< Psalmien 105 >
1 Kiittäkää Herraa, julistakaa hänen nimeänsä, tehkää hänen suuret tekonsa tiettäviksi kansojen keskuudessa.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Laulakaa hänelle, veisatkaa hänelle, puhukaa kaikista hänen ihmeistänsä.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Hänen pyhä nimensä olkoon teidän kerskauksenne; iloitkoon niiden sydän, jotka etsivät Herraa.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Kysykää Herraa ja hänen voimaansa, etsikää alati hänen kasvojansa.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Muistakaa hänen ihmetöitänsä, jotka hän on tehnyt, hänen ihmeitänsä ja hänen suunsa tuomioita,
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 te Aabrahamin, hänen palvelijansa, siemen, Jaakobin lapset, te hänen valittunsa.
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Hän, Herra, on meidän Jumalamme; hänen tuomionsa käyvät yli kaiken maan.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Hän muistaa liittonsa iankaikkisesti, säätämänsä sanan hamaan tuhansiin polviin,
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 liittonsa, jonka hän teki Aabrahamin kanssa, ja Iisakille vannomansa valan.
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 Hän vahvisti sen käskyksi Jaakobille, Israelille iankaikkiseksi liitoksi.
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Hän sanoi: "Sinulle minä annan Kanaanin maan, se olkoon teidän perintöosanne".
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Heitä oli vähäinen joukko, vain harvoja, ja he olivat muukalaisia siellä.
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Ja he vaelsivat kansasta kansaan ja yhdestä valtakunnasta toiseen kansaan.
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Hän ei sallinut kenenkään heitä vahingoittaa, ja hän rankaisi kuninkaita heidän tähtensä:
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 "Älkää koskeko minun voideltuihini, älkää tehkö pahaa minun profeetoilleni".
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Ja kun hän kutsui nälänhädän maahan ja kokonaan mursi leivän tuen,
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 oli hän lähettänyt heidän edellänsä miehen: Joosef oli myyty orjaksi.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Hänen jalkojansa vaivattiin kahleilla, hän joutui rautoihin,
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 siksi kunnes hänen sanansa kävi toteen ja Herran puhe osoitti hänet puhtaaksi.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Niin kuningas lähetti ja päästätti hänet, kansojen hallitsija laski hänet irti.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Hän pani hänet talonsa herraksi ja kaiken omaisuutensa haltijaksi,
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 sitomaan mielensä mukaan hänen ruhtinaitansa ja opettamaan viisautta vanhimmille.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Niin joutui Israel Egyptiin, Jaakob muukalaiseksi Haamin maahan.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Ja Herra teki kansansa hyvin hedelmälliseksi ja väkevämmäksi heidän vihamiehiänsä.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Hän käänsi näitten sydämen vihaamaan hänen kansaansa, kavalasti kohtelemaan hänen palvelijoitaan.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Hän lähetti Mooseksen, palvelijansa, ja Aaronin, jonka hän oli valinnut.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Nämä tekivät hänen tunnustekonsa heidän keskellään, tekivät ihmeitä Haamin maassa.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Hän lähetti pimeyden ja pimensi kaiken, eivätkä he vastustaneet hänen sanojansa.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Hän muutti heidän vetensä vereksi ja kuoletti heiltä kalat.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Heidän maansa vilisi sammakoita aina kuningasten kammioita myöten.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Hän käski, ja paarmoja tuli ja sääskiä koko heidän alueellensa.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Hän antoi heille rakeita sateen sijaan, tulen leimauksia heidän maahansa.
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Ja hän hävitti heidän viini-ja viikunapuunsa ja murskasi puut heidän alueeltansa.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Hän käski, ja heinäsirkkoja tuli ja tuhosirkkoja lukematon joukko;
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 ne söivät kaiken ruohon heidän maastansa, söivät hedelmän heidän vainioiltansa.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Ja hän surmasi kaikki heidän maansa esikoiset, kaikki heidän miehuutensa ensimmäiset.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Sitten hän vei Israelin sieltä varustettuna hopealla ja kullalla, eikä ollut hänen sukukunnissaan kompastuvaista.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Egypti iloitsi heidän lähdöstänsä, koska sen oli vallannut pelko heidän tähtensä.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Hän levitti suojaksi pilven ja tulen valaisemaan yötä.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 He pyysivät, ja hän pani tulemaan viiriäiset, ja hän ravitsi heitä taivaan leivällä.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Hän avasi kallion, ja vettä vuoti; se juoksi virtana kautta erämaan.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Sillä hän muisti pyhän sanansa, muisti Aabrahamia, palvelijaansa.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Niin hän vei kansansa pois sen iloitessa, valittunsa heidän riemuitessaan.
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 Ja hän antoi heille pakanain maat, ja he ottivat omaksensa kansojen vaivannäöt,
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 että he noudattaisivat hänen käskyjänsä ja ottaisivat hänen laeistansa vaarin. Halleluja!
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.