< 2 Rois 11 >
1 Et lorsque Athalie, mère d'Achazia, vit que son fils était mort, elle se leva et fit périr toute la descendance royale.
Nígbà tí Ataliah ìyá Ahasiah rí i wí pé ọmọ rẹ̀ ti kú, ó tẹ̀síwájú láti pa gbogbo ìdílé ọba náà run.
2 Mais Jéhoschéba, fille du roi Joram, sœur d'Achazia, prit Joas, fils d'Achazia, et l'enleva du milieu des fils du roi qui avaient été tués, lui et sa nourrice, et les mit dans la chambre à coucher; et elles le cachèrent à Athalie, afin qu'il ne fût pas tué.
Ṣùgbọ́n Jehoṣeba ọmọbìnrin ọba Jehoramu àti arábìnrin Ahasiah, mú Joaṣi ọmọ Ahasiah, ó sì jí i lọ kúrò láàrín àwọn ọmọ-aládébìnrin ti ọba náà, tí ó kù díẹ̀ kí a pa. Ó gbé òhun àti olùtọ́jú rẹ̀ sínú ìyẹ̀wù láti fi pamọ́ kúrò fún Ataliah; bẹ́ẹ̀ ni a kò pa á.
3 Il resta caché avec elle dans la maison de Yahvé pendant six ans, pendant qu'Athalie régnait sur le pays.
Ó wà ní ìpamọ́ pẹ̀lú olùtọ́jú ní ilé tí a kọ́ fún Olúwa fún ọdún mẹ́fà nígbà tí Ataliah fi jẹ ọba lórí ilẹ̀ náà.
4 La septième année, Jehojada envoya chercher les chefs de centaines de Carites et de la garde, et les fit venir auprès de lui dans la maison de l'Éternel; il fit alliance avec eux, dans la maison de l'Éternel, et leur montra le fils du roi.
Ní ọdún keje, Jehoiada ránṣẹ́ ó sí mú àwọn olórí lórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, pẹ̀lú àwọn balógun àti àwọn olùṣọ́, ó sì mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Ó ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú wọn, ó sì fi wọ́n sí abẹ́ ìbúra nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Níbẹ̀ ni ó fi ọmọkùnrin ọba hàn wọ́n.
5 Il leur donna cet ordre: « Voici ce que vous devez faire: un tiers d'entre vous, qui entre le jour du sabbat, sera chargé de la garde de la maison du roi;
Ó pàṣẹ fún wọn, wí pé, “Ìwọ tí ó wà nínú àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ń lọ fún iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi—ìdámẹ́ta yín fún ṣíṣọ́ ààfin ọba.
6 un tiers d'entre vous sera à la porte Sur; et un tiers d'entre vous à la porte derrière la garde. Vous veillerez ainsi sur la maison, et vous formerez une barrière.
Ìdámẹ́ta ní ẹnu ìlẹ̀kùn huri, àti ìdámẹ́ta ní ẹnu ìlẹ̀kùn ní ẹ̀yìn olùṣọ́, tí ó yípadà ní ṣíṣọ́ ilé tí a kọ́,
7 Les deux compagnies d'entre vous, tous ceux qui sortent le jour du sabbat, surveilleront la maison de l'Éternel autour du roi.
àti ẹ̀yin tí ó wà ní ẹgbẹ́ kejì yòókù tí kì í lọ ibi iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi gbogbo ni kí ó ṣọ́ ilé tí a kọ́ fún Olúwa fún ọba.
8 Vous entourerez le roi, chacun l'arme à la main, et celui qui entrera dans les rangs sera tué. Soyez avec le roi quand il sortira et quand il entrera. »
Ẹ mú ibùjókòó yín yí ọba ká, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀. Ẹnikẹ́ni tí ó bá súnmọ́ ọgbà yìí gbọdọ̀ kú. Ẹ dúró súnmọ́ ọba ní ibikíbi tí ó bá lọ.”
9 Les chefs de centaines firent tout ce que le prêtre Jehojada avait ordonné; ils prirent chacun leurs hommes, ceux qui devaient entrer le jour du sabbat et ceux qui devaient sortir le jour du sabbat, et ils vinrent auprès du prêtre Jehojada.
Olórí àwọn ọ̀rọ̀ọ̀rún ṣe gẹ́gẹ́ bí Jehoiada àlùfáà ti pa á láṣẹ. Olúkúlùkù mú àwọn ọkùnrin rẹ̀ àwọn tí ó ń lọ sí iṣẹ́ ìsìn ní ọjọ́ ìsinmi àti àwọn tí wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Jehoiada àlùfáà.
10 Le prêtre remit aux chefs de centaines les lances et les boucliers qui avaient appartenu au roi David et qui se trouvaient dans la maison de l'Éternel.
Nígbà náà, ó fún àwọn olórí ní àwọn ọ̀kọ̀ àti àwọn àpáta tí ó ti jẹ́ ti ọba Dafidi tí ó sì wà nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
11 La garde se tenait, chacun l'arme à la main, depuis le côté droit de la maison jusqu'au côté gauche de la maison, le long de l'autel et de la maison, autour du roi.
Àwọn olùṣọ́, olúkúlùkù pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀, wọ́n sì dúró ṣinṣin yìí ọba ká—lẹ́bàá pẹpẹ àti ilé ìhà gúúsù sí ìhà àríwá ilé tí a kọ́ fun Olúwa náà.
