< 2 Samuelin 10 >

1 Senjälkeen ammonilaisten kuningas kuoli, ja hänen poikansa Haanun tuli kuninkaaksi hänen sijaansa.
Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, ọba àwọn ará Ammoni sì kú, Hanuni ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
2 Niin Daavid sanoi: "Minä osoitan laupeutta Haanunille, Naahaan pojalle, niinkuin hänen isänsä osoitti laupeutta minulle". Ja Daavid lähetti palvelijoitaan lohduttamaan häntä hänen isänsä kuoleman johdosta. Kun Daavidin palvelijat tulivat ammonilaisten maahan,
Dafidi sì wí pé, “Èmi yóò ṣe oore fún Hanuni ọmọ Nahaṣi gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ sì ti ṣe oore fún mi.” Dafidi sì ránṣẹ́ láti tù Hanuni nínú láti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ wá, nítorí ti baba rẹ̀. Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì wá sí ilé àwọn ọmọ Ammoni.
3 sanoivat ammonilaisten päämiehet herrallensa Haanunille: "Luuletko sinä, että Daavid tahtoo kunnioittaa sinun isääsi, kun hän lähettää lohduttajia sinun luoksesi? Varmasti on Daavid lähettänyt palvelijansa sinun luoksesi tutkimaan kaupunkia ja vakoilemaan ja hävittämään sitä."
Àwọn olórí àwọn ọmọ Ammoni sì wí fún Hanuni olúwa wọn pé, “Ǹjẹ́ o rò pé Dafidi ń bu ọlá fún baba rẹ nígbà tí ó rán ènìyàn wá láti bá ọ kẹ́dùn? Kò ha ṣe pé Dafidi rán àwọn ìránṣẹ́ sí ọ láti wo ìlú àti láti yọ́ ọ wò àti láti gbà ọ́.”
4 Niin Haanun otatti kiinni Daavidin palvelijat, ajatti toisen puolen heidän partaansa ja leikkautti toisen puolen heidän vaatteistaan, peräpuolia myöten, ja päästi heidät sitten menemään.
Hanuni sì mú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi ó fá apá kan irùngbọ̀n wọn, ó sì gé ààbọ̀ kúrò ní agbádá wọn, títí ó fi dé ìdí wọn, ó sì rán wọn lọ.
5 Ja kun se ilmoitettiin Daavidille, lähetti hän sanan heitä vastaan, sillä miehiä oli pahasti häväisty. Ja kuningas käski sanoa: "Jääkää Jerikoon, kunnes partanne on kasvanut, ja tulkaa sitten takaisin".
Wọ́n sì sọ fún Dafidi, ó sì ránṣẹ́ lọ pàdé wọn, nítorí tí ojú ti àwọn ọkùnrin náà púpọ̀: ọba sì wí pé, “Ẹ dúró ní Jeriko títí irùngbọ̀n yín yóò fi hù, nígbà náà ni kí ẹ tó máa bọ̀.”
6 Kun ammonilaiset näkivät joutuneensa Daavidin vihoihin, lähettivät ammonilaiset lähettiläitä ja palkkasivat Beet-Rehobin ja Sooban aramilaisia, kaksikymmentä tuhatta jalkamiestä, ja Maakan kuninkaalta tuhat miestä ja Toobin miehiä kaksitoista tuhatta.
Àwọn ará Ammoni sì ri pé, wọ́n di ẹni ìríra níwájú Dafidi, àwọn ọmọ Ammoni sì ránṣẹ́, wọ́n sì fi owó bẹ́ ogún àwọn ará Siria ti Beti-Rehobu; àti Siria-Soba, ogún ẹgbẹ̀rún ẹlẹ́ṣẹ̀ àti ti ọba Maaka, ẹgbẹ̀rún ọkùnrin àti ti Tobu ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin lọ́wẹ̀.
7 Kun Daavid sen kuuli, lähetti hän Jooabin ja koko sotajoukon, kaikki urhot.
Dafidi sì gbọ́, ó sì rán Joabu, àti gbogbo ogún àwọn ọkùnrin alágbára.
8 Niin ammonilaiset lähtivät ja asettuivat sotarintaan portin oven edustalle, mutta Sooban ja Rehobin aramilaiset ja Toobin ja Maakan miehet olivat eri joukkona kedolla.
Àwọn ọmọ Ammoni sì jáde wá, wọ́n sì tẹ́ ogun ní ẹnu odi; ará Siria-Soba, àti ti Rehobu, àti Tobu, àti Maaka, wọ́n sì tẹ ogun ni pápá fún ara wọn.
9 Kun Jooab näki, että häntä uhkasi hyökkäys edestä ja takaa, valitsi hän miehiä kaikista Israelin valiomiehistä ja asettui sotarintaan aramilaisia vastaan.
