< Jobin 37 >

1 Siitä myös hämmästyy minun sydämeni ja vapisee.
“Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú, ó sì kúrò ní ipò rẹ̀.
2 Kuulkaat visusti hänen vihansa huutoa, ja puhetta, joka hänen suustansa käy ulos.
Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀, àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.
3 Hän toimittaa sen oikeuden kaikkein taivasten alla; ja hänen leimauksensa paistaa maan ääristä.
Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo, mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.
4 Senjälkeen kuuluu pitkäisen jylinä, ja se jylisee suurella äänellä; ja koska hänen jylinänsä kuullaan, ei sitä taideta estää.
Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù; ó sì fi ohùn ọláńlá rẹ̀ sán àrá. Òhun kì yóò sì dá àrá dúró, nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.
5 Jumala jylistää pauhinallansa ihmeellisesti, ja tekee suuria ja tutkimattomia töitä.
Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu; ohùn ńlá ńlá ni í ṣe tí àwa kò le mọ̀.
6 Hän puhuu lumelle, ja se kohta tulee maan päälle, ja sadekuurolle, ja niin sadekuurolla on voima.
Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’ àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, ‘Fún òjò ńlá agbára rẹ̀.’
7 Hänen kädessänsä ovat kaikki ihmiset kätketyt, että kaikki tuntisivat hänen tekonsa.
Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀, ó sì tún dá olúkúlùkù ènìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀.
8 Metsän pedot pakenevat varjoon ja pysyvät asumapaikoissansa.
Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ, wọn a sì wà ni ipò wọn.
9 Etelästä tulee tuulispää ja pohjasta kylmä.
Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá, àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọsánmọ̀ ká.
10 Jumalan hengestä tulee pakkanen ja ahdistaa laviat vedet.
Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni, ibú omi á sì súnkì.
11 Seijes myös hajoittaa pilvet, ja hänen valkeutensa levittää itsensä pilvien lävitse.
Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo, a sì tú àwọsánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.
12 Hän kääntää pilvensä kuhunka hän tahtoo, tekemään kaikkia, mitä hän tahtoo maan piirin päällä.
Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀, kí wọn kí ó lè ṣe ohunkóhun tí ó pàṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.
13 Jos se tapahtuu yhdelle sukukunnalle eli maakunnalle, koska hän löydetään laupiaaksi.
Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀, tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.
14 Kuules näitä Job: seiso ja ota vaari Jumalan ihmeellisistä töistä.
“Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí; dúró jẹ́ẹ́ kí o sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.
15 Tiedätkös, koska Jumala saattaa nämät heidän päällensä, ja koska hän antaa pilviensä valkeuden paistaa?
Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀, tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọsánmọ̀ rẹ̀ dán?
16 Tiedätkös, kuinka pilvet hajoittavat heitänsä? täydellisen viisauden ihmeellisiä töitä?
Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ, iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?
17 Että sinun vaattees lämpeevät, kuin ilma tyventyy etelästä?
Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná, nígbà tí ó fi atẹ́gùn ìhà gúúsù mú ayé dákẹ́.
18 Levitätkö sinä hänen kanssansa pilviä, jotka vahvat ovat niinkuin valettu peili?
Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin, tí ó sì dàbí dígí tí ó yọ̀ dà?
19 Ilmoita sinä meille, mitä meidän pitäis hänelle sanoman; sillä emme ulotu hänen tykönsä pimeydeltä.
“Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un; nítorí pé àwa kò le wádìí ọ̀rọ̀ náà nítorí òkùnkùn wa.
20 Kuka luettelee hänelle, mitä minä puhun? jos joku puhuu, niin hän niellään.
A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀? Tàbí ẹnìkan lè wí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbé mi mì?
21 Ei nähdä nyt valkeutta, joka pilvissä leimahtaa; vaan kuin tuuli puhaltaa, niin seijestyy.
Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí oòrùn tí ń dán nínú àwọsánmọ̀, ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì gbá wọn mọ́.
22 Pohjoisesta tulee kulta peljättävän Jumalan kunniaksi.
Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá; lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rù ńlá wa.
23 Mutta Kaikkivaltiasta emme taida löytää, joka on niin suuri voimassa; ja ei hän tarvitse vastata oikeudessansa ja suuressa vanhurskaudessansa.
Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá; nínú ìdájọ́ àti títí bi òun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.
24 Sentähden täytyy ihmisten häntä peljätä: ja ei hän katso yhtään taitavaa sydämestä.
Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀, òun kì í ṣe ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?”

< Jobin 37 >