< Jobin 3 >

1 Senjälkeen Job avasi suunsa ja kirosi syntymäpäivänsä;
Ẹ̀yìn èyí ní Jobu yanu, ó sì fi ọjọ́ ìbí rẹ̀ ré
2 Job lausui ja sanoi:
Jobu sọ, ó sì wí pé,
3 "Kadotkoon se päivä, jona minä synnyin, ja se yö, joka sanoi: 'Poika on siinnyt'.
“Kí ọjọ́ tí a bí mi kí ó di ìgbàgbé, àti òru ni, nínú èyí tí a wí pé, ‘A lóyún ọmọkùnrin kan!’
4 Se päivä muuttukoon pimeydeksi; älköön Jumala korkeudessa sitä kysykö, älköönkä valonsäde sille paistako.
Kí ọjọ́ náà kí ó já si òkùnkùn, kí Ọlọ́run kí ó má ṣe kà á sí láti ọ̀run wá; bẹ́ẹ̀ ni kí ìmọ́lẹ̀ kí ó má ṣe mọ́ sí i.
5 Omistakoon sen pimeys ja pilkkopimeä, pilvi laskeutukoon sen päälle, peljästyttäkööt sitä päivänpimennykset.
Kí òkùnkùn àti òjìji ikú fi ṣe ti ara wọn; kí àwọsánmọ̀ kí ó bà lé e; kí ìṣúdudu ọjọ́ kí ó pa láyà.
6 Sen yön ryöstäköön pimeys; älköön se iloitko vuoden päivien parissa, älköön tulko kuukausien lukuun.
Kí òkùnkùn kí ó ṣú bo òru náà biribiri, kí ó má ṣe yọ pẹ̀lú ọjọ́ ọdún náà: kí a má ṣe kà a mọ́ iye ọjọ́ oṣù.
7 Katso, hedelmätön olkoon se yö, älköön siinä riemuhuuto raikuko.
Kí òru náà kí ó yàgàn; kí ohun ayọ̀ kan kí ó má ṣe wọ inú rẹ̀ lọ.
8 Kirotkoot sen päivänmanaajat, ne, jotka saavat hereille Leviatanin.
Kí àwọn tí í fi ọjọ́ gégùn ún kí o fi gégùn ún, tí wọ́n mura tán láti ru Lefitani sókè.
9 Pimentykööt sen kointähdet, odottakoon se valoa, joka ei tule, älköön se aamuruskon silmäripsiä nähkö,
Kí ìràwọ̀ òwúrọ̀ ọjọ́ rẹ̀ kí ó ṣókùnkùn; kí ó má wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n kí ó máa mọ́ sí i, bẹ́ẹ̀ ni kí ó má ṣe rí àfẹ̀mọ́júmọ́
10 koska se ei sulkenut minulta kohdun ovia eikä kätkenyt vaivaa minun silmiltäni.
nítorí tí kò sé ìlẹ̀kùn inú ìyá mi, láti pa ìbànújẹ́ rẹ́ ní ojú mi.
11 Miksi en kuollut heti äidin helmaan, miksi en menehtynyt kohdusta tullessani?
“Èéṣe tí èmi kò fi kú láti inú wá, tàbí tí èmi kò kú ní ìgbà tí mo ti inú jáde wá?
12 Miksi olivat minua vastaanottamassa polvet, minkätähden rinnat imeäkseni?
Èéṣe tí orúnkún wá pàdé mi, tàbí ọmú tí èmi yóò mu?
13 Sillä makaisinhan rauhassa silloin, nukkuisin ja saisin levätä
Ǹjẹ́ nísinsin yìí èmi ìbá ti dùbúlẹ̀ jẹ́ẹ́; èmi ìbá ti sùn, èmi ìbá ti sinmi
14 kuningasten ja maan neuvosmiesten kanssa, jotka ovat rakentaneet itselleen pyramiideja,
pẹ̀lú àwọn ọba àti ìgbìmọ̀ ayé tí wọ́n mọ ilé fún ara wọn wá dùbúlẹ̀ nínú ìsọdahoro.
15 päämiesten kanssa, joilla on ollut kultaa, jotka ovat täyttäneet talonsa hopealla;
Tàbí pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé tí ó ní wúrà, tí wọ́n sì fi fàdákà kun ilé wọn.
16 tahi olisin olematon niinkuin maahan kätketty keskoinen, niinkuin sikiöt, jotka eivät ole päivänvaloa nähneet.
Tàbí bí ọlẹ̀ tí a sin, èmi kì bá ti sí: bí ọmọ ìṣunú tí kò rí ìmọ́lẹ̀?
17 Siellä lakkaavat jumalattomat raivoamasta, siellä saavat uupuneet levätä;
Níbẹ̀ ni ẹni búburú ṣíwọ́ ìyọnilẹ́nu, níbẹ̀ ni ẹni àárẹ̀ wà nínú ìsinmi.
18 kaikki vangit ovat rauhassa, eivät kuule käskijän ääntä.
Níbẹ̀ ni àwọn ìgbèkùn sinmi pọ̀, wọn kò gbóhùn amúnisìn mọ́.
19 Yhtäläiset ovat siellä pieni ja suuri, orja on vapaa herrastansa.
Àti èwe àti àgbà wà níbẹ̀, ẹrú sì di òmìnira kúrò lọ́wọ́ olówó rẹ̀.
20 Miksi hän antaa vaivatulle valoa ja elämää murhemielisille,
“Nítorí kí ni a ṣe fi ìmọ́lẹ̀ fún òtòṣì, àti ìyè fún ọlọ́kàn kíkorò,
21 jotka odottavat kuolemaa, eikä se tule, jotka etsivät sitä enemmän kuin aarretta,
tí wọ́n dúró de ikú, ṣùgbọ́n òun kò wá, tí wọ́n wá a jù ìṣúra tí a bò mọ́lẹ̀ pamọ́ lọ.
22 jotka iloitsisivat riemastuksiin asti, riemuitsisivat, jos löytäisivät haudan-
Ẹni tí ó yọ̀ gidigidi, tí inú wọ́n sì dùn nígbà tí wọ́n wá ibojì òkú rí?
23 miehelle, jonka tie on ummessa, jonka Jumala on aitaukseen sulkenut?
Kí ni a fi ìmọ́lẹ̀ fún ẹni tí ọ̀nà rẹ̀ fi ara pamọ́ fún, tí Ọlọ́run sì ṣọgbà dí mọ́ ká?
24 Sillä huokaukseni on tullut minun leiväkseni, valitukseni valuu kuin vesi.
Nítorí pé èémí-ẹ̀dùn wà ṣáájú oúnjẹ mi; ìkérora mi sì tú jáde bí omi.
25 Sillä mitä minä kauhistuin, se minua kohtasi, ja mitä minä pelkäsin, se minulle tapahtui.
Nítorí pé ohun náà tí mo bẹ̀rù gidigidi ni ó dé bá mi yìí, àti ohun tí mo fòyà rẹ̀ bá mi ó sì ṣubú lù mí.
26 Ennenkuin tyynnyin, rauhan ja levon sain, tuli tuska jälleen."
Èmi wà láìní àlàáfíà, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ní ìsinmi; bẹ́ẹ̀ ni èmi kò ni ìfàyàbalẹ̀, bí kò ṣe ìdààmú.”

< Jobin 3 >