekiah jẹ ọba, Sennakeribu ọba Asiria kọlu gbogbo ìlú olódi ti Juda ó sì pa wọ́n run.
14 Ézéchias, roi de Juda, envoya au roi d'Assyrie, à Lakis, pour lui dire: « Je t'ai offensé. Retire-toi de moi. Ce que tu m'as imposé, je le supporterai. » Le roi d'Assyrie donna à Ézéchias, roi de Juda, trois cents talents d'argent et trente talents d'or.
Bẹ́ẹ̀ ni Hesekiah ọba Juda sì ránṣẹ́ yìí sí ọba Asiria ní Lakiṣi, wí pé, “Mo ti ṣẹ̀, padà lẹ́yìn mi: èmi yóò sì san ohunkóhun tí ìwọ bá béèrè lọ́wọ́ mi.” Ọba Asiria sì bu fún Hesekiah ọba Juda ọ̀ọ́dúnrún tálẹ́ǹtì fàdákà àti ọgbọ̀n tálẹ́ǹtì wúrà.
15 Ézéchias lui donna tout l'argent qui se trouvait dans la maison de l'Éternel et dans les trésors de la maison du roi.
Hesekiah fún un ní gbogbo fàdákà tí a rí nínú ilé Olúwa àti nínú ìṣúra ilé ọba.
16 En ce temps-là, Ézéchias, roi de Juda, enleva l'or des portes du temple de l'Éternel et des piliers qu'il avait recouverts, et le donna au roi d'Assyrie.
Ní àkókò yìí Hesekiah ọba Juda ké wúrà tí ó wà ní ẹnu ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, kúrò àti ti òpó tí Hesekiah ọba Juda ti gbéró ó sì fi fún ọba Asiria.
17 Le roi d'Assyrie envoya Tartan, Rabsaris et Rabshakeh, de Lakis, au roi Ézéchias, avec une grande armée vers Jérusalem. Ils montèrent et arrivèrent à Jérusalem. Lorsqu'ils furent montés, ils vinrent se placer près du conduit de l'étang supérieur, qui est sur la route du champ du foulon.
Ọba Asiria rán alákòóso gíga jùlọ, ìjòyè pàtàkì àti àwọn adarí pápá pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun tí ó pọ̀, láti Lakiṣi sí ọba Hesekiah ní Jerusalẹmu. Wọ́n wá sí òkè Jerusalẹmu wọ́n sì dúró ní etí ìdarí omi àbàtà òkè, ní ojú ọ̀nà tó lọ sí òpópó pápá alágbàfọ̀.
18 Lorsqu'ils eurent appelé le roi, Eliakim, fils de Hilkija, chef de la maison, Shebna, le scribe, et Joach, fils d'Asaph, l'archiviste, sortirent vers eux.
Wọ́n sì pe ọba; àti Eliakimu ọmọ Hilkiah ẹni tí í ṣe ilé olùtọ́jú, Ṣebna akọ̀wé, àti Joah ọmọkùnrin Asafu tí ó jẹ́ akọ̀wé ìrántí jáde pẹ̀lú wọn.
19 Rabschaké leur dit: « Dis à Ézéchias: Le grand roi, le roi d'Assyrie, dit: « Quelle est cette confiance en laquelle tu te confies?
Olùdarí pápá wí fún wọn pé, “Sọ fún Hesekiah pé, “‘Èyí ni ohun tí ọba ńlá, ọba Asiria sọ: Kí ni ìgbẹ́kẹ̀lé yìí tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé?
20 Tu dis, mais ce ne sont que de vaines paroles: 'Il y a un conseil et une force pour la guerre'. Or, en qui vous confiez-vous, puisque vous vous êtes révoltés contre moi?
Ìwọ wí pé ìwọ ni ìmọ̀ àti agbára láti jagun, ṣùgbọ́n ìwọ sọ̀rọ̀ òfìfo lásán. Ǹjẹ́ ta ni ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé, tí ìwọ fi ń ṣe ọ̀tẹ̀ sí mi?
21 Voici, vous vous confiez dans le bâton de ce roseau froissé, en Égypte même. Si un homme s'appuie dessus, elle entrera dans sa main et la transpercera. Il en est de même de Pharaon, roi d'Égypte, pour tous ceux qui se confient en lui.
