< Jeremian 9 >

1 Jospa minun päässäni olis kyllä vettä, ja minun silmäni olis kyynelten lähde, että minä voisin itkeä päivää ja yötä lyötyjä minun kansastani.
Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
2 Jospa minulla olis matkamiesten maja korvessa, niin minä jättäisin minun kansani ja menisin pois heidän tyköänsä; sillä he ovat kaikki huorintekiät ja paha joukko.
Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
3 He ampuvat kielellänsä niinkuin joutsellansa valhetta ja ei totuutta; vaeltavat väkivallalla maassa ja menevät yhdestä pahuudesta niin toiseen, ei totellen minua, sanoo Herra.
Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
4 Jokainen karttakoon lähimmäistänsä, ja älköön uskoko veljeänsäkään; sillä veli sortaa ja painaa alas veljensä, ja ystävä pettää ystävänsä.
“Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
5 Ystävä pilkkaa ystäväänsä, ja ei puhu totuutta; he totuttavat kielensä puhumaan valhetta, ja ahkeroitsevat pahaa tehdä.
Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
6 Sinä asut petoksen keskellä, ja ei he taida minua tuta petoksen tähden, sanoo Herra.
Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
7 Sentähden sanoo Herra Zebaot näin: katso, minä sulaan heitä; ja koettelen heitä; sillä mitä minä muuta teen minun kansani tyttären tähden?
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
8 Heidän petolliset kielensä ovat murhanuolet; suullansa he puhuvat lähimmäisensä kanssa ystävällisesti, vaan sydämessänsä he väijyvät häntä.
Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
9 Eikö minun sentähden pitäisi rankaiseman heitä, sanoo Herra? ja eikö minun sieluni pitäisi kostaman senkaltaiselle kansalle kuin tämä on?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
10 Minä itken ja surkuttelen vuorilla, ja valitan korvessa laitumilla; sillä he ovat peräti hajoitetut, niin ettei siitä enään kenkään vaella, ei myös siellä kuulu karjan ääntä; taivaan linnut ja kaikki karja ovat jo lentäneet ja menneet pois.
Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
11 Ja minä teen Jerusalemin kiviraunioksi, ja lohikärmeiden pesäksi; ja minä hävitän Juudan kaupungit, niin ettei niissä yhtäkään pidä asuman.
“Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
12 Joka viisas olis, hän ajattelis sitä, ja ilmoittais, mitä Herran suu hänelle sanoo. Minkätähden siis maa niin hukutetuksi ja hävitetyksi tulee, että se on niinkuin erämaa, josta ei yksikään vaella?
Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
13 Ja Herra sanoi: sentähden, että he hylkäävät minun lakini, jonka minä heille annoin, ja ei tottele minun ääntäni eikä elä sen jälkeen,
Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
14 Vaan seuraavat oman sydämensä tahtoa ja Baalia, niinkuin heidän isänsä heitä opettaneet ovat.
Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
15 Sentähden näin sanoo Herra Zebaot, Israelin Jumala: katso, minä syötän tämän kansan koiruoholla, ja annan heidän sappea juoda.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
16 Minä hajoitan heidät pakanain sekaan, joita ei he eikä heidän isänsä tunne, ja lähetän miekan heidän peräänsä, siihenasti että minä heidät kaikki lopetan.
Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
17 Näin sanoo Herra Zebaot: tutkikaat tätä; toimittakaat teillenne itkeväisiä vaimoja, että he tulisivat; ja lähettäkäät niiden perään, jotka taitavat ovat, että he tulisivat,
Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
18 Ja kiiruhtaisivat meitä valittamaan, että meidän silmämme kyyneleitä vuodattaisivat, ja meidän silmäripsemme vettä tiukkuisivat,
Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
19 Että valitus kuuluis Zionissa (näin: ) voi kuinka me olemme näin hävitetyt! me olemme peräti häväistyt, sillä meidän täytyy maalta paeta, että meidän asuinsiamme ovat kukistetut.
A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
20 Kuulkaa siis, te vaimot, Herran sanaa, ja käsittäkäät korviinne hänen suunsa puhe; antakaat teidän tyttärenne itkeä, ja opettakaan toinen toistansa valittamaan, (näin: )
Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
21 Kuolema on tullut meidän akkunoistamme sisälle ja meidän huoneisiimme langennut, lapsia kaduilla tappamaan ja nuorukaisia kujilla.
Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
22 Näin sanoo Herra: sano: ihmisten ruumiit pitää, niinkuin loka maan päällä, kaatuman, ja niinkuin jalalliset jäävät elomiehen perään, jossa ei ole ylösottajaa.
Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
23 Näin sanoo Herra: älkään viisas kerskatko viisaudestansa, älkään väkevä kerskatko väkevyydestänsä, älkään myös rikas kerskatko rikkaudestansa;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
24 Vaan joka tahtoo kerskata, niin kerskatkaan siitä, että hän tietää ja tuntee minun, että minä olen Herra, joka teen laupiuden, oikeuden ja vanhurskauden maan päällä; sillä se minulle kelpaa, sanoo Herra.
Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
25 Katso, se aika tulee, sanoo Herra, että minä rankaisen kaikki ympärileikatut ympärileikkaamattomain kanssa:
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
26 Egyptin, Juudan, Edomin, Ammonin lapset, ja Moabin ja kaikki, jotka maan äärissä korvessa asuvat; sillä kaikilla pakanoilla on ympärileikkaamatoin esinahka, mutta koko Israelin huoneella on ympärileikkaamatoin sydän.
Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”

< Jeremian 9 >