< 4 Mooseksen 21 >

1 Ja koska Arad Kanaanealaisten kuningas, joka asui etelän puolessa, kuuli Israelin tulleeksi vakoojain tien kautta, soti hän Israelia vastaan ja vei heistä monikahtoja vangiksi.
Nígbà tí ọba Aradi ará Kenaani, tí ń gbé ní gúúsù gbọ́ wí pé Israẹli ń bọ̀ wá ní ojú ọ̀nà Atarimu, ó bá Israẹli jà ó sì fi agbára mú díẹ̀ lára wọn.
2 Niin lupasi Israel Herralle lupauksen ja sanoi: jos sinä annat tämän kansan minun käteni alle, niin minä kiroon heidän kaupunkinsa.
Nígbà náà ni Israẹli jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa pé, “Bí o bá lè fi àwọn ènìyàn yìí lé wa lọ́wọ́, gbogbo ìlú wọn ni a ó parun.”
3 Ja Herra kuuli Israelin rukouksen: ja antoi heille Kanaanealaiset, ja he kirosivat heitä ja heidän kaupungeitansa. Ja kutsui sen paikan Horma.
Olúwa gbọ́ ẹ̀bẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli, ó sì fi àwọn ará Kenaani lé wọn lọ́wọ́. Wọ́n pa wọ́n run pátápátá; torí náà ni a ṣe ń pe ibẹ̀ ní Horma.
4 Sitte menivät he pois Horin vuoren tyköä, Punaisen meren tietä, vaeltamaan Edomilaisten maata ympäri. Ja kansa suuttui matkasta.
Wọ́n rin ìrìnàjò láti òkè Hori lọ sí ọ̀nà tó lọ sí Òkun Pupa, láti kọjá yípo Edomu. Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn bínú ní ojú ọ̀nà;
5 Ja kansa puhui Jumalaa ja Mosesta vastaan: miksi sinä toit meitä Egyptistä korpeen kuolemaan? Sillä ei tässä ole leipää eikä vettä, ja meidän sielumme suuttuu tähän huonoon ruokaan.
wọ́n sì sọ̀rọ̀ lòdì sí Ọlọ́run àti Mose, wọ́n wí pé, “Èéṣe tí ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti kí a ba le wá kú sí aginjù yìí? Kò sí oúnjẹ! Kò sì sí omi! Àwa sì kórìíra oúnjẹ tí kò dára yìí!”
6 Niin Herra lähetti kansan sekaan tuliset kärmeet, jotka kansaa purivat, niin että paljo kansaa Israelista kuoli.
Nígbà náà ni Olúwa rán ejò olóró sí àárín wọn; wọ́n gé àwọn ènìyàn jẹ, ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ Israẹli sì kú.
7 Niin tuli kansa Moseksen tykö, ja sanoivat: me teimme syntiä, puhuen Herraa ja sinua vastaan. Rukoile Herraa nämät kärmeet meidän seastamme ottamaan pois: ja Moses rukoili kansan edestä.
Àwọn ènìyàn sì wá sí ọ̀dọ̀ Mose wọn wí pé, “A ti dá ẹ̀ṣẹ̀ nígbà tí asọ̀rọ̀-òdì sí Olúwa àti sí ìwọ pẹ̀lú. Gba àdúrà pé kí Olúwa mú ejò náà kúrò lọ́dọ̀ wa.” Nígbà náà ni Mose gbàdúrà fún àwọn ènìyàn.
8 Niin sanoi Herra Mosekselle: tee sinulles tulinen kärme, ja nosta se merkiksi ylös: ja tapahtuu, että se joka purtu on, kuin hän katsoo sen päälle, niin hän elää.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Rọ ejò, a ó sì gbé e kọ́ sókè lórí igi, ẹni tí ejò bá ti gé jẹ lè wò ó yóò sì yè.”
9 Ja Moses teki vaskikärmeen, ja nosti sen merkiksi ylös: ja tapahtui, että jos joku kärmeeltä purtiin, ja katsahti vaskikärmeen päälle, niin hän jäi elämään.
Nígbà náà ni Mose sì rọ ejò onírin ó sì gbé e kọ́ sórí igi, bí ejò bá sì bu ẹnikẹ́ni jẹ bí ó bá ti wò ó yóò sì yè.
10 Ja Israelin lapset läksivät, ja sioittivat heitänsä Obotiin.
Àwọn ọmọ Israẹli tẹ̀síwájú wọ́n sì péjọ sí Obotu.
11 Ja läksivät Obotista, ja sioittivat itsensä Abarimin mäen tykö, siihen korpeen, joka Moabin kohdalla on, auringon nousemiseen päin.
Wọ́n gbéra ní Obotu wọ́n sì pa ibùdó sí Iye-Abarimu, ní aginjù tí ó kọjú sí Moabu ní ìdojúkọ ìlà-oòrùn.
