< Joosuan 13 >

1 Kuin Josua vanheni ja ijälliseksi tuli, sanoi Herra hänelle: sinä olet vanhentunut ja ijälliseksi tullut, ja maata on vielä aivan paljo jäänyt omistamata.
Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
2 Tämä on se jälellä oleva maa: kaikki Philistealaisten maan ääret ja koko Gessuri,
“Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
3 Sihorista, joka juoksee Egyptin editse, Ekronin maan ääriin asti, pohjan puoleen, jotka luetaan Kanaanealaisille; ne viisi Philistealaisten päämiestä ovat: Gasilainen, Asdonilainen, Asklonilainen, Gatilainen, Ekronilainen ja Avilainen.
láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
4 Mutta eteläänpäin ovat kaikki Kanaanealaisten maat ja Meara, joka on Zidonilaisten, Aphekiin saakka ja hamaan Amorilaisten maan ääriin asti,
láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
5 Ja myös Gibiläisten maa, ja koko Libanon auringon nousemiseen päin, BaalGadista Hermonin vuoren alta, siihenasti kuin Hamatiin tullaan.
àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
6 Kaikki jotka vuorella asuvat, Libanonista lämpimään veteen asti, ja kaikki Zidonilaiset: minä ajan ne Israelin lasten edestä pois; ainoasti jaa ne Israelille perimiseksi, niinkuin minä olen sinulle käskenyt.
“Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
7 Niin jaa nyt tämä maa yhdeksän sukukunnan välillä perimiseksi, ja puolelle Manassen sukukunnalle.
pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
8 Sillä Rubenilaiset ja Gadilaiset ovat toisen puolen Manassen sukukunnan kanssa saaneet perimisensä, jonka Moses heille oli antanut sillä puolella Jordania itään päin, niinkuin Herran palvelia Moses heille sen antanut oli:
Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
9 Aroerista, joka on Arnonin ojan reunalla, ja siitä kaupungista, joka on ojan keskellä, ja koko Medeban lakeuden Diboniin asti,
Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
10 Ja kaikki Sihonin Amorilaisten kuninkaan kaupungit, joka hallitsi Hesbonissa, Ammonin lasten maan rajoihin asti,
Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
11 Ja Gileadin ja Gessurin ja Maakatin maan ääret, ja koko Hermonin vuoren, ja koko Basanin Salkaan asti;
Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
12 Koko Ogin Basanin kuninkaan valtakunnan, joka hallitsi Astarotissa ja Edreissä, joka vielä jäänyt oli uljaista, ja Moses löi heitä ja ajoi heitä pois.
ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
13 Mutta Israelin lapset ei ajaneet Gessurilaisia ja Maakatilaisia ulos, vaan Gessurilainen ja Maakatilainen asuu Israelin lasten seassa tähän päivään asti.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
14 Mutta Leviläisten sukukunnalle ei hän antanut yhtään perimistä; sillä Herran Israelin Jumalan polttouhri on heidän perintönsä, niinkuin hän heille sanonut oli.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
15 Ja Moses antoi Rubenin lasten suvulle, heidän sukukuntainsa jälkeen:
Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
16 Että heidän rajansa oli Aroerista, joka on Arnonin ojan reunalla, ja se kaupunki ojan keskellä kaiken sen tasaisen kedon kanssa Medeban tykönä;
láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
17 Hesbonin kaupunkeinensa, jotka ovat tasaisella kedolla: Dibonin, BamotBaalin ja BetBaalMeonin,
sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
18 Jaksan, Kedemotin, Mephaotin,
Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
19 Kirjataimin, Sibman, Zeretin, Saharin laakson, vuorilla,
Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
20 Ja BetPeorin, ne ojat Pisgan tykönä ja BetJesimotin,
Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
21 Ja kaikki lakeuden kaupungit, ja koko Sihonin, Amorilaisten kuninkaan valtakunnan, joka hallitsi Hesbonissa, jonka Moses löi, niin myös Midianin päämiehet: Evin, Rekemin, Zurin, Hurin ja Reban, Sihonin päämiehet, jotka maassa asuivat.
gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
22 Ja Bileaminkin Beorin pojan, tietäjän, Israelin lapset miekalla kuoliaaksi löivät muita tapettaessa.
Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
23 Ja Rubenin lasten raja oli Jordani rajoinensa. Tämä on Rubenin lasten perimys heidän sukukuntainsa, kaupunkeinsa ja kyläinsä jälkeen.
Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
24 Ja Moses antoi Gadin lasten sukukunnalle heidän sukukuntainsa jälkeen,
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
25 Että heidän rajansa oli Jaeser, ja kaikki Gileadin kaupungit, ja puoli Ammonin lasten maata, Aroeriin asti, joka on Rabban kohdalla,
Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
26 Ja Hesbonista RamatMitspeen ja Betoniimiin asti, ja Mahanaimista Debirin rajaan asti,
àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
27 Ja laaksossa Betaram ja BetNimra, Sukkot ja Zaphon, joka jäi Sihonin Hesbonin kuninkaan valtakunnasta; joiden raja oli Jordani Kinneretin meren ääreen asti, toisella puolella Jordania itään päin.
àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
28 Tämä on Gadin lasten perimys heidän sukukunnissansa, kaupungeissansa ja kylissänsä.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
29 Ja Moses antoi puolelle Manassen lasten suvulle sen mikä puolelle Manassen sukukunnalle tuli, heidän sukukuntainsa jälkeen,
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
30 Että heidän rajansa oli Mahanaimista koko Basan, koko Ogin Basanin kuninkaan valtakunta ja kaikki Jairin kylät, jotka ovat Basanissa, kuusikymmentä kaupunkia,
Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
31 Ja puolen Gileadia ja Astarotia, Edreiä Ogin valtakunnan kaupungit Basanissa (antoi hän) Makirin Manassen pojan lapsille, toiselle puolelle Makirin lapsia heidän sukukuntainsa jälkeen.
ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
32 Tämä on se minkä Moses antoi Moabin kedoilla, sillä puolella Jordania, Jerihon kohdalla itään päin.
Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
33 Mutta Levin sukukunnalle ei antanut Moses yhtään perimystä; Herra Israelin Jumala on heidän perimisensä, niinkuin hän heille sanonut oli.
Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.

< Joosuan 13 >