< 2 Rois 12 >

1 Joas commença à régner la septième année de Jéhu, et il régna quarante ans à Jérusalem. Le nom de sa mère était Tsibia, de Beer Schéba.
Ní ọdún keje tí Jehu, Jehoaṣi di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Sibia: Ó wá láti Beerṣeba.
2 Joas fit ce qui est droit aux yeux de Yahvé pendant toute sa vie, selon les instructions du prêtre Jehoïada.
Jehoaṣi ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa ní gbogbo ọdún tí Jehoiada àlùfáà fi àṣẹ fún un.
3 Cependant, les hauts lieux ne furent pas supprimés. Le peuple continuait à offrir des sacrifices et à brûler des parfums sur les hauts lieux.
Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò sí wọn ní ìdí, àwọn ènìyàn sì tẹ̀síwájú láti máa rú ẹbọ àti sísun tùràrí níbẹ̀.
4 Joas dit aux prêtres: « Tout l'argent des choses saintes qui est apporté dans la maison de l'Éternel, en monnaie courante, l'argent du peuple pour lequel chacun est évalué, et tout l'argent qu'il vient au cœur de chacun d'apporter dans la maison de l'Éternel,
Jehoaṣi sọ fún àwọn àlùfáà pé, “Gba gbogbo owó tí wọ́n mú wá gẹ́gẹ́ bí ọrẹ mímọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa owó tí a gbà ní ìgbà kíka àwọn ènìyàn ìlú, owó tí a gbà láti ọwọ́ olúkúlùkù bí wọ́n ti ṣe jẹ́ ẹ̀yà àti owó tí ó ti ọkàn olúkúlùkù wá tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
5 que les prêtres le leur apportent, chacun de son donateur; et ils répareront les dégâts de la maison, partout où il y en aura. »
Jẹ́ kí gbogbo àlùfáà gba owó náà lọ́wọ́ ọ̀kan nínú àwọn akápò. Kí a sì lò ó fún tuntun ohunkóhun tí ó bá bàjẹ́ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.”
6 Mais il arriva qu'en la vingt-troisième année du roi Joas, les prêtres n'avaient pas réparé les dégâts de la maison.
Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹtàlélógún ọba Jehoaṣi, àwọn àlùfáà kò ì tí ì tún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.
7 Alors le roi Joas appela le prêtre Jehoïada et les autres prêtres, et leur dit: « Pourquoi ne réparez-vous pas les dégâts de la maison? Ne prenez donc plus d'argent de vos trésors, mais livrez-le pour réparer les dégâts de la maison. »
Nígbà náà, ọba Jehoaṣi pe Jehoiada àlùfáà àti àwọn àlùfáà yòókù, ó sì bi wọ́n pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin kò fi tún ìbàjẹ́ tí a ṣe sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe? Ẹ má ṣe gba owó mọ́ lọ́wọ́ àwọn afowópamọ́, ṣùgbọ́n ẹ gbé e kalẹ̀ fún títún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe.”
8 Les prêtres consentirent à ne plus prendre d'argent du peuple et à ne pas réparer les dégâts de la maison.
Àwọn àlùfáà fi ara mọ́ pé wọn kò nígbà owó kankan mọ́ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ sì ni, wọn kò sì ní tún ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe mọ́ fúnra wọn.
9 Mais le prêtre Jehoïada prit un coffre, perça un trou dans son couvercle et le plaça à côté de l'autel, à droite en entrant dans la maison de l'Éternel; et les prêtres qui gardaient le seuil y mirent tout l'argent qu'on apportait dans la maison de l'Éternel.
Jehoiada àlùfáà mú àpótí kan, ó sì lu ihò sí ìdérí rẹ̀. Ó gbé e sí ẹ̀gbẹ́ pẹpẹ ní apá ọ̀tún bí ẹnìkan ti wọlé tí a kọ́ fún Olúwa. Àwọn àlùfáà tí ó ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé fi sínú àpótí náà gbogbo owó tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
10 Lorsqu'ils virent qu'il y avait beaucoup d'argent dans le coffre, le scribe du roi et le grand prêtre montèrent, mirent tout dans des sacs et comptèrent l'argent qui se trouvait dans la maison de l'Éternel.
Ìgbàkígbà tí wọ́n bá ti rí wí pé owó púpọ̀ wà nínú àpótí, akọ̀wé ọba àti olórí àlùfáà yóò wá, wọ́n á ka owó náà tí wọ́n ti mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Wọn a sì kó o sínú àwọn àpò.
11 Ils remirent l'argent pesé entre les mains de ceux qui travaillaient, qui avaient la surveillance de la maison de l'Éternel, et ils le payèrent aux charpentiers et aux constructeurs qui travaillaient à la maison de l'Éternel,
Nígbà tí wọ́n bá ti pinnu iye rẹ̀, wọn a kó owó náà fún àwọn tí a ti yàn láti bojútó iṣẹ́ náà lórí ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Pẹ̀lú u rẹ̀, wọ́n sọ fún àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ lórí ilé tí a kọ́ fún Olúwa; àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùkọ́lé.
