< Aamoksen 2 >
1 Näin sanoo Herra: Mooabin kolmen rikoksen, neljän rikoksen tähden minun päätökseni on peruuttamaton. Koska se on polttanut Edomin kuninkaan luut kalkiksi,
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Moabu, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà, nítorí ó ti sun ún, di eérú, egungun ọba Edomu,
2 sentähden minä lähetän tulen Mooabia vastaan, ja se kuluttaa Kerijotin palatsit. Ja Mooab kuolee sodan melskeessä, sotahuudon ja pasunan pauhinassa.
Èmi yóò rán iná sí orí Moabu èyí tí yóò jó àwọn ààfin Kerioti run. Moabu yóò sì kú pẹ̀lú ariwo pẹ̀lú igbe àti pẹ̀lú ìró ìpè.
3 Ja minä hävitän tuomarin sen keskeltä, ja kaikki sen päämiehet minä tapan yhdessä sen kanssa, sanoo Herra.
Èmi yóò ké onídàájọ́ rẹ̀ kúrò, Èmi yóò sì pa gbogbo àwọn ọmọ-aládé rẹ́ nínú rẹ̀,” ni Olúwa wí.
4 Näin sanoo Herra: Juudan kolmen rikoksen, neljän rikoksen tähden minun päätökseni on peruuttamaton. Koska he ovat hyljänneet Herran lain eivätkä ole pitäneet hänen käskyjänsä, vaan heidän valhejumalansa, joiden perässä jo heidän isänsä kulkivat, ovat heidät vietelleet,
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Juda, àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Nítorí wọn ti kọ òfin Olúwa sílẹ̀, wọn kò sì pa àwọn ìlànà rẹ̀ mọ́. Nítorí àwọn òrìṣà ti sì wọ́n lọ́nà, òrìṣà tí àwọn Baba ńlá wọn ń tẹ̀lé,
5 sentähden minä lähetän tulen Juudaa vastaan, ja se kuluttaa Jerusalemin palatsit.
Èmi yóò rán iná sí orí Juda èyí tí yóò jó àwọn ààfin Jerusalẹmu run.”
6 Näin sanoo Herra: Israelin kolmen rikoksen, neljän rikoksen tähden minun päätökseni on peruuttamaton. Sillä he myyvät hurskaan rahasta ja köyhän kenkäparista,
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Israẹli àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padà. Wọ́n ta olódodo fún fàdákà àti aláìní fún bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì.
7 polkevat maan tomuun vaivaisten pään ja vääntävät mutkaiseksi nöyrien tien. Ja poika ja isä käyvät saman naisen pariin häväisten minun pyhän nimeni.
Wọ́n fi ẹsẹ̀ tẹ orí àwọn tálákà mọ́lẹ̀, bí wọ́n ti ń tẹ erùpẹ̀ ilẹ̀ tí wọ́n ko sì ṣe òtítọ́ si àwọn tí a ni lára. Baba àti ọmọ ń wọlé tọ wúńdíá kan náà, láti ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́.
8 He loikovat pantiksi otetuilla vaatteilla jokaisen alttarin ääressä ja juovat sakotettujen viiniä jumalansa huoneessa.
Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bàá a pẹpẹ, lórí aṣọ tí wọ́n fi jẹ́ ẹ̀jẹ́ ní ilé òrìṣà wọn wọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtánràn.
9 Ja kuitenkin minä hävitin heidän edestänsä amorilaiset, jotka olivat korkeakasvuiset kuin setrit ja vahvat kuin tammet, ja minä hävitin niiden hedelmän ylhäältä ja niiden juuret alhaalta.
“Mo pa àwọn ará Amori run níwájú wọn gíga ẹni tí ó dàbí igi kedari. Òun sì le koko bí igi óákù mo pa èso rẹ̀ run láti òkè wá àti egbò rẹ̀ láti ìsàlẹ̀ wá.
10 Ja minä johdatin teidät Egyptin maasta ja kuljetin teitä erämaassa neljäkymmentä vuotta, että saisitte ottaa omaksenne amorilaisten maan.
Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì sìn yín la aginjù já ní ogójì ọdún láti fi ilẹ̀ àwọn ará Amori fún un yín.
11 Ja minä herätin teidän pojistanne profeettoja ja nuorukaisistanne nasiireja. Vai eikö niin ole, te israelilaiset? sanoo Herra.
“Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàrín àwọn ọmọ yín àti láàrín àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Nasiri èyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Israẹli?” ni Olúwa wí.
12 Mutta te juotitte nasiireille viiniä, ja profeettoja te kielsitte sanoen: "Älkää ennustako".
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Nasiri ní ọtí mu e sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọtẹ́lẹ̀.
13 Katso, minä rusennan teidät alallenne, niinkuin täyteen kuormattu puimajyrä rusentaa lyhteet.
“Ní báyìí, èmi yóò tẹ̀ yín mọ́lẹ̀ bí kẹ̀kẹ́ tí ó kún fún ìtí ti í tẹ̀.
14 Silloin nopeakaan ei pääse pakoon, ei väkevällä ole apua voimastaan, eikä sankari pelasta henkeänsä;
Ẹni tí ó yára bí àṣá kò ní rí ọ̀nà àbáyọ alágbára kò ní le è dúró lé agbára rẹ̀ jagunjagun kì yóò le gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
15 jousimies ei kestä paikallansa, nopeajalkainen ei pelastu, eikä ratsumies pelasta henkeänsä.
Tafàtafà kì yóò dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó gún ẹṣin kì yóò gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là.
16 Ja sankareista rohkein pakenee alasti sinä päivänä, sanoo Herra.
Àní jagunjagun tí ó gbóyà jùlọ yóò sálọ ní ìhòhò ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí.