< 2 Aikakirja 21 >

1 Sitten Joosafat meni lepoon isiensä tykö, ja hänet haudattiin isiensä viereen Daavidin kaupunkiin. Ja hänen poikansa Jooram tuli kuninkaaksi hänen sijaansa.
Nígbà náà Jehoṣafati sùn pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú wọn ní ìlú ńlá Dafidi. Jehoramu ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.
2 Ja hänellä oli veljiä: Joosafatin pojat Asarja, Jehiel, Sakarja, Asarjahu, Miikael ja Sefatja. Nämä kaikki olivat Joosafatin, Israelin kuninkaan, poikia.
Àwọn arákùnrin Jehoramu ọmọ Jehoṣafati jẹ́ Asariah, Jehieli, Sekariah. Asariahu, Mikaeli àti Ṣefatia. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Jehoṣafati ọba Israẹli.
3 Ja heidän isänsä oli antanut heille suuria lahjoja, hopeata, kultaa ja kalleuksia, sekä varustettuja kaupunkeja Juudassa; mutta kuninkuuden hän oli antanut Jooramille, sillä tämä oli esikoinen.
Baba wọn ti fún wọn ní ẹ̀bùn púpọ̀ ti fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò iyebíye pẹ̀lú àwọn ìlú ààbò ní Juda, ṣùgbọ́n, ó ti gbé ìjọba fún Jehoramu nítorí òun ni àkọ́bí ọmọkùnrin.
4 Kun Jooram oli noussut isänsä valtaistuimelle ja vahvistunut, tappoi hän miekalla kaikki veljensä, niin myös muutamia Israelin päämiehiä.
Nígbà tí Jehoramu fi ẹsẹ̀ rẹ̀ múlẹ̀ gidigidi lórí ìjọba baba a rẹ̀, ó sì fi idà pa gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli.
5 Jooram oli kolmenkymmenen kahden vuoden vanha tullessaan kuninkaaksi, ja hän hallitsi Jerusalemissa kahdeksan vuotta.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ.
6 Mutta hän vaelsi Israelin kuningasten tietä, niinkuin Ahabin suku oli tehnyt, sillä hänellä oli puolisona Ahabin tytär; ja niin hän teki sitä, mikä on pahaa Herran silmissä.
Ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé Ahabu ti ṣe, nítorí ó fẹ́ ọmọbìnrin Ahabu. Ó ṣe búburú lójú Olúwa.
7 Mutta Herra ei tahtonut tuhota Daavidin sukua, koska hän oli tehnyt liiton Daavidin kanssa ja koska hän oli luvannut antaa hänelle ja hänen pojillensa lampun ainiaaksi.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, nítorí tí májẹ̀mú tí Olúwa ti dá fún Dafidi kì í ṣe ìfẹ́ Olúwa láti pa ìdílé Dafidi run ó ti ṣe ìlérí láti tọ́jú fìtílà kan fún un àti àwọn àtẹ̀lé rẹ̀ títí láé.
8 Hänen aikanaan edomilaiset luopuivat Juudan vallanalaisuudesta ja asettivat itsellensä kuninkaan.
Ní àkókò Jehoramu, Edomu ṣọ̀tẹ̀ sí Juda, wọ́n sì gbé ọba tiwọn kalẹ̀.
9 Niin Jooram lähti sinne päällikköineen ja kaikkine sotavaunuineen. Ja hän nousi yöllä ja voitti edomilaiset, jotka olivat saartaneet hänet, ja sotavaunujen päälliköt.
Bẹ́ẹ̀ ni, Jehoramu lọ síbẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀ àti gbogbo àwọn kẹ̀kẹ́. Àwọn ará Edomu yí i ká àti àwọn alákòóso àwọn kẹ̀kẹ́ rẹ̀. Ṣùgbọ́n ó dìde ní òru ó sì ṣẹ́gun wọn ní òru.
10 Niin edomilaiset luopuivat Juudan vallanalaisuudesta vapaiksi, aina tähän päivään asti. Siihen aikaan luopui hänen vallanalaisuudestaan myös Libna, koska hän oli hyljännyt Herran, isiensä Jumalan.
Títí di ọjọ́ òní ni Edomu ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Juda. Libina ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jehoramu ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
11 Hänkin teetti uhrikukkuloita Juudan vuoristoon ja saattoi Jerusalemin asukkaat haureuteen ja vietteli Juudan.
Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Juda. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jerusalẹmu ó ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
12 Mutta profeetta Elialta tuli hänelle tällainen kirjoitus: "Näin sanoo Herra, sinun isäsi Daavidin Jumala: Koska et ole vaeltanut isäsi Joosafatin teitä etkä Aasan, Juudan kuninkaan, teitä,
Jehoramu gba ìwé láti ọwọ́ Elijah wòlíì, tí ó wí pé, “Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dafidi wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jehoṣafati tàbí Asa ọba Juda.