Nígbà tí Joabu sì rí i pé ogun náà dojúkọ òun níwájú àti lẹ́yìn, ó sì yàn nínú gbogbo àwọn akíkanjú ọkùnrin ní Israẹli, ó sì tẹ́ ogun kọjú sí àwọn ará Siria.
10 Mutta muun väen hän antoi veljensä Abisain johtoon, ja tämä asettui sotarintaan ammonilaisia vastaan.
Ó sì fi àwọn ènìyàn tí ó kù lé Abiṣai àbúrò rẹ̀ lọ́wọ́, kí ó lè tẹ ogun kọjú sí àwọn ọmọ Ammoni.
11 Ja hän sanoi: "Jos aramilaiset tulevat minulle ylivoimaisiksi, niin tule sinä minun avukseni; jos taas ammonilaiset tulevat sinulle ylivoimaisiksi, niin minä tulen sinua auttamaan.
Ó sì wí pé, “Bí agbára àwọn ará Siria bá pọ̀ ju èmi lọ, ìwọ yóò sì wá ràn mí lọ́wọ́, ṣùgbọ́n bí ọwọ́ àwọn ọmọ Ammoni bá sì pọ̀jù ọ́ lọ, èmi ó sì wá ràn ọ́ lọ́wọ́.
12 Ole luja, ja pysykäämme lujina kansamme puolesta ja meidän Jumalamme kaupunkien puolesta. Tehköön sitten Herra, minkä hyväksi näkee."
Mú ọkàn lè, jẹ́ kí a ṣe onígboyà nítorí àwọn ènìyàn wa, àti nítorí àwọn ìlú Ọlọ́run wa; Olúwa yóò sì ṣe èyí tí ó dára lójú rẹ̀.”
13 Sitten Jooab ja väki, joka oli hänen kanssaan, ryhtyi taisteluun aramilaisia vastaan, ja nämä pakenivat häntä.
Joabu àti àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì bá àwọn ará Siria pàdé ìjà, wọ́n sì sá níwájú rẹ̀.
14 Ja kun ammonilaiset näkivät aramilaisten pakenevan, pakenivat hekin Abisaita ja menivät kaupunkiin. Sitten Jooab palasi ahdistamasta ammonilaisia ja tuli Jerusalemiin.
Nígbà tí àwọn ọmọ Ammoni sì rí i pé àwọn ará Siria sá, àwọn pẹ̀lú sì sá níwájú Abiṣai, wọ́n sì wọ inú ìlú lọ. Joabu sì padà kúrò lẹ́yìn àwọn ọmọ Ammoni, ó sì wá sí Jerusalẹmu.
15 Kun aramilaiset näkivät, että Israel oli voittanut heidät, kokoontuivat he kaikki,
Nígbà tí àwọn ará Siria sì rí i pé àwọn ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì kó ara wọn jọ
16 ja Hadareser lähetti nostattamaan niitä aramilaisia, jotka asuivat tuolla puolella Eufrat-virran; ja he tulivat Heelamiin, ja Soobak, Hadareserin sotapäällikkö, johti heitä.
Hadadeseri sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Siria tí ó wà ní òkè odò Eufurate jáde wá, wọ́n sì wá sí Helami; Sobaki olórí ogun Hadadeseri sì ṣe olórí wọn.
17 Kun se ilmoitettiin Daavidille, kokosi hän kaiken Israelin ja meni Jordanin yli ja tuli Heelamiin; ja aramilaiset asettuivat sotarintaan Daavidia vastaan ja taistelivat hänen kanssaan.
Nígbà tí a sọ fún Dafidi, ó sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì wá sí Helami, àwọn ará Siria sì tẹ́ ogun kọjú sí Dafidi, wọ́n sì bá a jà.
18 Mutta aramilaiset pakenivat Israelia, ja Daavid tappoi aramilaisilta seitsemän sataa vaunuhevosta ja neljäkymmentä tuhatta ratsumiestä, ja heidän sotapäällikkönsä Soobakin hän siellä löi kuoliaaksi.
Àwọn ará Siria sì sá níwájú Israẹli, Dafidi sì pa nínú àwọn ará Siria ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sobaki olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ̀.
19 Kun kaikki Hadareserin alaiset kuninkaat näkivät, että Israel oli voittanut heidät, tekivät he Israelin kanssa rauhan ja palvelivat heitä. Sitten aramilaiset eivät enää uskaltaneet auttaa ammonilaisia.
Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadeseri sì rí i pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Israẹli, wọ́n sì bá Israẹli làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n. Àwọn ará Siria sì bẹ̀rù láti máa ran àwọn ọmọ Ammoni lọ́wọ́ mọ́.

< 2 Samuelin 10 >