< Ruutin 1 >

1 Ja tuomarien hallitessa oli kallis aika maalla, ja mies Juudan Betlehemistä meni vaeltamaan Moabilaisten maalle, hän ja hänen emäntänsä ja kaksi hänen poikaansa.
Ní ìgbà tí àwọn onídàájọ́ ń ṣe àkóso ilẹ̀ Israẹli, ìyàn kan mú ní ilẹ̀ náà, ọkùnrin kan láti Bẹtilẹhẹmu ti Juda, òun àti aya rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjì lọ láti máa gbé ní ilẹ̀ Moabu fún ìgbà díẹ̀.
2 Hänen nimensä oli EliMelek, ja hänen emäntänsä nimi Noomi, ja hänen kahden poikansa nimi Mahlon ja Kiljon, he olivat Ephratilaisia Juudan Betlehemistä. Ja kuin he tulivat Moabilaisten maalle, pysyivät he siellä.
Orúkọ ọkùnrin náà ń jẹ́ Elimeleki, orúkọ ìyàwó rẹ̀ ni Naomi, orúkọ àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì sì ni Maloni àti Kilioni àwọn ará Efrata, ti Bẹtilẹhẹmu ti Juda. Wọ́n sì lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọ́n ń gbé níbẹ̀.
3 Ja EliMelek Noomin mies kuoli, ja hän jäi hänestä kahden poikansa kanssa.
Ní àsìkò tí wọ́n ń gbé ibẹ̀, Elimeleki, ọkọ Naomi kú, ó sì ku òun pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì.
4 He naivat Moabilaisia vaimoja: yhden nimi oli Orpa ja toisen nimi Ruut, ja asuivat siellä liki kymmenen ajastaikaa.
Wọ́n sì fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ará Moabu méjì, orúkọ ọ̀kan ń jẹ́ Oripa, èkejì sì ń jẹ́ Rutu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sì ti gbé níbẹ̀ fún bí ọdún mẹ́wàá,
5 Ja kuolivat nekin molemmat, sekä Mahlon että Kiljon, ja se vaimo jäi jälkeen kahdesta pojastansa ja miehestänsä.
Maloni àti Kilioni náà sì kú, Naomi sì wà láìsí ọkọ tàbí ọmọ kankan fún un mọ́.
6 Ja hän nousi miniöinensä ja palasi Moabilaisten maalta; sillä hän oli Moabilaisten maalla ollessansa kuullut, että Herra oli etsinyt kansaansa ja antanut heille leipää.
Nígbà tí Naomi gbọ́ ní Moabu tí ó wà wí pé Olúwa ti bẹ àwọn ènìyàn rẹ̀ wò nípa fífún wọn ní ọ̀pọ̀ oúnjẹ. Ó sì dìde pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì láti padà sí ìlú rẹ̀.
7 Ja hän läksi pois siitä paikasta, jossa hän oli ollut, molempain miniöinsä kanssa; ja kuin he matkustivat tiellä palataksensa Juudan maalle,
Òun pẹ̀lú àwọn ìyàwó ọmọ rẹ̀ méjèèjì ni wọ́n jọ fi ibi tí ó ń gbé sílẹ̀ tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn padà sí ilẹ̀ Juda.
8 Sanoi Noomi kahdelle miniällensä: menkäät ja palatkaat kukin teidän äitinne huoneesen: tehköön Herra teille laupiuden, niinkuin te olette niille kuolleille ja minulle tehneet!
Ṣùgbọ́n ní ojú ọ̀nà, Naomi wí fún àwọn aya ọmọ rẹ̀ méjèèjì pé, “Kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín padà sí ilé ìyá rẹ̀. Kí Olúwa ṣe àánú fún yín bí ẹ ti ṣe sí èmi àti àwọn ọkọ yín tí ó kú.
9 Herra antakoon teidän kummankin löytää levon miehensä huoneessa! Ja hän suuta antoi heidän, ja he korottivat äänensä ja itkivät,
Kí Olúwa kí ó fi yín lọ́kàn balẹ̀ ní ilé ọkọ mìíràn.” Naomi sì fi ẹnu kò wọ́n ní ẹnu wí pé “Ó dìgbà,” wọ́n sì sọkún kíkankíkan.
10 Ja sanoivat hänelle: sinun kanssas me käymme kansas tykö.
Wọ́n sì wí fún un pé, “Rárá, a ó bà ọ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
11 Mutta Noomi sanoi: palatkaat, tyttäreni: miksi te tahdotte minun kanssani käydä? kuinka minä taidan lapsia saada minun kohdussani teille mieheksi?
Ṣùgbọ́n Naomi dáhùn wí pé, “Ẹ padà sílé ẹ̀yin ọmọ mi. Nítorí kí ni ẹ fi fẹ́ wá pẹ̀lú mi? Ṣé mo tún le bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn ni, tí ó le ṣe ọkọ yin?
