< 3 Mooseksen 25 >

1 Ja Herra puhui Mosekselle Sinain vuorella, sanoen:
Olúwa sọ fún Mose ní orí òkè Sinai pé,
2 Puhu Israelin lapsille ja sano heille: koska te tulette siihen maahan, jonka minä teille annan, niin maan pitää pitämän Herralle lepoa.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Nígbà tí ẹ bá dé ilẹ̀ náà tí èmi ó fi fún yín, ilẹ̀ náà gbọdọ̀ sinmi fún Olúwa.
3 Kuusi vuotta pitää sinun peltos kylvämän, ja kuusi vuotta viinamäkes leikkaaman, ja sen hedelmät kokooman;
Ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi gbin oko rẹ, ọdún mẹ́fà ni ìwọ ó fi tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ, tí ìwọ ó sì fi kó èso wọn jọ.
4 Mutta seitsemäntenä vuonna pitää maan pitämän Herralle suuren pyhän, jona ei sinun pidä kylvämän sinun peltoas taikka leikkaaman sinun viinamäkeäs.
Ṣùgbọ́n ní ọdún keje kí ilẹ̀ náà ní ìsinmi: ìsinmi fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ tọ́jú ọgbà àjàrà rẹ.
5 Ja mitä itsestänsä kasvaa laihostas, ei sinun pidä leikkaaman, ja viinamarjoja, jotka ilman sinun työtäs ovat kasvaneet, ei sinun pidä noukkiman; sillä se on maan lepovuosi.
Ẹ má ṣe kórè ohun tí ó tìkára rẹ̀ hù, ẹ má ṣe kórè èso àjàrà ọgbà tí ẹ ò tọ́jú. Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ ní ìsinmi fún ọdún kan.
6 Mutta maan lepoa sinun pitää sentähdn pitämän, että sinun pitää siitä syömän, sinun palvelias ja piikas, niin myös päivämiehes, huonekuntaises, ja muukalaiset sinun tykönäs.
Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ọdún ìsinmi ni yóò jẹ́ oúnjẹ fún yín àní fún ẹ̀yin tìkára yín, àwọn ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin yín, àwọn alágbàṣe àti àwọn tí ń gbé pẹ̀lú yín fún ìgbà díẹ̀.
7 Ja sinun karjalles ja eläimilles sinun maallas kaikki, mitä siinä kasvaa, pitää oleman ruaksi.
Fún àwọn ohun ọ̀sìn yín, àti àwọn ẹranko búburú ní ilẹ̀ yín. Ohunkóhun tí ilẹ̀ náà bá mú jáde ní ẹ lè jẹ.
8 Ja sinun pitää lukeman sinulles seitsemän lepovuotta, niin että seitsemän vuotta pitää seitsemän kertaa luettaman: ja ne seitsemän lepovuoden aikaa tekee yhdeksän vuotta viidettäkymmentä.
“‘Ọdún ìsinmi méje èyí tí í ṣe ọdún mọ́kàndínláàádọ́ta ni kí ẹ kà.
9 Niin sinun pitää antaman soittaa basunalla ylitse koko teidän maakuntanne, kymmenentenä päivänä seitsemäntenä kuukautena: juuri sovintopäivänä pitää teidän antaman basunan käydä yli koko teidän maakuntanne.
Lẹ́yìn náà, kí ẹ fọn fèrè ní gbogbo ibikíbi ní ọjọ́ kẹwàá oṣù keje ní ọjọ́ ìwẹ̀nùmọ́. Ní ọjọ́ ètùtù yìí, ẹ fọn fèrè yíká gbogbo ilẹ̀ yín.
10 Ja teidän pitää sen viidennenkymmenennen vuoden pyhittämän, ja pitää kuuluttaman vapauden maassa kaikille niille, jotka siinä asuvat; sillä se on teidän riemuvuotenne: silloin pitää itsekunkin pääsemän jälleen omaan saamaansa, itsekukin omaan sukuunsa.
Ẹ ya àádọ́ta ọdún náà sọ́tọ̀ kí ẹ sì kéde òmìnira fún gbogbo ẹni tí ń gbé ilẹ̀ náà. Yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Kí olúkúlùkù padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀ àti sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ̀.
11 Sillä viideskymmenes vuosi on teidän riemuvuotenne: ei teidän pidä kylvämän, eikä leikkaaman itsestänsä kasvanutta, eikä myös hakeman niitä, mitkä ilman työtä kasvaneet ovat.