12 aux maçons et aux tailleurs de pierre, pour l'achat de bois et de pierres taillées afin de réparer les dégâts causés à la maison de l'Éternel, et pour tout ce qui était prévu pour réparer la maison.
Àwọn ilé ńlá àti àwọn agékúta. Wọ́n ra igi gẹdú àti òkúta tí wọ́n tọ́jú fún tuntun ilé tí a kọ́ fún Olúwa ṣe. Wọ́n tún ohun gbogbo tí wọ́n ná fún títún tẹmpili ṣe.
13 Mais on ne fit pas pour la maison de l'Éternel de coupes d'argent, d'éteignoirs, de bassins, de trompettes, ni d'ustensiles d'or ou d'argent, avec l'argent qu'on apportait dans la maison de l'Éternel;
Owó tí a mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa kò jẹ́ níná fún ṣíṣe òpó fàdákà, ohun èlò ta fi ń fa ẹnu fìtílà, àwokòtò, ìpè, ohun èlò wúrà tàbí ohun èlò fàdákà kan fún ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
14 car on le donnait à ceux qui faisaient le travail, et on réparait la maison de l'Éternel avec cet argent.
A sì san án fún àwọn ọkùnrin tí ó ń ṣiṣẹ́, tí wọ́n ń tọ́jú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
15 De plus, ils ne demandèrent pas de comptes aux hommes entre les mains desquels ils remettaient l'argent pour le donner à ceux qui faisaient le travail, car ils étaient fidèles.
Wọn kò sì bá àwọn ọkùnrin náà ṣírò, ní ọwọ́ ẹni tí wọ́n fún ní owó láti san fún àwọn òṣìṣẹ́. Torí wọ́n ṣe é pẹ̀lú òdodo tí ó pé.
16 L'argent des offrandes pour le délit et l'argent des offrandes pour le péché n'était pas apporté dans la maison de l'Éternel. Il appartenait aux prêtres.
Owó láti ibi ọrẹ ẹ̀bi àti ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ ní a kò mú wá sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa, ó jẹ́ ti àwọn àlùfáà.
17 Alors Hazaël, roi de Syrie, monta et combattit contre Gath, et la prit; et Hazaël se mit en tête de monter à Jérusalem.
Ní déédé àkókò yìí, Hasaeli ọba Siria gòkè lọ láti dojúkọ Gati àti láti fi agbára mú un. Nígbà náà, ó yípadà láti dojúkọ Jerusalẹmu.
18 Joas, roi de Juda, prit toutes les choses saintes que Josaphat, Joram et Achazia, ses pères, rois de Juda, avaient consacrées, et ses propres choses saintes, et tout l'or qui se trouvait dans les trésors de la maison de l'Éternel et de la maison du roi, et il l'envoya à Hazaël, roi de Syrie; et il s'éloigna de Jérusalem.
Ṣùgbọ́n Jehoaṣi ọba Juda mú gbogbo ohun mímọ́ tí a gbé ka iwájú tí a yà sọ́tọ̀ nípasẹ̀ baba rẹ̀ Jehoṣafati, Jehoramu àti Ahasiah, àwọn ọba Juda, àti àwọn ẹ̀bùn tí òun tìkára rẹ̀ ti yà sọ́tọ̀ àti gbogbo wúrà, tí ó rí nínú ibi ìfowópamọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa àti ní ti ààfin ọba, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Hasaeli; ọba Siria, tí ó sì fà padà kúrò ní Jerusalẹmu.
19 Le reste des actes de Joas, et tout ce qu'il a fait, cela n'est-il pas écrit dans le livre des Chroniques des rois de Juda?
Pẹ̀lú ìyókù ìṣe Joaṣi, àti ohun gbogbo tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
20 Ses serviteurs se levèrent et formèrent une conspiration, et ils frappèrent Joas à la maison de Millo, sur le chemin qui descend à Silla.
Àwọn oníṣẹ́ rẹ̀ dìtẹ̀ sí i wọ́n sì lù ú pa ní Beti-Milo ní ọ̀nà sí Silla.
21 Jozacar, fils de Shimeath, et Jehozabad, fils de Shomer, ses serviteurs, le frappèrent, et il mourut; on l'enterra avec ses pères dans la ville de David, et Amatsia, son fils, régna à sa place.
Àwọn oníṣẹ́ tí ó pa á jẹ́ Josabadi ọmọ Ṣimeati àti Jehosabadi ọmọ Ṣomeri. Ó kú, wọ́n sì sin ín pẹ̀lú baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Dafidi. Amasiah ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< 2 Rois 12 >