< Tuomarien 6 >

1 Ja Israelin lapset taas tekivät pahaa Herran edessä; ja Herra antoi heidät Midianilaisten käteen seitsemäksi ajastajaksi.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 Koska Midianilaisten käsi oli ylen ankara Israelin päällä, tekivät Israelin lapset heillensä Midianilaisten tähden hautoja vuorille, ja luolia ja linnoja.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Ja kuin Israel jotakin kylvi, tulivat Midianilaiset ja Amalekilaiset, ja ne itäiseltä maalta heidän päällensä,
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 Ja asettivat leirinsä heitä vastaan ja turmelivat kaiken maan kasvun Gasariin asti; ja ei yhtäkään elatusta Israelille jättäneet ei lampaita, härkiä eikä aaseja.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Sillä he tulivat laumoinensa ja majoinensa, ja niinkuin suuri metsäsirkkain paljous, että sekä he ja heidän kamelinsa olivat lukemattomat, ja tulivat hävittämään maata.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Niin Israel peräti köyhtyi Midianilaisten tähden. Silloin huusivat Israelin lapset Herran tykö.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Ja kuin Israelin lapset huusivat Herran tykö Midianilaisten tähden,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 Lähetti Herra prophetan Israelin lasten tykö, joka sanoi heille: näin sanoo Herra Israelin Jumala: minä johdatin teidät Egyptistä, ja talutin teidät ulos orjuuden huoneesta,
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Ja pelastin teidät Egyptiläisten kädestä ja kaikkein kädestä, jotka teitä vaivasivat, jotka minä ajoin teidän edestänne ulos, ja annoin teille heidän maansa,
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 Ja minä sanoin teille: Minä olen Herra teidän Jumalanne, älkäät peljätkö Amorilaisten jumalia, joiden maassa te asutte; ja ette totelleet minun ääntäni.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Ja Herran enkeli tuli ja istui tammen alla Ophrassa, joka Joaksen Abiesriläisen oma oli; ja hänen poikansa Gideon tappoi nisuja viinakuurnan tykönä, saadaksensa ne säilytetyksi Midianilaisilta.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Silloin ilmaantui Herran enkeli hänelle ja sanoi: Herra olkoon sinun kanssas, sinä väkevä sotamies!
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 Niin sanoi Gideon hänelle: minun Herrani, jos Herra on meidän kanssamme, miksi meille siis kaikki nämät tapahtuneet ovat? Kussa ovat kaikki hänen ihmeensä, jotka meidän isämme ilmoittivat meille ja sanoivat: eikö Herra meitä johdattanut Egyptistä? Mutta nyt on Herra meidät hyljännyt ja antanut Midianilaisten käsiin.
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Ja Herra käänsi itsensä hänen tykönsä ja sanoi: mene tässä väkevyydessäs! Sinä vapahdat Israelin Midianilaisten kädestä: enkö minä ole sinua lähettänyt?
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Hän sanoi hänelle: minun Herrani, millä minä vapahdan Israelin? Katso, minun sukuni on kaikkein köyhin Manassessa, ja minä olen kaikkein pienin minun isäni huoneessa.
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 Ja Herra sanoi hänelle: totisesti minä olen sinun kanssas, ja sinä lyöt Midianilaiset niinkuin yhden miehen.
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Mutta hän sanoi hänelle: jos minä olen nyt löytänyt armon sinun tykönäs, niin anna minulle merkki, että sinä se olet, joka minun kanssani puhut.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Älä kumminkaan täältä lähde, siihenasti kuin minä tulen sinun tykös, ja kannan minun ruokauhrini ja panen sinun etees. Hän sanoi: minä olen siihenasti kuin sinä palajat.
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Gideon tuli ja teurasti vohlan, ja otti ephan happamattomia jauhoja, ja pani lihan koriin ja lihan liemen pataan, ja vei hänen tykönsä tammen alle ja pani eteen.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Ja Jumalan enkeli sanoi hänelle: ota liha ja happamaton leipä, ja pane tämän kiven päälle, ja kaada liemi ulos; ja hän teki niin.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Ja Herran enkeli ojensi sauvansa pään, joka oli hänen kädessänsä, ja satutti lihaan ja happamattomaan leipään, ja tuli nousi kivestä ja kulutti lihan ja happamattoman leivän. Ja Herran enkeli katosi hänen silmäinsä edestä.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 Kun Gideon näki sen olevan Herran enkelin, sanoi hän: Herra, Herra, olenko minä niin nähnyt Herran enkelin kasvoista kasvoihin!
