< Jobin 20 >

1 Silloin Zophar Naemasta vastasi ja sanoi:
Ìgbà náà ní Sofari, ará Naama dáhùn, ó sì wí pé,
2 Minun ajatakseni vaativat siis minua vastaamaan, ja en minä taida itsiäni pidättää.
“Nítorí náà ní ìrò inú mi dá mi lóhùn, àti nítorí èyí náà ní mo sì yára si gidigidi.
3 Minä tahdon kuulla, jos joku minua nuhtelee ja laittaa; sillä minun ymmärrykseni benki vastaa minun puolestani.
Mo ti gbọ́ ẹ̀san ẹ̀gàn mi, ẹ̀mí òye mi sì dá mi lóhùn.
4 Etkös tiedä sen aina niin käyneen siitä ajasta kuin ibminen on pantu maan päälle,
“Ìwọ kò mọ̀ èyí rí ní ìgbà àtijọ́, láti ìgbà tí a sọ ènìyàn lọ́jọ̀ sílé ayé,
5 Että jumalattomien kerskaus ei ulotu kauvas; ulkokullattuin ilo on silmänräpäykseksi.
pé, orin ayọ̀ ènìyàn búburú, ìgbà kúkúrú ni, àti pé, ní ìṣẹ́jú kan ní ayọ̀ àgàbàgebè?
6 Jos hänen korkeutensa ulottuis taivaasen, ja hänen päänsä sattuis pilviin;
Bí ọláńlá rẹ̀ tilẹ̀ gòkè dé ọ̀run, ti orí rẹ̀ sì kan àwọsánmọ̀;
7 Niin pitää hänen viimein katooman niinkuin loka, niin että ne jotka hänen ovat näneet, sanovat: kussa hän on?
ṣùgbọ́n yóò ṣègbé láéláé bí ìgbẹ́ ara rẹ̀; àwọn tí ó ti rí i rí yóò wí pé, ‘Òun ha dà?’
8 Niinkuin uni katoo, niin ei pidä häntä löydettämän, ja niinkuin yönäkö pitää hänen raukeaman.
Yóò fò lọ bí àlá, a kì yóò sì rí i, àní a ó lé e lọ bi ìran òru.
9 Se silmä, joka hänen nähnyt on, ei pidä häntä enää näkemän, ja hänen paikkansa ei pidä häntä enää näkemän.
Ojú tí ó ti rí i rí kì yóò sì rí i mọ́, bẹ́ẹ̀ ni ibùjókòó rẹ̀ kì yóò sì ri i mọ́.
10 Hänen lapsensa pitää kerjääjiä palveleman, ja hänen kätensä pitää jälleen hänelle antaman, mitä hän ryövännyt on.
Àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wá àti rí ojúrere lọ́dọ̀ tálákà, ọwọ́ rẹ̀ yóò sì kó ọrọ̀ wọn padà.
11 Hänen luunsa pitää maksaman hänen salaiset syntinsä, ja pitää makaaman maassa hänen kanssansa.
Egungun rẹ̀ kún fún agbára ìgbà èwe rẹ̀, tí yóò bá a dùbúlẹ̀ nínú erùpẹ̀.
12 Ehkä vielä pahuus maistais makiasti hänen suussansa, kuitenkin pitää hänen sen kätkemän kielensä päälle.
“Bí ìwà búburú tilẹ̀ dún ní ẹnu rẹ̀, bí ó tilẹ̀ pa á mọ́ nísàlẹ̀ ahọ́n rẹ̀,
13 Hän säästää, ja ei hylkää sitä, vaan pitää sen suussansa.
bí ó tilẹ̀ dá a sì, tí kò si kọ̀ ọ́ sílẹ̀, tí ó pa á mọ́ síbẹ̀ ní ẹnu rẹ̀,
14 Hänen ruokansa pitää muuttuman hänen vatsassansa, kärmeen sapeksi hänen sisälmyksissänsä.
ṣùgbọ́n oúnjẹ rẹ̀ nínú ikùn rẹ̀ ti yípadà, ó jásí òróró paramọ́lẹ̀ nínú rẹ̀;
15 Sen tavaran jonka hän niellyt on, pitää hänen ylös oksentaman; ja Jumala ajaa ne ulos hänen vatsastansa.
Ó ti gbé ọrọ̀ mì, yóò sì tún bí i jáde; Ọlọ́run yóò pọ̀ ọ́ yọ jáde láti inú rẹ̀ wá.
