< Jeremian 49 >

1 Ammonin lapsia vastaan sanoo Herra näin: eikö Israelilla lapsia ole, eli eikö hänellä perillistä ole? Miksi siis Malkom omistaa Gadin maan ja hänen kansansa asuu hänen kaupungeissansa?
Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Sentähden katso, aika tulee, sanoo Herra, että minä annan kuulla sotariekunan Ammonin lasten Rabbatin ylitse, että sen pitää yhdessä koossa autiona oleman, ja kylinensä tulella poltettaman; mutta Israelin pitää omistaman heidät, joilta he ovat omistetut olleet, sanoo Herra.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
3 Valita, o Hesbon, sillä Ai on kukistettu; huutakaat, te Rabban kylät, ja pukekaat itsenne säkkeihin, itkekäät ja juoskaat ympäri muureja; sillä Malkom viedään vankina pois, pappeinsa ja ruhtinastensa kanssa.
“Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Mitä sinä röyhkeilet laaksoistas? Sinun laaksos ovat upotetut, sinä tottelematoin tytär, joka luotat tavaroihis, (ja sanot sydämessäs: ) kuka tohtii tulla minun tyköni?
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Katso, minä annan tulla pelvon sinun päälles, sanoo Herra, Herra Zebaot, kaikista niistä, jotka asuvat sinun ympärilläs; niin että te jokainen pitää ajettaman pois toisensa tyköä, ja ei pidä kenenkään karkureita kokooman.
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Mutta sitte minä käännän Ammonin lasten vankiuden, sanoo Herra.
“Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
7 Edomia vastaan sanoo Herra Zebaot näin: eikö tietoa enään ole Temanissa? Eikö neuvoa enään ole taitavilla? joko heidän tietonsa loppui?
Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Paetkaat, palatkaat ja kätkekäät teitänne syvälle, Te Dedanin asuvaiset; sillä minä annan Esaulle tulla onnettomuuden, hänen etsikkonsa ajan.
Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 Viinan hakiat pitää tuleman sinun päälles, joiden ei pidä mitään sinulle jättämän jälkeensä; ja varkaat pitää yöllä tuleman sinun päälles, heidän pitää kyllä varastaman.
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 Sillä minä olen paljastanut Esaun, ja ilmoittanut hänen salaisen paikkansa, niin ettei hän taida itsiänsä kätkeä; hänen siemenensä, hänen veljensä ja hänen kylänsä miehet ovat hävitetyt, niin ettei yhtään enään ole.
Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Kuitenkin niiden, jotka jäävät orvoistas, tahdon minä suoda elää; ja sinun leskeis pitää minuun luottaman.
Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 Sillä näin sanoo Herra: katso, jotka ei ole syypäät juomaan kalkkia, niiden pitää totisesti juoman, ja sinun pitäis rankaisematta pääsemän? Ei sinun pidä rankaisematta pääsemän, vaan sinun pitää kaiketi juoman.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
13 Sillä minä olen vannonut itse kauttani, sanoo Herra, että Botsran pitää tuleman ihmeeksi, häväistykseksi, hävitykseksi ja kiroukseksi; ja kaikki hänen kaupunkinsa ijankaikkiseksi autioksi.
Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 Minä olen kuullut sanoman Herralta, että sanansaattaja on lähetetty pakanoille: kootkaat teitänne ja tulkaat tänne häntä vastaan, ja sotikaat.
Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 Sillä katso, minä olen sinun alentanut pakanain seassa, ja tehnyt sinun ylönkatsotuksi ihmisten seassa.
“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Sinun ylpeytes ja sinun sydämes koreus on sinun pettänyt, että sinä asut vuorten raoissa ja vallitset korkiat vuoret. Jos sinä tekisit pesäs niin korkiaksi kuin kotka, niin minä kuitenkin sieltä sinun kukistan alas, sanoo Herra.
Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
17 Juuri niin pitää Edom autioksi tuleman; ja kaikkein, jotka siitä käyvät ohitse, pitää ihmettelemän ja viheltämän kaikkia hänen vaivojansa.
“Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
18 Niinkuin Sodoma ja Gomorra lähikyläinsä kanssa kukistetut ovat, sanoo Herra, niin ettei kenkään siellä asu, eikä joku ihminen siellä olla taida.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 Katso, hän tulee ylös niinkuin jalopeura ylpeästä Jordanista vahvoja majoja vastaan; sillä minä tahdon antaa hänen nopiasti sieltä juosta, ja kuka tietää sen nuorukaisen, jonka minä varustan heitä vastaan? Sillä kuka on minun kaltaiseni? kuka tahtoo minun eteeni panna ajan? Ja kuka paimen voi olla minua vastaan?
