< Sefanjan 3 >
1 Voi sitä kauhiaa, rietasta ja väkivaltaista kaupunkia!
Ègbé ni fún ìlú aninilára, ọlọ̀tẹ̀ àti aláìmọ́.
2 Ei hän tahdo kuulla, eikä antaa itsiänsä kurittaa; ei hän tahdo uskaltaa Herran päälle, eikä pidä itsiänsä Jumalansa tykö.
Òun kò gbọ́rọ̀ sí ẹnikẹ́ni, òun kò gba ìtọ́ni, òun kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni òun kò súnmọ́ ọ̀dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀.
3 Hänen päämiehensä ovat hänessä niinkuin kiljuvat jalopeurat, ja hänen tuomarinsa niinkuin sudet ehtoolla, jotka ei mitään jätä huomeneksi.
Àwọn olórí rẹ̀ jẹ́ kìnnìún tí ń ké ramúramù, àwọn onídàájọ́ rẹ̀, ìkookò àṣálẹ́ ni wọn, wọn kò sì fi nǹkan kan kalẹ̀ fún òwúrọ̀.
4 Hänen prophetansa ovat irstaiset ja petturit; hänen pappinsa saastuttavat pyhyyden, ja kääntävät lain väkivaltaisesti.
Àwọn wòlíì rẹ̀ gbéraga, wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ènìyàn. Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti ba ibi mímọ́ jẹ́, wọ́n sì rú òfin.
5 Mutta Herra, joka heidän seassansa on, on vanhurskas, ja ei tee mitään väärin; vaan antaa joka aamulla oikeutensa julkisesti opettaa, eikä lakkaa; vaan väärintekiä ei taida hävetä.
Olúwa ni àárín rẹ̀ jẹ́ olódodo; kì yóò ṣe ohun tí kò tọ̀nà. Àràárọ̀ ni ó máa ń mú ìdájọ́ rẹ̀ wá sí ìmọ́lẹ̀, kì í sì kùnà ní gbogbo ọjọ́ tuntun, síbẹ̀ àwọn aláìṣòótọ́ kò mọ ìtìjú.
6 Minä olen antanut pakanat hävittää ja heidän linnansa autioksi tehdä, ja heidän katunsa niin tyhjentää, ettei kenkään niitä pidä käymän. Heidän kaupunkinsa ovat hävitetyt, ettei kenenkään pidä niissä enään asuman.
“Èmi ti ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò, ilé gíga wọn sì ti bàjẹ́. Mo ti fi ìgboro wọn sílẹ̀ ní òfo tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnìkankan kò kọjá níbẹ̀. Ìlú wọn parun tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí yóò ṣẹ́kù, kò sì ní sí ẹnìkan rárá.
7 Minä annoin sinulle sanoa: kuitenkin pitää sinun minua pelkäämän, ja antaman sinuas kurittaa, niin ei pidä hänen asuinsiansa hävitettämän, eikä mitään, josta minä olen häntä nuhdellut; mutta he ahkeroitsevat kaikkinaista pahuutta.
Èmi wí fún ìlú náà wí pé, ‘Nítòótọ́, ìwọ yóò bẹ̀rù mi, ìwọ yóò sì gba ìtọ́ni!’ Bẹ́ẹ̀ ni, a kì yóò ké ibùgbé rẹ̀ kúrò bí ó ti wù kí ń jẹ wọ́n ní yà tó. Ṣùgbọ́n síbẹ̀ wọ́n sì tún ní ìtara láti ṣe ìbàjẹ́.
8 Sentähden, sanoo Herra, täytyy myös teidän minua odottaa, siihenasti kuin minäkin aikanani nousen saaliille; kuin minä myös tuomitsen, ja kokoon pakanat, ja valtakunnat yhteen saatan ja vihani heidän päällensä vuodatan, ja kaiken minun vihani hirmuisuuden; sillä koko maan pitää minun kiivauteni tuli syömän.
Nítorí náà ẹ dúró dè mí,” ni Olúwa wí, “títí di ọjọ́ náà tí èmi yóò fi jẹ́rìí sí yin. Nítorí ìpinnu mi ni láti kó orílẹ̀-èdè jọ kí èmi kí ó lè kó ilẹ̀ ọba jọ àti láti da ìbínú mi jáde sórí wọn, àní gbogbo ìbínú gbígbóná mi. Nítorí gbogbo ayé ni a ó fi iná owú mi jẹ run.
9 Silloin minä tahdon kansoille tosin antaa saarnata suloisilla huulilla, että heidän kaikkein pitää Herran nimeä avuksensa huutaman, ja häntä yksimielisesti palveleman.
“Nígbà náà ni èmi yóò yí èdè àwọn ènìyàn padà sí èdè mímọ́, nítorí kí gbogbo wọn bá a lè máa pe orúkọ Olúwa, láti fi ọkàn kan sìn ín.
10 Jotka minua kumartavat, ne hajoitetut siltä puolelta Etiopian virtoja, pitää minulle lahjaksi tuotaman.
Láti òkè odò Etiopia, àwọn olùjọsìn mi, àwọn ènìyàn mi tí ó ti fọ́nká, yóò mú ọrẹ wá fún mi.