Àádọ́ta ọdún ni yóò jẹ́ ọdún ìdásílẹ̀ fún yín. Ẹ má ṣe gbin ohunkóhun, ẹ kò sì gbọdọ̀ kórè ohun tí ó hù fúnra rẹ̀ tàbí kí ẹ kórè ọgbà àjàrà tí ẹ kò dá.
12 Sillä se on riemuvuosi, se pitää pyhitettämän teiltä. Mutta teidän pitää syömän niitä kaikkia, mitä maa kantaa.
Torí pé ọdún ìdásílẹ̀ ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ mímọ́ fún yín. Ẹ jẹ ohun tí ẹ mú jáde nínú oko náà.
13 Tämä on riemuvuosi, jona itsekunkin teistä pitää omaan saamaansa pääsemän jällensä.
“‘Ní ọdún ìdásílẹ̀ yìí, kí olúkúlùkù gbà ohun ìní rẹ̀ padà.
14 Jos sinä jotakin myyt lähimmäiselles, taikka ostat jotakin häneltä, niin ei yhdenkään pidä pettämän veljeänsä.
“‘Bí ẹ bá ta ilẹ̀ fún ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín tàbí bí ẹ bá ra èyíkéyìí láti ọ̀dọ̀ rẹ̀, ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ.
15 Vaan riemuvuoden luvun jälkeen pitää sinun ostaman lähimmäiseltäs, ja vuoden tulon jälkeen pitää hänen sinulle myymän.
Kí ẹ ra ilẹ̀ lọ́wọ́ àwọn ènìyàn yín ní gẹ́gẹ́ bí iye owó tí ó kù kí ọdún ìdásílẹ̀ pé, kí òun náà sì ta ilẹ̀ fún yín gẹ́gẹ́ bí iye ọdún rẹ̀ tókù láti kórè.
16 Sitä usiammat kuin vuodet ovat, pitää sinun korottaman hinnan, ja sen harvemmat kuin vuodet ovat, pitää sinun alentaman hinnan; sillä vuoden tulon luvun jälkeen pitää hänen myymän sinulle.
Bí iye ọdún rẹ̀ bá gùn, kí iye owó rẹ̀ pọ̀, bí iye ọdún rẹ̀ bá kúrú, kí iye owó rẹ̀ kéré, torí pé ohun tí ó tà gan an ní iye èso rẹ̀.
17 Älkään kenkään pettäkö lähimmäistänsä, mutta pelkää sinun Jumalaas; sillä minä olen Herra teidän Jumalanne.
Ẹ má ṣe rẹ́ ara yín jẹ, ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.
18 Sentähden tehkäät minun säätyni ja pitäkäät minun oikeuteni, että te ne teette, ja turvallisesti asutte maassa.
“‘Ẹ tẹ̀lé àwọn ìlànà mi, kí ẹ sì kíyèsi láti pa òfin mi mọ́, kí ẹ ba à le máa gbé láìléwu ní ilẹ̀ náà.
19 Ja maan pitää antaman teille hedelmänsä, ja teillä pitää oleman kyllä syötävää, ja asuman pelkäämätä siinä.
Nígbà yìí ni ilẹ̀ náà yóò so èso rẹ̀, ẹ ó sì jẹ àjẹyó, ẹ ó sì máa gbé láìléwu.
20 Ja jos te sanotte: mitä meidän pitää syömän seitsemäntenä vuonna? katso, ei meidän pidä kylvämän, eikä vuoden tuloa kokooman.
Ẹ le béèrè pé, “Kí ni àwa ó jẹ ní ọdún keje, bí a kò bá gbin èso tí a kò sì kórè?”
21 Niin minä käsken minun siunaukseni tulla kuudentena vuotena teidän ylitsenne, niin että sen pitää tekemän teille kolmen vuoden tulon.
Èmi ó pèsè ìbùkún sórí yín tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ yín yóò so èso tó tó fún ọdún mẹ́ta lẹ́yìn rẹ̀.
22 Ja teidän pitää kylvämän kahdeksantena vuonna, ja vanhasta vuoden kasvusta syömän yhdeksänteen vuoteen asti, niin että te syötte vanhasta uutiseen asti.
Bí ẹ bá gbin èso yín ní ọdún kẹjọ, àwọn èso ti tẹ́lẹ̀ ní ẹ ó máa jẹ, títí tí ìkórè ti ọdún kẹsànán yóò fi dé.
23 Sentähden ei teidän pidä maata peräti myymän; sillä maan on minun, ja te olette muukalaiset ja vieraat minun edessäni.
“‘Ẹ má ṣe ta ilẹ̀ yín ní àtàpa torí pé ẹ̀yin kọ́ lẹ ni ín, ti Ọlọ́run ni, ẹ̀yin jẹ́ àjèjì àti ayálégbé.