16 Hänen pitää imemän kärmeen myrkkyä, ja kyykärmeen kieli on hänen tappava.
Ó ti fà oró paramọ́lẹ̀ mú; ahọ́n ejò olóró ní yóò pa á.
17 Ei hänen pidä näkemän ojia ja virtoja, joista hunaja ja voi vuotavat.
Kì yóò rí odò wọ̀n-ọn-nì, ìṣàn omi, odò tí ń ṣàn fún oyin àti ti òrí-àmọ́.
18 Hän tekee työtä, ja ei saa nautita, ja hänen kalunsa pitää toisen saaman, niin ettei hänellä pidä niistä iloa oleman.
Ohun tí ó ṣiṣẹ́ fún ni yóò mú un padà, kí yóò sì gbé e mì; gẹ́gẹ́ bí ọrọ̀ tí ó ní, kì yóò sì ìgbádùn nínú rẹ̀.
19 Sillä hän on polkenut ja hyljännyt köyhän, hän on repinyt itsellensä huoneita, joita ei hän ole rakentanut.
Nítorí tí ó fi owó rẹ̀ ni tálákà lára, ó sì ti pẹ̀yìndà si wọ́n; nítorí ti ó fi agbára gbé ilé tí òun kò kọ́.
20 Sillä hänen vatsansa ei ole taitanut täyteen tulla, ja hänen kalliit kalunsa ei taida häntä pelastaa.
“Nítorí òun kò mọ̀ ìwà pẹ̀lẹ́ nínú ara rẹ̀, kì yóò sì gbà nínú èyí tí ọkàn rẹ̀ fẹ́ sílẹ̀.
21 Hänen ruastansa ei pidä mitään jäämän; sentähden ei pidä hänen hyvät päivänsä pysyväiset oleman.
Ohun kan kò kù fún jíjẹ́ rẹ̀; nítorí náà ọ̀rọ̀ rẹ̀ kì yóò dúró pẹ́.
22 Ehkä hänellä olis yltäkyllä, niin pitää hänellä kuitenkin ahdistus oleman: kaikki käden vaiva pitää hänen päällensä tuleman.
Nínú ànító rẹ̀, ìdààmú yóò dé bá a; àwọn ènìyàn búburú yóò dáwọ́jọ lé e lórí.
23 Hänen vatsansa pitää vihdoin täyteen tuleman, ja hänen pitää lähettämän vihansa hirmuisuuden hänen päällensä: hän antaa sataa sotansa hänen päällensä.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ó bá fẹ́ jẹun, Ọlọ́run yóò fà ríru ìbínú rẹ̀ sí í lórí, nígbà tó bá ń jẹun lọ́wọ́, yóò sì rọ òjò ìbínú rẹ̀ lé e lórí.
24 Hänen pitää pakeneman rautaisia sota-aseita, ja vaskijoutsen pitää hänen lävitsensä käymän.
Bi o tilẹ̀ sá kúrò lọ́wọ́ ohun ìjà ìrìn; ọrun akọ irin ní yóò ta a po yọ.
25 Avoin miekka pitää käymän hänen lävitsensä, ja miekan välkkynä, joka hänelle pitää karvas oleman, pitää pelvolla hänen päällensä tuleman.
O fà á yọ, ó sì jáde kúrò lára; idà dídán ní ń jáde láti inú òróòro wá. Ẹ̀rù ńlá ń bẹ ní ara rẹ̀;
26 Koko pimeys on hänelle kätketty tavaraksi; tuli pitää hänen kuluttaman, joka ei puhallettu ole, ja sille, joka jää hänen majaansa, pitää pahoin käymän.
òkùnkùn biribiri ní a ti pamọ́ fún ìṣúra rẹ̀. Iná ti a kò fẹ́ ní yóò jó o run yóò sì jẹ èyí tí ó kù nínú àgọ́ rẹ̀ run.
27 Taivaan pitää ilmoittaman hänen pahuutensa, ja maan pitää asettaman itsensä häntä vastaan.
Ọ̀run yóò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn, ayé yóò sì dìde dúró sí i.
28 Hänen huoneensa hedelmä pitää vietämän pois, ja hajoitettaman hänen vihansa päivänä.
Ìbísí ilé rẹ̀ yóò kọjá lọ, àti ohun ìní rẹ̀ yóò sàn dànù lọ ni ọjọ́ ìbínú Ọlọ́run.
29 Tämä on jumalattoman ihmisen osa Jumalalta, ja hänen puheensa perintö Jumalalta.
Èyí ni ìpín ènìyàn búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá, àti ogún tí a yàn sílẹ̀ fún un láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.”

< Jobin 20 >