11 Siihen aikaan ei pidä sinun enään häpeemän kaikkia sinun tekojas, joilla minua vastaan olet syntiä tehnyt; sillä minä tahdon ylpiät pyhät silloin sinun seastas ottaa pois, niin ettes enää tohdi itsiäs korottaa minun vuoreni tähden.
Ní ọjọ́ náà ni a kì yóò sì dójútì nítorí gbogbo iṣẹ́ ibi ni tí ó ti ṣẹ̀ sí mi, nígbà náà ni èmi yóò mu kúrò nínú ìlú yìí, àwọn tí ń yọ̀ nínú ìgbéraga wọn. Ìwọ kì yóò sì gbéraga mọ́ ní òkè mímọ́ mi.
12 Minä tahdon sinusta antaa jäädä köyhän ja halvan kansan; heidän pitää Herran nimeen turvaaman.
Ṣùgbọ́n Èmi yóò fi àwọn ọlọ́kàn tútù àti onírẹ̀lẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú ni àárín rẹ̀, wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa.
13 Jääneet Israelista ei pidä mitään pahaa tekemän, eikä valhetta puhuman, ja ei heidän suussansa pidä viekasta kieltä löydettämän; vaan he elätetään levossa, ja ei ole ketään peljättäjää.
Àwọn ìyókù Israẹli kì yóò hùwà ibi, wọn kì yóò sọ̀rọ̀ èké. Bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò rí ahọ́n àrékérekè ní ẹnu wọn. Àwọn yóò jẹun, wọn yóò sì dùbúlẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ẹnikẹ́ni kì yóò dẹ́rùbà wọ́n.”
14 Riemuitse, sinä Zionin tytär, huuda, Israel, iloitse ja riemuitse kaikesta sydämestäs, sinä tytär Jerusalem.
Kọrin, ìwọ ọmọbìnrin Sioni, kígbe sókè, ìwọ Israẹli! Fi gbogbo ọkàn yọ̀, kí inú rẹ kí ó sì dùn, ìwọ ọmọbìnrin Jerusalẹmu.
15 Sillä Herra on sinun rangaistukses ottanut pois, ja sinun vihollises kääntänyt pois; Herra Israelin kuningas on sinun tykönäs, ettes enään pelkää onnettomuutta.
Olúwa ti mú ìdájọ́ rẹ wọ̀n-ọn-nì kúrò, ó sì ti ti àwọn ọ̀tá rẹ padà sẹ́yìn. Olúwa, ọba Israẹli wà pẹ̀lú rẹ; ìwọ kì yóò sì bẹ̀rù ibi kan mọ́.
16 Siihen aikaan sanotaan Jerusalemille: älä pelkää, ja Zionille: älä käsiäs laske alas!
Ní ọjọ́ náà, wọn yóò sọ fún Jerusalẹmu pé, “Má ṣe bẹ̀rù Sioni; má sì ṣe jẹ́ kí ọwọ́ rẹ kí ó dẹ̀.
17 Sillä Herra sinun Jumalas on sinun tykönäs, väkevä vapahtaja; hän on sinusta suuresti riemuitseva, ja on oleva sinulle suloinen, ja antava anteeksi, ja sinusta pitää kiitoksella riemuittaman.
Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, Ó ní agbára láti gbà ọ là. Yóò yọ̀ ni orí rẹ fún ayọ̀; Yóò tún ọ ṣe nínú ìfẹ́ rẹ̀, Yóò sì fi orin yọ̀ ní orí rẹ.”
18 Jotka murehtivat sitä, ettei he ole tulleet juhlakokoukseen, ja ovat sinusta, ne minä tahdon koota; tämä pilkka on heille kuormaksi.
“Èmi ó kó àwọn tí ó ń banújẹ́ fún àjọ̀dún tí a yàn jọ, àwọn tí ó jẹ́ tirẹ̀; àwọn tí ẹ̀gàn rẹ̀ jásí ẹ̀rù.
19 Katso, minä tahdon siihen aikaan kaikki lopettaa, jotka sinua vaivaavat, ja tahdon ontuvaisia auttaa, ja hyljätyt koota, ja saatan heidät kiitokseksi ja nimeksi kaikessa maassa, jossa he katsottiin ylön.
Ní àkókò náà ni èmi yóò dojúkọ àwọn tí ń ni yín lára, èmi yóò gba àtiro là, èmi yóò sì ṣa àwọn tí ó ti fọ́nká jọ, èmi yóò fi ìyìn àti ọlá fún wọn ní gbogbo ilẹ̀ tí a bá ti dójútì wọ́n.
20 Siihen aikaan tahdon minä teidät tänne tuoda, ja sillä ajalla teitä koota; sillä minä asetan teidät nimeksi ja ylistykseksi kaikkein kansain seassa maan päällä, kuin minä teidän vankiutenne käännän teidän silmäinne edessä, sanoo Herra.
Ní àkókò náà ni èmi yóò ṣà yín jọ; nígbà náà ni èmi yóò mú un yín padà wá sílé. Èmi yóò fi ọlá àti ìyìn fún un yín láàrín gbogbo ènìyàn àgbáyé, nígbà tí èmi yóò yí ìgbèkùn yín padà bọ sípò ní ojú ara yín,” ni Olúwa wí.