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 Mutta Herra sanoi hänelle: rauha olkoon sinulle! älä pelkää, et sinä kuole.
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Ja Gideon rakensi Herralle alttarin siinä, jonka hän kutsui rauhan Herraksi. Se on vielä tänäpänä Abiesriläisten Ophrassa.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 Ja sinä yönä sanoi Herra hänelle: ota mulli isäs karjasta ja toinen mulli, joka on seitsemännellä vuodella, ja kukista Baalin alttari, joka on sinun isälläs, ja hävitä metsistö, joka siinä tykönä on,
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Ja rakenna Herralle sinun Jumalalles alttari tälle korkialle vuorelle, sopivaiselle paikalle, ja ota toinen mulleista ja uhraa se polttouhriksi metsistön puilla jonka sinä hakkaat.
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Silloin otti Gideon kymmenen miestä palvelioistansa ja teki niinkuin Herra hänelle sanonut oli. Mutta hän pelkäsi ei saavansa sitä päivällä tehdä isänsä huoneen ja kaupungin asuvaisten tähden, ja teki sen yöllä.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Kuin kaupungin kansa aamulla nousivat, katso, Baalin alttari oli kukistettu ja metsistö maahan hakattu, joka sen tykönä oli, ja toinen mulli pantu polttouhriksi alttarille, joka siihen rakennettu oli.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Ja he sanoivat toinen toisellensa: kuka on tämän tehnyt? Koska he visusti kyselivät ja tutkistelivat, niin he sanoivat: Gideon Joaksen poika sen teki.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Niin kaupungin asuvaiset puhuivat Joakselle, sanoen: anna poikas tulla tänne! Hänen pitää kuoleman; sillä hän on Baalin alttarin kukistanut ja metsistön hakannut, joka siinä tykönä oli.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Niin Joas sanoi kaikille, jotka seisoivat häntä vastaan: riitelettekö te Baalin puolesta? autatteko te häntä? Joka riitelee hänen puolestansa, sen pitää kuoleman ennen aamua: jos hän on jumala, niin kostakoon itse, että hänen alttarinsa on kukistettu.
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Ja siitä päivästä kutsui hän hänen JerubBaal ja sanoi: Baal kostakoon itse, että hänen alttarinsa kukistettu on.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Kuin kaikki Midianilaiset ja Amalekilaiset ja ne itäiseltä maalta kokosivat itsensä yhteen, ja menivät ja sioittivat heitänsä Jisreelin laaksoon,
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Niin Herran henki täytti Gideonin, ja hän puhalsi basunaan ja kutsui Abieserin seuraamaan itsiänsä.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 Ja hän lähetti sanan koko Manasselle ja kutsui myös heitä seuraamaan. Hän lähetti myös sanan Asserille, Sebulonille ja Naphtalille, ja hekin tulivat heitä vastaan.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Ja Gideon sanoi Jumalalle: jos sinä vapahdat Israelin minun käteni kautta, niinkuin sinä sanonut olet;
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 Katso, minä panen villaisen nahan pihalle: jos kaste tulee ainoastaan nahan päälle ja kaikki muu maa on kuiva, niin minä ymmärrän, ettäs minun käteni kautta Israelin vapahdat, niinkuin sinä sanonut olet.
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Ja se tapahtui niin: kuin hän toisena päivänä varhain nousi, kääri hän nahan kokoon ja pusersi kasteen nahasta ja täytti maljan vedestä.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 Ja Gideon sanoi Jumalalle: älköön sinun vihas syttykö minua vastaan, jos minä vielä kerran puhun: minä koettelen vielä kerran sitä nahalla: anna ainoastaan nahan kuivan olla ja kaikella muulla maalla kasteen.
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Jumala teki myös niin sinä yönä: ja nahka ainoastaan jäi kuivaksi, ja kaste tuli kaiken maan päälle.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.

< Tuomarien 6 >