< 1 Kuninkaiden 17 >
1 Tisbeläinen Elia, eräs Gileadiin asettuneita siirtolaisia, sanoi Ahabille: "Niin totta kuin Herra, Israelin Jumala, elää, jonka edessä minä seison: näinä vuosina ei tule kastetta eikä sadetta muutoin kuin minun sanani kautta".
Elijah ará Tiṣibi láti Tiṣbi ní Gileadi wí fún Ahabu pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ti wà, ẹni tí èmi ń sìn, kì yóò sí ìrì tàbí òjò ní ọdún díẹ̀ tí ń bọ̀ bí kò ṣe nípa ọ̀rọ̀ mi.”
2 Ja hänelle tuli tämä Herran sana:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Elijah wá pé,
3 "Mene pois täältä ja käänny itään päin ja kätkeydy Keritin purolle, joka on Jordanin itäpuolella.
“Kúrò níhìn-ín, kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, kí o sì fi ara rẹ pamọ́ níbi odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani.
4 Sinä saat juoda purosta, ja minä olen käskenyt kaarneiden elättää sinua siellä."
Ìwọ yóò mu nínú odò náà, mo sì ti pàṣẹ fún àwọn ẹyẹ ìwò láti máa bọ́ ọ níbẹ̀.”
5 Niin hän meni ja teki Herran sanan mukaan: hän meni ja asettui Keritin purolle, joka on Jordanin itäpuolella.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó sì lọ sí ẹ̀bá odò Keriti, tí ń bẹ níwájú Jordani, ó sì dúró síbẹ̀.
6 Ja kaarneet toivat hänelle leipää ja lihaa aamuin sekä leipää ja lihaa illoin, ja hän joi purosta.
Àwọn ẹyẹ ìwò sì mú àkàrà àti ẹran wá fún un ní òwúrọ̀, àti àkàrà àti ẹran ní alẹ́, ó sì ń mu nínú odò náà.
7 Mutta jonkun ajan kuluttua puro kuivui, koska siinä maassa ei ollut satanut.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, odò náà sì gbẹ nítorí kò sí òjò ní ilẹ̀ náà.
8 Ja hänelle tuli tämä Herran sana:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ ọ́ wá wí pé,
9 "Nouse ja mene Sarpatiin, joka on Siidonin aluetta, ja asetu sinne. Katso, minä olen käskenyt leskivaimon elättää sinua siellä."
“Lọ nísinsin yìí sí Sarefati ti Sidoni, kí o sì dúró síbẹ̀. Èmi ti pàṣẹ fún obìnrin opó kan níbẹ̀ láti máa bọ́ ọ.”
10 Niin hän nousi ja meni Sarpatiin. Ja kun hän tuli kaupungin portille, niin katso, siellä oli leskivaimo keräilemässä puita. Hän huusi tälle ja sanoi: "Tuo minulle vähän vettä astiassa juodakseni".
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì lọ sí Sarefati. Nígbà tí ó sì dé ibodè ìlú náà, obìnrin opó kan ń ṣa igi jọ níbẹ̀. Ó sì ké sí i, ó sì béèrè pé, “Ǹjẹ́ o lè bu omi díẹ̀ fún mi wá nínú ohun èlò kí èmi kí ó lè mu?”
11 Kun hän meni hakemaan, huusi hän hänelle ja sanoi: "Tuo minulle myös palanen leipää kädessäsi".
Bí ó sì ti ń lọ bù ú wá, ó ké sí i pé, “Jọ̀ ọ́, mú òkèlè oúnjẹ díẹ̀ fún mi wá lọ́wọ́ rẹ.”
12 Mutta hän vastasi: "Niin totta kuin Herra, sinun Jumalasi, elää, minulla ei ole leipäkakkuakaan, vaan ainoastaan kourallinen jauhoja ruukussa ja vähän öljyä astiassa. Ja katso, kerättyäni pari puuta minä menen leipomaan itselleni ja pojalleni, syödäksemme ja sitten kuollaksemme."
Obìnrin opó náà sì dá a lóhùn wí pé, “Bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti wà, èmi kò ní àkàrà, bí kò ṣe ìkúnwọ́ ìyẹ̀fun nínú ìkòkò àti òróró díẹ̀ nínú kólòbó. Èmi ń ṣa igi díẹ̀ jọ láti kó lọ ilé, kí èmi kí ó sì pèsè rẹ̀ fún mi àti fún ọmọ mi, kí àwa lè jẹ ẹ́: kí a sì kú.”
13 Niin Elia sanoi hänelle: "Älä pelkää; mene ja tee, niinkuin olet sanonut. Mutta leivo minulle ensin pieni kaltiainen ja tuo se minulle. Leivo sitten itsellesi ja pojallesi.