24 Ja teidän pitää koko teidän omassa maassanne antaman maan lunastettaa.
Ní gbogbo orílẹ̀-èdè ìní yín, ẹ fi ààyè sílẹ̀ fún ìràpadà ilẹ̀ náà.
25 Jos sinun veljes köyhtyy, ja myy sinulle omaisuudestansa, ja hänen lähimmäinen lankonsa tulee hänen tykönsä, ja tahtoo lunastaa, niin pitää hänen lunastaman sen, minkä hänen veljensä myynyt on.
“‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn yín bá tálákà, dé bi pé ó ta ara àwọn ẹrù rẹ̀, kí ará ilé rẹ̀ tí ó súnmọ́ ọ ra ohun tí ó tà padà.
26 Ja jos joku on, jolla ei yhtään lunastajaa ole, ja taitaa niin paljo matkaan saada, kuin sen lunastukseksi tarvitaan.
Ẹni tí kò ní ẹni tó lè rà á padà fún un, tí òun fúnra rẹ̀ sì ti lọ́rọ̀, tí ó sì ní ànító láti rà á.
27 Niin pitää luettaman vuosiluku sittenkuin hän myi, ja annettaman hänelle, joka myi, mitä liiaksi on, että hän tulis omaisuuteensa jälleen.
Kí ó mọ iye owó tí ó jẹ fún iye ọdún tí ó tà á, kí ó dá iye tí ó kù padà fún ẹni tí ó tà á fún, lẹ́yìn náà, ó lè padà sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
28 Mutta jos ei hän takaansa löydä niin paljo että hän sais sen jälleen, niin pitää sen, minkä hän myynyt on, oleman ostajan kädessä riemuvuoteen asti; niin hänen pitää oleman vapaan ja saaman omansa jälleen.
Ṣùgbọ́n bí kò bá rí ọ̀nà àti san án padà fún un. Ohun tí ó tà wà ní ìkáwọ́ ẹni tí ó rà á títí di ọdún ìdásílẹ̀. Kí ó dá a padà fún ẹni tí ó ni i ní ọdún ìdásílẹ̀, ẹni tí ó ni í tẹ́lẹ̀ lè tún padà gbà ohun ìní rẹ̀.
29 Se joka myy asuttavan huoneen kaupungin muurin sisältä, hänellä on vapaa ehto ajastajassa, sitä lunastaa jällensä: ja sen pitää oleman ajan, jolla hän lunastaa sen.
“‘Bí arákùnrin kan bá ta ilé gbígbé kan ní ìlú olódi, kí ó rà á padà ní ìwọ̀n ọdún kan sí àkókò tí ó tà á, ní ìwọ̀n ọdún kan ni kí ó rà á padà.
30 Ja jos ei hän lunasta sitä koko ajastajassa, niin pitää ostajan sen huoneen kaupungin muurin sisältä pitämän ijankaikkisesti ja hänen sukunsa, ja ei pidä vapaaksi tuleman ilovuotena.
Ṣùgbọ́n bí kò bá rà á padà láàrín ọdún náà ilé náà tí ó wà láàrín ìlú ni kí ó yọ̀ǹda pátápátá fún ẹni tí ó rà á, àti àwọn ìdílé rẹ̀. Kí wọ́n má da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
31 Mutta jos huone on maan kylässä, kussa ei yhtään muuria ympärillä ole, niin se pitää luettaman peltomaaksi: se lunastetaan ja tulee ilovuotena vapaaksi.
Ṣùgbọ́n àwọn ilé tí ó wà ní abúlé láìní odi ni kí a kà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ oko, a lè rà wọ́n padà, kí wọ́n sì da padà ní ọdún ìdásílẹ̀.
32 Leviläisten kaupungit ja huoneet kaupungeissa, joissa heidän tavaransa ovat, saavat he aina lunastaa.
“‘Àwọn ọmọ Lefi ní ẹ̀tọ́, nígbàkígbà láti ra ilẹ̀ wọn, tí ó jẹ́ ohun ìní wọn ní àwọn ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Lefi.
33 Se joka jotakin lunastaa Leviläisiltä, hänen pitää siitä luopuman ilovuonna, olkoon se ostettu huone eli omaisuus kaupungissa, jossa hän asunut on; sillä huoneet Leviläisten kaupungeissa ovat heidän omaisuutensa Israelin lasten seassa.