12 Sieltä läksivät he, ja sioittivat heitänsä Saredin ojan tykö.
Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti gbéra wọ́n sì pa ibùdó ní àfonífojì Seredi.
13 Niin he sieltä menivät ulos, ja sioittivat heitänsä tälle puolen Arnonia, joka korvessa on, ja tulee Amorilaisten maan ääristä; sillä Arnon on Moabin ja Amorin välillä.
Láti ibẹ̀ lọ, wọn ṣí, wọ́n sì dó sí ìhà kejì Arnoni, tí ó wà ní aginjù tí ó wà ní agbègbè ilẹ̀ àwọn ọmọ Amori. Arnoni jẹ́ ààlà fún ilẹ̀ Moabu, láàrín Moabu àti Amori.
14 Siitä sanotaan Herran sotain kirjassa: Vaheb Suphassa, ja Arnonin ojat.
Ìdí nìyìí tí ìwé ogun Olúwa se wí pé, “…Wahebu ní Sufa, Òkun Pupa àti ní odò Arnoni
15 Ja sen ojan juoksu, joka poikkee Arin asumiseen, ja ulottuu Moabin rajaan.
àti ní ìṣàn odò tí ó darí sí ibùjókòó Ari tí ó sì fi ara ti ìpínlẹ̀ Moabu.”
16 Ja sieltä läksivät he Beraan, se on se kaivo, josta Herra sanoi Mosekselle: kokoa kansa, ja minä annan heille vettä.
Láti ibẹ̀ ni wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ rìn dé Beeri, èyí ni kànga tí Olúwa sọ fún Mose, “Kó àwọn ènìyàn jọ èmi ó sì fún wọn ní omi.”
17 Silloin veisasi Israel tämän virren: Nouse, kaivo, veisatkaat hänestä toinen toisellenne.
Nígbà náà ni Israẹli kọ orin yìí pé, “Sun jáde, ìwọ kànga! Ẹ máa kọrin nípa rẹ̀,
18 Tämä on se kaivo, jonka päämiehet kaivoivat, kansan johdattajat kaivoivat, lain opettajan kautta sauvallansa. Tästä korvesta matkustivat he Mattanaan.
nípa kànga tí àwọn ọmọ-aládé gbẹ́, nítorí àwọn ọlọ́lá ènìyàn ni ó gbẹ́ ẹ; tí àwọn ọlọ́lá àwọn ènìyàn sì fi ọ̀pá aládé àti ọ̀pá oyè wọn gbẹ́.” Nígbà náà wọ́n kúrò láti aginjù lọ sí Mattana,
19 Ja Mattanasta niin Nahalieliin, Ja Nahalielistä niin Bamotiin,
láti Mattana lọ sí Nahalieli, láti Nahalieli lọ sí Bamoti,
20 Ja Bamotista siihen laaksoon, joka on Moabin kedolla, Pisgan kukkulaa kohden, joka katsahtaa korpeen päin.
àti láti Bamoti lọ sí àfonífojì ní Moabu níbi tí òkè Pisga, tí ó wà ní òkè ilé omi ti kọjú sí aginjù.
21 Ja Israel lähetti sanansaattajat Sihonin Amorilaisten kuninkaan tykö, ja käski sanoa hänelle:
Israẹli rán oníṣẹ́ láti sọ fún Sihoni ọba àwọn ará Amori wí pé,
22 Salli minun vaeltaa maakuntas lävitse: emme poikkee peltoihin, emmekä viinamäkiin, emmekä juo vettä kaivosta; maantietä myöten me vaellamme, siihenasti kuin me tulemme sinun maas ääristä ulos.
“Jẹ́ kí a kọjá ní orílẹ̀-èdè rẹ. A kò ní kọjá sí inú oko pápá tàbí ọgbà àjàrà àbí mu omi láti inú kànga. A máa gba òpópónà náà ti ọba títí tí a ó fi la ilẹ̀ rẹ kọjá.”
23 Mutta Sihon ei sallinut Israelin vaeltaa maakuntansa lävitse, vaan Sihon kokosi kaiken väkensä, ja meni Israelia vastaan korpeen, ja tuli Jaksaan, ja soti Israelia vastaan.
Ṣùgbọ́n Sihoni kò ní jẹ́ kí àwọn Israẹli kọjá ní ilẹ̀ wọn. Ó pe àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ wọ́n sì wọ́de ogun lọ sí aginjù nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Nígbà tí ó dé Jahasi, ó bá àwọn ọmọ Israẹli jà.
24 Mutta Israel löi hänen miekan terällä, ja omisti hänen maansa Arnonista Jabbokiin asti, ja vielä Ammonin lapsiin saakka; sillä Ammonin maan ääret olivat vahvat.
Àmọ́, Israẹli ṣẹ́gun, wọn fi ojú idà pa wọ́n, wọ́n sì gba ilẹ̀ láti ọwọ́ Arnoni lọ dé Jabbok, títí tí ó fi dé ilẹ̀ àwọn ará Ammoni, nítorí pé ààlà wọn jẹ́ olódi.
