< Joosuan 22 >

1 Silloin kutsui Josua tykönsä Rubenilaiset, Gadilaiset ja puolen Manassen sukukuntaa:
Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
2 Ja sanoi heille: te piditte kaikki mitä Moses Herran palvelia teille käski, ja olette kuulleet minun ääneni kaikissa mitä minä olen teille käskenyt.
ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
3 Ette hyljänneet teidän veljiänne isoon aikaan tähän päivään asti, ja te piditte Herran teidän Jumalanne käskyn.
Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
4 Ja nyt on Herra teidän Jumalanne antanut teidän veljillenne levon, niinkuin hän sanoi heille; palatkaat siis nyt ja menkäät teidän majoillenne perintömaahanne, jonka Moses Herran palvelia antoi teille tuolla puolella Jordania.
Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
5 Ainoastaan ottakaat visusti vaari, että te teette sen käskyn ja lain jälkeen, jonka Moses Herran palvelia on teille käskenyt, että te rakastatte Herraa teidän Jumalaanne, ja vaellatte kaikissa hänen teissänsä, ja pidätte hänen käskynsä, ja riiputte hänessä kiinni, ja palvelette häntä kaikesta teidän sydämestänne ja kaikesta teidän sielustanne.
Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
6 Niin Josua siunasi heitä ja antoi heidän mennä, ja he menivät majoillensa.
Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
7 Manassen puolelle sukukunnalle on Moses antanut Basanissa ja toiselle puolelle antoi Josua heidän veljeinsä keskellä tällä puolella Jordania länteen päin. Ja kuin Josua antoi heidän käydä majoillensa ja siunasi heitä,
(Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
8 Puhui hän heille, sanoen: te tulette kotia suurella saaliilla teidän majoillenne ja sangen suurella karjalaumalla, hopialla, kullalla, vaskella, raudalla ja aivan paljoilla vaatteilla; niin jakakaat teidän vihamiestenne saalis teidän veljeinne kanssa.
Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
9 Ja niin palasivat Rubenilaiset ja Gadilaiset ja puoli Manassen sukukuntaa, ja menivät pois Israelin lasten tyköä Silosta, joka Kanaanin maalla on, menemään Gileadin maahan, perintömaahansa, jonka he olivat perineet Herran käskyn jälkeen Moseksen kautta.
Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
10 Ja kuin he tulivat Jordanin rajoille, jotka Kanaanin maassa ovat, rakensivat Rubenilaiset, Gadilaiset ja puoli Manassen sukukuntaa siinä lähes Jordania jalon suuren alttarin.
Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
11 Ja kuin Israelin lapset kuulivat sanottavan: katso, Rubenin lapset, Gadin lapset ja puoli Manassen sukukuntaa ovat rakentaneet alttarin Kanaanin maata vastaan, lähes Jordanin rajoja Israelin lasten puolelle;
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
12 Ja Israelin lapset kuulivat sen, ja koko Israelin lasten joukko kokoontui Silossa, menemään ylös sotimaan heitä vastaan.
gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
13 Ja Israelin lapset lähettivät Rubenilaisten, Gadilaisten ja puolen Manassen sukukunnan tykö Gileadin maahan Pinehaan, papin Eleatsarin pojan,
Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
14 Ja kymmenen ylimmäistä päämiestä hänen kanssansa, yhden päämiehen kustakin isänsä huoneesta, kaikista Israelin sukukunnista, joista kukin oli isäinsä huonetten päämies Israelin tuhanten ylitse.
Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
15 Ja he tulivat Rubenilaisten, Gadilaisten ja puolen Manassen sukukunnan tykö Gileadin maahan ja puhuivat heidän kanssansa, sanoen:
Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
16 Näin kaikki Herran kansa käski teille sanoa: mikä on se rikos, jolla te olette rikkoneet Israelin Jumalaa vastaan, kääntääksenne itsenne tänäpäivänä Herrasta pois, rakentaen itsellenne alttaria, asettaaksenne teitänne tänäpäivänä Herraa vastaan.
“Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
17 Vähäkö meillä on Peorin pahuudesta, josta emme puhtaat ole hamaan tähän päivään asti? josta myös rangaistus tuli Herran kansan päälle.
Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
18 Ja te käännätte itsenne tänäpäivänä Herrasta pois; niin tapahtuu, että panette itsenne tänäpänä Herraa vastaan, niin pitää huomenna hänen vihansa palaman koko Israelin kansan päälle.
Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
19 Jos te luulette, että teidän perintömaanne on saastainen, niin tulkaat tänne ylitse Herran perintömaahan, jossa Herran maja on, ja ottakaat perintö meidän seassamme ja älkäät asettako teitänne Herraa vastaan ja meitä vastaan, rakentaen teillenne alttarin, paitsi Herran meidän Jumalamme alttaria.
Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
20 Eikö Akan Seran poika tehnyt raskaasti syntiä kirotussa, ja viha tuli koko Israelin ylitse ja ei hän yksin hukkunut pahuudessansa.
Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
21 Niin vastasivat Rubenin ja Gadin lapset ja puoli Manassen sukukuntaa ja sanoivat Israelin tuhanten päämiehille:
Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
22 Herra väkevä Jumala, Herra väkevä Jumala tietää sen, ja Israel myös mahtaa itse tietää; jos me olemme langenneet pois ja syntiä tehneet Herraa vastaan, niin älkäät auttako hän meitä tänäpäivänä.
Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
23 Ja jos me olemme alttarin rakentaneet, kääntääksemme meitämme Herrasta pois ja uhrataksemme sen päällä polttouhria ja ruokauhria, taikka tehdäksemme kiitosuhria sen päällä, niin etsiköön sitä Herra.
Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
24 Ja jos emme paljo ennemmin ole sitä tehneet sen asian pelvon tähden, sanoen: tästälähin mahtaa teidän lapsenne sanoa meidän lapsillemme: mitä teidän on tekemistä Herran Israelin Jumalan kanssa?
“Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
25 Herra on pannut Jordanin rajamaaksi meidän ja teidän välillemme, te Rubenin ja Gadin lapset; ei ole teillä yhtään osaa Herrassa: ja niin teidän lapsenne saattavat pois meidän lapsemme Herraa pelkäämästä.
Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
26 Sentähden me sanoimme: tehkäämme se meillemme, rakentakaamme alttari, ei uhriksi eli polttouhriksi,
“Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
27 Mutta todistukseksi meidän ja teidän vaiheellamme, ja meidän sukumme meidän jälkeemme, tehdäksemme Herran palvelusta hänen edessänsä meidän polttouhrillamme, kiitosuhrillamme ja muilla uhreillamme; ja teidän lapsenne ei pidä tästälähin sanoman meidän lapsillemme: ei ole teillä yhtään osaa Herrassa.
Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
28 Sillä me sanoimme: se olkoon, kuin he niin sanovat meille, taikka meidän lapsillemme tästedes, niin me taidamme sanoa: katsokaat vertausta Herran alttariin, jonka meidän vanhempamme tehneet ovat, ei polttouhriksi taikka teurasuhriksi vaan todistukseksi teidän ja meidän vaiheellamme.
“Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
29 Pois se meistä, että me asetamme itsemme Herraa vastaan, ja käännymme tänäpäivänä hänestä pois, ja rakennamme alttarin polttouhriksi, ruokauhriksi ja muuksi uhriksi, paitsi Herran meidän Jumalamme alttaria, joka on hänen majansa edessä.
“Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
30 Kuin Pinehas pappi ja kansan ylimmäiset ja Israelin tuhanten päämiehet, jotka olivat hänen kanssansa, kuulivat nämät sanat, jotka Rubenin, Gadin ja Manassen lapset sanoivat, kelpasi se heille sangen hyvin.
Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
31 Ja Pinehas papin Eleatsarin poika sanoi Rubenin, Gadin ja Manassen lapsille: tänäpänä ymmärsimme me Herran olevan meidän kanssamme, ettette syntiä tehneet tällä rikoksella Herraa vastaan: nyt te vapahditte Israelin lapset Herran kädestä.
Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
32 Niin meni Pinehas papin Eleatsarin poika, ja ylimmäiset Gileadin maalta, Rubenin ja Gadin lasten tyköä Kanaanin maahan jälleen Israelin lasten tykö ja sanoi sen heille.
Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
33 Niin se kelpasi hyvin Israelin lapsille, ja Israelin lapset kunnioittivat Jumalaa ja ei enää sanoneet, että he tahtoivat sinne mennä heitä vastaan sotaväen kanssa maata hävittämään, jossa Rubenin ja Gadin lapset asuivat.
Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
34 Ja Rubenin ja Gadin lapset kutsuivat sen alttarin, että se olis todistukseksi meidän välillämme, ja että Herra on Jumala.
Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”

< Joosuan 22 >