Torí náà ohun ìní àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n rà padà, fún àpẹẹrẹ, èyí ni pé ilẹ̀ tí a bá tà ní ìlúkílùú tí ó jẹ́ tiwọn, ó sì gbọdọ̀ di dídápadà ní ọdún ìdásílẹ̀, torí pé àwọn ilẹ̀ tí ó wà ní ìlú àwọn Lefi ni ìní wọn láàrín àwọn ará Israẹli.
34 Mutta maata heidän kaupunkeinsa ympäriltä ei pidä myytämän; sillä se on heidän saamansa ijankaikkisesti.
Ṣùgbọ́n ilẹ̀ tí wọ́n ti ń da ẹran tí ó jẹ́ ti ìlú wọn, wọn kò gbọdọ̀ tà wọ́n, ilẹ̀ ìní wọn láéláé ni.
35 Jos veljes köyhtyy ja tulee voimattomaksi tykönäs, niin sinun pitää pitämän hänen ylös, niinkuin muukalaisen, taikka huonekuntaisen, että hän eläis sinun kanssas.
“‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà tí kò sì le è pèsè fún àìní ara rẹ̀, ẹ pèsè fún un bí ẹ ti ń ṣe fún àwọn àlejò tàbí àwọn tí ẹ gbà sílé: kí ó ba à le è máa gbé láàrín yín.
36 Ja ei sinun pidä ottaman korkoa eli voittoa häneltä; vaan pelkää sinun Jumalaas, että sinun veljes sais elää sinun kanssas.
Ẹ kò gbọdọ̀ gba èlé kankan lọ́wọ́ rẹ̀, ẹ bẹ̀rù Olúwa kí arákùnrin yín le è máa gbé láàrín yín.
37 Ei sinun pidä antaman rahaas hänelle korolle, eikä antaman viljaas kasvulle.
Ẹ má ṣe gba èlé lórí owó tí ẹ yá a bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọdọ̀ jẹ èrè lórí oúnjẹ tí ẹ tà fún un.
38 Sillä minä olen Herra teidän Jumalanne, joka teidän johdatin Egyptin maalta, antaakseni teille Kanaanin maan, ja ollakseni teidän Jumalanne.
Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín tí ó mú yín jáde láti ilẹ̀ Ejibiti láti fún yín ní ilẹ̀ Kenaani àti láti jẹ́ Ọlọ́run yín.
39 Jos veljes köyhtyy sinun tykönäs, ja myy itsensä sinulle, niin ei sinun pidä häntä pitämän niinkuin orjaa.
“‘Bí arákùnrin yín kan bá tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ fún ọ bí ẹrú. Má ṣe lò ó bí ẹrú.
40 Mutta hänen pitää oleman sinun tykönäs niinkuin päivämiehen, eli huonekuntaisen, palvellen sinua riemuvuoteen asti.
Jẹ́ kí ó wà lọ́dọ̀ rẹ bí alágbàṣe tàbí àlejò láàrín yín, kí ó máa ṣiṣẹ́ sìn ọ́ títí di ọdún ìdásílẹ̀.
41 Silloin pitää hänen käymän ulos vapaana sinun tyköäs lapsinensa, ja pitää tuleman sukunsa tykö jälleen, ja isäinsä saaman päälle.
Nígbà náà ni kí ó yọ̀ǹda òun àti àwọn ọmọ rẹ̀, kí wọ́n padà sí ìdílé wọn àti sí ilẹ̀ ìní baba wọn.
42 Sillä he ovat minun palveliani, jotka minä Egyptin maalta johdattanut olen: sentähden ei pidä heitä orjan tavalla myytämän.
Torí pé ìránṣẹ́ mi ni àwọn ará Israẹli jẹ́. Ẹni tí mo mú jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, torí èyí ẹ kò gbọdọ̀ tà wọ́n lẹ́rú.
43 Ei sinun pidä ankarasti heitä hallitseman, vaan pelkäämän sinun Jumalaas.
Ẹ má ṣe rorò mọ́ wọn: ṣùgbọ́n ẹ bẹ̀rù Ọlọ́run yín.
44 Jos tahdot pitää orjaa ja piikaa, niin sinun pitää ostaman ne pakanoilta, jotka teidän ympärillänne ovat.
“‘Àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin yín lè jẹ́ láti orílẹ̀-èdè tí ó yí yín ká, ẹ lè ra àwọn ẹrú wọ̀nyí lọ́wọ́ wọn.
45 Ja huonekuntalaisilta, jotka muukalaiset ovat teidän seassanne, pitää teidän ne ostaman, ja heidän suvuiltansa, jotka he teidän tykönänne teidän maassanne synnyttäneet ovat: ja ne pitää teidän omanne oleman.
