< Jeremian 32 >

1 Tämä on se sana, joka tapahtui Herralta Jeremialle, kymmenentenä Zedekian, Juudan kininkaan, vuonna, joka on Nebukadnetsarin kahdeksastoistakymmenes vuosi.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
2 Silloin Babelin kuninkaan sotajoukko piiritti Jerusalemin; mutta propheta Jeremia oli vankina pihassa vankihuoneen edessä, joka oli Juudan kuninkaan huoneessa.
Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
3 Johonka Zedekia, Juudan kuningas, oli antanut panna hänen, sanoen: miksi sinä ennustat ja sanot: näitä sanoo Herra: katso, minä annan tämän kaupungin Babelin kuninkaan käsiin, ja hän on voittava sen?
Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
4 Ja Zedekian, Juudan kuninkaan, ei pidä kaldealaisilta pääsemän, vaan minä kaiketi annan hänen Babelin kuninkaan käsiin, niin että hänen pitää suusta suuhun häntä puhutteleman, ja silmillänsä hänen silmänsä näkemän.
Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
5 Ja hänen pitää viemän Zedekian Babeliin; siellä hänen pitää myös pysymän, siihenasti kuin minä etsin häntä, sanoo Herra. Vaikka te soditte kaldealaisia vastaan, ei sen kuitenkaan pidä teille menestyvän.
Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
6 Ja Jeremia sanoi: Herran sana on tapahtunut minulle ja sanoi:
Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
7 Katso, Hanamel Sallumin, sinun setäs poika, tulee sinun tykös, ja on sanova: osta minun peltoni Anatotissa, sillä sinulla on lähimmäinen oikeus sitä ostaa.
Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
8 Ja niin Hanamel minun setäni poika tuli minun tyköni, niinkuin Herra oli sanonut, pihalla vankihuoneen edessä, ja sanoi minulle: osta minun peltoni Anatotissa, joka on Benjaminin maalla; sillä sinulla on siihen perintö-oikeus, ja sinä olet lähimmäinen: osta se sinulles. Niin minä ymmärsin, sen olevan Herran sanan.
“Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
9 Ja ostin Hanamelilta minun setäni pojalta pellon, joka on Anatotissa, ja punnitsin hänelle rahaa seitsemäntoista sikliä ja kymmenen hopea penninkiä.
Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
10 Ja kirjoitin kirjaan, ja vahvistin sen sinetillä, ja otin todistukset, ja punnitsin rahan vaa'alla.
Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
11 Ja otin sinetillä vahvistetun kauppakirjan tyköni, oikeuden ja tavan jälkeen, ja myös avoimen kirjan,
Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
12 Ja annoin kauppakirjan Barukille Neerijan pojalle, Mahsejan pojan, Hanamelin, minun setäni pojan silmäin edessää ja todistajain silmäin edessä, jotka kauppakirjan allekirjoittaneet olivat, ja kaikkien Juudalaisten silmäin edessä, jotka pihassa vankihuoneen edessä asuivat.
Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
13 ja minä käskin Barukia heidän silmäinsä edessä ja sanoin:
“Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
14 Näin sanoo Herra Zebaot, Israelin Jumala: ota nämä kirjat, tämä sinetillä vahvistettu kauppakirja, ja tämä avoin kirja, ja pane ne saviastiaan, että ne olisivat kauvan aikaa tallella.
èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
15 Sillä näin sanoo Herra Zebaot, Israelin Jumala: vielä nyt pitää ostettaman huoneita, peltoja ja viinamäkiä tässä maassa.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
16 Ja kun minä olin antanut Baarukille Nerian pojalle kauppakirjan, rukoilin minä Herraa ja sanoin:
“Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
17 Ah Herra, Herra! katso, sinä olet tehnyt taivaat ja maan suurella voimallas ja ojennetulla käsivarrellas; ei ole mitään sinulle mahdotonta.
“Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
18 Sinä, joka monelle tuhannelle teet hyvin, ja kostat isäin pahat teot heidän lastensa helmaan heidän jälkeensä; sinä suuri ja väkevä Jumala, Zebaot on sinun nimes,
O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
19 Suuri neuvossa ja väkevä töissä, ja sinun silmäs ovat avoinna kaikkein ihmisten lasten teiden päälle, antaakses kullekin heidän menonsa jälkeen ja heidän töittensä hedelmän jälkeen.
Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
20 Sinä, joka Egyptin maalla merkkejä ja ihmeitä teit, ja aina tähän päivään asti, sekä Israelin että ihmisten kanssa, ja teit sinulles nimen, niinkuin se tänäpänä on.
O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
21 Sinä veit kansas Israelin ulos Egyptin maalta merkeillä ja ihmeillä ja väkevällä kädellä, ojennetulla käsivarrella, ja suurella pelvolla,
O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
22 Ja annoit heille tämän maan, jonka sinä heidän isillensä vannonut olit, sen heille antaakses: maan, joka rieskaa ja hunajaa vuosi.
Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
23 Ja koska he sinne tulivat ja omistivat sen, ei he kuulleet sinun ääntäs, eikä vaeltaneet sinun lakisi jälkeen; ja kaikkea mitä sinä käskenyt olit heidän tehdä, ei he sitä tehneet; sentähden sinä annoit myös kaiken tämän onnettomuuden heille tapahtua.
Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
24 Katso, tämä kaupunki on piiritetty, niin että se pitää voitettaman, ja kaupunki annettaman Kaldealaisten käsiin, jotka sotivat sitä vastaan miekalla, nälällä ja rutolla; ja niinkuin sinä olet sanonut, niin nyt tapahtuu, sen sinä näet.
“Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
25 Ja sinä Herra, Herra, sanoit minulle: osta sinulles pelto rahalla, ja ota todistukset, vaikka kaupunki pitää annettaman joutuu Kkaldealaisten käsiin.
Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
26 Ja Herran sana tapahtui Jeremialle ja sanoi:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
27 Katso, minä Herra olen kaiken lihan Jumala: pitäsikö minulle jotain oleman mahdotointa?
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
28 Sentähden sanoo Herra näin: katso, minä annan tämän kaupungin Kaldealaisten käsiin ja Nebukadnetsarin, Babelin kuninkaan käteen, ja hän on sen voittava.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
29 Ja kaldealaisten, jotka sotivat tätä kaupunkia vastaan, pitää tänne tuleman, ja sytyttävät tämän kaupungin tuleen ja polttavat sen niine taloineen, ja tähän kaupunkiin tulen sytyttämän, ja polttaman sen huoneinensa, kussa he Baalille kattoin pällä suitsuttaneet, ja muille jumalille juomauhreja uhranneet ovat, minua vihoittaaksensa.
Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
30 Sillä Israelin lapset ja Juudan lapset ovat tosin nuoruudestansa tehneet pahaa minun silmäini edessä; ja Israelin lapset ovat vihoittaneet minun kättensä töillä, sanoo Herra.
“Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
31 Siitä ajasta, kuin tämä kaupunki rakennettiin, niin tähän päivään asti, on hän tehnyt minun vihaiseksi ja julmaksi, niin että minun tyätyi heittää hänen pois kasvojeni edestä,
Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
32 Kaikkein Israelin lasten ja Juudan lasten pahuuden tähden, jonka he ovat tehneet, minua vihoittaaksensa, he ja heidän kuninkaansa, ruhtinaansa, pappinsa ja prophetansa, sekä Juudan miehet ja Jerusalemin asuvaiset.
Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
33 He ovat kääntäneet selkänsä minulle ja ei kasvojansa; vaikka minä annoin aikanansa ja alinomaa opettaa heitä, mutta ei he tahtoneet kuulla eikä oppia ottaa.
Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
34 Päälliseksi he ovat panneet kauhistuksensa siihen huoneeseen, jolla minusta on nimi, saastuttakksensa sitä.
Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
35 Ja ovat rakentaneet Baalin korkeuksia Ben-Hinnomin laaksossa, polttaakseen poikiansa ja tyttäriänsä Molokille, jota en minä ole heidän käskenyt, eiä myös ole minun mieleeni johtunut, että heidän tämän kauhistuksen piti tekemän, jolal he Juudan saattivat syntiä tekemään.
Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
36 Ja nyt sentähden sanoo Herra, Israelin Jumala näin tästä kaupungista, josta te sanotte, että hän pitää miekan, nälän ja ruton kautta Babelin kuninkaan käsiin annettaman.
“Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
37 Katso, minä tahdon heidät koota kaikista maakunnista, joihin minä olen heitä sysännyt pois suuressa vihassani, hirmuisuudessani ja julmuudessani ja tahdon tuottaa heitä jälleen tähän paikkaan, että heidän turvallisesti asuman pitää;
Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
38 Ja heidän pitää minun kansani oleman, ja minä tahdon olla heidän Jumalansa.
Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
39 Ja tahdon heille yhden sydämen ja yhden tien antaa, että he pelkäisivät minua kaikkena elinaikanansa, että heille ja heidän lapsillensa heidän jälkeensä pitäsi hyvästi käymän.
Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
40 Ja tahdon ijankaikkisen liiton tehdä heidän kanssansa, niin etten minä lakkaa heille hyvää tekemästä; ja tahdon minun pelkoni antaa heidän sydämihinsä, ettei he poikkeaisi minusta.
Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
41 Ja se pitää minun iloni oleman, että heille hyvää teen; ja tahdon heitä tähän maahan istuttaa uskollisesti, kaikesta minun sydämestäni ja kaikesta sielustani.
Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
42 Sillä näin sanoo Herra: niinkuin minä olen antanut tulla tämän kansan päälle kaiken tämän tämän suuren onnettomuuden, niin myös minä annan tulla heidän päällensä kaiken sen hyvän, kuin minä olen heille puhunut.
“Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
43 Ja vielä nyt pitää peltoja ostettaman tässä maassa, josta te sanotte: sen pitää autiona oleman, niin ettei siinä väkeä eli karjaa oleman pidä, ja pitää Kaldealaisten käsiin annettaman.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
44 Kuitenkin pitää pvielä nyt peltoja ostettaman rahalla ja kirjoituksella, niin sinetillä vahvistettaman ja todistajilla: Benjaminin maalla, ja ympäri Jerusalemia, ja Juudan kaupungeissa, jotka vuorilla ovat sillä minä tahdon kääntää heidän vankiutensa, sanoo Herra.
Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”

< Jeremian 32 >