< Jesajan 37 >
1 Kun kuningas Hiskia sen kuuli, repäisi hän vaatteensa, pukeutui säkkiin ja meni Herran temppeliin.
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
2 Ja hän lähetti palatsin päällikön Eljakimin ja kirjuri Sebnan sekä pappein vanhimmat, säkkeihin puettuina, profeetta Jesajan, Aamoksen pojan, tykö.
Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 Ja he sanoivat hänelle: "Näin sanoo Hiskia: 'Hädän, kurituksen ja häväistyksen päivä on tämä päivä, sillä lapset ovat tulleet kohdun suulle saakka, mutta ei ole voimaa synnyttää.
Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
4 Ehkä Herra, sinun Jumalasi, kuulee Rabsaken sanat, joilla hänen Herransa, Assurin kuningas, on lähettänyt hänet herjaamaan elävää Jumalaa, ja rankaisee häntä näistä sanoista, jotka Herra, sinun Jumalasi, on kuullut. Niin kohota nyt rukous jäännöksen puolesta, joka vielä on olemassa.'"
Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
5 Kun kuningas Hiskian palvelijat tulivat Jesajan tykö,
Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 sanoi Jesaja heille: "Sanokaa näin herrallenne: 'Näin sanoo Herra: Älä pelkää niitä sanoja, jotka olet kuullut ja joilla Assurin kuninkaan poikaset ovat häväisseet minua.
Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Katso, minä annan häneen mennä sellaisen hengen, että hän kuultuaan sanoman palajaa omaan maahansa; ja minä annan hänen kaatua miekkaan omassa maassansa.'"
Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 Ja Rabsake kääntyi takaisin ja tapasi Assurin kuninkaan sotimassa Libnaa vastaan; sillä hän oli kuullut, että tämä oli lähtenyt Laakiista pois.
Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
9 Mutta kun Sanherib kuuli Tirhakasta, Etiopian kuninkaasta, sanottavan: "Hän on lähtenyt liikkeelle sotiakseen sinua vastaan", niin hän sen kuultuaan lähetti sanansaattajat Hiskian tykö ja käski sanoa:
Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
10 "Sanokaa näin Hiskialle, Juudan kuninkaalle: 'Älä anna Jumalasi, johon sinä luotat, pettää itseäsi äläkä ajattele: Jerusalem ei joudu Assurin kuninkaan käsiin.
“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
11 Olethan kuullut, mitä Assurin kuninkaat ovat tehneet kaikille maille, kuinka he ovat vihkineet ne tuhon omiksi. Ja sinäkö pelastuisit!
Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
12 Ovatko kansain jumalat pelastaneet niitä, jotka minun isäni ovat tuhonneet: Goosania, Harrania, Resefiä ja Telassarin edeniläisiä?
Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Missä on Hamatin kuningas ja Arpadin kuningas, Sefarvaimin kaupungin, Heenan ja Ivvan kuningas?'"
Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
14 Kun Hiskia oli ottanut kirjeen sanansaattajilta ja lukenut sen, meni hän Herran temppeliin; ja Hiskia levitti sen Herran eteen.
Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15 Ja Hiskia rukoili Herraa ja sanoi:
Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
16 "Herra Sebaot, Israelin Jumala, jonka valtaistuinta kerubit kannattavat, sinä yksin olet maan kaikkien valtakuntain Jumala; sinä olet tehnyt taivaan ja maan.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17 Herra, kallista korvasi ja kuule; Herra, avaa silmäsi ja katso. Kuule kaikki Sanheribin sanat, jotka hän lähetti herjatakseen elävää Jumalaa.
Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
18 Se on totta, Herra, että Assurin kuninkaat ovat hävittäneet kaikki maat ja omankin maansa.
“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
19 Ja he ovat heittäneet niiden jumalat tuleen; sillä ne eivät olleet jumalia, vaan ihmiskätten tekoa, puuta ja kiveä, ja sentähden he voivat hävittää ne.
Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
20 Mutta pelasta nyt meidät, Herra, meidän Jumalamme, hänen käsistänsä, että kaikki maan valtakunnat tulisivat tietämään, että sinä, Herra, olet ainoa."
Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
21 Niin Jesaja, Aamoksen poika, lähetti Hiskialle tämän sanan: "Näin sanoo Herra, Israelin Jumala: Koska sinä olet rukoillut minua avuksi Sanheribia, Assurin kuningasta, vastaan,
Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
22 niin tämä on se sana, jonka Herra on puhunut hänestä: Neitsyt, tytär Siion, halveksii ja pilkkaa sinua; tytär Jerusalem nyökyttää ilkkuen päätänsä sinun jälkeesi.
èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
23 Ketä olet herjannut ja häväissyt, ja ketä vastaan olet korottanut äänesi? Korkealle olet kohottanut silmäsi Israelin Pyhää vastaan.
Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
24 Palvelijaisi kautta sinä herjasit Herraa ja sanoit: 'Monilla vaunuillani minä nousin vuorten harjalle, Libanonin ääriin saakka; minä hakkasin maahan sen korkeat setrit, sen parhaat kypressit ja tunkeuduin sen etäisimmälle harjalle, sen rehevimpään metsään;
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
25 minä kaivoin kaivoja ja join kuiviin vedet, ja jalkapohjallani minä kuivasin kaikki Egyptin virrat'.
Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
26 Etkö ole kuullut: kauan sitten minä olen tätä valmistanut, muinaisuudesta saakka tätä aivoitellut! Nyt minä olen sen toteuttanut, ja niin sinä sait hävittää varustetut kaupungit autioiksi kiviroukkioiksi,
“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
27 ja niiden asukkaat olivat voimattomat, he kauhistuivat ja joutuivat häpeään; heidän kävi niinkuin kedon ruohon ja niinkuin vihannan heinän, niinkuin katolla kasvavain kortten ja niinkuin laihon ennen oljelle tulemistaan.
Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
28 Istuitpa sinä tai lähdit tai tulit, minä sen tiedän, niinkuin senkin, että sinä raivoat minua vastaan.
“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
29 Koska sinä minua vastaan raivoat ja koska sinun ylpeytesi on tullut minun korviini, niin minä panen koukkuni sinun nenääsi ja suitseni sinun suuhusi ja vien sinut takaisin samaa tietä, jota tulitkin.
Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
30 Ja tämä on oleva sinulle merkkinä: tänä vuonna syödään jälkikasvua ja toisena vuonna kesanto-aaluvaa, mutta kolmantena vuonna te kylväkää ja leikatkaa, istuttakaa viinitarhoja ja syökää niiden hedelmää.
“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
31 Ja Juudan heimon pelastuneet, jotka ovat jäljelle jääneet, tekevät taas juurta alaspäin ja hedelmää ylöspäin.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
32 Sillä Jerusalemista lähtee kasvamaan jäännös, pelastunut joukko Siionin vuorelta. Herran Sebaotin kiivaus on sen tekevä.
Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33 Sentähden, näin sanoo Herra Assurin kuninkaasta: Hän ei tule tähän kaupunkiin eikä siihen nuolta ammu, ei tuo sitä vastaan kilpeä eikä luo sitä vastaan vallia.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34 Samaa tietä, jota hän tuli, hän palajaa, ja tähän kaupunkiin hän ei tule, sanoo Herra.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
35 Sillä minä varjelen tämän kaupungin ja pelastan sen itseni tähden ja palvelijani Daavidin tähden."
“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
36 Niin Herran enkeli lähti ja löi Assurin leirissä sata kahdeksankymmentä viisi tuhatta miestä, ja kun noustiin aamulla varhain, niin katso, he olivat kaikki kuolleina ruumiina.
Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
37 Silloin Sanherib, Assurin kuningas, lähti liikkeelle ja meni pois; hän palasi maahansa ja jäi Niiniveen.
Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
38 Mutta kun hän oli kerran rukoilemassa jumalansa Nisrokin temppelissä, surmasivat hänen poikansa Adrammelek ja Sareser hänet miekalla; sitten he pakenivat Araratin maahan. Ja hänen poikansa Eesarhaddon tuli kuninkaaksi hänen sijaansa.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.