Elijah sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù. Lọ, kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ti wí. Ṣùgbọ́n kọ́kọ́ ṣe àkàrà kékeré kan fún mi nínú rẹ̀ ná, kí o sì mú fún mi wá, lẹ́yìn náà, kí o ṣe tìrẹ àti ti ọmọ rẹ.
14 Sillä näin sanoo Herra, Israelin Jumala: Jauhot eivät lopu ruukusta, eikä öljyä ole puuttuva astiasta siihen päivään asti, jona Herra antaa sateen maan päälle."
Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Ìkòkò ìyẹ̀fun náà kì yóò ṣófo, bẹ́ẹ̀ ni kólòbó òróró náà kì yóò gbẹ, títí di ọjọ́ tí Olúwa yóò rọ òjò sí orí ilẹ̀.’”
15 Niin hän meni ja teki, niinkuin Elia oli sanonut. Ja hänellä sekä myös Elialla ja vaimon perheellä oli syötävää pitkäksi aikaa.
Ó sì lọ, ó sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Elijah ti sọ fún un. Oúnjẹ sì wà fún Elijah àti obìnrin náà àti ilé rẹ̀ ní ojoojúmọ́.
16 Jauhot eivät loppuneet ruukusta, eikä öljyä puuttunut astiasta, sen Herran sanan mukaan, jonka hän oli Elian kautta puhunut.
Nítorí ìkòkò ìyẹ̀fun náà kò ṣófo, kólòbó òróró náà kò gbẹ, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Elijah sọ.
17 Sen jälkeen vaimon, talon emännän, poika sairastui; ja hänen tautinsa kävi hyvin kovaksi, niin ettei hänessä enää ollut henkeä.
Ó sì ṣe lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ọmọ obìnrin tí ó ni ilé náà ṣe àìsàn, àìsàn náà sì le tó bẹ́ẹ̀, tí ó fi kú.
18 Silloin vaimo sanoi Elialle: "Mitä minulla on tekemistä sinun kanssasi, Jumalan mies? Sinä olet tullut minun luokseni saattamaan minun pahat tekoni muistoon ja tuottamaan kuoleman minun pojalleni."
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Kí lo ní sí mi, ènìyàn Ọlọ́run? Ìwọ ha tọ̀ mí wá láti mú ẹ̀ṣẹ̀ mi wá sí ìrántí, àti láti pa mí ní ọmọ?”
19 Mutta hän sanoi hänelle: "Anna poikasi minulle". Ja hän otti tämän hänen sylistään ja vei hänet yliskammioon, jossa asui, ja pani hänet vuoteellensa.
Elijah sì wí fún un pé, “Gbé ọmọ rẹ fún mi.” Ó sì yọ ọ́ jáde ní àyà rẹ̀, ó sì gbé e lọ sí iyàrá òkè ilé níbi tí òun ń gbé, ó sì tẹ́ ẹ sí orí ibùsùn tirẹ̀.
20 Ja hän huusi Herraa ja sanoi: "Herra, minun Jumalani, oletko tehnyt niin pahoin tätä leskeä kohtaan, jonka vieraana minä olen, että olet surmannut hänen poikansa?"
Nígbà náà ni ó sì ké pe Olúwa wí pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ ha mú ibi wá bá opó náà pẹ̀lú lọ́dọ̀ ẹni tí èmi ń ṣe àtìpó, nípa pípa ọmọ rẹ̀?”
21 Sitten hän ojentautui pojan yli kolme kertaa, huusi Herraa ja sanoi: "Herra, minun Jumalani, anna tämän pojan sielun tulla häneen takaisin".
Nígbà náà ni ó sì na ara rẹ̀ lórí ọmọdé náà ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sì ké pe Olúwa pé, “Olúwa Ọlọ́run mi, jẹ́ kí ẹ̀mí ọmọdé yìí kí ó tún padà tọ̀ ọ́ wá!”
22 Ja Herra kuuli Eliaa, ja pojan sielu tuli häneen takaisin, ja hän virkosi henkiin.
Olúwa sì gbọ́ igbe Elijah, ẹ̀mí ọmọdé náà sì tún padà tọ̀ ọ́ wá, ó sì sọjí.
23 Ja Elia otti pojan ja toi hänet yliskammiosta alas huoneeseen ja antoi hänet hänen äidillensä. Ja Elia sanoi: "Katso, poikasi elää".
Elijah sì mú ọmọdé náà, ó sì gbé e sọ̀kalẹ̀ láti inú yàrá òkè náà wá sínú ilé. Ó sì fi lé ìyá rẹ̀ lọ́wọ́; Elijah sì wí pé, “Wò ó, ọmọ rẹ yè!”
24 Niin vaimo sanoi Elialle: "Nyt minä tiedän, että sinä olet Jumalan mies ja että Herran sana sinun suussasi on tosi".
Obìnrin náà sì wí fún Elijah pé, “Nísinsin yìí mo mọ̀ pé ènìyàn Ọlọ́run ni ìwọ ń ṣe, àti pé òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ẹnu rẹ.”