12 Alors on fit sortir le fils du roi, on lui mit la couronne et on lui donna l'alliance; on le fit roi et on l'oignit; on battit des mains et on dit: « Vive le roi! »
Jehoiada mú ọmọkùnrin ọba jáde, ó sì gbé adé náà lé e: ó fún un ní ẹ̀dà májẹ̀mú, wọ́n sì kéde ọba rẹ̀. Wọ́n fi àmì òróró yàn án, àwọn ènìyàn pa àtẹ́wọ́, wọ́n sì kígbe, “Kí ẹ̀mí ọba kí ó gùn.”
13 Lorsqu'Athalie entendit le bruit de la garde et du peuple, elle entra avec le peuple dans la maison de l'Éternel.
Nígbà tí Ataliah gbọ́ ariwo tí àwọn olùṣọ́ àti àwọn ènìyàn ń pa, ó lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
14 Elle regarda, et voici, le roi se tenait près de la colonne, selon la tradition, avec les chefs et les trompettes près du roi; et tout le peuple du pays se réjouissait et sonnait des trompettes. Alors Athalie déchira ses vêtements et s'écria: « Trahison! Trahison! »
Ó wò ó, níbẹ̀ ni ọba, tí ó dúró lẹ́bàá òpó, gẹ́gẹ́ bí àṣà ti rí. Àwọn balógun àti àwọn afùnpè wà ní ẹ̀bá ọba, gbogbo àwọn ènìyàn ilé náà sì ń yọ̀, wọ́n sì ń fun ìpè pẹ̀lú. Nígbà náà Ataliah fa aṣọ ìgúnwà rẹ̀ ya. Ó sì kégbe pé, “Ọ̀tẹ̀! Ọ̀tẹ̀!”
15 Le prêtre Jehoïada donna des ordres aux chefs de centaines qui étaient à la tête de l'armée, et leur dit: « Faites-la sortir entre les rangs. Tuez par l'épée tous ceux qui la suivent. » Car le prêtre avait dit: « Qu'elle ne soit pas tuée dans la maison de l'Éternel. »
Jehoiada àlùfáà pàṣẹ fún olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, ta ni ó wà ní ìkáwọ́ ọ̀wọ́ ogun: “Mú u jáde láàrín àwọn ẹgbẹ́ ogun yìí kí o sì fi sí ipa idà ẹnikẹ́ni tí ó bá tẹ̀lé.” Nítorí àlùfáà ti sọ, “A kò gbọdọ̀ pa á nínú ilé tí a kọ́ fún Olúwa.”
16 Ils s'emparèrent donc d'elle; elle passa par le chemin d'entrée des chevaux dans la maison du roi, et c'est là qu'elle fut tuée.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n fi agbára mú un bí ó ti dé ibi tí àwọn ẹṣin tí ń wọ ilẹ̀ ààfin ọba àti níbẹ̀ ni a ti pa á.
17 Jehojada fit une alliance entre l'Éternel, le roi et le peuple, pour qu'ils soient le peuple de l'Éternel, et entre le roi et le peuple.
Nígbà náà ni Jehoiada dá májẹ̀mú láàrín Olúwa àti ọba àti àwọn ènìyàn tí yóò jẹ́ ènìyàn Olúwa. Ó dá májẹ̀mú láàrín ọba àti àwọn ènìyàn pẹ̀lú.
18 Tout le peuple du pays se rendit à la maison de Baal et la démolit. Ils brisèrent complètement ses autels et ses images, et ils tuèrent Mattan, le prêtre de Baal, devant les autels. Le prêtre nomma des officiers sur la maison de Yahvé.
Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà lọ sí ilé tí a kọ́ fún òrìṣà Baali wọ́n sì ya á bolẹ̀. Wọ́n fọ́ àwọn pẹpẹ àti òrìṣà sí wẹ́wẹ́. Wọ́n sì pa Mattani àlùfáà Baali níwájú àwọn pẹpẹ. Nígbà náà, Jehoiada àlùfáà náà sì yan àwọn olùṣọ́ sí ilé tí a kọ́ fún Olúwa.
19 Il prit les chefs de centaines, les Carites, les gardes et tout le peuple du pays; ils firent descendre le roi de la maison de l'Éternel et vinrent par le chemin de la porte des gardes à la maison du roi. Il s'assit sur le trône des rois.
Ó mú pẹ̀lú u rẹ̀ àwọn olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún àti gbogbo balógun àti àwọn olùṣọ́ àti gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà àti lápapọ̀, wọ́n mú ọba sọ̀kalẹ̀ wá láti ilé tí a kọ́ fún Olúwa. Wọ́n sì wọ inú ààfin lọ, wọ́n sì wọlé nípa ìlẹ̀kùn ti àwọn olùṣọ́. Ọba sì mú ààyè rẹ̀ ní orí ìtẹ́ ọba.
20 Tout le peuple du pays se réjouissait, et la ville était tranquille. Ils avaient tué Athalie par l'épée à la maison du roi.
Gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà sì yọ̀, ìlú náà sì dákẹ́ jẹ́ẹ́. Nítorí a pa Ataliah pẹ̀lú idà náà ní ààfin ọba.
21 Joas était âgé de sept ans lorsqu'il commença à régner.
Joaṣi jẹ́ ọmọ ọdún méje nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ ìjọba rẹ̀.