< Hesekielin 5 >
1 "Ja sinä, ihmislapsi, ota itsellesi terävä miekka; ota se partaveitseksesi, ja ajele sillä hiuksesi ja partasi. Ota sitten vaaka ja jaa ne.
“Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
2 Polta kolmannes tulessa keskellä kaupunkia, sittenkuin piirityspäivät ovat lopussa. Kolmannes ota ja lyö miekalla sen ympärillä. Kolmannes hajota tuuleen, ja minä ajan niitä takaa paljastetulla miekalla;
Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
3 ota niistä sitten vähäinen määrä ja sido ne helmukseesi,
Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
4 ja ota niistä vielä osa, viskaa ne tuleen ja polta ne tulessa. Siitä lähtee tuli koko Israelin heimoon.
Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
5 Näin sanoo Herra, Herra: Tämä on Jerusalem; pakanain keskelle minä olen sen asettanut, ja niiden maat ovat sen ympärillä.
“Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
6 Mutta se on niskoitellut minun oikeuksiani vastaan jumalattomammin kuin pakanat ja minun käskyjäni vastaan jumalattomammin kuin maat, jotka ovat sen ympärillä; sillä minun oikeuteni he ovat pitäneet halpoina ja minun käskyjeni mukaan he eivät ole vaeltaneet.
Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
7 Sentähden, näin sanoo Herra, Herra: Koska teidän metelinne on ollut pahempi kuin pakanain, jotka ympärillänne ovat, ja koska te ette ole vaeltaneet minun käskyjeni mukaan, ette ole noudattaneet minun oikeuksiani ettekä ole tehneet niiden pakanainkaan oikeuksien mukaan, jotka ympärillänne ovat,
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
8 sentähden, näin sanoo Herra, Herra: Katso, myös minä käyn sinun kimppuusi ja teen tuomiot sinun keskelläsi pakanain silmien edessä
“Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
9 ja teen sinulle kaikkien kauhistustesi tähden, mitä en ole ennen tehnyt ja minkäkaltaista en vasta ole tekevä.
Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
10 Sentähden tulevat sinun keskelläsi isät syömään lapsiansa, ja lapset tulevat syömään isiänsä, ja minä teen sinussa tuomiot ja hajotan sinun jäännöksesi kaikkiin tuuliin.
Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
11 Sentähden, niin totta kuin minä elän, sanoo Herra, Herra: Totisesti, koska olet saastuttanut minun pyhäkköni kaikilla iljetyksilläsi ja kaikilla kauhistuksillasi, käännyn minäkin pois, en sääli enkä armahda.
Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
12 Kolmannes sinusta kuolee ruttoon ja nääntyy nälkään sinun keskelläsi. Kolmannes kaatuu miekkaan sinun ympärilläsi. Kolmanneksen minä hajotan kaikkiin tuuliin, ja minä ajan niitä takaa paljastetulla miekalla.
Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
13 Ja minun vihani täyttyy, ja minä tyydytän kiivauteni heissä ja kostan. Ja he tulevat tietämään, että minä, Herra, olen puhunut kiivaudessani, kun minä panen vihani täytäntöön heissä.
“Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
14 Ja minä teen sinut raunioksi ja häväistyksi pakanain kesken, jotka sinun ympärilläsi ovat, jokaisen ohikulkijan silmäin edessä.
“Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
15 Ja se on oleva häväistys ja herjaus, varoitus ja peljätys pakanain seassa, jotka ympärilläsi ovat, kun minä teen sinussa tuomiot vihassa ja kiivaudessa ja kiivailla rangaistuksilla-minä, Herra, olen puhunut-
O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
16 kun minä lähetän heidän kimppuunsa nälän pahat nuolet, joista tulee tuhooja ja jotka minä lähetän teitä tuhoamaan; ja minä vielä lisään teille nälkää ja murran teiltä leivän tuen.
Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
17 Ja minä lähetän teidän kimppuunne nälän ja pahat petoeläimet, jotka riistävät sinulta lapset; rutto ja veri käyvät sinun ylitsesi, ja minä annan miekan tulla sinun ylitsesi. Minä, Herra, olen puhunut."
Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”