Bákan náà, ẹ sì le è ra àwọn àlejò tí ń gbé láàrín yín, àti àwọn ìdílé wọn tí a bí sáàrín yín. Wọn yóò sì di ohun ìní yín.
46 Ja pitäkäät heitä omananne, ja teidän lapsillenne teidän jälkeenne ijankaikkiseksi perimiseksi, ja niiden pitää oleman teidän orjanne; mutta veljenne Israelin lapset ei pidä toinen toistansa ankarasti hallitseman.
Ẹ lè fi wọ́n sílẹ̀ bí ogún fún àwọn ọmọ yín, wọ́n sì lè sọ wọ́n di ẹrú títí láé. Ṣùgbọ́n ẹ kò gbọdọ̀ rorò mọ́ ọmọ Israẹli kankan.
47 Jos muukalainen eli huonekuntainen hyötyy sinun tykönäs, ja sinun veljes köyhtyy hänen tykönänsä, niin että hän myy itsensä muukalaiselle, joka huonekuntainen sinun tykönäs on, eli jollekulle muukalaisen suvusta,
“‘Bí àlejò kan láàrín yín tàbí ẹni tí ń gbé àárín yín fún ìgbà díẹ̀ bá lọ́rọ̀ tí ọmọ Israẹli sì tálákà dé bi pé ó ta ara rẹ̀ lẹ́rú fún àlejò tàbí ìdílé àlejò náà.
48 Niin pitää hänellä oikeus oleman lunastettaa jälleen sittekuin hän myyty on, että joku hänen veljistänsä pitäis hänen lunastaman jällensä;
Ó lẹ́tọ̀ọ́ si ki a rà á padà lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ta ara rẹ̀. Ọ̀kan nínú ìbátan rẹ̀ le è rà á padà.
49 Eli hänen setänsä eli setänsä poika lunastakaan hänen, taikka joku hänen lähimmäisestä suvustansa, eli jos hän itse taitaa niin paljo matkaan saada, niin pitää hänen lunastaman itsensä.
Àbúrò baba rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá tan nínú ìdílé rẹ̀ le è rà wọ̀n padà. Bí ó bá sì ti lọ́rọ̀, ó lè ra ara rẹ̀ padà.
50 Ja hänen pitää lukua laskeman ostajansa kanssa, siitä vuodesta kuin hän myi itsensä ilovuoteen asti, ja raha pitää luettaman vuoden luvun jälkeen, sittekuin hän myytiin, ja kaiken sen ajan palkka pitää siihen luettaman:
Kí òun àti olówó rẹ̀ ka iye ọdún tí ó ta ara rẹ̀ títí dé ọdún ìdásílẹ̀ kí iye owó ìdásílẹ̀ rẹ̀ jẹ́ iye tí wọ́n ń san lórí alágbàṣe fún iye ọdún náà.
51 Ja jos vielä monta vuotta on ilovuoteen, niin hänen pitää sitä enemmän antaman lunastuksestansa, senjälkeen kuin hän ostettu on.
Bí iye ọdún rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù bá pọ̀, kí iye owó fún ìràpadà rẹ̀ pọ̀.
52 Mutta jos harvat vuodet ovat ilovuoteen, niin laskekaan lukua hänen kanssansa ja hänen pitää vuotten jälkeen antaman lunastuksensa.
Bí ó bá sì ṣe pé kìkì ọdún díẹ̀ ni ó kù títí di ọdún jubili, kí ó ṣe ìṣirò rẹ̀, kí ó sì san owó náà bí iye ìṣirò rẹ̀ padà.
53 Ja pitää hänen palkkansa myös siihen luettaman vuosi vuodelta, ja ei hänen pidä ankaruudella häntä hallitseman sinun edessäs.
Bí ẹ ti ń ṣe sí i lọ́dọọdún, ẹ rí i dájú pé olówó rẹ̀ kò korò mọ́ ọ.
54 Jos ei hän näin lunasta itsiänsä, niin hänen pitää ilovuonna vapaana käymän ulos lapsinensa.
“‘Bí a kò bá rà á padà nínú gbogbo ọ̀nà wọ̀nyí, kí ẹ tú òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sílẹ̀ ní ọdún ìdásílẹ̀.
55 Sillä Israelin lapset ovat minun palveliani; he ovat minun palveliani, jotka minä olen Egyptin maalta johdattanut ulos: Minä olen Herra teidän Jumalanne.
Nítorí pé ìránṣẹ́ ni àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ fún mi. Ìránṣẹ́ mi ni wọ́n, tí mo mú jáde láti Ejibiti wá. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.

< 3 Mooseksen 25 >