Wò ó, nísinsin yìí, ìwọ gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti, ẹ̀rún ọ̀pá pẹlẹbẹ ìyè fífọ́ yìí, èyí tí yóò wọ inú ọwọ́ ẹni tí ó sì bá fi ara tì í. Bẹ́ẹ̀ ni Farao ọba Ejibiti ṣe rí fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
22 Mais si vous me dites: « Nous nous confions en Yahvé notre Dieu », n'est-ce pas lui dont Ezéchias a enlevé les hauts lieux et les autels, et qui a dit à Juda et à Jérusalem: « Vous vous prosternerez devant cet autel à Jérusalem »?
Tí ìwọ bá sì sọ fún mi pé, “Àwa gbẹ́kẹ̀ wa lé Olúwa Ọlọ́run.” Òun ha kọ́ ní ẹnìkan náà tí ibi gíga àti àwọn pẹpẹ tí Hesekiah mú kúrò, tí ó wí fún Juda àti Jerusalẹmu pé, “O gbọdọ̀ sìn níwájú pẹpẹ yìí ní Jerusalẹmu”?
23 Maintenant, donnez des gages à mon maître, le roi d'Assyrie, et je vous donnerai deux mille chevaux, si vous êtes capable de les monter.
“‘Wá nísinsin yìí, ṣe àdéhùn pẹ̀lú ọ̀gá mi, ọba Asiria èmi yóò sì fún ọ ní ẹgbẹ̀rún méjì ẹṣin tí ìwọ bá lè kó àwọn tí yóò gùn ún sí orí rẹ!
24 Comment pouvez-vous donc détourner le visage d'un seul des plus petits serviteurs de mon maître, et vous fier à l'Égypte pour les chars et les cavaliers?
Báwo ni ìwọ yóò ha ti ṣe le yí ojú balógun kan tí ó kéré jùlọ padà nínú àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi, tí ìwọ sì gbẹ́kẹ̀ rẹ lé Ejibiti fún àwọn kẹ̀kẹ́ àti ẹlẹ́ṣin?
25 Suis-je maintenant monté sans Yahvé contre ce lieu pour le détruire? C'est Yahvé qui m'a dit: « Monte contre ce pays, et détruis-le »".
Síwájú sí i, èmi ti wá láti mú àti láti parun ibí yìí láìsí ọ̀rọ̀ láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Olúwa fún rara rẹ̀ sọ fún mi pé kí n yára láti yan lórí ìlú yìí, kí n sì pa á run.’”
26 Alors Eliakim, fils de Hilkija, Shebna et Joach, dirent à Rabschaké: « Parle à tes serviteurs en langue syrienne, car nous la comprenons. Ne nous parle pas en langue juive, à l'oreille des gens qui sont sur la muraille. »
Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah, àti Ṣebna àti Joah sọ fún olùdarí pápá pé, “Jọ̀wọ́ sọ̀rọ̀ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ ní èdè Aramaiki, nítorí ti ó tí yé wa, má ṣe sọ̀rọ̀ fún wa pẹ̀lú èdè Heberu ní etí ìgbọ́ àwọn ènìyàn tí ń bẹ lórí odi.”
27 Mais Rabschaké leur dit: « Mon maître m'a-t-il envoyé vers votre maître et vers vous, pour vous dire ces paroles? Ne m'a-t-il pas envoyé vers les hommes assis sur la muraille, pour qu'ils mangent leurs propres excréments et boivent leur propre urine avec vous? »
Ṣùgbọ́n aláṣẹ dáhùn pé, “Ṣé fún ọ̀gá rẹ àti ìwọ nìkan ní ọ̀gá mi rán mi sí láti sọ àwọn nǹkan wọ̀nyí kì í sì í ṣe fún àwọn ọkùnrin tí ó jókòó lórí odi ni gẹ́gẹ́ bí ìwọ, ni yóò ní láti jẹ ìgbẹ́ ará wọn kí wọ́n sì mu ìtọ̀ ará wọn?”
28 Alors Rabschaké se leva et cria d'une voix forte, dans la langue des Juifs, et parla ainsi: « Écoutez la parole du grand roi, le roi d'Assyrie.
Nígbà náà, aláṣẹ dìde, ó sì pè jáde ní èdè Heberu pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ ọba ńlá, ọba Asiria!
29 Le roi dit: « Ne laissez pas Ézéchias vous tromper, car il ne pourra pas vous délivrer de sa main.
Èyí ni ohun tí ọba sọ, má ṣe jẹ́ kí Hesekiah tàn ọ́ jẹ kò le gbà ọ́ kúrò ní ọwọ́ mi.
