< Sakarjan 2 >

1 Ja minä nostin silmäni ja näin, ja katso, miehen kädessä oli mittanuora.
Mó si tún gbé ojú mi, sókè, mo sì wò, sì kíyèsi i, ọkùnrin kan ti o mú okùn ìwọ̀n lọ́wọ́ rẹ̀.
2 Ja minä sanoin: kuhunkas menet? Mutta hän sanoi minulle: mittaamaan Jerusalemia, ja katsomaan, kuinka pitkä ja leviä se on oleva.
Mo sí wí pé, “Níbo ni ìwọ ń lọ?” O sí wí fún mí pé, “Láti wọn Jerusalẹmu, láti rí iye ìbú rẹ̀, àti iye gígùn rẹ̀.”
3 Ja katso, enkeli, joka puhui minun kanssani, läksi ulos, ja toinen enkeli meni häntä vastaan,
Sì kíyèsi i, angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ jáde lọ, angẹli mìíràn si jáde lọ pàdé rẹ̀.
4 Ja sanoi hänelle: juokse tuonne, ja puhu sille pojalle ja sano: Jerusalemissa pitää ilman muureja asuttaman, ihmisten ja karjan paljouden tähden, joka siinä oleva on.
Ó si wí fún un pé, “Sáré, sọ fún ọ̀dọ́mọkùnrin yìí wí pé, ‘A ó gbé inú Jerusalẹmu bi ìlú ti kò ní odi, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn àti ohun ọ̀sìn inú rẹ̀.
5 Ja minä tahdon olla, sanoo Herra, tulinen muuri hänen ympärillänsä, ja tahdon itse olla kunniaksi hänen keskellänsä.
Olúwa wí pé: Èmi ó sì jẹ́ odi iná fún un yíká, èmi ó sì jẹ́ ògo láàrín rẹ̀.’
6 Hoi! hoi! paetkaat pohjan maasta, sanoo Herra; sillä minä hajoitin teitä neljään tuuleen taivaan alla, sanoo Herra.
“Wá! Wá! Sá kúrò ni ilẹ̀ àríwá,” ni Olúwa wí, “nítorí pé bí afẹ́fẹ́ mẹ́rin ọ̀run ni mo tú yín káàkiri,” ni Olúwa wí.
7 Hoi Zion, joka asut Babelin tyttären tykönä! pelasta sinus.
“Gbà ara rẹ̀ sílẹ̀, ìwọ Sioni, ìwọ tí ó ń bà ọmọbìnrin Babeli gbé.”
8 Sillä näin sanoo Herra Zebaot: joka sen (ilmoitetun) kunnian jälkeen lähetti minun niiden pakanain tykö, jotka teitä raatelivat: joka teihin rupee, se rupee hänen silmänsä terään.
Nítorí báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Lẹ́yìn ògo rẹ̀ ni a ti rán mi sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ń kó yin: nítorí ẹni tí ó tọ́ yin, ó tọ́ ọmọ ojú rẹ̀.
9 Sillä katso, minä nostan käteni heidän ylitsensä, että heidän pitää oleman niille saaliiksi, jotka ennen heitä palvelivat; että teidän pitää ymmärtämän Herran Zebaotin minua lähettäneeksi.
Nítorí kíyèsi i, èmi ó gbọn ọwọ́ mi sí orí wọn, wọn yóò sì jẹ́ ìkógun fún ìránṣẹ́ wọn: ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi.
10 Veisaa ja riemuitse, Zionin tytär; sillä katso, minä tulen ja tahdon asua sinun tykönäs, sanoo Herra.
“Kọrin kí o sì yọ̀, ìwọ ọmọbìnrin Sioni. Nítorí èmi ń bọ̀ àti pé èmi yóò sì gbé àárín rẹ,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
11 Silloin pitää paljon pakanoita Herrassa kiinni riippuman, jotka minun kansani pitää oleman: ja minä tahdon asua sinun tykönäs, ettäs ymmärtäisit Herran Zebaotin lähettäneen minun sinun tykös.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ni yóò dàpọ̀ mọ́ Olúwa ní ọjọ́ náà, wọn yóò sì di ènìyàn mi, èmi yóò sì gbé àárín rẹ, ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí ọ.
12 Ja Herra on perivä Juudan osaksensa siinä pyhässä maassa, ja on taas Jerusalemin valitseva.
Olúwa yóò sì jogún Juda ìní rẹ̀, ni ilẹ̀ mímọ́, yóò sì tún yan Jerusalẹmu.
13 Vaijetkoon kaikki liha Herran edessä; sillä hän on noussut pyhästä asuinsiastansa.
Ẹ̀ dákẹ́, gbogbo ẹran-ara níwájú Olúwa: nítorí a jí i láti ibùgbé mímọ́ rẹ̀ wá.”

< Sakarjan 2 >