< Jobin 29 >

1 Job puhui taas sananlaskunsa ja sanoi:
Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
2 Ah jos minä olisin niinkuin entisinä kuukausina! niinä päivinä, joina Jumala minun kätki,
“Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
3 Koska hänen valkeutensa paisti minun pääni päälle, ja minä kävin pimeissä hänen valkeudessansa,
nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
4 Niinkuin minä olin nuorena olessani; koska Jumalan salaisuus oli minun majani päällä;
Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
5 Koska Kaikkivaltias oli vielä minun kanssani, ja minun nuorukaiseni minun ympärilläni;
nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
6 Koska minä pesin minun tieni voilla, ja kallio vuoti minulle öljy-ojat;
nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
7 Koska minä menin kaupunin porteille, ja annoin valmistaa istuimeni kujille;
“Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
8 Kuin nuoret näkivät minun, niin he pakenivat, ja vanhat nousivat ja seisoivat minun edessäni,
nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
9 Ylimmäiset lakkasivat puhumasta, ja panivat kätensä suunsa päälle,
àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
10 Ruhtinasten ääni kätkeysi, ja heidän kielensä suun lakeen tarttui.
Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
11 Sillä kenen korva minun kuuli, se kiitti minua onnelliseksi, ja jonka silmä minun näki, se todisti minusta.
Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
12 Sillä minä autin köyhää, joka huusi, ja orpoa, jolla ei auttajaa ollut.
nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
13 Niiden siunaus, jotka katoomallansa olivat, tuli minun päälleni; ja minä ilahutin leskein sydämen.
Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
14 Vanhurskaus oli minun pukuni, jonka minä päälleni puin, ja minun oikeuteni oli minulle niinkuin hame ja kaunistus.
Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
15 Minä olin sokian silmä ja ontuvan jalka.
Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
16 Minä olin köyhäin isä, ja jonka asiaa en minä ymmärtänyt, sen minä visusti tutkin.
Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
17 Minä särjin väärän syömähampaat, ja otin saaliin hänen hampaistansa,
Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
18 Minä ajattelin: minä riuduin pesässäni, ja teen päiväni moneksi niinkuin sannan.
“Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
19 Minun juureni putkahti veden tykönä, ja kaste pysyi laihoni päällä.
Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
20 Minun kunniallisuuteni uudistui minun edessäni, ja minun joutseni muuttui uudeksi minun kädessäni.
Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
21 He kuulivat minua ja odottivat, ja vaikenivat minun neuvooni.
“Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
22 Minun sanani jälkeen ei yksikään enempää puhunut, ja minun puheeni tiukkui heidän päällensä.
Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
23 He odottivat minua niinkuin sadetta, ja avasivat suunsa niinkuin ehtoosadetta vastaan.
Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
24 Jos minä nauroin heidän puoleensa, ei he luottaneet sen päälle, eikä tahtoneet minua murheesen saattaa.
Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
25 Kuin minä tulin heidän kokouksiinsa, niin minun täytyi istua ylimpänä: ja asuin niinkuin kuningas sotaväen keskellä, lohduttaissani murheellisia.
Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.

< Jobin 29 >