“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Kuulkaat siis Herran neuvoa, jonka hän piti Edomista, ja hänen ajatuksiansa, jotka hän ajatteli Temanin asuvaisista: mitämaks että karjalapset pitää riepoittaman heitä, ja kukistaman heidän asumasiansa;
Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Niin että maan pitää vapiseman heidän lankeemisessansa, ja heidän parkunsa ja huutonsa pitää kuultaman Punaisessa meressä.
Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
22 Katso, hän lentää ylös niinkuin kotka, ja hajoittaa siipensä Botsran ylitse; silloin pitää Edomin sankarien sydän oleman niinkuin synnyttäväisen vaimon sydän.
Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
23 Damaskua vastaan: Hematissa ja Arpadissa on surkia meno; he epäilevät, sillä he kuulevat pahoja sanomia; asuvaiset meren tykönä ovat hämmästyksissä, niin ettei heillä ole lepoa.
Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damasku epäilee ja pakenee: hän vapisee ja on ahdistukssessa ja kivussa, niinkuin synnyttäväinen.
Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Kuinka? Eikö se kuuluisa kaupunki ole hyljätty, minun ilokaupunkini?
Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
26 Sentähden pitää hänen nuorukaisensa lankeeman hänen kaduillansa, ja kaikki hänen sotaväkensä tapettaman siihen aikaan, sanoo Herra Zebaot.
Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 Ja minä sytytän tulen Damaskun muurien päälle, niin että sen pitää polttaman Benhadadin huoneet.
“Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
28 Kedaria vastaan ja Hatsorin valtakuntia vastaan, jotka Nebukadnetsar, Babelin kuningas löi. Näin sanoo Herra: ylös, menkäät Kedariin, ja kukistakaat idän lapset.
Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 Heidän majansa ja laumansa pitää heiltä otettaman pois, heidän telttansa ja kaikki heidän kappaleensa, ja heidän kamelinsa pitää heidän ottaman myötänsä; ja pitää julmasti huutaman heidän tähtensä ympäristöltä.
Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 Paetkaat, joutukaat kiiruusti, menkäät syvään asumaan, te Hatsorin asuvaiset, sanoo Herra. Sillä Nebukadnetsar, Babelin kuningas, on teistä neuvoa pitänyt, ja ajattelee ja aikoo jotain teitä vastaan.
“Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 Ylös, menkäät kansaa vastaan, joka levossa on ja asuu suruttomasti, sanoo Herra; ei heillä ole ovea eikä telkeä, ja he asuvat yksinänsä.
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Heidän kamelinsa pitää ryöstettämän, ja heidän karjansa paljous otettaman pois; ja minä hajoitan heidät joka tuuleen, jotka nurkissa asuvat, ja joka taholta annan minä heidän onnettomuutensa tulla heidän päällensä, sanoo Herra.
Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
33 Ja Hatsorin pitää tuleman lohikärmetten asumasiaksi ja ijankaikkiseksi autioksi, niin ettei kenenkään pidä siellä asuman, ja ei yhdenkään ihmisen siellä oleman.
“Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
34 Tämä on Herran sana, joka tapahtui Jeremialle, prophetalle Elamia vastaan, Zedekian Juudan kuninkaan valtakunnan alussa, ja sanoi:
Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
35 Näin sanoo Herra Zebaot: katso, minä taitan Elamin joutsen, heidän ylimmäisen voimansa.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 Ja annan tulla Elamin päälle neljä tuulta neljästä taivaan äärestä, ja hajoitan heidät kaikkiin niihin tuuliin, niin ettei yhtään kansaa pidä oleman, kuhunka ei joku Elamin hajoitetuista tule.
Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 Ja minä saatan Elamin epäilemään heidän vihollistensa edessä ja niiden edessä, jotka väijyvät heidän henkeänsä, ja annan onnettomuuden tulla heidän päällensä, minun julman vihani, sanoo Herra; ja lähetän miekan heidän päällensä, siihenasti että minä heidät lopetan.
Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 Minun istuimeni panen minä Elamiin, ja hävitän sieltä sekä kuninkaan että ruhtinaat, sanoo Herra.
Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
39 Mutta viimeisellä ajalla käännän minä Elamin vankiuden, sanoo Herra.
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.

< Jeremian 49 >