13 vaan olet vaeltanut Israelin kuningasten tietä ja saattanut Juudan ja Jerusalemin asukkaat haureuteen, niinkuin Ahabin suku saattoi heidät haureuteen; ja koska myös olet tappanut veljesi, jotka olivat sinun isäsi perhekuntaa ja paremmat kuin sinä,
Ṣùgbọ́n ìwọ ti rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, ìwọ sì ti tọ́ Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu láti ṣe àgbèrè sí ara wọn, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe. Ìwọ sì ti pa àwọn arákùnrin rẹ, ẹ̀yà ara ilé baba à rẹ, àwọn ọkùnrin tí ó dára jù ọ́ lọ.
14 katso, sentähden Herra rankaisee sinun kansaasi, poikiasi, vaimojasi ja kaikkea, mitä sinulla on, kovalla vitsauksella;
Bẹ́ẹ̀ ni nísinsin yìí, Olúwa ti fẹ́rẹ lu àwọn ènìyàn rẹ, àwọn ọmọ rẹ, àwọn ìyàwó rẹ àti gbogbo ohun tí ó jẹ́ tìrẹ, pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn ńlá.
15 ja sinä itse olet sairastava vaikeata tautia, sisusvaivaa, kunnes vuoden, parin kuluttua sisuksesi taudin voimasta tunkeutuvat ulos."
Ìwọ tìkára yóò ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú àìsàn lílọ́ra ti ìfun, títí tí àìsàn náà yóò fi jẹ́ kí àwọn ìfun rẹ jáde sí ìta.’”
16 Niin Herra herätti Jooramia vastaan filistealaisten hengen ja niiden arabialaisten hengen, jotka asuivat etiopialaisten naapureina,
Olúwa ru ìbínú àwọn ará Filistini àti àwọn Arabia tí wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá àwọn ará Kuṣi sí Jehoramu.
17 ja he menivät Juudaa vastaan, valloittivat sen ja veivät saaliinaan kaiken tavaran, mitä oli kuninkaan linnassa, niin myöskin hänen poikansa ja vaimonsa, niin ettei hänelle jäänyt muuta poikaa kuin Jooahas, hänen nuorin poikansa.
Wọ́n dojú ìjà kọ Juda, wọ́n gbà á, wọ́n sì kó gbogbo ọrọ̀ tí a rí ní ilé ọba pẹ̀lú, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ àti àwọn ọmọkùnrin kankan kò kù sílẹ̀ fún un bí kò ṣe Ahasiah, àbíkẹ́yìn nínú àwọn ọmọ rẹ̀.
18 Ja kaiken tämän jälkeen Herra rankaisi häntä parantumattomalla sisusvaivalla.
Lẹ́yìn gbogbo èyí, Olúwa jẹ Jehoramu ní yà pẹ̀lú ààrùn tí kò ṣe é wòsàn nínú ìfun.
19 Parin vuoden kuluttua, toisen vuoden lopulla, hänen sisuksensa taudin voimasta tunkeutuivat ulos, ja hän kuoli koviin tuskiin. Mutta hänen kansansa ei polttanut hänen kunniakseen kuolinsuitsutusta, niinkuin oli poltettu hänen isiensä kunniaksi.
Ní àkókò kan ní ìparí ọdún kejì, àwọn ìfun rẹ̀ jáde nítorí ààrùn náà ó sì kú nínú ìrora ńlá. Àwọn ènìyàn rẹ̀ kò dá iná láti fi bu ọlá fún un, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe fún àwọn baba a rẹ̀.
20 Hän oli kolmenkymmenen kahden vuoden vanha tullessaan kuninkaaksi, ja hän hallitsi Jerusalemissa kahdeksan vuotta. Ja hän meni pois kenenkään kaipaamatta, ja hänet haudattiin Daavidin kaupunkiin, mutta ei kuningasten hautoihin.
Jehoramu jẹ́ ẹni ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ní ìgbà tí ó di ọba, Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mẹ́jọ. Ó kọjá lọ, kò sí ẹni tí ó kábámọ̀. A sì sin ín si ìlú ńlá ti Dafidi. Ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú ibojì àwọn ọba.

< 2 Aikakirja 21 >