12 Palatkaat, minun tyttäreni, ja menkäät, sillä minä olen ylen vanha miestä ottamaan; ja vaikka minä sanoisin: se on toivottava, että minä ottaisin tänä yönä itselleni miehen ja synnyttäisin poikia,
Ẹ padà sílé, ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí èmi ti di arúgbó jù láti ní ọkọ mìíràn. Bí èmí wí pé, èmí ní ìrètí, bí èmí tilẹ̀ ní ọkọ mìíràn ní alẹ́ yìí, tí èmí sì bí àwọn ọmọkùnrin mìíràn,
13 Kuinka te odottaisitte niinkauvan kuin ne suureksi tulisivat? Ja kuinka te taidatte viivyttää, ettette ota miestä? Ei, minun tyttäreni: sillä minä suuresti murehdin teidän tähtenne, ja Herran käsi on sattunut minuun.
ẹ̀yin ha le è dúró dìgbà tí wọ́n yóò fi dàgbà? Ẹ̀yin ó le è dúró dè wọ́n láì fẹ́ ọkọ mìíràn? Rárá, ẹ̀yin ọmọbìnrin mi, nítorí pé inú mi bàjẹ́ gidigidi ju tiyín lọ, nítorí tí ọwọ́ Olúwa fi jáde sí mi!”
14 Niin he korottivat äänensä ja itkivät vielä hartaammasti; ja Orpa antoi suuta anoppinsa, mutta Ruut riippui hänessä.
Wọ́n sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì tún sọkún. Nígbà náà ní Oripa fi ẹnu ko ìyá ọkọ rẹ̀ ní ẹnu wí pé ó dìgbà, ṣùgbọ́n Rutu dì mọ́ ọn síbẹ̀.
15 Mutta hän sanoi hänelle: katsos, kälys on palannut omaistensa tykö ja jumalainsa tykö: palaja sinäkin kälys kanssa!
Naomi wí pé, “Wò ó, arábìnrin rẹ ti padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀ àti òrìṣà rẹ̀, ìwọ náà padà pẹ̀lú rẹ̀.”
16 Ruut vastasi: älä minulle sitä puhu, että minä luovun sinusta ja palajan pois tyköäs; sillä kuhunka sinä menet, sinne myös minä menen, ja kussa sinä yödyt, siellä tahdon myös minä yötä olla: sinun kansas on minun kansani, ja sinun Jumalas on minun Jumalani.
Ṣùgbọ́n Rutu dáhùn wí pé, “Má ṣe rọ̀ mí láti fi ọ́ sílẹ̀ tàbí láti padà lẹ́yìn rẹ. Ibi tí ìwọ bá lọ ní èmi yóò lọ, ibi ti ìwọ bá dúró ni èmi yóò dúró, àwọn ènìyàn rẹ ni yóò jẹ́ ènìyàn mi, Ọlọ́run rẹ ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run mi.
17 Kussa sinä kuolet, siellä minäkin tahdon kuolla ja itseni haudattaa antaa. Herra tehköön minulle sen ja sen, jos ei ainoastaan kuolema eroita meitä!
Níbi tí ìwọ bá kú sí ni èmi yóò kú sí, níbẹ̀ ni wọn yóò sì sin mí sí. Kí Olúwa jẹ mí ní ìyà tí ó lágbára, bí ohunkóhun bí kò ṣe ikú bá yà wá.”
18 Kuin hän näki hänen täydellä mielellä häntä seuraavan, lakkasi hän sitä puhumasta hänen kanssansa.
Nígbà tí Naomi rí i wí pé Rutu ti pinnu láti tẹ̀lé òun kò rọ̀ láti padà mọ́.
19 Ja he matkustivat kahden Betlehemiin asti. Ja kuin he tulivat Betlehemiin, liikkui koko kaupunki heidän tähtensä, ja sanoivat: onko tämä Noomi?
Àwọn méjèèjì sì ń lọ títí wọ́n fi dé ìlú Bẹtilẹhẹmu. Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, ariwo ìpadàbọ̀ wọn gba ìlú kan, àwọn obìnrin ibẹ̀ sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Naomi ni èyí bí?”
20 Mutta hän sanoi heille: älkäät minua kutsuko Noomi, vaan kutsukaat minua Mara; sillä Kaikkivaltias on minun suuresti surulliseksi tehnyt.
Naomi sì dáhùn wí pé, “Ẹ má ṣe pè mí ní Naomi mọ́, ẹ pè mí ní Mara, nítorí wí pé Olódùmarè ti mú kí ayé mi di kíkorò.
21 Täysinäisenä minä täältä läksin, vaan Herra antoi minun tyhjänä palata. Miksi te siis kutsutte minua Noomi? sillä Herra on minun alentanut ja Kaikkivaltias on minua vaivannut.
Mo jáde ní kíkún, ṣùgbọ́n Olúwa mú mi padà ní òfo. Nítorí náà kín ló dé tí ẹ fi ń pè mí ní Naomi, nígbà tí Olódùmarè ti kọ̀ mí sílẹ̀, tí ó sì mú ìdààmú bá mi?”
22 Ja niin palasi Noomi, ja Ruut Moabilainen hänen miniänsä palasi hänen kanssansa Moabilaisten maalta; ja he tulivat Betlehemiin ohran leikkaamisen alussa.
Báyìí ni Naomi ṣe padà láti Moabu pẹ̀lú Rutu, ará Moabu ìyàwó ọmọ rẹ̀. Wọ́n gúnlẹ̀ sí Bẹtilẹhẹmu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè ọkà barle.

< Ruutin 1 >