25 Ja näin Israel sai kaikki nämät kaupungit, ja Israel asui kaikissa Amorilaisten kaupungeissa, Hesbonissa ja kaikissa sen tyttärissä.
Israẹli sì gba gbogbo ìlú Amori wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ pẹ̀lú Heṣboni, àti gbogbo ibùgbé ìlú tó yí i ká.
26 Sillä Hesbonin kaupunki oli Sihonin Amorilaisten kuninkaan oma, ja hän soti ennen Moabilaisten kuninkaan kanssa, ja otti häneltä kaiken hänen maansa Arnoniin asti.
Heṣboni ni ìlú Sihoni ọba àwọn ará Amori, ẹni tí ó bá ọba Moabu ti tẹ́lẹ̀ jà tí ó sì gba gbogbo ilẹ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀ títí dé Arnoni.
27 Siitä sananlaskussa sanotaan: tulkaat Hesboniin: rakennettakoon ja valmistettakoon Sihonin kaupunki;
Ìdí nìyìí tí akọrin sọ wí pé, “Wá sí Heṣboni kí ẹ jẹ́ kí a tún un kọ́; jẹ́ kí ìlú Sihoni padà bọ̀ sípò.
28 Sillä tuli on käynyt Hesbonista ulos, ja liekki Sihonin kaupungista: se on kuluttanut Moabin Arin, ja Arnonin korkeuden asuvaiset.
“Iná jáde láti Heṣboni, ọ̀wọ́-iná láti Sihoni. Ó jó Ari àti Moabu run, àti ìlú àwọn olùgbé ibi gíga Arnoni.
29 Voi sinuas Moab! sinä Kamosin kansa olet hukkunut! Hän saatti poikansa pakolaiseksi ja hänen tyttärensä vangiksi, Sihonille Amorilaisten kuninkaalle.
Ègbé ní fún ọ, ìwọ Moabu! Ẹ ti parun, ẹ̀yin ènìyàn Kemoṣi! Ó ti fi ọmọ rẹ̀ ọkùnrin sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìsáǹsá àti ọmọ rẹ̀ obìnrin gẹ́gẹ́ bí ìgbèkùn fún Sihoni ọba àwọn Amori.
30 Me olemme heitä ampuneet, Hesbon on kukistettu Diboniin asti: me hävitimme heitä hamaan Nophaan, joka Medebaan ulottuu.
“Ṣùgbọ́n àti bì wọ́n ṣubú; a ti pa ìjẹgàba Heṣboni run, a pa wọ́n run títí dé Diboni. A sì ti bì wọ́n lulẹ̀ títí dé Nofa, tí ó sì fi dé Medeba.”
31 Ja niin Israel asui Amorilaisten maakunnassa.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Israẹli sì ń gbé ní ilẹ̀ Amori.
32 Sitte lähetti Moses vakoomaan Jaeseria, ja he voittivat sen tyttärinensä, ja omistivat ne Amorilaiset, jotka siinä asuivat.
Lẹ́yìn ìgbà tí Mose rán ayọ́lẹ̀wò lọ sí Jaseri, àwọn ọmọ Israẹli sì gba àwọn agbègbè tó yí wọn ká wọ́n sì lé àwọn Amori tó wà níbẹ̀ jáde.
33 Ja he palasivat ja menivät ylöspäin tietä Basaniin. Niin Og, Basanin kuningas, meni heitä vastaan, hän ja kaikki hänen väkensä, sotimaan Edreissä.
Nígbà náà wọ́n pẹ̀yìndà wọ́n sì gòkè lọ sí Baṣani, Ogu ọba ti Baṣani àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wọ́de ogun jáde láti pàdé wọn ní ojú ogun ní Edrei.
34 Ja Herra sanoi Mosekselle: älä pelkää häntä, sillä minä annoin hänen sinun käsiis, sekä kaiken hänen väkensä, että hänen maansa: ja sinun pitää tekemän hänelle niinkuin sinä Sihonille Amorilaisten kuninkaalle teit, joka Hesbonissa asui.
Olúwa sọ fún Mose pé, “Má ṣe bẹ̀rù rẹ̀, nítorí tí mó tí fi òun lé ọ lọ́wọ́, àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, àti ilẹ̀ rẹ̀, kí ìwọ kí ó ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe sí Sihoni ọba Amori ẹni tí ó ń jẹ ọba ní Heṣboni.”
35 Ja he löivät hänen ja hänen poikansa ja hänen väkensä, siihenasti ettei yksikään elämään jäänyt, ja he valloittivat hänen maansa.
Wọ́n sì pa á, pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀, wọn kò fi ku ẹnìkan fún un láàyè. Wọ́n sì gba ìní ilẹ̀ rẹ̀.

< 4 Mooseksen 21 >