30 Ne laissez pas Ézéchias vous faire croire en Yahvé, en disant: « Yahvé nous délivrera et cette ville ne sera pas livrée entre les mains du roi d'Assyrie. »
Ẹ má ṣe jẹ́ kí Hesekiah mú yín gbẹ́kẹ̀lé Olúwa nípa sísọ pé, ‘Olúwa yóò gbà wá nítòótọ́; ìlú yìí ni wọn kò ní fi lé ọba ìlú Asiria lọ́wọ́.’
31 N'écoutez pas Ézéchias. Car le roi d'Assyrie dit: « Faites la paix avec moi, sortez vers moi, et que chacun de vous mange de sa vigne, que chacun mange de son figuier, et que chacun boive de l'eau de sa citerne,
“Má ṣe tẹ́tí sí Hesekiah. Èyí ni ohun tí ọba Asiria wí pé, ‘Fi ẹ̀bùn wá ojúrere mi, kí o sì jáde tọ̀ mí wá.’ Nígbà náà olúkúlùkù yín yóò jẹun láti inú àjàrà rẹ̀ àti igi ọ̀pọ̀tọ́, yóò sì mu omi láti inú àmù rẹ̀,
32 jusqu'à ce que je vienne et que je vous emmène dans un pays semblable à votre pays, un pays de blé et de vin nouveau, un pays de pain et de vignes, un pays d'oliviers et de miel, afin que vous viviez et ne mouriez pas. N'écoutez pas Ézéchias quand il vous persuade en disant: « Yahvé nous délivrera. »
títí tí èmi yóò fi wá mú ọ lọ sí ilé gẹ́gẹ́ bí i tìrẹ, ilẹ̀ ọkà àti ọtí wáìnì, ilẹ̀ oúnjẹ àti ọgbà àjàrà, ilẹ̀ òróró olifi àti ti ilẹ̀ oyin; yàn ìyè má sì ṣe yàn ikú! “Kí ẹ má ṣe gbọ́ tí Hesekiah, nítorí ó ń tàn yín tí ó ba tí wí pé, ‘Olúwa yóò gbà wá?’
33 Un seul des dieux des nations a-t-il jamais délivré son pays de la main du roi d'Assyrie?
Ṣé òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè kankan ti gba ilé rẹ lọ́wọ́ àwọn ọba Asiria?
34 Où sont les dieux de Hamath et d'Arpad? Où sont les dieux de Sépharvaïm, de Héna et d'Ivva? Ont-ils délivré Samarie de ma main?
Níbo ni àwọn òrìṣà Hamati àti Arpadi gbé wà? Níbo ni àwọn òrìṣà Sefarfaimi, Hena àti Iffa gbé wà? Wọ́n ha gba Samaria kúrò lọ́wọ́ mi bí?
35 Quels sont, parmi tous les dieux des pays, ceux qui ont délivré leur pays de ma main, pour que Yahvé délivre Jérusalem de ma main?'"
Ta ni nínú gbogbo àwọn òrìṣà ilẹ̀ yìí tí ó ti gbìyànjú láti gba ilẹ̀ rẹ̀ kúrò lọ́wọ́ mi? Báwo ni Olúwa yóò ṣe gba Jerusalẹmu kúrò lọ́wọ́ mi?”
36 Mais le peuple se taisait et ne lui répondait pas un mot, car l'ordre du roi était: « Ne lui répondez pas. »
Ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ènìyàn náà dákẹ́ síbẹ̀ wọn kò sì sọ ohunkóhun, láti fi fèsì, nítorí ọba ti paláṣẹ, “Ẹ má ṣe dá a lóhùn.”
37 Alors Éliakim, fils de Hilkija, chef de la maison, vint avec Shebna, le scribe, et Joach, fils d'Asaph, l'archiviste, auprès d'Ézéchias, les vêtements déchirés, et lui rapporta les paroles de Rabschaké.
Nígbà náà Eliakimu ọmọ Hilkiah olùtọ́jú ààfin, Ṣebna akọ̀wé àti Joah ọmọ Asafu akọ̀wé ránṣẹ́ lọ sí ọ̀dọ̀ Hesekiah, pẹ̀lú aṣọ wọn yíya, ó sì wí fún un ohun tí olùdarí pápá ti sọ.

< 2 Rois 18 >